< Numbers 24 >

1 Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Olúwa lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù.
Då nu Bileam såg att det var: HERRENS vilja att han skulle välsigna Israel, gick han icke, såsom de förra gångerna, bort och såg efter tecken, utan vände sitt ansikte mot öknen.
2 Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
Och när Bileam lyfte upp sina ögon och såg Israel lägrad efter sina stammar, kom Guds Ande över honom.
3 ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, “Àsọtẹ́lẹ̀ tí Balaamu ọmọ Beori, àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
Och han hov upp sin röst och kvad: »Så säger Bileam, Beors son, så säger mannen med det slutna ögat,
4 àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ là kedere.
så säger han som hör Guds tal, han som skådar syner från den Allsmäktige, i det han sjunker ned och får sina ögon öppnade:
5 “Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu, àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!
Huru sköna äro icke dina tält, du Jakob, dina boningar, du Israel!
6 “Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde, gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá, gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn, gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
De likna dalar som utbreda sig vida, de äro såsom lustgårdar invid en ström, såsom aloeträd, planterade av HERREN, såsom cedrar invid vatten.
7 Omi yóò sàn láti inú garawa: èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi. “Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ; ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
Vatten flödar ur hans ämbar, hans sådd bliver rikligen vattnad. Större än Agag skall hans konung vara, ja, upphöjd bliver hans konungamakt.
8 “Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá; wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré. Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run, wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú; wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
Det är Gud som har fört honom ut ur Egypten. Hans styrka är såsom en vildoxes. Han skall uppsluka de folk som stå honom emot, deras ben skall han sönderkrossa, och med sina pilar skall han genomborra dem.
9 Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún, bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn? “Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ, kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
Han har lagt sig ned, han vilar såsom ett lejon, såsom en lejoninna -- vem vågar oroa honom? Välsignad vare den som välsignar dig, och förbannad vare den som förbannar dig!»
10 Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.
Då upptändes Balaks vrede mot Bileam, och han slog ihop händerna. Och Balak sade till Bileam: »Till att förbanna mina fiender kallade jag dig hit, och se, du har i stället nu tre gånger välsignat dem.
11 Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”
Giv dig nu av hem igen. Jag tänkte att jag skulle få bevisa dig stor ära; men se, HERREN har förmenat dig att bliva ärad.»
12 Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,
Bileam svarade Balak: »Sade jag icke redan till sändebuden som du skickade till mig:
13 ‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?
'Om Balak än gåve mig så mycket silver och guld som hans hus rymmer, kunde jag dock icke överträda HERRENS befallning, så att jag efter eget tycke gjorde något, vad det vara må.' Vad HERREN säger, det måste jag tala.
14 Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
Se, jag går nu hem till mitt folk; men jag vill varsko dig om vad detta folk skall göra mot ditt folk i kommande dagar.»
15 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe: “Òwe Balaamu ọmọ Beori, òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
Och han hov upp sin röst och kvad: »Så säger Bileam, Beors son, så säger mannen med det slutna ögat,
16 ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí, tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo, tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:
så säger han som hör Guds tal och har kunskap från den Högste, han som skådar syner från den Allsmäktige, i det han sjunker ned och får sina ögon öppnade:
17 “Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí. Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́. Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu; yóò yọ jáde láti Israẹli. Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu, yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
Jag ser honom, men icke denna tid, jag skådar honom, men icke nära. En stjärna träder fram ur Jakob, och en spira höjer sig ur Israel. Den krossar Moabs tinningar och slår ned alla söner till Set.
18 Wọn yóò borí Edomu; yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
Edom skall han få till besittning till besittning Seir -- sina fienders länder. Ty Israel skall göra mäktiga ting;
19 Olórí yóò jáde láti Jakọbu yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
ur Jakob skall en härskare komma; han skall förgöra i städerna dem som rädda sig dit.»
20 Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
Och han fick se Amalek; då hov han upp sin röst och kvad: »En förstling bland folken är Amalek, men på sistone hemfaller han åt undergång.»
21 Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Ibùgbé rẹ ní ààbò, ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
Och han fick se kainéerna; då hov han upp sin röst och kvad: »Fast är din boning, och lagt på klippan är ditt näste.
22 síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”
Likväl skall Kain bliva utrotad; ja, Assur skall omsider föra dig i fångenskap.»
23 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀: “Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
Och han lov åter upp sin röst och kvad: »O ve! Vem skall bliva vid liv, när Gud låter detta ske?
24 Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu; wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi, ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
Skepp skola komma från kittéernas kust, de skola tukta Assur, tukta Eber; också han skall hemfalla åt undergång.»
25 Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.
Och Bileam stod upp och vände tillbaka hem; också Balak for sin väg.

< Numbers 24 >