< Numbers 23 >

1 Balaamu wí fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ méje fún mi níbí, kí o sì mú akọ màlúù méje àti àgbò méje wá fún mi.”
Nake Balamu akĩĩra Balaki atĩrĩ, “Njakĩra igongona mũgwanja haha, na ũhaarĩrie ndegwa mũgwanja na ndũrũme mũgwanja.”
2 Balaki ṣe bí Balaamu ti sọ, àwọn méjèèjì fi akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
Balaki agĩĩka o ũrĩa Balamu oigĩte, na igũrũ rĩa o kĩgongona-inĩ makarutĩra igongona rĩa ndegwa ĩmwe na ndũrũme ĩmwe.
3 Nígbà náà Balaamu sọ fún Balaki pé, “Dúró ti ẹbọ sísun rẹ kí èmi sì lọ sí ẹ̀gbẹ́ kan. Bóyá Olúwa yóò farahàn mí. Ohunkóhun tí ó bá fihàn mí, èmi yóò wí fún ọ.” Nígbà náà ó sì lọ sí ibi gíga.
Ningĩ Balamu akĩĩra Balaki atĩrĩ, “Wee ikara haha hakuhĩ na iruta rĩaku nyambe thiĩ keheri-inĩ. Hihi Jehova nĩegũũka acemanie na niĩ. Ũndũ ũrĩa wothe ekũnguũrĩria nĩngũkwĩra.” Nake agĩthiĩ handũ hatheri hatũũgĩru.
4 Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀, Balaamu sì sọ pé, “Mo tí ṣe pẹpẹ méje, lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan mo ti fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ.”
Ngai agĩcemania nake hau, nake Balamu akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩhaarĩirie igongona mũgwanja, na o kĩgongona-inĩ ngaruta ndegwa ĩmwe na ndũrũme ĩmwe.”
5 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ sí ẹnu Balaamu ó wí pé, “Padà sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jẹ́ iṣẹ́ yìí fún un.”
Nake Jehova agĩĩkĩra ndũmĩrĩri yake kanua ka Balamu, akĩmwĩra atĩrĩ, “Cooka kũrĩ Balaki ũmũhe ndũmĩrĩri ĩno.”
6 Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Moabu.
Tondũ ũcio Balamu agĩcooka kũrĩ Balaki, akĩmũkora arũngiĩ hakuhĩ na igongona rĩake, marĩ hamwe na anene othe a Moabi.
7 Nígbà náà ni Balaamu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ jáde wí pé, “Balaki mú mi láti Aramu wá, ọba Moabu láti òkè ìlà-oòrùn wá Ó wí pé, ‘Wá fi Jakọbu bú fún mi; wá, kí o sì jẹ́rìí sí Israẹli.’
Nake Balamu akĩaria ndũmĩrĩri yake, akiuga atĩrĩ: “Balaki andehithĩtie kuuma bũrũri wa Aramu, mũthamaki wa Moabi akanduta kuuma irĩma-inĩ cia mwena wa irathĩro. Akoiga atĩrĩ, ‘Ũka ũnumĩre Jakubu; ũka ũthitange Isiraeli.’
8 Báwo ní èmi ó ṣe fi bú àwọn tí Ọlọ́run kò fi bú? Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wí àwọn tí Olúwa kò bá wí?
Ndaakĩhota atĩa kũruma arĩa Ngai atarumĩte? Ndaakĩhota atĩa gũthitanga arĩa Jehova atathitangĩte?
9 Láti ṣóńṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn, láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n. Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀ wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀-èdè.
Kuuma tũcũmbĩrĩ twa ndwaro cia mahiga nĩndĩramoona, kuuma kũrĩa gũtũũgĩru nĩndĩramoona. Ndĩrona andũ matũũraga meikarĩtie, nao matiĩtaraga atĩ o nĩ amwe a ndũrĩrĩ.
