< Numbers 22 >

1 Nígbà náà àwọn ọmọ Israẹli rin ìrìnàjò lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n sì pa ibùdó lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani tí ó kọjá lọ sí Jeriko.
Og Israels Børn rejste derfra; og de lejrede sig paa Moabiternes slette Marker, paa hin Side Jordanen mod Jeriko.
2 Nísinsin yìí, Balaki ọmọ Sippori rí gbogbo ohun tí àwọn Israẹli ti ṣe sí àwọn ará Amori,
Og Balak, Zippors Søn, saa alt det, som Israel havde gjort Amoriterne.
3 ẹ̀rù sì ba Moabu nítorí pé ọ̀pọ̀ ènìyàn wà níbẹ̀ nítòótọ́, Moabu kún fún ẹ̀rù nítorí àwọn ọmọ Israẹli.
Og Moabiterne frygtede saare for Folket, fordi det var talrigt; og Moabiterne gruede for Israels Børn.
4 Moabu sọ fún àwọn àgbàgbà Midiani pé, “Nísinsin yìí ni àwọn wọ̀nyí yóò lá gbogbo ohun tí ó yí wa ká, bí màlúù ṣe ń jẹ koríko tí ó wà nínú oko.” Bẹ́ẹ̀ ni Balaki ọmọ Sippori, tí ó jẹ́ ọba Moabu nígbà náà,
Da sagde Moab til Midianiternes Ældste: Nu skal denne Flok opslikke alt rundt omkring os, ligesom Oksen opslikker grønne Urter paa Marken; men Balak, Zippors Søn, var Moabiternes Konge paa den Tid.
5 rán oníṣẹ́ pé Balaamu ọmọ Beori, tí ó wà ní Petori, ní ẹ̀bá odò Eufurate, ti ilẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ. Balaki sọ pé, “Àwọn ènìyàn kan jáde wá láti Ejibiti; wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ ayé wọ́n sì pa ibùdó súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi.
Og han sendte Bud til Bileam, Beors Søn, til Pethor, som er ved Floden, til hans Folks Børns Land, for at kalde ham, sigende: Se, et Folk er udgaaet af Ægypten, se, det skjuler Jordens Kreds, og det ligger tværs over for mig.
6 Nísinsin yìí, wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú, nítorí wọ́n ní agbára jù fún mi. Nípa ṣíṣe èyí èmi ó ṣẹ́gun wọn, kí n sì lé wọn kúrò ní ilẹ̀ yìí. Nítorí tí mo mọ̀ pé ìbùkún ni fún àwọn tí ìwọ bá bùkún, ìfibú sì ni ẹni tí ìwọ bá fi bú.”
Og nu, kære, gak hid, forband mig dette Folk, thi det er mig for mægtigt, maaske jeg kunde slaa det og uddrive det af Landet; thi jeg ved, at hvem du velsigner, er velsignet, og hvem du forbander, skal være forbandet.
7 Àti àwọn àgbàgbà Moabu àti Midiani sì lọ pẹ̀lú owó àyẹ̀wò lọ́nà wọn, nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ Balaamu, wọ́n sọ nǹkan tí Balaki sọ fún wọn.
Og de Ældste af Moabiterne gik hen med de Ældste af Midianiterne, og Spaamandsløn var i deres Haand, og de kom til Bileam, og de talede Balaks Ord til ham.
8 “Ẹ sùn níbí lálẹ́ yìí,” Balaamu sọ fún un pé, “èmi ó padà wá fún un yín ní èsì nǹkan tí Olúwa bá wí fún mi.” Nítorí tí àwọn ìjòyè Moabu dúró sọ́dọ̀ rẹ̀.
Og han sagde til dem: Bliver her i denne Nat, saa vil jeg give eder Svar, ligesom Herren vil tale til mig; saa bleve Moabiternes Fyrster hos Bileam.
9 Ọlọ́run tọ Balaamu wá ó sì wí pé, “Ta ni àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ yìí?”
Og Gud kom til Bileam og sagde: Hvo ere de Mænd, som ere hos dig?
