< Numbers 23 >

1 Balaamu wí fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ méje fún mi níbí, kí o sì mú akọ màlúù méje àti àgbò méje wá fún mi.”
Și Balaam i-a spus lui Balac: Zidește-mi aici șapte altare și pregătește-mi aici șapte boi și șapte berbeci.
2 Balaki ṣe bí Balaamu ti sọ, àwọn méjèèjì fi akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
Și Balac a făcut cum spusese Balaam; și Balac și Balaam au oferit pe fiecare altar un taur și un berbec.
3 Nígbà náà Balaamu sọ fún Balaki pé, “Dúró ti ẹbọ sísun rẹ kí èmi sì lọ sí ẹ̀gbẹ́ kan. Bóyá Olúwa yóò farahàn mí. Ohunkóhun tí ó bá fihàn mí, èmi yóò wí fún ọ.” Nígbà náà ó sì lọ sí ibi gíga.
Și Balaam i-a spus lui Balac: Stai în picioare lângă ofranda ta arsă și eu voi merge, poate cumva DOMNUL va veni să mă întâlnească și orice îmi va arăta îți voi spune. Și el a mers la un loc înalt.
4 Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀, Balaamu sì sọ pé, “Mo tí ṣe pẹpẹ méje, lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan mo ti fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ.”
Și Dumnezeu a întâlnit pe Balaam, iar el i-a spus: Am pregătit șapte altare și am oferit pe fiecare altar un taur și un berbec.
5 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ sí ẹnu Balaamu ó wí pé, “Padà sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jẹ́ iṣẹ́ yìí fún un.”
Și DOMNUL a pus cuvânt în gura lui Balaam și a spus: Întoarce-te la Balac și astfel să vorbești.
6 Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Moabu.
Și s-a întors la el și, iată, el stătea în picioare lângă ofranda lui arsă, el și toți prinții lui Moab.
7 Nígbà náà ni Balaamu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ jáde wí pé, “Balaki mú mi láti Aramu wá, ọba Moabu láti òkè ìlà-oòrùn wá Ó wí pé, ‘Wá fi Jakọbu bú fún mi; wá, kí o sì jẹ́rìí sí Israẹli.’
Și și-a rostit parabola și a spus: Balac împăratul lui Moab m-a adus din Aram, din munții din est, spunând: Vino, blestemă-mi pe Iacob și vino, sfidează pe Israel.
8 Báwo ní èmi ó ṣe fi bú àwọn tí Ọlọ́run kò fi bú? Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wí àwọn tí Olúwa kò bá wí?
Cum să blestem, pe cel pe care Dumnezeu nu l-a blestemat? Sau cum să sfidez, pe cel pe care DOMNUL nu l-a sfidat?
9 Láti ṣóńṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn, láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n. Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀ wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀-èdè.
Pentru că din vârful stâncilor îl văd și de pe dealuri îl privesc, iată, poporul va locui singur și nu va fi socotit printre națiuni.
10 Ta ni ó lè ka eruku Jakọbu tàbí ka ìdámẹ́rin Israẹli? Jẹ́ kí èmi kú ikú olódodo, kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dà bí tirẹ̀!”
Cine poate număra pulberea lui Iacob și numărul celei de a patra părți a lui Israel? Lasă-mă să mor moartea celor drepți și sfârșitul meu să fie ca al lui!
11 Balaki sọ fún Balaamu pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀tá mi bú, ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan, ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”
Și Balac i-a spus lui Balaam: Ce mi-ai făcut? Te-am luat ca să blestemi pe dușmanii mei și, iată, tu i-ai binecuvântat cu totul.
12 Ó sì dáhùn wí pé, “Ṣé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”
Și el a răspuns și a zis: Nu trebuie să iau seama să vorbesc ceea ce DOMNUL a pus în gura mea?
13 Nígbà náà Balaki sọ fún un pé, “Wá pẹ̀lú mi sí ibòmíràn tí o ti lè rí wọn; wà á rí díẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn. Láti ibẹ̀, wá fi wọ́n bú fún mi.”
Și Balac i-a spus: Vino cu mine, te rog, la un alt loc, de unde să îi vezi, vei vedea până la cea mai îndepărtată margine a lor, dar nu îi vei vedea pe toți; și blestemă-i pentru mine de acolo.
14 Ó sì lọ sí pápá Sofimu ní orí òkè Pisga, ó sì kọ́ pẹpẹ méje síbẹ̀ ó sì fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
Și l-a dus în câmpul lui Țofim, pe vârful Pisga; și a zidit șapte altare și a oferit un taur și un berbec pe fiecare altar.
