< Numbers 21 >

1 Nígbà tí ọba Aradi ará Kenaani, tí ń gbé ní gúúsù gbọ́ wí pé Israẹli ń bọ̀ wá ní ojú ọ̀nà Atarimu, ó bá Israẹli jà ó sì fi agbára mú díẹ̀ lára wọn.
A gdy król Aradu, Kananejczyk, który mieszkał na południu, usłyszał, że Izrael nadciąga drogą, którą [przeszli] szpiedzy, stoczył walkę z Izraelem i wziął jeńców.
2 Nígbà náà ni Israẹli jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí o bá lè fi àwọn ènìyàn yìí lé wa lọ́wọ́, gbogbo ìlú wọn ni a ó parun.”
Wtedy Izrael złożył PANU ślub, mówiąc: Jeśli wydasz ten lud w moje ręce, całkowicie zniszczę ich miasta.
3 Olúwa gbọ́ ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fi àwọn ará Kenaani lé wọn lọ́wọ́. Wọ́n pa wọ́n run pátápátá; torí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ ní Horma.
I PAN wysłuchał głosu Izraela, i wydał mu Kananejczyków. Całkowicie zniszczyli ich oraz ich miasta, a nadano temu miejscu nazwę Chorma.
4 Wọ́n rin ìrìnàjò láti òkè Hori lọ sí ọ̀nà tó lọ sí Òkun Pupa, láti kọjá yípo Edomu. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn bínú ní ojú ọ̀nà;
Potem wyruszyli od góry Hor w kierunku Morza Czerwonego, aby obejść ziemię Edom. I lud bardzo się zniechęcił w drodze.
5 wọ́n sì sọ̀rọ̀ lòdì sí Ọlọ́run àti Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti kí a ba le wá kú sí aginjù yìí? Kò sí oúnjẹ! Kò sì sí omi! Àwa sì kórìíra oúnjẹ tí kò dára yìí!”
Lud zaczął więc mówić przeciw Bogu i Mojżeszowi: Dlaczego wyprowadziliście nas z Egiptu, abyśmy pomarli na tej pustyni? Bo nie ma chleba ani wody, a nasza dusza obrzydziła sobie ten cienki chleb.
6 Nígbà náà ni Olúwa rán ejò olóró sí àárín wọn; wọ́n gé àwọn ènìyàn jẹ, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Israẹli sì kú.
Zesłał więc PAN na lud węże jadowite, które go kąsały; i pomarło wiele osób z Izraela.
7 Àwọn ènìyàn sì wá sí ọ̀dọ̀ Mose wọn wí pé, “A ti dá ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí asọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa àti sí ìwọ pẹ̀lú. Gba àdúrà pé kí Olúwa mú ejò náà kúrò lọ́dọ̀ wa.” Nígbà náà ni Mose gbàdúrà fún àwọn ènìyàn.
I lud przyszedł do Mojżesza, i powiedział: Zgrzeszyliśmy przez to, że mówiliśmy przeciw PANU i przeciw tobie. Módl się do PANA, aby oddalił od nas te węże. I Mojżesz modlił się za lud.
8 Olúwa sọ fún Mose pé, “Rọ ejò, a ó sì gbé e kọ́ sókè lórí igi, ẹni tí ejò bá ti gé jẹ lè wò ó yóò sì yè.”
Wtedy PAN powiedział do Mojżesza: Wykonaj jadowitego węża i umieść go na drzewcu. I stanie się tak, że każdy ukąszony, kiedy spojrzy na niego, będzie żył.
9 Nígbà náà ni Mose sì rọ ejò onírin ó sì gbé e kọ́ sórí igi, bí ejò bá sì bu ẹnikẹ́ni jẹ bí ó bá ti wò ó yóò sì yè.
Mojżesz wykonał więc węża miedzianego i umieścił go na drzewcu; gdy wąż kogoś ukąsił, a ten spojrzał na węża miedzianego, pozostawał przy życiu.
10 Àwọn ọmọ Israẹli tẹ̀síwájú wọ́n sì péjọ sí Obotu.