10 Balaamu sọ fún Ọlọ́run pé, “Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, rán iṣẹ́ yìí sí mi pé,
Og Bileam sagde til Gud: Balak, Zippors Søn, Moabiternes Konge, har sendt til mig, sigende:
11 ‘Àwọn ènìyàn kan ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá tí wọ́n bo ojú ilẹ̀. Nísinsin yìí, wá, kí o wá fi wọ́n bú fún mi. Bóyá èmi yóò lè bá wọn jà, èmi ó sì lé wọn jáde.’”
Se her det Folk, som er udgaaet af Ægypten og skjuler Jordens Kreds! gak nu hid, forband mig det, maaske jeg kunde stride imod det og uddrive det.
12 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún Balaamu pé, “Má ṣe bá wọn lọ. Ìwọ kò gbọdọ̀ gé ègún lé àwọn ènìyàn náà lórí, nítorí a ti bùkún wọn.”
Og Gud sagde til Bileam: Du skal ikke gaa med dem, du skal ikke forbande Folket; thi det er velsignet.
13 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaamu dìde ó sì sọ fún àwọn ìjòyè Balaki pé, “Ẹ padà sí orílẹ̀-èdè yín, nítorí tí Olúwa ti kọ̀ láti jẹ́ kí n tẹ̀lé yín.”
Da stod Bileam op om Morgenen og sagde til Balaks Fyrster: Gaar til eders Land; thi Herren vægrer sig ved at tillade mig at gaa med eder.
14 Nígbà náà àwọn ìjòyè Moabu sì padà tọ Balaki lọ wọ́n sì wí pé, “Balaamu kọ̀ láti tẹ̀lé wa.”
Saa gjorde Moabiternes Fyrster sig rede og kom til Balak, og de sagde: Bileam vægrede sig ved at gaa med os.
15 Nígbà náà Balaki rán àwọn ìjòyè mìíràn tí wọ́n pọ̀ àwọn tí wọ́n sì níyì ju alákọ́kọ́ lọ.
Da blev Balak endnu ved at sende flere og herligere Fyrster end disse.
16 Wọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ Balaamu wọ́n sì sọ pé, “Èyí ni ohun tí Balaki ọmọ Sippori sọ, má ṣe jẹ́ kí ohunkóhun kí ó dè ọ́ lọ́nà láti wá sí ọ̀dọ̀ mi,
Og de kom til Bileam, og de sagde til ham: Saa siger Balak, Zippors Søn: Kære, lad dig ikke forhindre fra at gaa til mig.
17 nítorí pé èmi yóò fún ọ ní ẹ̀bùn dáradára, èmi yóò sì ṣe ohunkóhun tí ìwọ bá sọ. Wá, kí o sì wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú fún mi.”
Thi jeg vil ære dig saare, og alt det, du siger til mig, vil jeg gøre; men gak hid, kære, forband mig dette Folk!
18 Ṣùgbọ́n Balaamu dá wọn lóhùn pé, “Kódà tí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò ní ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí kéré tí ó kọjá òfin Olúwa Ọlọ́run mi.
Og Bileam svarede og sagde til Balaks Tjenere: Dersom Balak vilde give mig sit Hus, fuldt af Sølv og Guld, kunde jeg dog ikke overtræde Herren min Guds Ord ved at gøre lidet eller stort.
19 Nísinsin yìí ẹ dúró níbí di ọjọ́ kejì gẹ́gẹ́ bí àwọn tókù ti ṣe nígbà náà èmi yóò mọ ohun tí Olúwa yóò tún sọ fún mi.”
Men bliver dog nu her, ogsaa I, i denne Nat, saa vil jeg fornemme, hvad Herren vil ydermere tale med mig.
20 Ní alẹ́ ọjọ́ náà Ọlọ́run sì tọ Balaamu wá ó sì sọ wí pé, “Nígbà tí ọkùnrin yìí ti wá pè ọ́, lọ pẹ̀lú wọn, ṣùgbọ́n ẹnu nǹkan tí mo sọ fún ọ ni kí o ṣe.”
