< Numbers 22 >

1 Nígbà náà àwọn ọmọ Israẹli rin ìrìnàjò lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n sì pa ibùdó lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani tí ó kọjá lọ sí Jeriko.
Stamtąd ruszyli się synowie Izraelscy, i położyli się obozem na polach Moabskich, z tej strony Jordanu przeciw Jerychowi.
2 Nísinsin yìí, Balaki ọmọ Sippori rí gbogbo ohun tí àwọn Israẹli ti ṣe sí àwọn ará Amori,
A widząc Balak, syn Seforów, wszystko, co uczynił Izrael Amorejczykowi,
3 ẹ̀rù sì ba Moabu nítorí pé ọ̀pọ̀ ènìyàn wà níbẹ̀ nítòótọ́, Moabu kún fún ẹ̀rù nítorí àwọn ọmọ Israẹli.
Uląkł się Moab tego ludu wielce, bo go było wiele; i zatrwożył sobą Moab dla synów Izraelskich.
4 Moabu sọ fún àwọn àgbàgbà Midiani pé, “Nísinsin yìí ni àwọn wọ̀nyí yóò lá gbogbo ohun tí ó yí wa ká, bí màlúù ṣe ń jẹ koríko tí ó wà nínú oko.” Bẹ́ẹ̀ ni Balaki ọmọ Sippori, tí ó jẹ́ ọba Moabu nígbà náà,
Przetoż rzekł Moab do starszych Madyjańskich: Teraz pożre to mnóstwo wszystko, co jest około nas, jako wół pożera trawę polną. A Balak, syn Seforów, był królem Moabskim na on czas.
5 rán oníṣẹ́ pé Balaamu ọmọ Beori, tí ó wà ní Petori, ní ẹ̀bá odò Eufurate, ti ilẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ. Balaki sọ pé, “Àwọn ènìyàn kan jáde wá láti Ejibiti; wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ ayé wọ́n sì pa ibùdó súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi.
I posłał posły do Balaama, syna Beorowego, do Pethoru miasta, które jest nad rzeką ziemi synów ludu jego, aby go wezwano, mówiąc: Oto lud wyszedł z Egiptu, oto okrył wierzch ziemi, i osadza się przeciwko mnie.
6 Nísinsin yìí, wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú, nítorí wọ́n ní agbára jù fún mi. Nípa ṣíṣe èyí èmi ó ṣẹ́gun wọn, kí n sì lé wọn kúrò ní ilẹ̀ yìí. Nítorí tí mo mọ̀ pé ìbùkún ni fún àwọn tí ìwọ bá bùkún, ìfibú sì ni ẹni tí ìwọ bá fi bú.”
Przetoż teraz przyjdź proszę, a przeklinaj mnie kwoli lud ten, bo możniejszy jest nad mię; owa snać go będę mógł porazić, i wygnać go z ziemi; bo ja wiem, że komu błogosławisz, błogosławiony będzie; a kogo przeklinasz, przeklęty będzie.
7 Àti àwọn àgbàgbà Moabu àti Midiani sì lọ pẹ̀lú owó àyẹ̀wò lọ́nà wọn, nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ Balaamu, wọ́n sọ nǹkan tí Balaki sọ fún wọn.
Poszli tedy starsi Moabscy, i starsi Madyjańscy, mając zapłatę za wieszczbę w rękach swych.
8 “Ẹ sùn níbí lálẹ́ yìí,” Balaamu sọ fún un pé, “èmi ó padà wá fún un yín ní èsì nǹkan tí Olúwa bá wí fún mi.” Nítorí tí àwọn ìjòyè Moabu dúró sọ́dọ̀ rẹ̀.
A przyszedłszy do Balaama, powiedzieli mu słowa Balakowe. I rzekł do nich: Zostańcie tu przez noc, a dam wam odpowiedź, jako mi oznajmi Pan.
9 Ọlọ́run tọ Balaamu wá ó sì wí pé, “Ta ni àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ yìí?”
I zostały książęta Moabskie z Balaamem. Tedy przyszedł Bóg do Balaama, i rzekł: Cóż to za mężowie u ciebie?