10 Ta ni ó lè ka eruku Jakọbu tàbí ka ìdámẹ́rin Israẹli? Jẹ́ kí èmi kú ikú olódodo, kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dà bí tirẹ̀!”
Nũũ ũngĩhota gũtara rũkũngũ rwa Jakubu, kana atare gĩcunjĩ kĩa inya kĩa Isiraeli? Rekei ngue gĩkuũ kĩa arĩa athingu, na marigĩrĩrio makwa-rĩ, marotuĩka ta mao!”
11 Balaki sọ fún Balaamu pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀tá mi bú, ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan, ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”
Balaki akĩũria Balamu atĩrĩ, “Wanjĩka atĩa? Ngũrehire ũnumĩre thũ ciakwa, no ndũrĩ ũreka ũndũ o tiga kũmarathima!”
12 Ó sì dáhùn wí pé, “Ṣé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”
Balamu akĩmũũria atĩrĩ, “Githĩ ndiagĩrĩirwo njarie o kĩrĩa Jehova ekĩrĩte kanua-inĩ gakwa?”
13 Nígbà náà Balaki sọ fún un pé, “Wá pẹ̀lú mi sí ibòmíràn tí o ti lè rí wọn; wà á rí díẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn. Láti ibẹ̀, wá fi wọ́n bú fún mi.”
Ningĩ Balaki akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũka tũthiĩ nawe handũ hangĩ harĩa ũkũmoona; ũkũmoona o gĩcunjĩ kĩmwe kĩao, no ti othe hamwe. Na ũrĩ hau ũnumĩre andũ acio.”
14 Ó sì lọ sí pápá Sofimu ní orí òkè Pisga, ó sì kọ́ pẹpẹ méje síbẹ̀ ó sì fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
Nĩ ũndũ ũcio akĩmũtwara gĩthaka-inĩ gĩa Zofimu, gacũmbĩrĩ ga Kĩrĩma kĩa Pisiga, naho hau agĩaka igongona mũgwanja, na o kĩgongona-inĩ agĩthĩnjĩra ndegwa ĩmwe na ndũrũme ĩmwe.
15 Balaamu ṣo fún Balaki pé, “Dúró níbí ti ẹbọ sísun rẹ nígbà tí mo bá lọ pàdé rẹ̀ níbẹ̀.”
Balamu akĩĩra Balaki atĩrĩ, “Wee ikara haha hakuhĩ na iruta rĩaku nyambe thiĩ ngacemanie nake haarĩa.”
16 Olúwa pàdé Balaamu ó sì fi ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jíṣẹ́ fún un.”
Jehova agĩcemania na Balamu, agĩĩkĩra ndũmĩrĩri kanua gake, akĩmwĩra atĩrĩ, “Cooka kũrĩ Balaki ũmũhe ndũmĩrĩri ĩno.”
17 Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì bá à tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu. Balaki sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”
Tondũ ũcio Balamu agĩcooka kũrĩ Balaki na akĩmũkora arũngiĩ hakuhĩ na iruta rĩake, marĩ hamwe na anene a Moabi. Balaki akĩmũũria atĩrĩ, “Jehova oiga atĩa?”
18 Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ, “Dìde, Balaki; kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sippori.
Balamu agĩcooka akĩaria ndũmĩrĩri yake, akiuga atĩrĩ: “Arahũka, wee Balaki na ũigue; Thikĩrĩria, wee mũrũ wa Ziporu.
19 Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà. Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é? Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu un ṣẹ?
Ngai ti mũndũ, atĩ nĩguo aheenanie, o na ti mũrũ wa mũndũ, atĩ nĩguo ericũkwo. No oige ũndũ na ndawĩĩke? No eranĩre ũndũ na ndaũhingie?
20 Èmi gba àṣẹ láti bùkún; Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.
Niĩ njathĩtwo ndathimane; nake arathimanĩte-rĩ, ndingĩhota kũgarũra ũndũ ũcio.
