< Numbers 24 >

1 Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Olúwa lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù.
Der Bileam saa, at det behagede Herren, at han velsignede Israel, da gik han ikke hen, som de andre Gange, at søge Spaadomme; men han rettede sit Ansigt mod Ørken.
2 Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
Og Bileam opløftede sine Øjne og saa Israel, som var lejret efter dets Stammer; og Guds Aand kom over ham.
3 ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, “Àsọtẹ́lẹ̀ tí Balaamu ọmọ Beori, àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
Og han tog til sit Sprog og sagde: Det siger Bileam, Beors Søn, og det siger den Mand, hvis Øje er tillukket,
4 àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ là kedere.
det siger den, som hører Guds Taler, den, som ser den Almægtiges Syn, den, der sank ned, og hvem Øjnene bleve aabnede paa:
5 “Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu, àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!
Hvor skønne ere dine Telte, Jakob! og dine Boliger, Israel!
6 “Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde, gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá, gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn, gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
Ligesom Bække udbrede de sig, som Haverne ved en Flod, som Aloetræer, Herren har plantet, som Cedrene ved Vandet.
7 Omi yóò sàn láti inú garawa: èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi. “Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ; ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
Der skal flyde Vand af hans Spande, og hans Afkom skal være ved de mange Vande, og hans Konge skal blive mægtigere end Agag, og hans Rige skal ophøjes.
8 “Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá; wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré. Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run, wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú; wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
Gud er den, som førte ham ud af Ægypten, de have megen Styrke, som Enhjørningen; han skal fortære Hedningerne, sine Fjender, og bryde deres Ben og saare dem med sine Pile.
9 Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún, bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn? “Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ, kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
Han har bøjet sig, lagt sig som en Løve og som en Løvinde, hvo tør jage ham op? velsignet være de, som dig velsigne, og forbandet være de, som dig forbande.
10 Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.
Da optændtes Balaks Vrede imod Bileam, og han slog sine Hænder sammen; og Balak sagde til Bileam: Jeg kaldte dig til at forbande mine Fjender, og se, du har velsignet nu tre Gange.
11 Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”
Og nu, fly du til dit Sted; jeg havde sagt: Jeg vil ære dig, men se, Herren har forhindret dig fra den Ære.
12 Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,
Og Bileam sagde til Balak: Talede jeg ikke ogsaa til dine Bud, som du sendte til mig, og sagde:
13 ‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?
Dersom Balak vilde give mig sit Hus, fuldt af Sølv og Guld, saa kunde jeg ikke overtræde Herrens Ord, til at gøre godt eller ondt efter mit eget Hjerte; det som Herren vil tale, det vil jeg tale.
14 Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
Og nu se, jeg drager til mit Folk; gak hid, jeg vil raade dig, hvad dette Folk skal gøre ved dit Folk i de sidste Dage.
15 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe: “Òwe Balaamu ọmọ Beori, òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
Og han tog til sit Sprog og sagde: Det siger Bileam, Beors Søn, det siger den Mand, hvis Øje er tillukket;
16 ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí, tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo, tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:
det siger den, som hører Guds Taler, og som ved den Højestes Vidskab, den, som ser den Almægtiges Syn, den, der sank ned, og hvem Øjnene bleve aabnede paa:
17 “Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí. Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́. Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu; yóò yọ jáde láti Israẹli. Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu, yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
Jeg ser ham, dog ikke nu, jeg skuer ham, men ikke nær; der opgaar en Stjerne af Jakob, og der hæver sig et Spir af Israel, og det knuser Moabs Hjørner og ødelægger alle Seths Børn.
18 Wọn yóò borí Edomu; yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
Og Edom skal være hans Ejendom, og Sejr, hans Fjende, skal være hans Ejendom; men Israel skal gøre kraftige Gerninger.
19 Olórí yóò jáde láti Jakọbu yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
Af Jakob skal een herske, og de overblevne skal han udrydde af Stæderne.
20 Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
Og der han saa Amalekiterne, da tog han til sit Sprog og sagde: Amalek er det første af Hedningefolkene; men i hans sidste Tid skal han gaa til Grunde.
21 Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Ibùgbé rẹ ní ààbò, ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
Og der han saa Keniterne, da tog han til sit Sprog og sagde: Fast er din Bolig, og bygget paa Klippen er din Rede.
22 síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”
Thi mon Kain skal hjemfalde til, Undergang, indtil Assur fører dig i Fangenskab?
23 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀: “Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
Og han tog til sit Sprog og sagde: Ve! hvo skal blive ved Live, naar Gud beskikker det?
24 Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu; wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi, ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
Og Skibe fra Kithims Egn skulle komme, og de skulle undertrykke Assur og undertrykke Eber, ja ogsaa han skal gaa til Grunde.
25 Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.
Og Bileam stod op og gik og vendte tilbage til sit Sted; og Balak gik ogsaa sin Vej.

< Numbers 24 >