< Numbers 23 >

1 Balaamu wí fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ méje fún mi níbí, kí o sì mú akọ màlúù méje àti àgbò méje wá fún mi.”
And Bil'am said unto Balak, Build me here seven altars, and prepare me here seven bullocks and seven rams.
2 Balaki ṣe bí Balaamu ti sọ, àwọn méjèèjì fi akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
And Balak did as Bil'am had spoken; and Balak and Bil'am offered a bullock and a ram on every altar.
3 Nígbà náà Balaamu sọ fún Balaki pé, “Dúró ti ẹbọ sísun rẹ kí èmi sì lọ sí ẹ̀gbẹ́ kan. Bóyá Olúwa yóò farahàn mí. Ohunkóhun tí ó bá fihàn mí, èmi yóò wí fún ọ.” Nígbà náà ó sì lọ sí ibi gíga.
And Bil'am said unto Balak, Place thyself by thy burnt-offering; and I will go, peradventure the Lord will come to meet me, and whatsoever he may show me I will tell thee: and he went thoughtfully alone.
4 Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀, Balaamu sì sọ pé, “Mo tí ṣe pẹpẹ méje, lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan mo ti fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ.”
And God met Bil'am: and he said unto him, The seven altars have I made ready, and I have offered a bullock and a ram upon every altar.
5 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ sí ẹnu Balaamu ó wí pé, “Padà sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jẹ́ iṣẹ́ yìí fún un.”
And the Lord put a word in Bil'am's mouth, and said, Return unto Balak, and thus shalt thou speak.
6 Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Moabu.
And he returned unto him, and, lo, he was standing by his burnt-offering, he, and all the princes of Moab.
7 Nígbà náà ni Balaamu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ jáde wí pé, “Balaki mú mi láti Aramu wá, ọba Moabu láti òkè ìlà-oòrùn wá Ó wí pé, ‘Wá fi Jakọbu bú fún mi; wá, kí o sì jẹ́rìí sí Israẹli.’
And he took up his parable, and said, From Aram did Balak send for me, the king of Moab, out of the mountains of the east, Come, curse me Jacob, and come, defy Israel.
8 Báwo ní èmi ó ṣe fi bú àwọn tí Ọlọ́run kò fi bú? Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wí àwọn tí Olúwa kò bá wí?
How shall I denounce, whom God hath not denounced? and how shall I defy, whom the Lord hath not defied?
9 Láti ṣóńṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn, láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n. Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀ wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀-èdè.
For from the top of rocks I see him, and from hills I behold him: lo, it is a people that shall dwell alone, and among the nations it shall not be reckoned.
10 Ta ni ó lè ka eruku Jakọbu tàbí ka ìdámẹ́rin Israẹli? Jẹ́ kí èmi kú ikú olódodo, kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dà bí tirẹ̀!”
Who can count the dust of Jacob, and number the fourth part of Israel? May my soul die the death of the righteous, and may my last end be like his!
11 Balaki sọ fún Balaamu pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀tá mi bú, ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan, ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”
And Balak said unto Bil'am, What hast thou done unto me? to denounce my enemies did I take thee, and, behold, thou hast even blessed them.
12 Ó sì dáhùn wí pé, “Ṣé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”
And he answered and said, Must I not take heed to speak that only which the Lord may put in my mouth?
13 Nígbà náà Balaki sọ fún un pé, “Wá pẹ̀lú mi sí ibòmíràn tí o ti lè rí wọn; wà á rí díẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn. Láti ibẹ̀, wá fi wọ́n bú fún mi.”
And Balak said unto him, Come, I pray thee, with me unto another place, from where thou canst see them; nevertheless a portion of them only wilt thou see, but the whole of them thou wilt not see: and denounce them for me from there.
14 Ó sì lọ sí pápá Sofimu ní orí òkè Pisga, ó sì kọ́ pẹpẹ méje síbẹ̀ ó sì fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
And he brought him to the field of the watchmen, on the top of Pisgah, and he built seven altars, and offered a bullock and a ram on every altar.