I wyruszyli synowie Izraela, i rozbili obóz w Obot.
11 Wọ́n gbéra ní Obotu wọ́n sì pa ibùdó sí Iye-Abarimu, ní aginjù tí ó kọjú sí Moabu ní ìdojúkọ ìlà-oòrùn.
A z Obot wyruszyli i rozbili obóz w Ijje-Haabarim na pustyni, która leży naprzeciw Moabu ku wschodowi słońca.
12 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gbéra wọ́n sì pa ibùdó ní àfonífojì Seredi.
Stamtąd wyruszyli i rozbili obóz nad potokiem Zered.
13 Láti ibẹ̀ lọ, wọn ṣí, wọ́n sì dó sí ìhà kejì Arnoni, tí ó wà ní aginjù tí ó wà ní agbègbè ilẹ̀ àwọn ọmọ Amori. Arnoni jẹ́ ààlà fún ilẹ̀ Moabu, láàrín Moabu àti Amori.
Stamtąd wyruszyli i rozbili obóz po drugiej stronie [rzeki] Arnon, która wypływa na pustyni od granicy Amorytów; Arnon stanowi bowiem granicę Moabu między Moabitami a Amorytami.
14 Ìdí nìyìí tí ìwé ogun Olúwa se wí pé, “…Wahebu ní Sufa, Òkun Pupa àti ní odò Arnoni
Dlatego jest powiedziane w księdze wojen PANA: Jak uczynił w Morzu Czerwonym i w potokach Arnonu;
15 àti ní ìṣàn odò tí ó darí sí ibùjókòó Ari tí ó sì fi ara ti ìpínlẹ̀ Moabu.”
U ujścia tych potoków, które ciągnie się ku osadzie Ar i przylega do granicy Moabu.
16 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ rìn dé Beeri, èyí ni kànga tí Olúwa sọ fún Mose, “Kó àwọn ènìyàn jọ èmi ó sì fún wọn ní omi.”
Stamtąd udali się do Beer; to jest ta studnia, o której PAN powiedział do Mojżesza: Zgromadź lud, a dam mu wody.
17 Nígbà náà ni Israẹli kọ orin yìí pé, “Sun jáde, ìwọ kànga! Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,
Wtedy Izrael śpiewał tę pieśń: Wzbierz studnio! Śpiewajcie o niej.
18 nípa kànga tí àwọn ọmọ-aládé gbẹ́, nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ ẹ; tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fi ọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.” Nígbà náà wọ́n kúrò láti aginjù lọ sí Mattana,
To studnia, którą wykopali naczelnicy; wykopali ją dostojnicy ludu wraz z prawodawcą swoimi laskami. A z tej pustyni [poszli] do Mattany;
19 láti Mattana lọ sí Nahalieli, láti Nahalieli lọ sí Bamoti,
A z Mattany do Nahalielu, a z Nahalielu do Bamot;
20 àti láti Bamoti lọ sí àfonífojì ní Moabu níbi tí òkè Pisga, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí aginjù.
A z Bamot do kotliny, która [jest] w ziemi Moabu, i do szczytu Pizga wznoszącego się nad Jeszimonem.
21 Israẹli rán oníṣẹ́ láti sọ fún Sihoni ọba àwọn ará Amori wí pé,
I Izrael wysłał posłańców do Sichona, króla Amorytów, mówiąc:
22 “Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀-èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà àjàrà àbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”
Pozwól nam przejść przez twoją ziemię; nie pójdziemy ani przez pola, ani przez winnice; nie będziemy pić wód ze studni. Pójdziemy drogą królewską, dopóki nie przejdziemy twoich granic.
23 Ṣùgbọ́n Sihoni kò ní jẹ́ kí àwọn Israẹli kọjá ní ilẹ̀ wọn. Ó pe àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì wọ́de ogun lọ sí aginjù nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Nígbà tí ó dé Jahasi, ó bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
Sichon jednak nie pozwolił Izraelowi przejść przez swoją granicę; Sichon zebrał cały swój lud i wyszedł przeciw Izraelowi na pustynię, a gdy przyszedł do Jahazy, stoczył bitwę z Izraelem.
