< Numbers 23 >

1 Balaamu wí fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ méje fún mi níbí, kí o sì mú akọ màlúù méje àti àgbò méje wá fún mi.”
І сказав Валаам до Бала́ка: „Збудуй мені тут сім же́ртівників, і приготуй мені тут сім бичків та сім баранів“.
2 Balaki ṣe bí Balaamu ti sọ, àwọn méjèèjì fi akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
І зробив Балак, як Валаам говорив. І приніс Балак та Валаам бичка та барана на кожному жертівнику.
3 Nígbà náà Balaamu sọ fún Balaki pé, “Dúró ti ẹbọ sísun rẹ kí èmi sì lọ sí ẹ̀gbẹ́ kan. Bóyá Olúwa yóò farahàn mí. Ohunkóhun tí ó bá fihàn mí, èmi yóò wí fún ọ.” Nígbà náà ó sì lọ sí ibi gíga.
І сказав Валаам до Балака: „Стань над своїм цілопа́ленням, а я піду́, — може стрі́ну Господа навпроти себе, і що́ Він об'я́вить мені, я перекажу́ тобі“. І він пішов на лису го́ру.
4 Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀, Balaamu sì sọ pé, “Mo tí ṣe pẹpẹ méje, lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan mo ti fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ.”
І стрівся Валаамові Бог, і сказав він Йому: „Сім жертівників склав я, і приніс бичка та барана на кожному жертівнику“.
5 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ sí ẹnu Balaamu ó wí pé, “Padà sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jẹ́ iṣẹ́ yìí fún un.”
І вклав Господь слово до Валаамових уст та й сказав: „Вернись до Балака, і будеш так промовляти“.
6 Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Moabu.
І вернувсь він до нього, аж ось він стоїть над своїм цілопа́ленням, він та всі вельможі моавські.
7 Nígbà náà ni Balaamu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ jáde wí pé, “Balaki mú mi láti Aramu wá, ọba Moabu láti òkè ìlà-oòrùn wá Ó wí pé, ‘Wá fi Jakọbu bú fún mi; wá, kí o sì jẹ́rìí sí Israẹli.’
І він виголосив свою припові́стку проро́чу й сказав: „Із Араму мене припрова́див Валак, цар моавський, з гір сходу: Іди ж, прокляни мені Якова, а йди ж, скажи зло на Ізраїля!
8 Báwo ní èmi ó ṣe fi bú àwọn tí Ọlọ́run kò fi bú? Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wí àwọn tí Olúwa kò bá wí?
Що ж я буду того проклинати, що Бог не прокляв був його? І що ж буду казать зло на то́го, що гніву на нього не має Госпо́дь?
9 Láti ṣóńṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn, láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n. Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀ wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀-èdè.
Бо я бачу його з вершка скель, і з пагі́рків його оглядаю, — тож наро́д пробуває самітно, а серед людей не рахується.
10 Ta ni ó lè ka eruku Jakọbu tàbí ka ìdámẹ́rin Israẹli? Jẹ́ kí èmi kú ikú olódodo, kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dà bí tirẹ̀!”
Хто ж перелічив порох Яковів, і хто зрахував пил Ізраїлів? Хай душа моя вмре смертю праведних, і кінець мій хай буде такий, як його!“
11 Balaki sọ fún Balaamu pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀tá mi bú, ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan, ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”
І сказав Балак до Валаама: „Що́ ти зробив мені? Я взяв тебе, щоб ти прокляв моїх ворогів, а оце ти справді поблагослови́в їх!“
12 Ó sì dáhùn wí pé, “Ṣé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”
А той відповів та й сказав: „Чи ж не те, що́ Господь вкладе в мої уста, я буду пильнувати, щоб те́ говорити?“
13 Nígbà náà Balaki sọ fún un pé, “Wá pẹ̀lú mi sí ibòmíràn tí o ti lè rí wọn; wà á rí díẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn. Láti ibẹ̀, wá fi wọ́n bú fún mi.”
І сказав до нього Балак: „Ходи ж зо мною до іншого місця, звідки побачиш його. Тільки частину його будеш бачити, а всього його не побачиш. І прокляни мені його, мого ворога, звідти!“
14 Ó sì lọ sí pápá Sofimu ní orí òkè Pisga, ó sì kọ́ pẹpẹ méje síbẹ̀ ó sì fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
І він узяв його на Седе-Цофім, на верхів'я Пісґі, і збудував сім жертівників, і приніс бичка та барана на кожнім жертівнику.