15 Balaamu ṣo fún Balaki pé, “Dúró níbí ti ẹbọ sísun rẹ nígbà tí mo bá lọ pàdé rẹ̀ níbẹ̀.”
And he said unto Balak, Place thyself here by thy burnt-offering, while I will repair to yonder place.
16 Olúwa pàdé Balaamu ó sì fi ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jíṣẹ́ fún un.”
And the Lord met Bil'am, and put a word in his mouth, and said, Return unto Balak, and thus shalt thou speak.
17 Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì bá à tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu. Balaki sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”
And he came to him, and, behold, he was standing by his burnt-offering, and the princes of Moab with him; and Balak said unto him: What hath the Lord spoken?
18 Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ, “Dìde, Balaki; kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sippori.
And he took up his parable, and said, Rise up, Balak, and hear; bend hither thy ear unto me, son of Zippor!
19 Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà. Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é? Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu un ṣẹ?
God is not a man, that he should lie; nor a son of man, that he should repent: hath he said, and shall he not do it? and hath he spoken, and shall he not fulfill it?
20 Èmi gba àṣẹ láti bùkún; Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.
Behold, to bless I have received [the word]; and he hath blessed, and I cannot reverse it.
21 “Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jakọbu, kò sì rí búburú kankan nínú Israẹli. Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn. Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
He hath not beheld any wrong in Jacob, nor hath he seen perverseness in Israel: the Lord his God is with him, and the glory of the king dwelleth among him.
22 Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.
God, who brought them out of Egypt, is to them like the heights of the reem.
23 Kò ní àfọ̀ṣẹ sí Jakọbu, tàbí àfọ̀ṣẹ sí àwọn Israẹli. Nísinsin yìí a ó sọ nípa ti Jakọbu àti Israẹli, ‘Wo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe!’
For there is no enchantment in Jacob, nor is there any divination in Israel: at the proper time shall it be said to Jacob and to Israel, what God doth work.
24 Àwọn ènìyàn náà yóò dìde bí abo kìnnìún; wọ́n yóò sì gbé ara wọn sókè bí i kìnnìún òun kì yóò sì dùbúlẹ̀ títí yóò fi jẹ ohun ọdẹ títí yóò sì fi mu nínú ẹ̀jẹ̀ ohun pípa.”
Behold, it is a people, that shall rise up as a lioness, and as a lion shall it raise itself: it will not lie down until it have eaten the prey, and have drunk the blood of the slain.
25 Nígbà náà ni Balaki wí fún Balaamu pé, “O kò kúkú fi wọ́n bú, bẹ́ẹ̀ ni o kò súre fún wọn rárá!”
And Balak said unto Bil'am, Neither shalt thou denounce them, nor shalt thou any wise bless them.
26 Balaamu dáhùn ó sì wí fún Balaki pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ha ti wí fún ọ pé, gbogbo èyí tí Olúwa bá sọ, òun ni èmi yóò ṣe?”
But Bil'am answered and said unto Balak, Have I not spoken unto thee, saying, all that the Lord will speak, that must I do.
27 Nígbà náà Balaki sọ fún Balaamu pé, “Wá jẹ́ kí èmi kí ó mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá yóò tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn kí ó fi wọ́n bú láti ibẹ̀ lọ.”
And Balak said unto Bil'am, Come, I pray thee, I will take thee unto another place, peradventure it may be pleasing in the eyes of God that thou mayest denounce them for me from there.
28 Balaki gbé Balaamu wá sí orí òkè Peori, tí ó kọjú sí aginjù.
And Balak took Bil'am unto the top of Peor, that looketh toward the desert.
29 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Mọ pẹpẹ méje fún mi níbí kí o sì pèsè akọ màlúù àti àgbò fún mi.”
And Bil'am said unto Balak, Build me here seven altars, and prepare me here seven bullocks and seven rams.
30 Balaki sì ṣe bí Balaamu ti sọ fún un, ó sì gbé akọ màlúù kan àti àgbò lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
And Balak did as Bil'am had said, and he offered a bullock and a ram on every altar.

< Numbers 23 >