< Numbers 23 >

1 Balaamu wí fún Balaki pé, “Kọ́ pẹpẹ méje fún mi níbí, kí o sì mú akọ màlúù méje àti àgbò méje wá fún mi.”
A řekl Balám Balákovi: Udělej mi tuto sedm oltářů, a připrav mi také sedm volků a sedm skopců.
2 Balaki ṣe bí Balaamu ti sọ, àwọn méjèèjì fi akọ màlúù kọ̀ọ̀kan àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
I udělal Balák, jakž mluvil Balám. Tedy obětoval Balák a Balám volka a na každém oltáři.
3 Nígbà náà Balaamu sọ fún Balaki pé, “Dúró ti ẹbọ sísun rẹ kí èmi sì lọ sí ẹ̀gbẹ́ kan. Bóyá Olúwa yóò farahàn mí. Ohunkóhun tí ó bá fihàn mí, èmi yóò wí fún ọ.” Nígbà náà ó sì lọ sí ibi gíga.
Řekl pak Balám Balákovi: Postůj při oběti své zápalné, a půjdu, zdali by se potkal se mnou Hospodin, a což by koli mně ukázal, povím tobě. I odšel sám.
4 Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀, Balaamu sì sọ pé, “Mo tí ṣe pẹpẹ méje, lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan mo ti fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ.”
I potkal se Bůh s Balámem, a řekl jemu Balám: Sedm oltářů zpořádal jsem, a obětoval jsem volka a skopce na každém oltáři.
5 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ sí ẹnu Balaamu ó wí pé, “Padà sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jẹ́ iṣẹ́ yìí fún un.”
Vložil pak Hospodin slovo v ústa Balámova a řekl: Navrať se k Balákovi a tak mluv.
6 Ó sì padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì ba tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè Moabu.
I navrátil se k němu, a nalezl jej, an stojí při oběti své zápalné, i všecka knížata Moábská.
7 Nígbà náà ni Balaamu sọ ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ jáde wí pé, “Balaki mú mi láti Aramu wá, ọba Moabu láti òkè ìlà-oòrùn wá Ó wí pé, ‘Wá fi Jakọbu bú fún mi; wá, kí o sì jẹ́rìí sí Israẹli.’
Tedy vzav před sebe přísloví své, řekl: Z Aram přivedl mne Balák král Moábský, z hor východních, řka: Poď, zlořeč mi k vůli Jákoba, a poď, vydej klatbu na Izraele.
8 Báwo ní èmi ó ṣe fi bú àwọn tí Ọlọ́run kò fi bú? Báwo ni èmi ó ṣe bá wọn wí àwọn tí Olúwa kò bá wí?
Proč bych zlořečil, komuž Bůh silný nezlořečí? A proč bych klel, kohož Hospodin neproklíná?
9 Láti ṣóńṣó ibi gíga orí àpáta ni mo ti rí wọn, láti orí ibi gíga ni mo ti ń wò wọ́n. Mo rí àwọn ènìyàn tí ń gbé lọ́tọ̀ wọn kò sì ka ará wọn kún ara àwọn orílẹ̀-èdè.
Když s vrchu skal hledím na něj, a s pahrbků spatřuji jej, aj, lid ten sám bydlí, a k jiným národům se nepřiměšuje.
10 Ta ni ó lè ka eruku Jakọbu tàbí ka ìdámẹ́rin Israẹli? Jẹ́ kí èmi kú ikú olódodo, kí ìgbẹ̀yìn mi kí ó dà bí tirẹ̀!”
Kdo sečte prach Jákobův? a kdo počet? Kdo sečte čtvrtý díl Izraelského lidu? Ó bych já umřel smrtí spravedlivých, a dokonání mé ó by bylo jako i jeho!
11 Balaki sọ fún Balaamu pé, “Kí lo ṣe fún mi? Mo gbé ọ wá láti fi àwọn ọ̀tá mi bú, ṣùgbọ́n o kò ṣe nǹkan kan, ṣùgbọ́n o bùkún wọn!”
I řekl Balák Balámovi: Což mi to děláš? Abys zlořečil nepřátelům mým, povolal jsem tě, a ty pak ustavičně dobrořečíš jim.
12 Ó sì dáhùn wí pé, “Ṣé kí n má sọ nǹkan tí Olúwa fi sí mi lẹ́nu?”
Kterýž odpovídaje, řekl: Zdali toho, což Hospodin vložil v ústa má, nemám šetřiti, abych tak mluvil?
13 Nígbà náà Balaki sọ fún un pé, “Wá pẹ̀lú mi sí ibòmíràn tí o ti lè rí wọn; wà á rí díẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe gbogbo wọn. Láti ibẹ̀, wá fi wọ́n bú fún mi.”
I řekl jemu Balák: Poď, prosím, se mnou na jiné místo, odkudž bys viděl jej, (toliko zadní díl jeho viděti budeš, a všeho nebudeš viděti), a proklň mi jej odtud.
14 Ó sì lọ sí pápá Sofimu ní orí òkè Pisga, ó sì kọ́ pẹpẹ méje síbẹ̀ ó sì fi akọ màlúù àti àgbò kọ̀ọ̀kan rú ẹbọ lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
I pojav jej, vyvedl ho na rovinu Zofim, na vrch jednoho pahrbku, a udělav sedm oltářů, obětoval volka a skopce na každém oltáři.
