< Numbers 22 >
1 Nígbà náà àwọn ọmọ Israẹli rin ìrìnàjò lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n sì pa ibùdó lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani tí ó kọjá lọ sí Jeriko.
Potem synowie Izraela wyruszyli i rozbili obóz na równinach Moabu, z tej strony Jordanu [naprzeciw] Jerycha.
2 Nísinsin yìí, Balaki ọmọ Sippori rí gbogbo ohun tí àwọn Israẹli ti ṣe sí àwọn ará Amori,
A Balak, syn Sippora, widział wszystko, co Izrael uczynił Amorytom.
3 ẹ̀rù sì ba Moabu nítorí pé ọ̀pọ̀ ènìyàn wà níbẹ̀ nítòótọ́, Moabu kún fún ẹ̀rù nítorí àwọn ọmọ Israẹli.
Wtedy Moab bardzo się zląkł tego ludu, bo był liczny; i zatrwożył się Moab z powodu synów Izraela.
4 Moabu sọ fún àwọn àgbàgbà Midiani pé, “Nísinsin yìí ni àwọn wọ̀nyí yóò lá gbogbo ohun tí ó yí wa ká, bí màlúù ṣe ń jẹ koríko tí ó wà nínú oko.” Bẹ́ẹ̀ ni Balaki ọmọ Sippori, tí ó jẹ́ ọba Moabu nígbà náà,
Powiedział więc Moab do starszych Midianu: Teraz [to] mnóstwo pożre wszystko wokół nas, jak wół pożera trawę na polu. A w tym czasie królem Moabu był Balak, syn Sippora.
5 rán oníṣẹ́ pé Balaamu ọmọ Beori, tí ó wà ní Petori, ní ẹ̀bá odò Eufurate, ti ilẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ. Balaki sọ pé, “Àwọn ènìyàn kan jáde wá láti Ejibiti; wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ ayé wọ́n sì pa ibùdó súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi.
I wysłał posłańców do Balaama, syna Beora, do Petor, które leży nad rzeką ziemi synów jego ludu, aby go wezwać tymi słowy: Oto z Egiptu wyszedł lud, który okrył powierzchnię ziemi i stanął naprzeciwko mnie.
6 Nísinsin yìí, wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú, nítorí wọ́n ní agbára jù fún mi. Nípa ṣíṣe èyí èmi ó ṣẹ́gun wọn, kí n sì lé wọn kúrò ní ilẹ̀ yìí. Nítorí tí mo mọ̀ pé ìbùkún ni fún àwọn tí ìwọ bá bùkún, ìfibú sì ni ẹni tí ìwọ bá fi bú.”
Dlatego teraz przyjdź, proszę, i przeklnij mi ten lud, bo jest silniejszy ode mnie. Może zdołam go pobić i wypędzić z ziemi, bo wiem, [że] komu błogosławisz, [będzie] błogosławiony, a kogo przeklinasz, będzie przeklęty.
7 Àti àwọn àgbàgbà Moabu àti Midiani sì lọ pẹ̀lú owó àyẹ̀wò lọ́nà wọn, nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ Balaamu, wọ́n sọ nǹkan tí Balaki sọ fún wọn.
Wtedy starsi Moabu i starsi Midianu wybrali się w drogę, mając w swych rękach zapłatę za wróżbę. Przyszli do Balaama i przekazali mu słowa Balaka.
8 “Ẹ sùn níbí lálẹ́ yìí,” Balaamu sọ fún un pé, “èmi ó padà wá fún un yín ní èsì nǹkan tí Olúwa bá wí fún mi.” Nítorí tí àwọn ìjòyè Moabu dúró sọ́dọ̀ rẹ̀.
On zaś powiedział do nich: Pozostańcie tu na noc, a dam wam odpowiedź, jaką mi oznajmi PAN. I zostali książęta Moabu u Balaama.
9 Ọlọ́run tọ Balaamu wá ó sì wí pé, “Ta ni àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ yìí?”
I przyszedł Bóg do Balaama, i powiedział: Cóż to za ludzie [są] u ciebie?
