< Numbers 21 >
1 Nígbà tí ọba Aradi ará Kenaani, tí ń gbé ní gúúsù gbọ́ wí pé Israẹli ń bọ̀ wá ní ojú ọ̀nà Atarimu, ó bá Israẹli jà ó sì fi agbára mú díẹ̀ lára wọn.
Ko je kralj Arád, Kánaanec, ki je prebival na jugu, slišal govorico, da je Izrael prišel po poti oglednikov, potem se je bojeval zoper Izrael in nekatere izmed njih prijel kot jetnike.
2 Nígbà náà ni Israẹli jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí o bá lè fi àwọn ènìyàn yìí lé wa lọ́wọ́, gbogbo ìlú wọn ni a ó parun.”
Izrael se je zaobljubil Gospodu in rekel: »Če zares hočeš to ljudstvo izročiti v mojo roko, potem bom popolnoma uničil njihova mesta.«
3 Olúwa gbọ́ ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fi àwọn ará Kenaani lé wọn lọ́wọ́. Wọ́n pa wọ́n run pátápátá; torí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ ní Horma.
Gospod je prisluhnil Izraelovemu glasu in izročil Kánaance, in popolnoma so jih uničili in njihova mesta in ime kraja je imenoval Horma.
4 Wọ́n rin ìrìnàjò láti òkè Hori lọ sí ọ̀nà tó lọ sí Òkun Pupa, láti kọjá yípo Edomu. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn bínú ní ojú ọ̀nà;
Odpotovali so z gore Hor po poti Rdečega morja, da obidejo deželo Edóm in duša ljudstva je zaradi poti zelo izgubila pogum.
5 wọ́n sì sọ̀rọ̀ lòdì sí Ọlọ́run àti Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti kí a ba le wá kú sí aginjù yìí? Kò sí oúnjẹ! Kò sì sí omi! Àwa sì kórìíra oúnjẹ tí kò dára yìí!”
Ljudstvo je govorilo zoper Boga in zoper Mojzesa: »Zakaj sta nas privedla gor iz Egipta, da umremo v divjini? Kajti tukaj ni kruha niti tukaj ni nobene vode in naši duši se gabi ta lahek kruh.«
6 Nígbà náà ni Olúwa rán ejò olóró sí àárín wọn; wọ́n gé àwọn ènìyàn jẹ, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Israẹli sì kú.
Gospod pa je med ljudstvo poslal ognjene kače in te so pikale ljudstvo in mnogo Izraelovega ljudstva je umrlo.
7 Àwọn ènìyàn sì wá sí ọ̀dọ̀ Mose wọn wí pé, “A ti dá ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí asọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa àti sí ìwọ pẹ̀lú. Gba àdúrà pé kí Olúwa mú ejò náà kúrò lọ́dọ̀ wa.” Nígbà náà ni Mose gbàdúrà fún àwọn ènìyàn.
Zato je ljudstvo prišlo k Mojzesu in reklo: »Grešili smo, kajti govorili smo zoper Gospoda in zoper tebe. Moli h Gospodu, da kače odvzame od nas.« In Mojzes je molil za ljudstvo.
8 Olúwa sọ fún Mose pé, “Rọ ejò, a ó sì gbé e kọ́ sókè lórí igi, ẹni tí ejò bá ti gé jẹ lè wò ó yóò sì yè.”
Gospod je rekel Mojzesu: »Naredi si ognjeno kačo in jo obesi na kol, in zgodilo se bo, da vsak, kdor je pičen, ko pogleda nanjo, bo živel.«
9 Nígbà náà ni Mose sì rọ ejò onírin ó sì gbé e kọ́ sórí igi, bí ejò bá sì bu ẹnikẹ́ni jẹ bí ó bá ti wò ó yóò sì yè.
Mojzes je naredil kačo iz brona in jo obesil na kol in pripetilo se je, da če je kateregakoli človeka pičila kača, ko je pogledal kačo iz brona, je živel.
10 Àwọn ọmọ Israẹli tẹ̀síwájú wọ́n sì péjọ sí Obotu.