Da kom Gud til Bileam om Natten og sagde til ham: Dersom de Mænd ere komne for at kalde dig, da staa op, gak med dem; men dog, det Ord, som jeg vil tale til dig, det skal du gøre.
21 Balaamu dìde ní òwúrọ̀, ó sì di ẹrù lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ òun pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu.
Da stod Bileam op om Morgenen og sadlede sin Aseninde og drog med Moabiternes Fyrster.
22 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run bínú gidigidi, angẹli Olúwa sì dúró lójú ọ̀nà láti dojú ìjà kọ ọ́. Balaamu ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ lọ, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Men Guds Vrede optændtes, fordi han drog med, og Herrens Engel stillede sig i Vejen for at staa ham imod; men han red paa sin Aseninde, og hans tvende Drenge vare med ham.
23 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà tí a fàyọ ní ọwọ́ rẹ̀, ó kọjú kúrò ní ọ̀nà lọ sínú oko. Balaamu sì lù ú pé kí ó gbé òhun padà lọ sí ojú ọ̀nà.
Og Aseninden saa Herrens Engel staa i Vejen med et draget Sværd i sin Haand, og Aseninden veg af Vejen og gik ud paa Marken; men Bileam slog Aseninden for at bøje den ind paa Vejen.
24 Nígbà náà angẹli Olúwa dúró ní ojú ọ̀nà tóóró láàrín ọgbà àjàrà, pẹ̀lú ògiri ní ọ̀nà méjèèjì.
Da stod Herrens Engel i en Hulvej imellem Vingaardene, hvor der var Stengærde paa begge Sider.
25 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó lẹ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ ògiri, ó sì rún ẹsẹ̀ Balaamu mọ́ ògiri. Nígbà náà, ó tún nà án, lẹ́ẹ̀kan sí i.
Og der Aseninden saa Herrens Engel, da trykkede hun sig til Væggen og trykkede Bileams Fod til Væggen; og han slog hende end mere.
26 Nígbà náà angẹli Olúwa súnmọ́ wájú ó sì dúró níbi ọ̀nà tóóró níbi tí kò ti sí ọ̀nà láti yípadà, bóyá ní ọ̀tún tàbí òsì.
Men Herrens Engel blev ved at gaa frem og stod paa et snævert Sted, hvor der ingen Vej var til at vige til højre eller venstre Side.
27 Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó sì jókòó ní abẹ́ Balaamu, inú sì bí i tó sì nà án pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀.
Og Aseninden saa Herrens Engel, og hun lagde sig ned under Bileam; da optændtes Bileams Vrede, og han slog Aseninden med Kæppen.
28 Nígbà náà Olúwa ṣí ẹnu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì sọ fún Balaamu pé, “Kí ni mo ṣe fún ọ tí o fi nà mí lẹ́ẹ̀mẹ́ta?”
Da aabnede Herren Asenindens Mund, og hun sagde til Bileam: Hvad har jeg gjort dig, at du har slaget mig nu tre Gange.
29 Balaamu sọ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pé, “Nítorí ìwọ fi mí ṣẹ̀sín! Bí mo bá ní idà ní ọwọ́ ni èmi ìbá pa ọ́ nísinsin yìí.”
Og Bileam sagde til Aseninden: Fordi du har drillet mig, gid jeg havde et Sværd i min Haand, da vilde jeg nu slaa dig ihjel.
30 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sọ fún Balaamu pé, “Ṣé mi kì í ṣe kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ ni, tí o máa ń gùn ní gbogbo ìgbà, láti ìgbà pípẹ́ wá? Ǹjẹ́ mo hu irú ìwà báyìí sí ọ rí?” “Rárá,” Ó dáhùn.
Da sagde Aseninden til Bileam: Er jeg ikke din Aseninde, som du har redet paa al din Tid, indtil denne Dag? plejede jeg nogensinde at gøre saaledes imod dig? og han sagde: Nej.
31 Nígbà náà Olúwa ṣí ojú Balaamu, ó sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà rẹ̀ tí ó fàyọ. Ó sì tẹ orí rẹ̀ ba.
Da oplod Herren Bileams Øjne, at han saa Herrens Engel staaende i Vejen med det dragne Sværd i sin Haand; og han bøjede sig og faldt ned paa sit Ansigt.