10 Balaamu sọ fún Ọlọ́run pé, “Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, rán iṣẹ́ yìí sí mi pé,
Balaam odpowiedział Bogu: Balak, syn Sippora, król Moabu, wysłał [ich] do mnie, [mówiąc]:
11 ‘Àwọn ènìyàn kan ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá tí wọ́n bo ojú ilẹ̀. Nísinsin yìí, wá, kí o wá fi wọ́n bú fún mi. Bóyá èmi yóò lè bá wọn jà, èmi ó sì lé wọn jáde.’”
Oto z Egiptu wyszedł lud, który okrył powierzchnię ziemi. Przyjdź więc teraz, przeklnij mi go; może zdołam go pokonać i wypędzić.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún Balaamu pé, “Má ṣe bá wọn lọ. Ìwọ kò gbọdọ̀ gé ègún lé àwọn ènìyàn náà lórí, nítorí a ti bùkún wọn.”
Bóg powiedział do Balaama: Nie idź z nimi i nie przeklnij tego ludu, bo jest on błogosławiony.
13 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaamu dìde ó sì sọ fún àwọn ìjòyè Balaki pé, “Ẹ padà sí orílẹ̀-èdè yín, nítorí tí Olúwa ti kọ̀ láti jẹ́ kí n tẹ̀lé yín.”
Gdy Balaam wstał rano, powiedział do książąt Balaka: Wracajcie do waszej ziemi, bo PAN nie pozwala mi iść z wami.
14 Nígbà náà àwọn ìjòyè Moabu sì padà tọ Balaki lọ wọ́n sì wí pé, “Balaamu kọ̀ láti tẹ̀lé wa.”
Wstali więc książęta Moabu, przyszli do Balaka i powiedzieli: Balaam nie chciał iść z nami.
15 Nígbà náà Balaki rán àwọn ìjòyè mìíràn tí wọ́n pọ̀ àwọn tí wọ́n sì níyì ju alákọ́kọ́ lọ.
Wtedy Balak ponownie wysłał książąt – liczniejszych i dostojniejszych od pierwszych.
16 Wọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ Balaamu wọ́n sì sọ pé, “Èyí ni ohun tí Balaki ọmọ Sippori sọ, má ṣe jẹ́ kí ohunkóhun kí ó dè ọ́ lọ́nà láti wá sí ọ̀dọ̀ mi,
Przybyli oni do Balaama i powiedzieli mu: Tak mówi Balak, syn Sippora: Nie zwlekaj z przyjściem do mnie;
17 nítorí pé èmi yóò fún ọ ní ẹ̀bùn dáradára, èmi yóò sì ṣe ohunkóhun tí ìwọ bá sọ. Wá, kí o sì wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú fún mi.”
Ja bowiem wielce cię uczczę i uczynię wszystko, co mi powiesz, tylko przyjdź, proszę, i przeklnij mi ten lud.
18 Ṣùgbọ́n Balaamu dá wọn lóhùn pé, “Kódà tí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò ní ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí kéré tí ó kọjá òfin Olúwa Ọlọ́run mi.
Balaam odpowiedział sługom Balaka: Choćby Balak dał mi swój dom pełen srebra i złota, nie mógłbym przekroczyć słowa PANA, mego Boga, i uczynić [przeciwko niemu] czegoś małego czy wielkiego.
19 Nísinsin yìí ẹ dúró níbí di ọjọ́ kejì gẹ́gẹ́ bí àwọn tókù ti ṣe nígbà náà èmi yóò mọ ohun tí Olúwa yóò tún sọ fún mi.”
Lecz zostańcie tu i wy, proszę, na noc, a dowiem się, co PAN jeszcze będzie do mnie mówił.
20 Ní alẹ́ ọjọ́ náà Ọlọ́run sì tọ Balaamu wá ó sì sọ wí pé, “Nígbà tí ọkùnrin yìí ti wá pè ọ́, lọ pẹ̀lú wọn, ṣùgbọ́n ẹnu nǹkan tí mo sọ fún ọ ni kí o ṣe.”