Izraelovi otroci so se namerili naprej in se utaborili v Obótu.
11 Wọ́n gbéra ní Obotu wọ́n sì pa ibùdó sí Iye-Abarimu, ní aginjù tí ó kọjú sí Moabu ní ìdojúkọ ìlà-oòrùn.
In odpotovali so iz Obóta in se utaborili pri Ijé Abarímu, v divjini, ki je pred Moábom, proti sončnemu vzhodu.
12 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gbéra wọ́n sì pa ibùdó ní àfonífojì Seredi.
Od tam so odrinili in se utaborili v dolini Zared.
13 Láti ibẹ̀ lọ, wọn ṣí, wọ́n sì dó sí ìhà kejì Arnoni, tí ó wà ní aginjù tí ó wà ní agbègbè ilẹ̀ àwọn ọmọ Amori. Arnoni jẹ́ ààlà fún ilẹ̀ Moabu, láàrín Moabu àti Amori.
Od tam so odrinili in se utaborili na drugi strani Arnóna, ki je v divjini, ki prihaja iz pokrajin Amoréjcev, kajti Arnón je Moábova meja med Moábom in Amoréjci.
14 Ìdí nìyìí tí ìwé ogun Olúwa se wí pé, “…Wahebu ní Sufa, Òkun Pupa àti ní odò Arnoni
Zato je rečeno v knjigi Gospodovih vojn: »Kaj je storil v Rdečem morju in v potokih Arnóna
15 àti ní ìṣàn odò tí ó darí sí ibùjókòó Ari tí ó sì fi ara ti ìpínlẹ̀ Moabu.”
in pri vodotoku potokov, ki gredo dol k prebivališču Ar in leži na Moábovi meji.«
16 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ rìn dé Beeri, èyí ni kànga tí Olúwa sọ fún Mose, “Kó àwọn ènìyàn jọ èmi ó sì fún wọn ní omi.”
In od tam so odšli v Beêr, to je vodnjak, o katerem je Gospod govoril Mojzesu: »Zberi skupaj ljudstvo in jaz jim bom dal vodo.«
17 Nígbà náà ni Israẹli kọ orin yìí pé, “Sun jáde, ìwọ kànga! Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,
Potem je Izrael zapel to pesem: »Izviraj, o vodnjak. Pojte mu.
18 nípa kànga tí àwọn ọmọ-aládé gbẹ́, nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ ẹ; tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fi ọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.” Nígbà náà wọ́n kúrò láti aginjù lọ sí Mattana,
Princi so kopáli vodnjak, kopáli so ga plemiči izmed ljudstva, po navodilih postavodajalca, s svojimi palicami.« In iz divjine so odšli k Matánu,
19 láti Mattana lọ sí Nahalieli, láti Nahalieli lọ sí Bamoti,
in od Matána v Nahaliél, in iz Nahaliéla v Bamót,
20 àti láti Bamoti lọ sí àfonífojì ní Moabu níbi tí òkè Pisga, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí aginjù.
in iz Bamóta v dolino, ki je v moábski deželi, do vrha Pisge, ki gleda proti Ješimonu.
21 Israẹli rán oníṣẹ́ láti sọ fún Sihoni ọba àwọn ará Amori wí pé,
Izrael je poslal poslance k Sihónu, kralju Amoréjcev, rekoč:
22 “Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀-èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà àjàrà àbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”
»Pusti mi iti skozi tvojo deželo. Ne bomo se obrnili v polja ali v vinograde; ne bomo pili od vodá iz vodnjaka, temveč bomo šli vzdolž po kraljevi visoki poti, dokler ne bomo prešli tvojih mej.«
23 Ṣùgbọ́n Sihoni kò ní jẹ́ kí àwọn Israẹli kọjá ní ilẹ̀ wọn. Ó pe àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì wọ́de ogun lọ sí aginjù nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Nígbà tí ó dé Jahasi, ó bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
Sihón pa ni hotel trpeti, da gre Izrael skozi njegove meje, temveč je Sihón zbral vse ljudstvo in odšel ven zoper Izrael v divjino in prišel v Jahac in se bojeval zoper Izrael.
