< Numbers 22 >
1 Nígbà náà àwọn ọmọ Israẹli rin ìrìnàjò lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n sì pa ibùdó lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani tí ó kọjá lọ sí Jeriko.
І рушили Ізраїлеві сини, та й таборува́ли в моавських степах по тім боці приєрихонського Йорда́ну.
2 Nísinsin yìí, Balaki ọmọ Sippori rí gbogbo ohun tí àwọn Israẹli ti ṣe sí àwọn ará Amori,
І побачив Бала́к, син Ціппо́рів, усе, що зробив Ізра́їль аморе́янинові.
3 ẹ̀rù sì ba Moabu nítorí pé ọ̀pọ̀ ènìyàn wà níbẹ̀ nítòótọ́, Moabu kún fún ẹ̀rù nítorí àwọn ọmọ Israẹli.
І дуже злякався Моав того наро́ду, бо він був великий. І настра́шився Моав Ізра́їлевих синів.
4 Moabu sọ fún àwọn àgbàgbà Midiani pé, “Nísinsin yìí ni àwọn wọ̀nyí yóò lá gbogbo ohun tí ó yí wa ká, bí màlúù ṣe ń jẹ koríko tí ó wà nínú oko.” Bẹ́ẹ̀ ni Balaki ọmọ Sippori, tí ó jẹ́ ọba Moabu nígbà náà,
І сказав Моав до мідія́нських старших: Тепер повиску́бує оця громада всі наші околиці, як виску́бує віл польову́ зелени́ну“. А Бала́к, син Ціппо́рів, був того часу моавським царем.
5 rán oníṣẹ́ pé Balaamu ọmọ Beori, tí ó wà ní Petori, ní ẹ̀bá odò Eufurate, ti ilẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ. Balaki sọ pé, “Àwọn ènìyàn kan jáde wá láti Ejibiti; wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ ayé wọ́n sì pa ibùdó súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi.
І послав він послів до Валаа́ма, Беорового сина, до Петору, що над Річкою, до кра́ю синів народу його, щоб покликати його, говорячи: „Ось вийшов народ із Єгипту, ось покрив він пове́рхню землі, і сидить навпроти мене.
6 Nísinsin yìí, wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú, nítorí wọ́n ní agbára jù fún mi. Nípa ṣíṣe èyí èmi ó ṣẹ́gun wọn, kí n sì lé wọn kúrò ní ilẹ̀ yìí. Nítorí tí mo mọ̀ pé ìbùkún ni fún àwọn tí ìwọ bá bùkún, ìfibú sì ni ẹni tí ìwọ bá fi bú.”
А тепер ходи ж, прокляни́ мені цей народ, бо він міцніший за ме́не. Може я потра́плю вдарити його, і вижену його з кра́ю, бо знаю, що кого ти поблагосло́виш, той благослове́нний, а кого прокляне́ш, — прокля́тий“.
7 Àti àwọn àgbàgbà Moabu àti Midiani sì lọ pẹ̀lú owó àyẹ̀wò lọ́nà wọn, nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ Balaamu, wọ́n sọ nǹkan tí Balaki sọ fún wọn.
І пішли моавські старші та старші Мідіяну, — а дарунки за чари в руці їх, — і прийшли до Валаама, та й промовляли до нього Балакові слова́. І
8 “Ẹ sùn níbí lálẹ́ yìí,” Balaamu sọ fún un pé, “èmi ó padà wá fún un yín ní èsì nǹkan tí Olúwa bá wí fún mi.” Nítorí tí àwọn ìjòyè Moabu dúró sọ́dọ̀ rẹ̀.
А він їм сказав: „Ночуйте тут і цієї но́чі, і я перекажу́ вам слово, як Господь промовлятиме до мене“. І зостались моавські вельможі в Валаама.
9 Ọlọ́run tọ Balaamu wá ó sì wí pé, “Ta ni àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ yìí?”