24 Àmọ́, Israẹli ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Arnoni lọ dé Jabbok, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.
I Izrael pobił go ostrzem miecza, i wziął w posiadanie jego ziemię od Arnonu do Jabboku, aż do [ziemi] synów Ammona, gdyż granica Ammonitów była silna.
25 Israẹli sì gba gbogbo ìlú Amori wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Heṣboni, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.
Wtedy Izrael zdobył wszystkie te miasta i zamieszkał we wszystkich miastach Amorytów, w Cheszbonie i we wszystkich przylegających do niego wsiach.
26 Heṣboni ni ìlú Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ó bá ọba Moabu ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Arnoni.
Cheszbon był miastem Sichona, króla Amorytów, który walczył z królem Moabu i zabrał mu z rąk całą jego ziemię aż po Arnon.
27 Ìdí nìyìí tí akọrin sọ wí pé, “Wá sí Heṣboni kí ẹ jẹ́ kí a tún un kọ́; jẹ́ kí ìlú Sihoni padà bọ̀ sípò.
Dlatego mówią w przypowieści: Wejdźcie do Cheszbonu i niech się odbuduje, i umocni miasto Sichona.
28 “Iná jáde láti Heṣboni, ọ̀wọ́-iná láti Sihoni. Ó jó Ari àti Moabu run, àti ìlú àwọn olùgbé ibi gíga Arnoni.
Ponieważ ogień wyszedł z Cheszbonu, płomień z miasta Sichona; i pochłonął Ar moabskie oraz wzgórza Arnonu.
29 Ègbé ní fún ọ, ìwọ Moabu! Ẹ ti parun, ẹ̀yin ènìyàn Kemoṣi! Ó ti fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá àti ọmọ rẹ̀ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìgbèkùn fún Sihoni ọba àwọn Amori.
Biada tobie, Moabie! Zginąłeś, ludu Kemosza! Wydał swoich synów na tułaczkę i swoje córki w niewolę Sichonowi, królowi Amorytów.
30 “Ṣùgbọ́n àti bì wọ́n ṣubú; a ti pa ìjẹgàba Heṣboni run, a pa wọ́n run títí dé Diboni. A sì ti bì wọ́n lulẹ̀ títí dé Nofa, tí ó sì fi dé Medeba.”
Strzelaliśmy do nich, zginął Cheszbon aż po Dibon; a zburzyliśmy [je] aż do Nofach, które [idzie] aż do Medeby.
31 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli sì ń gbé ní ilẹ̀ Amori.
Tak to Izrael zamieszkał w ziemi Amorytów.
32 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose rán ayọ́lẹ̀wò lọ sí Jaseri, àwọn ọmọ Israẹli sì gba àwọn agbègbè tó yí wọn ká wọ́n sì lé àwọn Amori tó wà níbẹ̀ jáde.
Wtedy Mojżesz wysłał [wywiadowców] do Jazer na wyszpiegowanie, a oni zdobyli jego wsie i wypędzili Amorytów, którzy tam [byli].
33 Nígbà náà wọ́n pẹ̀yìndà wọ́n sì gòkè lọ sí Baṣani, Ogu ọba ti Baṣani àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wọ́de ogun jáde láti pàdé wọn ní ojú ogun ní Edrei.
Potem zawrócili i poszli w kierunku Baszanu; tam Og, król Baszanu, wyszedł przeciwko nim, on i cały jego lud, do walki w Edre.
34 Olúwa sọ fún Mose pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀, kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
Wtedy PAN powiedział do Mojżesza: Nie bój się go, gdyż wydałem go w twoje ręce wraz z całym jego ludem i ziemią i uczynisz z nim tak, jak uczyniłeś z Sichonem, królem Amorytów, który mieszkał w Cheszbonie.
35 Wọ́n sì pa á, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọn kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè. Wọ́n sì gba ìní ilẹ̀ rẹ̀.
I pobili go i jego synów oraz cały jego lud, tak że nikogo z niego nie pozostawili przy życiu, i wzięli w posiadanie jego ziemię.

< Numbers 21 >