< Numbers 24 >

1 Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Olúwa lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù.
And whanne Balaam siy that it pleside the Lord that he schulde blesse Israel, he yede not as he `hadde go bifore, `that he schulde seke fals dyuynyng `bi chiteryng of briddis, but he dresside his face ayens the desert,
2 Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
and reiside iyen, and siy Israel dwellynge in tentis bi hise lynagis. And whanne the Spirit of God felde on hym, and whanne a parable was takun,
3 ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, “Àsọtẹ́lẹ̀ tí Balaamu ọmọ Beori, àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
he seide, Balaam, the sone of Beor, seide, a man whois iye is stoppid seide,
4 àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ là kedere.
the herere of Goddis wordis seide, which bihelde the reuelacioun of almyyti God, which fallith doun, and hise iyen ben openyd so, Hou faire ben thi tabernaclis,
5 “Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu, àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!
Jacob, and thi tentis, Israel!
6 “Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde, gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá, gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn, gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
as valeys ful of woodis, and moiste gardyns bisidis floodis, as tabernaclis whiche the Lord hath set, as cedris bisidis watris;
7 Omi yóò sàn láti inú garawa: èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi. “Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ; ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
watir schal flowe of his bokat, and his seed schal be in to many watris, `that is, puplis. The kyng of hym schal be takun a wei for Agag, and the rewme of hym schal be doon awai.
8 “Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá; wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré. Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run, wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú; wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
God ledde hym out of Egipt, whos strengthe is lijk an vnicorn; thei schulen deuoure hethene men, enemyes `of hym, that is, of Israel; and thei schulen breke the boonus of hem, and schulen perse with arowis.
9 Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún, bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn? “Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ, kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
He restide and slepte as a lyoun, and as a lionesse, whom no man schal dore reise. He that blessith thee, schal be blessid; he that cursith, schal
10 Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.
be arettid in to cursyng And Balaach was wrooth ayens Balaam, and seide, whanne the hondis weren wrungun to gidere, I clepide thee to curse myn enemyes, whiche ayenward thou hast blessid thries.
11 Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”
Turne ayen to thi place; forsothe Y demede to onoure thee greetli, but the Lord priuyde thee fro onour disposid.
12 Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,
Balaam answeride to Balaach, Whethir Y seide not to thi messangeris, whiche thou sentist to me,
13 ‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?
Thouy Balaach schal yyue to me his hows ful of siluer and of gold, Y schal not mow passe the word of my Lord God, that Y brynge forth of myn herte ony thing, ethir of good ethir of yuel, but what euer thing the Lord schal seie, Y schal speke this?
14 Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
Netheles Y schal go to my puple, and Y schal yyue counsel to thee, what thi puple schal do in the laste tyme to this puple.
15 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe: “Òwe Balaamu ọmọ Beori, òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
Therfor whanne a parable was takun, he seide eft, Balaam, the sone of Beor seide, a man whos iye is stoppid,
16 ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí, tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo, tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:
seide, the herere of Goddis wordis seide, which knowith the doctrine of the hiyeste, and seeth the reuelacioun of almiyti God, which fallith doun and hath opyn iyen,
17 “Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí. Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́. Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu; yóò yọ jáde láti Israẹli. Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu, yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
Y schal se hym, but not now; Y schal biholde hym, but not nyy; a sterre schal be borun of Jacob, and a yerde schal rise of Israel; and he schal smyte the duykis of Moab, and he schal waste alle the sones of Seth; and Ydumye schal be hys possessioun,
18 Wọn yóò borí Edomu; yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
the eritage of Seir schal bifalle to his enemyes; forsothe Israel schal do strongli, of Jacob schal be he that schal be lord,
19 Olórí yóò jáde láti Jakọbu yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
and schal leese the relikis of the citee.
20 Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
And whanne he hadde seyn Amalech, he took a parable, and seide, Amalech is the bigynning of hethene men, whos laste thingis schulen be lost.
21 Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Ibùgbé rẹ ní ààbò, ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
Also `he siy Cyney, and whanne a parable was takun, he seide, Forsothe thi dwellyng place is strong, but if thou schalt sette thi nest in a stoon,
22 síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”
and schalt be chosun of the generacioun of Cyn, hou longe schalt thou mow dwelle? forsothe Assur schal take thee.
23 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀: “Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
And whanne a parable was takun, he spak eft, Alas! who schal lyue, whanne the Lord schal make thes thingis?
24 Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu; wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi, ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
Thei schulen come in grete schippis fro Ytalie, thei schulen ouercome Assiries, and thei schulen distrie Ebrews, and at the last also thei hem silf schulen perische.
25 Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.
And Balaam roos, and turnide ayen in to his place; and Balaach yede ayen bi the weye in which he cam.

< Numbers 24 >