15 Balaamu ṣo fún Balaki pé, “Dúró níbí ti ẹbọ sísun rẹ nígbà tí mo bá lọ pàdé rẹ̀ níbẹ̀.”
Řekl pak Balákovi: Postůj tuto při zápalné oběti své, a já půjdu tamto vstříc Hospodinu.
16 Olúwa pàdé Balaamu ó sì fi ọ̀rọ̀ sí ní ẹnu wí pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ Balaki kí o sì jíṣẹ́ fún un.”
I potkal se Hospodin s Balámem, a vloživ slovo v ústa jeho, řekl: Navrať se k Balákovi a mluv tak.
17 Nígbà náà ó lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ ó sì bá à tí ó dúró ti ẹbọ sísun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu. Balaki sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni Olúwa wí?”
Přišel tedy k němu, a hle, on stál při zápalné oběti své, a knížata Moábská s ním. Jemužto řekl Balák: Co mluvil Hospodin?
18 Nígbà náà ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ sísọ, “Dìde, Balaki; kí o sì gbọ́ mi ọmọ Sippori.
A on vzav přísloví své, řekl: Povstaň Baláku a slyš, pozoruj mne, synu Seforův.
19 Ọlọ́run kì í ṣe ènìyàn, tí yóò fi purọ́, tàbí ọmọ ènìyàn, tí ó lè yí ọkàn rẹ̀ padà. Ǹjẹ́ ó sọ̀rọ̀ kí ó má ṣe é? Ǹjẹ́ ó ti ṣèlérí kí ó má mu un ṣẹ?
Bůh silný není jako člověk, aby klamal, a jako syn člověka, aby se měnil. Což by řekl, zdaliž neučiní? Což by promluvil, zdali neutvrdí toho?
20 Èmi gba àṣẹ láti bùkún; Ó sì ti bùkún, èmi kò sì lè yípadà.
Hle, abych dobrořečil, přijal jsem to na sebe; nebo dobrořečilť jest, a já toho neodvolám.
21 “Kò rí ẹ̀ṣẹ̀ kankan nínú Jakọbu, kò sì rí búburú kankan nínú Israẹli. Olúwa Ọlọ́run wọn sì wà pẹ̀lú wọn. Ìhó ọba sì wà pẹ̀lú wọn.
Nepatříť na nepravosti v Jákobovi, aniž hledí na přestoupení v Izraeli; Hospodin Bůh jeho jestiť s ním, a zvuk krále vítězícího v něm.
22 Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n ní agbára màlúù ẹhànnà.
Bůh silný vyvedl je z Egypta, jako silou jednorožcovou byv jim.
23 Kò ní àfọ̀ṣẹ sí Jakọbu, tàbí àfọ̀ṣẹ sí àwọn Israẹli. Nísinsin yìí a ó sọ nípa ti Jakọbu àti Israẹli, ‘Wo ohun tí Ọlọ́run ti ṣe!’
Nebo není kouzlů proti Jákobovi, ani zaklínání proti Izraelovi; již od toho času vypravováno bude o Jákobovi a Izraelovi, co učinil s ním Bůh silný.
24 Àwọn ènìyàn náà yóò dìde bí abo kìnnìún; wọ́n yóò sì gbé ara wọn sókè bí i kìnnìún òun kì yóò sì dùbúlẹ̀ títí yóò fi jẹ ohun ọdẹ títí yóò sì fi mu nínú ẹ̀jẹ̀ ohun pípa.”
Aj, lid jakožto silný lev povstane, a jakožto lvíče vzchopí se; nepoloží se, dokudž by nejedl loupeže, a dokudž by nevypil krve zbitých.
25 Nígbà náà ni Balaki wí fún Balaamu pé, “O kò kúkú fi wọ́n bú, bẹ́ẹ̀ ni o kò súre fún wọn rárá!”
I řekl Balák Balámovi: Aniž mu již zlořeč více, ani dobrořeč.
26 Balaamu dáhùn ó sì wí fún Balaki pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ha ti wí fún ọ pé, gbogbo èyí tí Olúwa bá sọ, òun ni èmi yóò ṣe?”
Jemuž odpověděl Balám, řka: Zdaližť jsem nepravil, že, což by mi koli mluvil Hospodin, to učiním?
27 Nígbà náà Balaki sọ fún Balaamu pé, “Wá jẹ́ kí èmi kí ó mú ọ lọ sí ibòmíràn bóyá yóò tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn kí ó fi wọ́n bú láti ibẹ̀ lọ.”
I řekl Balák Balámovi: Poď, prosím, povedu tě na jiné místo, odkudž snad líbiti se bude Bohu, abys mi je proklel.
28 Balaki gbé Balaamu wá sí orí òkè Peori, tí ó kọjú sí aginjù.
A pojav Balák Baláma, uvedl jej na vrch hory Fegor, kteráž leží naproti poušti.
29 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Mọ pẹpẹ méje fún mi níbí kí o sì pèsè akọ màlúù àti àgbò fún mi.”
Tedy řekl Balám Balákovi: Udělej mi tuto sedm oltářů, a připrav mi také sedm volků a sedm skopců.
30 Balaki sì ṣe bí Balaamu ti sọ fún un, ó sì gbé akọ màlúù kan àti àgbò lórí pẹpẹ kọ̀ọ̀kan.
I učinil Balák, jakž řekl Balám, a obětoval volka a skopce na každém oltáři.

< Numbers 23 >