І прийшов Бог до Валаама та й сказав: „Хто ці люди з тобою?“
10 Balaamu sọ fún Ọlọ́run pé, “Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, rán iṣẹ́ yìí sí mi pé,
І сказав Валаа́м до Бога: „Балак, син Ціппорів, цар моавський, послав до мене сказати:
11 ‘Àwọn ènìyàn kan ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá tí wọ́n bo ojú ilẹ̀. Nísinsin yìí, wá, kí o wá fi wọ́n bú fún mi. Bóyá èmi yóò lè bá wọn jà, èmi ó sì lé wọn jáde.’”
Ось народ виходить з Єгипту, і закрив пове́рхню землі; тепер іди ж, прокляни мені його, — може я потра́плю воювати з ним, і вижену його“.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún Balaamu pé, “Má ṣe bá wọn lọ. Ìwọ kò gbọdọ̀ gé ègún lé àwọn ènìyàn náà lórí, nítorí a ti bùkún wọn.”
І сказав Бог до Валаама: „Не пі́деш ти з ними, не прокляне́ш того народу, бо благослове́нний він!“
13 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaamu dìde ó sì sọ fún àwọn ìjòyè Balaki pé, “Ẹ padà sí orílẹ̀-èdè yín, nítorí tí Olúwa ti kọ̀ láti jẹ́ kí n tẹ̀lé yín.”
І встав Валаам уранці та й сказав до Валакових вельмож: „Верта́йтесь до свого кра́ю, бо відмовив Господь позволити мені піти з вами“.
14 Nígbà náà àwọn ìjòyè Moabu sì padà tọ Balaki lọ wọ́n sì wí pé, “Balaamu kọ̀ láti tẹ̀lé wa.”
І встали моавські вельможі, і прийшли до Балака та й сказали: „Відмовив Валаам піти з нами“.
15 Nígbà náà Balaki rán àwọn ìjòyè mìíràn tí wọ́n pọ̀ àwọn tí wọ́n sì níyì ju alákọ́kọ́ lọ.
А Балак зно́ву послав вельмож, більше й поважніших від тих.
16 Wọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ Balaamu wọ́n sì sọ pé, “Èyí ni ohun tí Balaki ọmọ Sippori sọ, má ṣe jẹ́ kí ohunkóhun kí ó dè ọ́ lọ́nà láti wá sí ọ̀dọ̀ mi,
І прибули́ вони до Валаама та й сказали йому: „Так сказав Балак, син Ціппорів: Не стримуйся прийти до мене,
17 nítorí pé èmi yóò fún ọ ní ẹ̀bùn dáradára, èmi yóò sì ṣe ohunkóhun tí ìwọ bá sọ. Wá, kí o sì wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú fún mi.”
бо справді дуже вшаную тебе, і все, що скажеш мені, зроблю́. І ходи ж, — прокляни мені народ той!“
18 Ṣùgbọ́n Balaamu dá wọn lóhùn pé, “Kódà tí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò ní ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí kéré tí ó kọjá òfin Olúwa Ọlọ́run mi.
І відповів Валаам, і сказав Балаковим рабам: „Якщо Балак дасть мені повний свій дім срібла та золота, то й тоді я не зможу переступити наказу Господа, Бога мого, щоб зробити річ малу чи річ велику.
19 Nísinsin yìí ẹ dúró níbí di ọjọ́ kejì gẹ́gẹ́ bí àwọn tókù ti ṣe nígbà náà èmi yóò mọ ohun tí Olúwa yóò tún sọ fún mi.”
А тепер посидьте й ви тут цієї но́чі, а я пізна́ю, що ще Господь буде говорити мені“.
20 Ní alẹ́ ọjọ́ náà Ọlọ́run sì tọ Balaamu wá ó sì sọ wí pé, “Nígbà tí ọkùnrin yìí ti wá pè ọ́, lọ pẹ̀lú wọn, ṣùgbọ́n ẹnu nǹkan tí mo sọ fún ọ ni kí o ṣe.”
