< Numbers 24 >
1 Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Olúwa lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù.
Kwathi uBhalamu esebonile ukuthi kuyamthokozisa uThixo ukubusisa u-Israyeli, kasadinganga njalo imilingo njengakuqala, kodwa waphenduka wakhangela enkangala.
2 Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
Kwathi uBhalamu ekhangela wabona u-Israyeli emise izihonqo zakhe ngokwezizwe zakhe, uMoya kaNkulunkulu wehlela phezu kwakhe
3 ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, “Àsọtẹ́lẹ̀ tí Balaamu ọmọ Beori, àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
wasesitsho isambulelo sakhe: “Isambulelo sikaBhalamu indodana kaBheyori, isambulelo salowo omehlo akhe abonisisa kuhle,
4 àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ là kedere.
isambulelo salowo ozwa amazwi kaNkulunkulu, lowo obona umbono ovela kuSomandla, lowo owela phansi ngokuzehlisa, njalo omehlo akhe avulekile:
5 “Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu, àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!
Aze aba mahle amathente akho, Oh Jakhobe, izindawo zakho zokuhlala, Oh Israyeli!
6 “Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde, gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá, gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn, gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
Njengezigodi zisabalele, njengezivande zisekele umfula, sanhlaba ehlanyelwe nguThixo, njengezihlahla zomsedari ezingasemanzini.
7 Omi yóò sàn láti inú garawa: èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi. “Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ; ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
Amanzi azageleza emigqonyeni yabo; inhlanyelo yabo ibe semanzini amanengi. Inkosi yabo izakuba nkulu kulo-Agagi; umbuso wabo uzakuba ngophakemeyo.
8 “Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá; wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré. Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run, wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú; wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
UNkulunkulu wabakhupha eGibhithe; balamandla anjengawenyathi. Bayazitshwabadela izizwe eziyizitha njalo bephule amathambo azo abe yizicucu; ngemitshoko yabo babacibe.
9 Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún, bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn? “Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ, kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
Njengesilwane bayaqutha bacathame phansi, njengesilwanekazi, ngubani olesibindi sokubavusa na? Akuthi labo abakubusisayo babusiswe njalo lalabo abakuqalekisayo baqalekiswe!”
10 Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.
Ngakho uBhalaki wamthukuthelela kakhulu uBhalamu. Watshaya izandla zakhe wathi, “Ngikubizele ukuthi uzengiqalekisela izitha zami, kodwa wena usubabusise okwamahlandla la amathathu.
11 Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”
Wohle usuke nje khathesi ubuyele kini! Ngithe ngizakupha umvuzo omuhle kakhulu, pho-ke uThixo usekuvimbele ukwamukeliswa umvuzo.”
12 Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,
UBhalamu wamphendula uBhalaki wathi, “Kanti kangizitshelanga yini izithunywa zakho owazithuma kimi ukuthi,
13 ‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?
‘Loba uBhalaki enganginika isigodlo sakhe sigcwele isiliva legolide, akulalutho lolulodwa ebengizalwenza ngokwentando yami, okuhle kumbe okubi, okuphambene lomlayo kaThixo, kufanele ngitsho lokho kuphela uThixo akutshoyo na’?
14 Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
Khathesi sengibuyela ebantwini bakithi, kodwa woza, ngikuxwayise ukuthi kuyini okuzakwenziwa ngabantu laba ebantwini bakho ensukwini ezilandelayo.”
15 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe: “Òwe Balaamu ọmọ Beori, òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
Ngakho uBhalamu wasesitsho isambulelo sakhe: “Isambulelo sikaBhalamu indodana kaBheyori, isambulelo salowo omehlo akhe abonisisa kuhle,
16 ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí, tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo, tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:
isambulelo salowo olalela ezwe amazwi kaNkulunkulu, ololwazi oluvela koPhezukonke, obona umbono ovela kuSomandla, owela phansi ngokuzehlisa, njalo omehlo akhe avulekile:
17 “Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí. Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́. Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu; yóò yọ jáde láti Israẹli. Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu, yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
Ngiyambona, kodwa hatshi khathesi; ngiyambona, kodwa kungesikho eduze. Inkanyezi izaphuma ivela kuJakhobe; intonga yobukhosi izaphakama ivela ku-Israyeli. Uzacobodisa amabunzi kaMowabi, inkakhayi zamadodana wonke kaSethi.
18 Wọn yóò borí Edomu; yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
I-Edomi izanqotshwa; uSeyiri, oyisitha sakhe, uzanqotshwa, kodwa u-Israyeli uzakhula abe lamandla.
19 Olórí yóò jáde láti Jakọbu yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
Umbusi uzavela kuJakhobe njalo uzabhubhisa abaseleyo balelodolobho.”
20 Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
Ngakho uBhalamu wabona u-Amaleki wasesitsho isambulelo sakhe: “U-Amaleki wayengowokuqala ezizweni, kodwa ekucineni uzakuba lunxiwa.”
21 Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Ibùgbé rẹ ní ààbò, ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
Ngakho wasebona amaKheni wasesitsho isambulelo sakhe njalo: “Indawo yakho yokuhlala ivikelekile, isidleke sakho sakhelwe edwaleni;
22 síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”
kanti-ke lina maKheni lizabhujiswa ekuthunjweni kwenu yi-Asiriya.”
23 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀: “Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
Ngakho wasitsho isambulelo sakhe: “Kambe ngubani ongaphila nxa uNkulunkulu esenza lokhu na?
24 Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu; wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi, ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
Imikhumbi izakuza ivela okhunjini lwaseKhithimi; bazayehlula u-Asiriya kanye le-Ebha, kodwa laba bazachithwa babe ngamanxiwa.”
25 Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.
Ngakho uBhalamu wasukuma wasebuyela kibo loBhalaki wahamba ngeyakhe indlela.