15 Balaamu ṣo fún Balaki pé, “Dúró níbí ti ẹbọ sísun rẹ nígbà tí mo bá lọ pàdé rẹ̀ níbẹ̀.”
І сказав він до Балака: „Стань тут над своїм цілопа́ленням, а я стріну там Господа “.
16 Olúwa pàdé Balaamu ó sì fi ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jíṣẹ́ fún un.”
І стрів Господь Валаама, і вклав слово до уст його та й сказав: „Вернися до Балака, і будеш так промовляти“.
17 Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì bá à tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu. Balaki sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”
І прийшов він до нього, аж ось він стоїть над своїм цілопа́ленням, а з ним вельможі моавські. І сказав йому Балак: „Що́ ж говорив Господь?“
18 Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ, “Dìde, Balaki; kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sippori.
І він виголосив свою приповістку пророчу й сказав: „У стань же, Балаку, та й слухай, нахили своє ухо до мене, о сину Ціппо́рів!
19 Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà. Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é? Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu un ṣẹ?
Бог не чоловік, щоб неправду казати, і Він не син лю́дський, щоб Йому жалкува́ти. Чи ж Він був сказав — і не зробить, чи ж Він говорив — та й не виконає?
20 Èmi gba àṣẹ láti bùkún; Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.
Оце — я оде́ржав наказа — поблагослови́ти, і поблагослови́в Він, і я того не відверну́!
21 “Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jakọbu, kò sì rí búburú kankan nínú Israẹli. Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn. Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
Не видно стражда́ння між Яковом, і не запримі́тно нещастя в Ізраїлі, — з ним Господь, його Бог, а між ним — голосни́й крик на славу Царя!
22 Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.
Бог, що вивів був їх із Єгипту, Він для нього, — як міць одноро́жця!
23 Kò ní àfọ̀ṣẹ sí Jakọbu, tàbí àfọ̀ṣẹ sí àwọn Israẹli. Nísinsin yìí a ó sọ nípa ti Jakọbu àti Israẹli, ‘Wo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe!’
Бо нема ворожби́ поміж Яковом, і ча́рів нема між Ізраїлем, — тепер буде сказане Якову та Ізраїлеві, що́ Бог учинив.
24 Àwọn ènìyàn náà yóò dìde bí abo kìnnìún; wọ́n yóò sì gbé ara wọn sókè bí i kìnnìún òun kì yóò sì dùbúlẹ̀ títí yóò fi jẹ ohun ọdẹ títí yóò sì fi mu nínú ẹ̀jẹ̀ ohun pípa.”
Тож устане наро́д, як левиця, і піді́йметься він, немов лев! Він не ляже, аж поки не буде він жерти здобичу, і аж поки не буде він пить кров забитих!“
25 Nígbà náà ni Balaki wí fún Balaamu pé, “O kò kúkú fi wọ́n bú, bẹ́ẹ̀ ni o kò súre fún wọn rárá!”
І сказав Балак до Валаама: „Ні проклинати — не проклинай його, ні благословити — не благословляй його!“
26 Balaamu dáhùn ó sì wí fún Balaki pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ha ti wí fún ọ pé, gbogbo èyí tí Olúwa bá sọ, òun ni èmi yóò ṣe?”
І сказав Валаам, і відповів до Балака: „Чи ж не казав я тобі, говорячи: Усе, що́ буде промовляти Господь, те зроблю́?“
27 Nígbà náà Balaki sọ fún Balaamu pé, “Wá jẹ́ kí èmi kí ó mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá yóò tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn kí ó fi wọ́n bú láti ibẹ̀ lọ.”
І сказав Балак до Валаама: „Ходи ж, візьму́ тебе ще до іншого місця, — може сподо́бається в Божих оча́х, і ти звідти проклянеш мені його“.
28 Balaki gbé Balaamu wá sí orí òkè Peori, tí ó kọjú sí aginjù.
І взяв Балак Валаама на верхів'я Пеору, що зве́рнений до пустині.
29 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Mọ pẹpẹ méje fún mi níbí kí o sì pèsè akọ màlúù àti àgbò fún mi.”
І сказав Валаам до Балака: „Збудуй мені тут сім жертівників, і приготуй мені тут сім бичків та сім баранів“.
30 Balaki sì ṣe bí Balaamu ti sọ fún un, ó sì gbé akọ màlúù kan àti àgbò lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
І зробив Балак, як сказав був Валаам, і приніс бичка та барана на кожному жертівнику.

< Numbers 23 >