І прийшов Бог уночі до Валаама та й сказав йому: „Якщо ці люди прийшли покли́кати тебе, — устань, іди з ними. Але тільки те, що Я промовля́тиму до тебе, — те́ ти зробиш“.
21 Balaamu dìde ní òwúrọ̀, ó sì di ẹrù lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ òun pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu.
І встав Валаам уранці, і осідлав свою осли́цю, та й пішов із моавськими вельмо́жами.
22 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run bínú gidigidi, angẹli Olúwa sì dúró lójú ọ̀nà láti dojú ìjà kọ ọ́. Balaamu ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ lọ, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
І запалився гнів Божий, що він іде. І став Ангол Господній на дорозі за перешкоду йому, а він їде на своїй ослиці, і двоє слуг його з ним.
23 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà tí a fàyọ ní ọwọ́ rẹ̀, ó kọjú kúrò ní ọ̀nà lọ sínú oko. Balaamu sì lù ú pé kí ó gbé òhun padà lọ sí ojú ọ̀nà.
І побачила та ослиця Господнього Ангола, що стоїть на дорозі, а ви́тягнений меч його в руці його. І збо́чила ослиця з дороги, і пішла полем, а Валаам ударив ослицю, щоб збочила на доро́гу.
24 Nígbà náà angẹli Olúwa dúró ní ojú ọ̀nà tóóró láàrín ọgbà àjàrà, pẹ̀lú ògiri ní ọ̀nà méjèèjì.
І став Ангол Господній на стежці виноградників, — стіна з цієї сторони, і стіна з тієї.
25 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó lẹ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ ògiri, ó sì rún ẹsẹ̀ Balaamu mọ́ ògiri. Nígbà náà, ó tún nà án, lẹ́ẹ̀kan sí i.
І побачила та ослиця Господнього Ангола, і прити́снулася до стіни, та й притиснула до стіни Валаамову ногу. І він далі її бив.
26 Nígbà náà angẹli Olúwa súnmọ́ wájú ó sì dúró níbi ọ̀nà tóóró níbi tí kò ti sí ọ̀nà láti yípadà, bóyá ní ọ̀tún tàbí òsì.
І Ангол Господній знов перейшов, і став у тісно́му місці, де нема дороги збочити ні право́руч, ні ліво́руч.
27 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó sì jókòó ní abẹ́ Balaamu, inú sì bí i tó sì nà án pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀.
І побачила та ослиця Господнього Ангола — і лягла під Валаамом. І запалився гнів Валаамів, і він ударив ослицю києм.
28 Nígbà náà Olúwa ṣí ẹnu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì sọ fún Balaamu pé, “Kí ni mo ṣe fún ọ tí o fi nà mí lẹ́ẹ̀mẹ́ta?”
І відкрив Господь уста ослиці, і сказала вона до Валаама: „Що́ я зробила тобі, то ти оце тричі вдарив мене?“
29 Balaamu sọ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pé, “Nítorí ìwọ fi mí ṣẹ̀sín! Bí mo bá ní idà ní ọwọ́ ni èmi ìbá pa ọ́ nísinsin yìí.”
І сказав Валаам до ослиці: „Бо ти виставила мене на сміх. Коли б меч був у руці моїй, то тепер я забив би тебе!“
30 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sọ fún Balaamu pé, “Ṣé mi kì í ṣe kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ ni, tí o máa ń gùn ní gbogbo ìgbà, láti ìgbà pípẹ́ wá? Ǹjẹ́ mo hu irú ìwà báyìí sí ọ rí?” “Rárá,” Ó dáhùn.
І сказала осли́ця до Валаама: „Чи ж я не ослиця твоя, що ти їздив на мені, скільки живеш, аж до цього дня? Чи ж справді звикла я робити тобі так?“І він відказав: „Ні!“
31 Nígbà náà Olúwa ṣí ojú Balaamu, ó sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà rẹ̀ tí ó fàyọ. Ó sì tẹ orí rẹ̀ ba.
І відкрив Господь очі Валаамові, і побачив він Господнього Ангола, що стоїть на дорозі, а його ви́тягнений меч у руці його. І схилився він, і впав на обличчя своє.