24 Àmọ́, Israẹli ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Arnoni lọ dé Jabbok, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.
Izrael pa ga je udaril z ostrino meča in vzel v last njegovo deželo od Arnóna do Jabóka, celo do Amónovih otrok, kajti meja Amónovih otrok je bila trdna.
25 Israẹli sì gba gbogbo ìlú Amori wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Heṣboni, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.
Izrael je zavzel vsa ta mesta in Izrael je prebival v vseh mestih Amoréjcev v Hešbónu in v vseh njegovih vaseh.
26 Heṣboni ni ìlú Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ó bá ọba Moabu ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Arnoni.
Kajti Hešbón je bil mesto amoréjskega kralja Sihóna, ki se je bojeval zoper prejšnjega moábskega kralja in je vso njegovo deželo vzel iz njegove roke, celo do Arnóna.
27 Ìdí nìyìí tí akọrin sọ wí pé, “Wá sí Heṣboni kí ẹ jẹ́ kí a tún un kọ́; jẹ́ kí ìlú Sihoni padà bọ̀ sípò.
Zato tisti, ki govorijo v pregovorih, pravijo: »Pridite v Hešbón, naj bo Sihónovo mesto zgrajeno in pripravljeno,
28 “Iná jáde láti Heṣboni, ọ̀wọ́-iná láti Sihoni. Ó jó Ari àti Moabu run, àti ìlú àwọn olùgbé ibi gíga Arnoni.
kajti ogenj je odšel iz Hešbóna, plamen iz mesta Sihón. Ta je použil Ar Moáb in gospodarje visokih krajev Arnóna.
29 Ègbé ní fún ọ, ìwọ Moabu! Ẹ ti parun, ẹ̀yin ènìyàn Kemoṣi! Ó ti fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá àti ọmọ rẹ̀ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìgbèkùn fún Sihoni ọba àwọn Amori.
Gorje tebi, Moáb! Uničeno si, oh ljudstvo Kemoša. Svojim sinovom je dal, da pobegnejo in svoje hčere v ujetništvo Sihónu, kralju Amoréjcev.
30 “Ṣùgbọ́n àti bì wọ́n ṣubú; a ti pa ìjẹgàba Heṣboni run, a pa wọ́n run títí dé Diboni. A sì ti bì wọ́n lulẹ̀ títí dé Nofa, tí ó sì fi dé Medeba.”
Streljali smo nanje, Hešbón je uničen celo do Dibóna in opustošili smo jih celo do Nofa, ki sega do Médebe.«
31 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli sì ń gbé ní ilẹ̀ Amori.
Tako je Izrael prebival v deželi Amoréjcev.
32 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose rán ayọ́lẹ̀wò lọ sí Jaseri, àwọn ọmọ Israẹli sì gba àwọn agbègbè tó yí wọn ká wọ́n sì lé àwọn Amori tó wà níbẹ̀ jáde.
In Mojzes je poslal, da ogledajo Jaazêr in zavzeli so njegove vasi in napodili Amoréjce, ki so bili tam.
33 Nígbà náà wọ́n pẹ̀yìndà wọ́n sì gòkè lọ sí Baṣani, Ogu ọba ti Baṣani àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wọ́de ogun jáde láti pàdé wọn ní ojú ogun ní Edrei.
In obrnili so se ter odšli gor, po poti Bašána in bašánski kralj Og je odšel ven zoper njih, on in vse njegovo ljudstvo, da se bojujejo pri Edréi.
34 Olúwa sọ fún Mose pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀, kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
Gospod je rekel Mojzesu: »Ne boj se ga, kajti izročil sem ga v tvojo roko in vse njegovo ljudstvo in njegovo deželo in storil mu boš, kakor si storil Sihónu, kralju Amoréjcev, ki je prebival pri Hešbónu.«
35 Wọ́n sì pa á, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọn kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè. Wọ́n sì gba ìní ilẹ̀ rẹ̀.
Tako so udarili njega, njegove sinove in vse njegovo ljudstvo, dokler nihče ni ostal živ, in njegovo deželo vzeli v last.