32 Nígbà náà angẹli Olúwa béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí o fi na kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ nígbà mẹ́ta yìí? Mo wá síbí láti kọ ojú ìjà sí ọ nítorí ọ̀nà rẹ kò tọ́ níwájú mi.
Og Herrens Engel sagde til ham: Hvorfor har du slaget din Aseninde nu tre Gange? se, jeger udgangen at staa dig imod; thi for mine Øjne fører denne Vej til Fordærvelse.
33 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí mi ó sì yà kúrò fún mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta yìí. Tí ó bá jẹ́ wí pé kò yà kúrò. Èmi kì ìbá ti pa ọ́ pátápátá nísinsin yìí, ṣùgbọ́n Èmi yóò sì dá òun sí.”
Og Aseninden saa mig og veg nu tre Gange af Vejen for mit Ansigt, ellers, dersom hun ikke var vegen af Vejen for mit Ansigt, da vilde jeg nu endogsaa have slaaet dig ihjel og ladet hende leve.
34 Balaamu sọ fún angẹli Olúwa pé, “Mo ti dẹ́ṣẹ̀, èmi kò mọ̀ pé o dúró níwájú ọ̀nà láti dojúkọ mí, nísinsin yìí tí inú rẹ kò bá dùn, èmi ó padà.”
Da sagde Bileam til Herrens Engel: Jeg har syndet, thi jeg vidste ikke, at du stod lige imod mig paa Vejen; og nu, dersom det er ondt for dine Øjne, vil jeg vende tilbage igen.
35 Angẹli Olúwa sọ fún Balaamu pé, “Lọ pẹ̀lú àwọn arákùnrin náà, ṣùgbọ́n nǹkan tí mo sọ fún ọ nìkan ni kí o sọ.” Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Balaki.
Og Herrens Engel sagde til Bileam: Drag med Mændene, men kun det Ord, som jeg taler til dig, det skal du tale; saa drog Bileam med Balaks Fyrster.
36 Nígbà tí Balaki gbọ́ pé Balaamu ń bọ̀ wá, ó jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀ ní ìlú Moabu tí ó wà ní agbègbè Arnoni, ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ̀.
Og Balak hørte, at Bileam kom, og han drog ud ham i Møde til en Stad i Moab, som var ved Landemærket Arnon, som er ved det yderste Landemærke.
37 Balaki sì sọ fún Balaamu pé, “Ǹjẹ́ èmi kò a ránṣẹ́ kánjúkánjú sí ọ? Kí ló dé tí ìwọ kò fi wá sí ọ̀dọ̀ mi? Ṣé èmi kò tó láti sọ ọ́ di ẹni ńlá?”
Og Balak sagde til Bileam: Sendte jeg ikke Bud til dig at lade dig kalde? hvi drog du ikke til mig? mon jeg virkelig ikke skulde kunne ære dig?
38 Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Kíyèsi, èmi tọ̀ ọ́ wá, èmi kò ha ní agbára kan nísinsin yìí rárá láti wí ohun kan? Mo gbọdọ̀ sọ nǹkan tí Ọlọ́run fi sí mi lẹ́nu.”
Og Bileam sagde til Balak: Se, jeg er nu kommen til dig; mon jeg formaar at tale noget? det Ord, som Gud vil lægge i min Mund, det vil jeg tale.
39 Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú Balaki sí Kiriati-Hosotia.
Saa for Bileam med Balak, og de kom til Kirjath-Husoth.
40 Balaki rú ẹbọ akọ màlúù pẹ̀lú àgùntàn, ó sì fún Balaamu ní díẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Og Balak ofrede stort Kvæg og smaat Kvæg og sendte deraf til Bileam og til de Fyrster, som vare hos ham.
41 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaki gbé Balaamu lọ sí Bamoti Baali, láti ibẹ̀ ló ti rí apá kan àwọn ènìyàn.
Og det skete om Morgenen, da tog Balak Bileam og førte ham op paa Baals Høje; og han saa derfra det yderste af Folket.

< Numbers 22 >