< Numbers 24 >

1 Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Olúwa lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù.
Vida pak Balám, že by se líbilo Hospodinu, aby dobrořečil Izraelovi, již více nešel jako prvé, jednou i po druhé, k čárům svým, ale obrátil tvář svou proti poušti.
2 Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
A pozdvih očí svých, viděl Izraele bydlícího v staních po svých pokoleních, a byl nad ním duch Boží.
3 ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, “Àsọtẹ́lẹ̀ tí Balaamu ọmọ Beori, àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
I vzav podobenství své, dí: Řekl Balám, syn Beorův, řekl muž mající otevřené oči,
4 àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ là kedere.
Řekl slyšící výmluvnosti Boha silného, kterýž vidění všemohoucího vidí, kterýž když padne, otevřené má oči:
5 “Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu, àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!
Jak velmi krásní jsou stánkové tvoji, Jákobe, příbytkové tvoji, Izraeli!
6 “Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde, gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá, gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn, gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
Tak jako se potokové rozšiřují, jako zahrady vedlé řeky, jako stromoví aloes, kteréž štípil Hospodin, jako cedrové podlé vod.
7 Omi yóò sàn láti inú garawa: èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi. “Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ; ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
Poteče voda z okovu jeho, a símě jeho u vodách mnohých. A král jeho vyvýšen bude více než Agag, a vyzdvihne se království jeho.
8 “Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá; wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré. Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run, wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú; wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
Bůh silný vyvedl jej z Egypta, jako udatnost jednorožcova jest jemu; sžereť národy protivné sobě, a kosti jich potře a střelami svými prostřílí.
9 Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún, bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn? “Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ, kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
Složil se a ležel jako lvíče, a jako lev zůřivý; kdo jej zbudí? Kdo by požehnání dával tobě, požehnaný bude, a kdožť by zlořečil, bude zlořečený.
10 Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.
Tedy zapáliv se hněvem Balák proti Balámovi, tleskl rukama svýma a řekl Balámovi: Abys zlořečil nepřátelům mým, povolal jsem tebe, a aj, ustavičně dobrořečil jsi jim již po třikrát.
11 Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”
Protož nyní navrať se raději k místu svému. Bylť jsem řekl: Velikou ctí tě ctíti chci, a hle, Hospodin zbavil tě cti.
12 Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,
Jemuž odpověděl Balám: Však hned poslům tvým, kteréž jsi poslal ke mně, mluvil jsem, řka:
13 ‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?
Byť mi dal Balák plný dům svůj stříbra a zlata, nebudu moci přestoupiti řeči Hospodinovy, abych činil dobré neb zlé sám od sebe; což mi Hospodin oznámí, to mluviti budu,
14 Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
(Ale však ještě já, již odcházeje k lidu svému, počkej, poradím tobě, ) co učiní lid ten lidu tvému v posledních dnech.
15 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe: “Òwe Balaamu ọmọ Beori, òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
Tedy vzav podobenství své, dí: Řekl Balám, syn Beorův, řekl muž mající oči otevřené,
16 ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí, tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo, tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:
Řekl slyšící výmluvnosti Boha silného, kterýž zná naučení nejvyššího, a vidění všemohoucího vidí, kterýž když padne, otevřené má oči:
17 “Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí. Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́. Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu; yóò yọ jáde láti Israẹli. Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu, yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
Uzřímť jej, ale ne nyní, pohledím na něj, ale ne z blízka. Vyjdeť hvězda z Jákoba, a povstane berla z Izraele, kteráž poláme knížata Moábská, a zkazí všecky syny Set.
18 Wọn yóò borí Edomu; yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
I bude Edom podmaněn, a Seir v vládařstí přijde nepřátelům svým; nebo Izrael zmužile sobě počínati bude.
19 Olórí yóò jáde láti Jakọbu yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
Panovati bude pošlý z Jákoba, a zahladí ostatky z každého města.
20 Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
A když uzřel Amalecha, vzav podobenství své, řekl: Jakož počátek národů Amalech, tak konec jeho do gruntu zahyne.
21 Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Ibùgbé rẹ ní ààbò, ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
Uzřev pak Cinea, vzav podobenství své, řekl: Pevný jest příbytek tvůj, a na skále založils hnízdo své;
22 síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”
Ale však vyhnán bude Cineus, Assur zajatého jej povede.
23 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀: “Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
Opět vzav podobenství své, řekl: Ach, kdo bude živ, když toto učiní Bůh silný?
24 Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu; wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi, ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
A bárky z země Citim připlynou a ssouží Assyrské, ssouží také Židy, ale i ten lid do konce zahyne.
25 Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.
Potom vstav Balám, odšel a navrátil se na místo své; Balák také odšel cestou svou.

< Numbers 24 >