10 Balaamu sọ fún Ọlọ́run pé, “Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, rán iṣẹ́ yìí sí mi pé,
I odpowiedział Balaam Bogu: Balak, syn Seforów, król Moabski, posłał do mnie, mówiąc:
11 ‘Àwọn ènìyàn kan ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá tí wọ́n bo ojú ilẹ̀. Nísinsin yìí, wá, kí o wá fi wọ́n bú fún mi. Bóyá èmi yóò lè bá wọn jà, èmi ó sì lé wọn jáde.’”
Oto lud, który wyszedł z Egiptu, i okrył wierzch ziemi; terazże pójdź, przeklinaj mi go; snać będę mógł walczyć z nim, i wypędzę go.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún Balaamu pé, “Má ṣe bá wọn lọ. Ìwọ kò gbọdọ̀ gé ègún lé àwọn ènìyàn náà lórí, nítorí a ti bùkún wọn.”
Tedy rzekł Bóg do Balaama: Nie chodź z nimi, ani przeklinaj ludu tego; bo jest błogosławiony.
13 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaamu dìde ó sì sọ fún àwọn ìjòyè Balaki pé, “Ẹ padà sí orílẹ̀-èdè yín, nítorí tí Olúwa ti kọ̀ láti jẹ́ kí n tẹ̀lé yín.”
A wstawszy rano Balaam rzekł do książąt Balakowych: Wróćcie się do ziemi waszej; bo mi nie pozwala Pan puścić się w drogę z wami.
14 Nígbà náà àwọn ìjòyè Moabu sì padà tọ Balaki lọ wọ́n sì wí pé, “Balaamu kọ̀ láti tẹ̀lé wa.”
Wstawszy tedy książęta Moabskie, wrócili się do Balaka, i powiedzieli: Nie chciał Balaam iść z nami.
15 Nígbà náà Balaki rán àwọn ìjòyè mìíràn tí wọ́n pọ̀ àwọn tí wọ́n sì níyì ju alákọ́kọ́ lọ.
Tedy po wtóre posłał Balak więcej książąt, i zacniejszych nad pierwsze.
16 Wọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ Balaamu wọ́n sì sọ pé, “Èyí ni ohun tí Balaki ọmọ Sippori sọ, má ṣe jẹ́ kí ohunkóhun kí ó dè ọ́ lọ́nà láti wá sí ọ̀dọ̀ mi,
Którzy przyszedłszy do Balaama, mówili mu: Tak mówi Balak, syn Seforów: Nie ociągaj się proszę przyjść do mnie;
17 nítorí pé èmi yóò fún ọ ní ẹ̀bùn dáradára, èmi yóò sì ṣe ohunkóhun tí ìwọ bá sọ. Wá, kí o sì wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú fún mi.”
Albowiem ci wielką uczciwość wyrządzę, i wszystko, cobyś mi rzekł, uczynię; tylko przyjdź proszę a przeklinaj mi ten lud.
18 Ṣùgbọ́n Balaamu dá wọn lóhùn pé, “Kódà tí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò ní ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí kéré tí ó kọjá òfin Olúwa Ọlọ́run mi.
Tedy odpowiedział Balaam, i rzekł do sług Balakowych: Choćby mi dał Balak pełen dom swój srebra i złota, nie mógłbym przestąpić słów Pana, Boga mego, i uczynić przeciwko niemu, bądź mało bądź wiele;
19 Nísinsin yìí ẹ dúró níbí di ọjọ́ kejì gẹ́gẹ́ bí àwọn tókù ti ṣe nígbà náà èmi yóò mọ ohun tí Olúwa yóò tún sọ fún mi.”
Ale proszę zostańcie tu i wy przez noc, a dowiem się, co jeszcze Pan będzie mówił ze mną.
20 Ní alẹ́ ọjọ́ náà Ọlọ́run sì tọ Balaamu wá ó sì sọ wí pé, “Nígbà tí ọkùnrin yìí ti wá pè ọ́, lọ pẹ̀lú wọn, ṣùgbọ́n ẹnu nǹkan tí mo sọ fún ọ ni kí o ṣe.”