15 Balaamu ṣo fún Balaki pé, “Dúró níbí ti ẹbọ sísun rẹ nígbà tí mo bá lọ pàdé rẹ̀ níbẹ̀.”
Și i-a spus lui Balac: Stai aici în picioare lângă ofranda ta arsă, în timp ce eu mă voi întâlni cu DOMNUL mai încolo.
16 Olúwa pàdé Balaamu ó sì fi ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jíṣẹ́ fún un.”
Și DOMNUL a întâlnit pe Balaam și a pus un cuvânt în gura lui și a spus: Du-te din nou la Balac și spune astfel.
17 Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì bá à tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu. Balaki sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”
Și când a venit la el, iată, el stătea lângă ofranda sa arsă și prinții lui Moab stăteau cu el. Și Balac i-a spus: Ce a vorbit DOMNUL?
18 Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ, “Dìde, Balaki; kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sippori.
Iar el și-a rostit parabola și a spus: Ridică-te Balac și ascultă; dă-mi ascultare, tu, fiul lui Țipor,
19 Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà. Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é? Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu un ṣẹ?
Dumnezeu nu este om ca să mintă; nici fiu al omului ca să se pocăiască; a spus el și nu va face, sau a vorbit și nu va împlini?
20 Èmi gba àṣẹ láti bùkún; Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.
Iată, eu am primit poruncă să binecuvântez și el a binecuvântat; iar eu nu pot întoarce aceasta.
21 “Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jakọbu, kò sì rí búburú kankan nínú Israẹli. Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn. Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
El nu a zărit nelegiuirea în Iacob, nici nu a văzut stricăciune în Israel; DOMNUL Dumnezeul său este cu el și strigătul unui împărat este printre ei.
22 Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.
Dumnezeu i-a scos din Egipt; el are putere precum un unicorn.
23 Kò ní àfọ̀ṣẹ sí Jakọbu, tàbí àfọ̀ṣẹ sí àwọn Israẹli. Nísinsin yìí a ó sọ nípa ti Jakọbu àti Israẹli, ‘Wo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe!’
Cu adevărat nu este niciun farmec împotriva lui Iacob, nici nu este nicio ghicire împotriva lui Israel; referitor la acest timp se va spune despre Iacob și despre Israel: Ce a lucrat Dumnezeu!
24 Àwọn ènìyàn náà yóò dìde bí abo kìnnìún; wọ́n yóò sì gbé ara wọn sókè bí i kìnnìún òun kì yóò sì dùbúlẹ̀ títí yóò fi jẹ ohun ọdẹ títí yóò sì fi mu nínú ẹ̀jẹ̀ ohun pípa.”
Iată, poporul se va ridica asemenea unui leu mare și se va înălța ca un leu tânăr; nu se va întinde până nu va mânca din pradă și nu va bea sângele celor uciși.
25 Nígbà náà ni Balaki wí fún Balaamu pé, “O kò kúkú fi wọ́n bú, bẹ́ẹ̀ ni o kò súre fún wọn rárá!”
Și Balac i-a spus lui Balaam: Nici nu îi blestema dar nici nu îi binecuvânta.
26 Balaamu dáhùn ó sì wí fún Balaki pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ha ti wí fún ọ pé, gbogbo èyí tí Olúwa bá sọ, òun ni èmi yóò ṣe?”
Dar Balaam a răspuns și i-a zis lui Balac: Nu ți-am vorbit, spunând: Tot ceea ce DOMNUL vorbește, aceea trebuie să fac?
27 Nígbà náà Balaki sọ fún Balaamu pé, “Wá jẹ́ kí èmi kí ó mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá yóò tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn kí ó fi wọ́n bú láti ibẹ̀ lọ.”
Și Balac i-a spus lui Balaam: Vino, te rog, te voi duce într-un alt loc; poate cumva îi va plăcea lui Dumnezeu să mi-i blestemi de acolo.
28 Balaki gbé Balaamu wá sí orí òkè Peori, tí ó kọjú sí aginjù.
Și Balac a adus pe Balaam pe vârful Peor, care privește spre Ieșimon.
29 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Mọ pẹpẹ méje fún mi níbí kí o sì pèsè akọ màlúù àti àgbò fún mi.”
Și Balaam i-a spus lui Balac: Zidește-mi aici șapte altare și pregătește-mi aici șapte tauri și șapte berbeci.
30 Balaki sì ṣe bí Balaamu ti sọ fún un, ó sì gbé akọ màlúù kan àti àgbò lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
Și Balac a făcut cum spusese Balaam și a oferit un taur și un berbec pe fiecare altar.

< Numbers 23 >