< Numbers 21 >

1 Nígbà tí ọba Aradi ará Kenaani, tí ń gbé ní gúúsù gbọ́ wí pé Israẹli ń bọ̀ wá ní ojú ọ̀nà Atarimu, ó bá Israẹli jà ó sì fi agbára mú díẹ̀ lára wọn.
Då nu konungen i Arad, kananéen, som bodde i Sydlandet, hörde att Israel var i antågande på Atarimvägen, gav han sig i strid med Israel och tog några av dem till fånga.
2 Nígbà náà ni Israẹli jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí o bá lè fi àwọn ènìyàn yìí lé wa lọ́wọ́, gbogbo ìlú wọn ni a ó parun.”
Då gjorde Israel ett löfte åt HERREN och sade: »Om du giver detta folk i min hand, så skall jag giva deras städer till spillo.»
3 Olúwa gbọ́ ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fi àwọn ará Kenaani lé wọn lọ́wọ́. Wọ́n pa wọ́n run pátápátá; torí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ ní Horma.
Och HERREN hörde Israels röst och gav kananéerna i deras hand, och de gåvo dem och deras städer till spillo; så fick stället namnet Horma.
4 Wọ́n rin ìrìnàjò láti òkè Hori lọ sí ọ̀nà tó lọ sí Òkun Pupa, láti kọjá yípo Edomu. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn bínú ní ojú ọ̀nà;
Och de bröto upp från berget Hor och togo vägen åt Röda havet till, för att gå omkring Edoms land. Men under vägen blev folket otåligt.
5 wọ́n sì sọ̀rọ̀ lòdì sí Ọlọ́run àti Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti kí a ba le wá kú sí aginjù yìí? Kò sí oúnjẹ! Kò sì sí omi! Àwa sì kórìíra oúnjẹ tí kò dára yìí!”
Och folket talade emot Gud och emot Mose och sade: »Varför haven I fört oss upp ur Egypten, så att vi måste dö i öknen? Här finnes ju varken bröd eller vatten, och vår själ vämjes vid den usla föda vi få.»
6 Nígbà náà ni Olúwa rán ejò olóró sí àárín wọn; wọ́n gé àwọn ènìyàn jẹ, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Israẹli sì kú.
Då sände HERREN giftiga ormar bland folket, och dessa stungo folket; och mycket folk i Israel blev dödat.
7 Àwọn ènìyàn sì wá sí ọ̀dọ̀ Mose wọn wí pé, “A ti dá ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí asọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa àti sí ìwọ pẹ̀lú. Gba àdúrà pé kí Olúwa mú ejò náà kúrò lọ́dọ̀ wa.” Nígbà náà ni Mose gbàdúrà fún àwọn ènìyàn.
Då kom folket till Mose och sade: »Vi hava syndat därmed att vi talade mot HERREN och mot dig. Bed till HERREN att han tager bort dessa ormar ifrån oss.» Och Mose bad för folket.
8 Olúwa sọ fún Mose pé, “Rọ ejò, a ó sì gbé e kọ́ sókè lórí igi, ẹni tí ejò bá ti gé jẹ lè wò ó yóò sì yè.”
Då sade HERREN till Mose: »Gör dig en orm och sätt upp den på en stång; sedan må var och en som har blivit ormstungen se på den, så skall han bliva vid liv.»
9 Nígbà náà ni Mose sì rọ ejò onírin ó sì gbé e kọ́ sórí igi, bí ejò bá sì bu ẹnikẹ́ni jẹ bí ó bá ti wò ó yóò sì yè.
Då gjorde Mose en orm av koppar och satte upp den på en stång; när sedan någon hade blivit stungen av en orm, såg han upp på kopparormen och blev så vid liv.
10 Àwọn ọmọ Israẹli tẹ̀síwájú wọ́n sì péjọ sí Obotu.
Och Israels barn bröto upp och lägrade sig i Obot;
11 Wọ́n gbéra ní Obotu wọ́n sì pa ibùdó sí Iye-Abarimu, ní aginjù tí ó kọjú sí Moabu ní ìdojúkọ ìlà-oòrùn.
och från Obot bröto de upp och lägrade sig vid Ije-Haabarim i öknen som ligger framför Moab, österut.
12 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gbéra wọ́n sì pa ibùdó ní àfonífojì Seredi.
Därifrån bröto de upp och lägrade sig i Sereds dal.
13 Láti ibẹ̀ lọ, wọn ṣí, wọ́n sì dó sí ìhà kejì Arnoni, tí ó wà ní aginjù tí ó wà ní agbègbè ilẹ̀ àwọn ọmọ Amori. Arnoni jẹ́ ààlà fún ilẹ̀ Moabu, láàrín Moabu àti Amori.
Därifrån bröto de upp och lägrade sig på andra sidan Arnon, där denna bäck från amoréernas område, där den har runnit upp, flyter fram i öknen; ty Arnon är Moabs gräns och flyter fram mellan Moabs land och amoréernas.
14 Ìdí nìyìí tí ìwé ogun Olúwa se wí pé, “…Wahebu ní Sufa, Òkun Pupa àti ní odò Arnoni
Därför heter det i »Boken om HERRENS krig»: »Vaheb i Sufa och dalarna där Arnon går fram,
15 àti ní ìṣàn odò tí ó darí sí ibùjókòó Ari tí ó sì fi ara ti ìpínlẹ̀ Moabu.”
och dalarnas sluttning, som sänker sig mot Ars bygd och stöder sig mot Moabs gräns.»
16 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ rìn dé Beeri, èyí ni kànga tí Olúwa sọ fún Mose, “Kó àwọn ènìyàn jọ èmi ó sì fún wọn ní omi.”
Därifrån drogo de till Beeri om brunnen där var det som HERREN sade till Mose: »Församla folket, så vill jag giva dem vatten.»