32 Nígbà náà angẹli Olúwa béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí o fi na kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ nígbà mẹ́ta yìí? Mo wá síbí láti kọ ojú ìjà sí ọ nítorí ọ̀nà rẹ kò tọ́ níwájú mi.
І сказав до нього Ангол Господній: „На́що ти вдарив ослицю свою оце тричі? Ось я вийшов за перешкоду, бо ця дорога погибельна передо мною.
33 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí mi ó sì yà kúrò fún mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta yìí. Tí ó bá jẹ́ wí pé kò yà kúrò. Èmi kì ìbá ti pa ọ́ pátápátá nísinsin yìí, ṣùgbọ́n Èmi yóò sì dá òun sí.”
І побачила мене ця ослиця, і збо́чила перед лицем моїм ось власне тричі. І коли б вона не збо́чила була перед лицем моїм, то тепер я й забив би тебе, а її позоставив би живою“.
34 Balaamu sọ fún angẹli Olúwa pé, “Mo ti dẹ́ṣẹ̀, èmi kò mọ̀ pé o dúró níwájú ọ̀nà láti dojúkọ mí, nísinsin yìí tí inú rẹ kò bá dùn, èmi ó padà.”
І сказав Валаам до Господнього Ангола: „Я згрішив, бо не знав, що ти стоїш да дорозі навпроти ме́не. А тепер, якщо це зле в оча́х твоїх, то я вернуся собі“.
35 Angẹli Olúwa sọ fún Balaamu pé, “Lọ pẹ̀lú àwọn arákùnrin náà, ṣùgbọ́n nǹkan tí mo sọ fún ọ nìkan ni kí o sọ.” Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Balaki.
І сказав Ангол Господній до Валаама: „Іди з цими людьми́, і те слово, що скажу́ тобі, — його тільки будеш говорити“. І пішов Валаам з Балаковими вельмо́жами.
36 Nígbà tí Balaki gbọ́ pé Balaamu ń bọ̀ wá, ó jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀ ní ìlú Moabu tí ó wà ní agbègbè Arnoni, ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ̀.
І почув Балак, що прийшов Валаам, і вийшов навпроти нього до Їр-Моаву, що на границі Арнону, що на краю́ границі.
37 Balaki sì sọ fún Balaamu pé, “Ǹjẹ́ èmi kò a ránṣẹ́ kánjúkánjú sí ọ? Kí ló dé tí ìwọ kò fi wá sí ọ̀dọ̀ mi? Ṣé èmi kò tó láti sọ ọ́ di ẹni ńlá?”
І сказав Балак до Валаама: „Чи ж справді не послав я до тебе, щоб покли́кати тебе, — чому ж не пішов ти до мене? Чи справді я не потра́плю вшанувати тебе?“
38 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Kíyèsi, èmi tọ̀ ọ́ wá, èmi kò ha ní agbára kan nísinsin yìí rárá láti wí ohun kan? Mo gbọdọ̀ sọ nǹkan tí Ọlọ́run fi sí mi lẹ́nu.”
І сказав Валаам до Балака: „Ось я прибув до тебе тепер. Чи потра́плю я сказати щось? Те слово, що Бог вкладе в уста мої, його тільки я буду промовляти“.
39 Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú Balaki sí Kiriati-Hosotia.
І пішов Валаам із Балаком, і прибули́ вони до Кір'ят-Хуцоту.
40 Balaki rú ẹbọ akọ màlúù pẹ̀lú àgùntàn, ó sì fún Balaamu ní díẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
І прині́с Балак на жертву худо́бу велику та худобу дрібну́, і послав Валаамові та вельможам, що з ним.
41 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaki gbé Balaamu lọ sí Bamoti Baali, láti ibẹ̀ ló ti rí apá kan àwọn ènìyàn.
І сталося вранці, і взяв Балак Валаама, та й вивів його на Бамот-Баал, щоб побачив ізвідти тільки частину того народу.