I przyszedł Bóg do Balaama w nocy, i powiedział do niego: Jeśli ci mężczyźni przyjdą, aby cię wezwać, wstań i idź z nimi; uczynisz jednak, co ci rozkażę.
21 Balaamu dìde ní òwúrọ̀, ó sì di ẹrù lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ òun pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu.
Wstał więc Balaam rano, osiodłał swoją oślicę i pojechał z książętami Moabu.
22 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run bínú gidigidi, angẹli Olúwa sì dúró lójú ọ̀nà láti dojú ìjà kọ ọ́. Balaamu ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ lọ, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
I zapłonął gniew Boga, że on poszedł; i stanął Anioł PANA na drodze jako przeciwnik. On zaś jechał na swojej oślicy i z nim dwaj jego słudzy.
23 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà tí a fàyọ ní ọwọ́ rẹ̀, ó kọjú kúrò ní ọ̀nà lọ sínú oko. Balaamu sì lù ú pé kí ó gbé òhun padà lọ sí ojú ọ̀nà.
A [gdy] oślica zobaczyła Anioła PANA stojącego na drodze z obnażonym mieczem w ręku, zboczyła z drogi i poszła w pole. Balaam zaś bił oślicę, aby ją zawrócić na drogę.
24 Nígbà náà angẹli Olúwa dúró ní ojú ọ̀nà tóóró láàrín ọgbà àjàrà, pẹ̀lú ògiri ní ọ̀nà méjèèjì.
Wtedy Anioł PANA stanął na ścieżce między winnicami, a płot był z jednej i z drugiej strony.
25 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó lẹ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ ògiri, ó sì rún ẹsẹ̀ Balaamu mọ́ ògiri. Nígbà náà, ó tún nà án, lẹ́ẹ̀kan sí i.
A gdy oślica zobaczyła Anioła PANA, przyparła do muru i przygniotła do niego nogę Balaama; a on znowu ją bił.
26 Nígbà náà angẹli Olúwa súnmọ́ wájú ó sì dúró níbi ọ̀nà tóóró níbi tí kò ti sí ọ̀nà láti yípadà, bóyá ní ọ̀tún tàbí òsì.
Potem Anioł PANA poszedł dalej i stanął w ciasnym miejscu, gdzie nie można go było wyminąć ani z prawej, ani z lewej [strony];
27 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó sì jókòó ní abẹ́ Balaamu, inú sì bí i tó sì nà án pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀.
A gdy oślica zobaczyła Anioła PANA, padła pod Balaamem. Wtedy Balaam bardzo się rozgniewał i bił oślicę kijem.
28 Nígbà náà Olúwa ṣí ẹnu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì sọ fún Balaamu pé, “Kí ni mo ṣe fún ọ tí o fi nà mí lẹ́ẹ̀mẹ́ta?”
Wtedy PAN otworzył usta tej oślicy, a ona powiedziała do Balaama: Cóż ci uczyniłam, że już trzy razy mnie zbiłeś?
29 Balaamu sọ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pé, “Nítorí ìwọ fi mí ṣẹ̀sín! Bí mo bá ní idà ní ọwọ́ ni èmi ìbá pa ọ́ nísinsin yìí.”
Balaam odpowiedział oślicy: Ponieważ drwisz ze mnie. Gdybym miał miecz w ręku, teraz bym cię zabił.
30 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sọ fún Balaamu pé, “Ṣé mi kì í ṣe kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ ni, tí o máa ń gùn ní gbogbo ìgbà, láti ìgbà pípẹ́ wá? Ǹjẹ́ mo hu irú ìwà báyìí sí ọ rí?” “Rárá,” Ó dáhùn.
Oślica powiedziała do Balaama: Czy nie jestem twoją oślicą, na której jeździsz, odkąd mnie dostałeś aż do dziś? Czy miałam zwyczaj tak tobie czynić? A on odpowiedział: Nie.
31 Nígbà náà Olúwa ṣí ojú Balaamu, ó sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà rẹ̀ tí ó fàyọ. Ó sì tẹ orí rẹ̀ ba.