Tedy przyszedł Bóg do Balaama w nocy, i rzekł do niego: Jeźliż, aby cię wezwali, przyszli mężowie ci, wstańże, idź z nimi; a wszakże, coć rozkażę, to uczynisz.
21 Balaamu dìde ní òwúrọ̀, ó sì di ẹrù lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ òun pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu.
Tedy wstawszy Balaam rano, osiodłał oślicę swoją, i jechał z książęty Moabskimi.
22 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run bínú gidigidi, angẹli Olúwa sì dúró lójú ọ̀nà láti dojú ìjà kọ ọ́. Balaamu ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ lọ, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
I rozpalił się gniew Boży, że on jechał; i stanął Anioł Pański na drodze, aby mu zastąpił; a on jechał na oślicy swojej, i dwoje pacholąt jego z nim.
23 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà tí a fàyọ ní ọwọ́ rẹ̀, ó kọjú kúrò ní ọ̀nà lọ sínú oko. Balaamu sì lù ú pé kí ó gbé òhun padà lọ sí ojú ọ̀nà.
A gdy ujrzała oślica Anioła Pańskiego, stojącego na drodze, a miecz jego dobyty w ręce jego, tedy ustąpiła oślica z drogi a szła na rolę, lecz bił Balaam oślicę, aby ją nawiódł na drogę.
24 Nígbà náà angẹli Olúwa dúró ní ojú ọ̀nà tóóró láàrín ọgbà àjàrà, pẹ̀lú ògiri ní ọ̀nà méjèèjì.
Tedy stanął Anioł Pański na ścieżce u winnicy między dwoma płoty.
25 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó lẹ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ ògiri, ó sì rún ẹsẹ̀ Balaamu mọ́ ògiri. Nígbà náà, ó tún nà án, lẹ́ẹ̀kan sí i.
A widząc oślica Anioła Pańskiego, przyciskała się do płota, tak iż przyparła nogę Balaamową do ściany; a on znowu ją bił.
26 Nígbà náà angẹli Olúwa súnmọ́ wájú ó sì dúró níbi ọ̀nà tóóró níbi tí kò ti sí ọ̀nà láti yípadà, bóyá ní ọ̀tún tàbí òsì.
Potem Anioł Pański szedł dalej, i stanął na miejscu ciasnem, gdzie nie było drogi do ustąpienia na prawo ani na lewo;
27 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó sì jókòó ní abẹ́ Balaamu, inú sì bí i tó sì nà án pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀.
A widząc oślica Anioła Pańskiego, padła pod Balaamem; i rozgniewał się Balaam wielce, a bił oślicę kijem.
28 Nígbà náà Olúwa ṣí ẹnu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì sọ fún Balaamu pé, “Kí ni mo ṣe fún ọ tí o fi nà mí lẹ́ẹ̀mẹ́ta?”
Zatem otworzył Pan usta onej oślicy, i rzekła do Balaama: Cóżem ci uczyniła, żeś mię bił już po trzy kroć?
29 Balaamu sọ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pé, “Nítorí ìwọ fi mí ṣẹ̀sín! Bí mo bá ní idà ní ọwọ́ ni èmi ìbá pa ọ́ nísinsin yìí.”
I rzekł Balaam do oślicy: Iż ze mnie szydzisz; bym był miał miecz w ręku swych, byłbym cię teraz zabił.
30 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sọ fún Balaamu pé, “Ṣé mi kì í ṣe kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ ni, tí o máa ń gùn ní gbogbo ìgbà, láti ìgbà pípẹ́ wá? Ǹjẹ́ mo hu irú ìwà báyìí sí ọ rí?” “Rárá,” Ó dáhùn.
Tedy oślica rzekła do Balaama: Azażem ja nie oślica twoja, na którejś jeżdżał, jakoś mię dostał, aż do tego czasu? A on rzekł: Nigdy.
31 Nígbà náà Olúwa ṣí ojú Balaamu, ó sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà rẹ̀ tí ó fàyọ. Ó sì tẹ orí rẹ̀ ba.
Wtem otworzył Pan oczy Balaamowe, że obaczył Anioła Pańskiego, stojącego na drodze, i miecz jego dobyty w ręce jego; tedy skłoniwszy się, pokłonił się twarzą swoją.