21 “Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jakọbu, kò sì rí búburú kankan nínú Israẹli. Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn. Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
“Gũtirĩ mũtino wonekete harĩ Jakubu, gũtirĩ ihooru rĩonetwo thĩinĩ wa Isiraeli. Jehova Ngai wao arĩ hamwe nao; kayũ ka mũthamaki karĩ thĩinĩ wao.
22 Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.
Ngai nĩamarutire bũrũri wa Misiri; marĩ na hinya o ta ndegwa ya gĩthaka.
23 Kò ní àfọ̀ṣẹ sí Jakọbu, tàbí àfọ̀ṣẹ sí àwọn Israẹli. Nísinsin yìí a ó sọ nípa ti Jakọbu àti Israẹli, ‘Wo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe!’
Gũtirĩ ũrogi ũngĩũraga Jakubu, gũtirĩ ũragũri ũngĩthũkia Isiraeli. Rĩu ha ũhoro wa Jakubu na wa Isiraeli kũrĩĩranagwo atĩrĩ, ‘Ta kĩonei ũrĩa Ngai ekĩte!’
24 Àwọn ènìyàn náà yóò dìde bí abo kìnnìún; wọ́n yóò sì gbé ara wọn sókè bí i kìnnìún òun kì yóò sì dùbúlẹ̀ títí yóò fi jẹ ohun ọdẹ títí yóò sì fi mu nínú ẹ̀jẹ̀ ohun pípa.”
Andũ acio maarahũkaga ta mũrũũthi wa nga; mookagĩra ta mũrũũthi wa njamba, ũrĩa ũtangĩhurũka ũtarĩĩte kĩrĩa ũnyiitĩte, na ũkanyua thakame ya kĩrĩa ũragĩte.”
25 Nígbà náà ni Balaki wí fún Balaamu pé, “O kò kúkú fi wọ́n bú, bẹ́ẹ̀ ni o kò súre fún wọn rárá!”
Ningĩ Balaki akĩĩra Balamu atĩrĩ, “Ndũkamarume o na atĩa, na ndũkamarathime o na atĩa!”
26 Balaamu dáhùn ó sì wí fún Balaki pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ha ti wí fún ọ pé, gbogbo èyí tí Olúwa bá sọ, òun ni èmi yóò ṣe?”
Balamu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Githĩ ndiakwĩrire no nginya njĩke ũrĩa wothe Jehova oigĩte?”
27 Nígbà náà Balaki sọ fún Balaamu pé, “Wá jẹ́ kí èmi kí ó mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá yóò tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn kí ó fi wọ́n bú láti ibẹ̀ lọ.”
Ningĩ Balaki akĩĩra Balamu atĩrĩ, “Ũka tũthiĩ ngũtware handũ hangĩ. Hihi Ngai no agwĩtĩkĩrie ũnumĩre andũ aya ũrĩ hau.”
28 Balaki gbé Balaamu wá sí orí òkè Peori, tí ó kọjú sí aginjù.
Balaki akĩoya Balamu akĩmũtwara kĩrĩma igũrũ kĩa Peoru, kũngʼethera Werũ ũrĩa ũtarĩ kĩndũ.
29 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Mọ pẹpẹ méje fún mi níbí kí o sì pèsè akọ màlúù àti àgbò fún mi.”
Nake Balamu akĩmwĩra atĩrĩ, “Njakĩra igongona mũgwanja haha, na ũhaarĩrie ndegwa mũgwanja na ndũrũme mũgwanja.”
30 Balaki sì ṣe bí Balaamu ti sọ fún un, ó sì gbé akọ màlúù kan àti àgbò lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
Balaki agĩĩka o ta ũrĩa Balamu oigĩte, na o kĩgongona-inĩ agĩthĩnjĩra ndegwa ĩmwe na ndũrũme ĩmwe.

< Numbers 23 >