Wówczas PAN otworzył oczy Balaama i zobaczył Anioła PANA stojącego na drodze z obnażonym mieczem w ręku; i pochylił się, i upadł na twarz.
32 Nígbà náà angẹli Olúwa béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí o fi na kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ nígbà mẹ́ta yìí? Mo wá síbí láti kọ ojú ìjà sí ọ nítorí ọ̀nà rẹ kò tọ́ níwájú mi.
A Anioł PANA powiedział do niego: Dlaczego zbiłeś swoją oślicę trzy razy? Oto wyszedłem, by się tobie sprzeciwić, bo twoja droga jest przewrotna przede mną;
33 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí mi ó sì yà kúrò fún mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta yìí. Tí ó bá jẹ́ wí pé kò yà kúrò. Èmi kì ìbá ti pa ọ́ pátápátá nísinsin yìí, ṣùgbọ́n Èmi yóò sì dá òun sí.”
A oślica widziała mnie i ustępowała przede mną trzy razy; gdyby nie ustąpiła przede mną, już bym cię teraz zabił, a ją pozostawił przy życiu.
34 Balaamu sọ fún angẹli Olúwa pé, “Mo ti dẹ́ṣẹ̀, èmi kò mọ̀ pé o dúró níwájú ọ̀nà láti dojúkọ mí, nísinsin yìí tí inú rẹ kò bá dùn, èmi ó padà.”
Balaam powiedział więc do Anioła PANA: Zgrzeszyłem, bo nie wiedziałem, że stanąłeś naprzeciwko mnie na drodze; dlatego teraz, jeśli to ci się nie podoba, zawrócę.
35 Angẹli Olúwa sọ fún Balaamu pé, “Lọ pẹ̀lú àwọn arákùnrin náà, ṣùgbọ́n nǹkan tí mo sọ fún ọ nìkan ni kí o sọ.” Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Balaki.
Lecz Anioł PANA powiedział do Balaama: Jedź z [tymi] ludźmi, ale będziesz mówił tylko to, co tobie powiem. I poszedł Balaam z książętami Balaka.
36 Nígbà tí Balaki gbọ́ pé Balaamu ń bọ̀ wá, ó jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀ ní ìlú Moabu tí ó wà ní agbègbè Arnoni, ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ̀.
A [gdy] Balak usłyszał, że Balaam nadchodzi, wyszedł mu naprzeciw, do pewnego miasta Moabu, które leżało na granicy Arnonu, na końcu granicy.
37 Balaki sì sọ fún Balaamu pé, “Ǹjẹ́ èmi kò a ránṣẹ́ kánjúkánjú sí ọ? Kí ló dé tí ìwọ kò fi wá sí ọ̀dọ̀ mi? Ṣé èmi kò tó láti sọ ọ́ di ẹni ńlá?”
I Balak powiedział do Balaama: Czyż nie posłałem do ciebie pilnie, aby cię wezwać? Dlaczego nie przyszedłeś do mnie? Czyż nie potrafię cię uczcić?
38 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Kíyèsi, èmi tọ̀ ọ́ wá, èmi kò ha ní agbára kan nísinsin yìí rárá láti wí ohun kan? Mo gbọdọ̀ sọ nǹkan tí Ọlọ́run fi sí mi lẹ́nu.”
Balaam odpowiedział Balakowi: Oto przybyłem do ciebie. Czy mogę cokolwiek powiedzieć? Będę mówił słowo, które Bóg włoży w moje usta.
39 Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú Balaki sí Kiriati-Hosotia.
Poszedł więc Balaam z Balakiem i przyszli do Kiriat-Chusot.
40 Balaki rú ẹbọ akọ màlúù pẹ̀lú àgùntàn, ó sì fún Balaamu ní díẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Balak złożył w ofierze woły i owce i posłał do Balaama oraz do książąt, którzy z nim [byli].
41 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaki gbé Balaamu lọ sí Bamoti Baali, láti ibẹ̀ ló ti rí apá kan àwọn ènìyàn.
A nazajutrz Balak zabrał Balaama i zaprowadził go na wyżyny Baala, skąd mógł widzieć kraniec [obozu] ludu.