17 Nígbà náà ni Israẹli kọ orin yìí pé, “Sun jáde, ìwọ kànga! Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,
Då sjöng Israel denna sång: »Flöda, du brunn! Ja, sjungen om den,
18 nípa kànga tí àwọn ọmọ-aládé gbẹ́, nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ ẹ; tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fi ọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.” Nígbà náà wọ́n kúrò láti aginjù lọ sí Mattana,
om brunnen som furstar grävde, som folkets ypperste borrade, med spiran, med sina stavar.
19 láti Mattana lọ sí Nahalieli, láti Nahalieli lọ sí Bamoti,
Från öknen drogo de till Mattana, från Mattana till Nahaliel, från: Nahaliel till Bamot,
20 àti láti Bamoti lọ sí àfonífojì ní Moabu níbi tí òkè Pisga, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí aginjù.
från Bamot till den dal som ligger: på Moabs mark uppe på Pisga, där man kan se ut över ödemarken.
21 Israẹli rán oníṣẹ́ láti sọ fún Sihoni ọba àwọn ará Amori wí pé,
Och Israel skickade sändebud till Sihon, amoréernas konung, och lät säga:
22 “Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀-èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà àjàrà àbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”
»Låt mig taga genom ditt land. Vi skola icke vika av ifrån vägen in i åkrar eller vingårdar, och icke dricka vatten ur brunnarna. Stora vägen skola vi gå, till dess vi hava kommit igenom ditt område.»
23 Ṣùgbọ́n Sihoni kò ní jẹ́ kí àwọn Israẹli kọjá ní ilẹ̀ wọn. Ó pe àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì wọ́de ogun lọ sí aginjù nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Nígbà tí ó dé Jahasi, ó bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
Men Sihon tillstadde icke Israel att tåga genom sitt område, utan församlade allt sitt folk och drog ut mot Israel i öknen, till dess han kom till Jahas; där gav han sig i strid med Israel.
24 Àmọ́, Israẹli ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Arnoni lọ dé Jabbok, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.
Men Israel slog honom med svärdsegg och intog hans land från Arnon ända till Jabbok, ända till Ammons barns land, ty Ammons barns gräns var befäst.
25 Israẹli sì gba gbogbo ìlú Amori wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Heṣboni, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.
Och Israel intog alla städerna där; och Israel bosatte sig i amoréernas alla städer, i Hesbon och alla underlydande orter.
26 Heṣboni ni ìlú Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ó bá ọba Moabu ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Arnoni.
Hesbon var nämligen Sihons, amoréernas konungs, stad, ty denne hade fört krig med den förre konungen i Moab och tagit ifrån honom hela hans land ända till Arnon.
27 Ìdí nìyìí tí akọrin sọ wí pé, “Wá sí Heṣboni kí ẹ jẹ́ kí a tún un kọ́; jẹ́ kí ìlú Sihoni padà bọ̀ sípò.
Därför säga skalderna: »Kommen till Hesbon! Byggas och befästas skall Sihons stad.
28 “Iná jáde láti Heṣboni, ọ̀wọ́-iná láti Sihoni. Ó jó Ari àti Moabu run, àti ìlú àwọn olùgbé ibi gíga Arnoni.
Ty eld gick ut från Hesbon, en låga från Sihons stad; den förtärde Ar i Moab, dem som bodde på Arnons höjder.
29 Ègbé ní fún ọ, ìwọ Moabu! Ẹ ti parun, ẹ̀yin ènìyàn Kemoṣi! Ó ti fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá àti ọmọ rẹ̀ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìgbèkùn fún Sihoni ọba àwọn Amori.
Ve dig, Moab! Förlorat är du, Kemos' folk! Han lät sina söner bliva slagna på flykten och sina döttrar föras bort i fångenskap, bort till amoréernas konung, Sihon.
30 “Ṣùgbọ́n àti bì wọ́n ṣubú; a ti pa ìjẹgàba Heṣboni run, a pa wọ́n run títí dé Diboni. A sì ti bì wọ́n lulẹ̀ títí dé Nofa, tí ó sì fi dé Medeba.”
Vi sköto ned dem -- förlorat var Hesbon, landet ända till Dibon; vi härjade ända till Nofa, Nofa, som når till Medeba.»
31 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli sì ń gbé ní ilẹ̀ Amori.
Så bosatte sig då Israel i amoréernas land.
32 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose rán ayọ́lẹ̀wò lọ sí Jaseri, àwọn ọmọ Israẹli sì gba àwọn agbègbè tó yí wọn ká wọ́n sì lé àwọn Amori tó wà níbẹ̀ jáde.
Och Mose sände ut och lät bespeja Jaeser, och de intogo dess underlydande orter; och han fördrev amoréerna som bodde där.
33 Nígbà náà wọ́n pẹ̀yìndà wọ́n sì gòkè lọ sí Baṣani, Ogu ọba ti Baṣani àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wọ́de ogun jáde láti pàdé wọn ní ojú ogun ní Edrei.
Sedan vände de sig åt annat hål. och drogo upp åt Basan till. Och Og, konungen i Basan, drog med allt sitt folk ut till strid mot dem, till Edrei.
34 Olúwa sọ fún Mose pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀, kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
Men HERREN sade till Mose: »Frukta icke för honom, ty i din hand har jag givit honom och allt hans folk och hans land. Och du skall göra med honom på samma sätt som du gjorde med Sihon, amoréernas konung, som bodde i Hesbon.»
35 Wọ́n sì pa á, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọn kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè. Wọ́n sì gba ìní ilẹ̀ rẹ̀.
Och de slogo honom jämte hans söner och allt hans folk, och läto ingen av dem slippa undan. Så intogo de hans land.

< Numbers 21 >