32 Nígbà náà angẹli Olúwa béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí o fi na kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ nígbà mẹ́ta yìí? Mo wá síbí láti kọ ojú ìjà sí ọ nítorí ọ̀nà rẹ kò tọ́ níwájú mi.
I rzekł do niego Anioł Pański: Przeczżeś bił oślicę swoję już po trzy kroć? Otom Ja wyszedł, abym się tobie sprzeciwił; bo przewrotna jest droga twoja przede mną;
33 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí mi ó sì yà kúrò fún mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta yìí. Tí ó bá jẹ́ wí pé kò yà kúrò. Èmi kì ìbá ti pa ọ́ pátápátá nísinsin yìí, ṣùgbọ́n Èmi yóò sì dá òun sí.”
A widząc mię oślica ustąpiła przede mną po trzy kroć, a gdyby była nie ustąpiła przede mną, już bym cię był teraz zabił a onę bym był żywą zostawił.
34 Balaamu sọ fún angẹli Olúwa pé, “Mo ti dẹ́ṣẹ̀, èmi kò mọ̀ pé o dúró níwájú ọ̀nà láti dojúkọ mí, nísinsin yìí tí inú rẹ kò bá dùn, èmi ó padà.”
Zatem rzekł Balaam do Anioła Pańskiego: Zgrzeszyłem, albowiem nie widziałem, żeś ty stanął przeciwko mnie na drodze; przetoż teraz, jeźlić się to nie podoba, wrócę się.
35 Angẹli Olúwa sọ fún Balaamu pé, “Lọ pẹ̀lú àwọn arákùnrin náà, ṣùgbọ́n nǹkan tí mo sọ fún ọ nìkan ni kí o sọ.” Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Balaki.
Lecz Anioł Pański rzekł do Balaama: Jedź z ludźmi tymi; wszakże tylko, co Ja tobie powiem, mówić będziesz. I jechał Balaam z książęty Balakowymi.
36 Nígbà tí Balaki gbọ́ pé Balaamu ń bọ̀ wá, ó jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀ ní ìlú Moabu tí ó wà ní agbègbè Arnoni, ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ̀.
A gdy usłyszał Balak, iż przyjeżdża Balaam, wyjechał przeciwko niemu, do niektórego miasta Moabskiego, które jest na granicy Arnonu, które jest przy końcu granicy.
37 Balaki sì sọ fún Balaamu pé, “Ǹjẹ́ èmi kò a ránṣẹ́ kánjúkánjú sí ọ? Kí ló dé tí ìwọ kò fi wá sí ọ̀dọ̀ mi? Ṣé èmi kò tó láti sọ ọ́ di ẹni ńlá?”
Tedy rzekł Balak do Balaama: Azażem z pilnością nie posyłał do ciebie wzywając cię? Czemużeś nie przyjechał do mnie? azaż cię zacnie uczcić nie mogę?
38 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Kíyèsi, èmi tọ̀ ọ́ wá, èmi kò ha ní agbára kan nísinsin yìí rárá láti wí ohun kan? Mo gbọdọ̀ sọ nǹkan tí Ọlọ́run fi sí mi lẹ́nu.”
I rzekł Balaam do Balaka: Otom przyjechał do ciebie; izali teraz, choćbym chciał, będę mógł co mówić? słowo, które włoży Bóg w usta moje, mówić będę.
39 Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú Balaki sí Kiriati-Hosotia.
Tedy jechał Balaam z Balakiem a przyjechali do miasta Husot.
40 Balaki rú ẹbọ akọ màlúù pẹ̀lú àgùntàn, ó sì fún Balaamu ní díẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
A tak Balak dał nabić wołów i owiec, i posłał do Balaama, i do książąt, którzy z nim byli.
41 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaki gbé Balaamu lọ sí Bamoti Baali, láti ibẹ̀ ló ti rí apá kan àwọn ènìyàn.
I stało się nazajutrz, że wziął Balak Balaama, i wprowadził go na wyżyny Baalowe, skąd widział i najdalszą część ludu.

< Numbers 22 >