< Numbers 21 >

1 Nígbà tí ọba Aradi ará Kenaani, tí ń gbé ní gúúsù gbọ́ wí pé Israẹli ń bọ̀ wá ní ojú ọ̀nà Atarimu, ó bá Israẹli jà ó sì fi agbára mú díẹ̀ lára wọn.
Da den kana'anittiske konge i Arad, som bodde i sydlandet, hørte at Israel drog frem på veien til Atarim, gav han sig i strid med Israel og førte nogen av dem bort som fanger.
2 Nígbà náà ni Israẹli jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí o bá lè fi àwọn ènìyàn yìí lé wa lọ́wọ́, gbogbo ìlú wọn ni a ó parun.”
Da gjorde Israel et løfte til Herren og sa: Gir du dette folk i min hånd, så vil jeg slå deres byer med bann.
3 Olúwa gbọ́ ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fi àwọn ará Kenaani lé wọn lọ́wọ́. Wọ́n pa wọ́n run pátápátá; torí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ ní Horma.
Og Herren hørte Israels bønn og overgav kana'anittene til dem, og de slo dem og deres byer med bann; og de kalte stedet Horma.
4 Wọ́n rin ìrìnàjò láti òkè Hori lọ sí ọ̀nà tó lọ sí Òkun Pupa, láti kọjá yípo Edomu. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn bínú ní ojú ọ̀nà;
Så brøt de op fra fjellet Hor og tok veien til det Røde Hav for å dra omkring Edoms land; men på veien blev folket utålmodig,
5 wọ́n sì sọ̀rọ̀ lòdì sí Ọlọ́run àti Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti kí a ba le wá kú sí aginjù yìí? Kò sí oúnjẹ! Kò sì sí omi! Àwa sì kórìíra oúnjẹ tí kò dára yìí!”
og de talte mot Gud og mot Moses og sa: Hvorfor har I ført oss op fra Egypten, så vi må dø her i ørkenen? For her er hverken brød eller vann, og vi er inderlig leie av denne usle mat.
6 Nígbà náà ni Olúwa rán ejò olóró sí àárín wọn; wọ́n gé àwọn ènìyàn jẹ, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Israẹli sì kú.
Da sendte Herren seraf-slanger inn iblandt folket, og de bet folket; og der døde meget folk av Israel.
7 Àwọn ènìyàn sì wá sí ọ̀dọ̀ Mose wọn wí pé, “A ti dá ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí asọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa àti sí ìwọ pẹ̀lú. Gba àdúrà pé kí Olúwa mú ejò náà kúrò lọ́dọ̀ wa.” Nígbà náà ni Mose gbàdúrà fún àwọn ènìyàn.
Så kom folket til Moses og sa: Vi har syndet, fordi vi har talt mot Herren og mot dig; bed til Herren at han vil ta slangene fra oss! Og Moses bad for folket.
8 Olúwa sọ fún Mose pé, “Rọ ejò, a ó sì gbé e kọ́ sókè lórí igi, ẹni tí ejò bá ti gé jẹ lè wò ó yóò sì yè.”
Da sa Herren til Moses: Gjør dig en seraf-slange og sett den på en stang, så skal hver den som er bitt og ser på den, få leve.
9 Nígbà náà ni Mose sì rọ ejò onírin ó sì gbé e kọ́ sórí igi, bí ejò bá sì bu ẹnikẹ́ni jẹ bí ó bá ti wò ó yóò sì yè.
Så gjorde Moses en kobberslange og satte den på en stang; og når en slange hadde bitt nogen, og han så på kobberslangen, blev han i live.
10 Àwọn ọmọ Israẹli tẹ̀síwájú wọ́n sì péjọ sí Obotu.
Siden brøt Israels barn op og leiret sig i Obot.
11 Wọ́n gbéra ní Obotu wọ́n sì pa ibùdó sí Iye-Abarimu, ní aginjù tí ó kọjú sí Moabu ní ìdojúkọ ìlà-oòrùn.
Så brøt de op fra Obot og leiret sig ved Ije-Ha'abarim i ørkenen rett i øst for Moab.
12 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gbéra wọ́n sì pa ibùdó ní àfonífojì Seredi.
Derfra brøt de op og leiret sig i Sered-dalen.
13 Láti ibẹ̀ lọ, wọn ṣí, wọ́n sì dó sí ìhà kejì Arnoni, tí ó wà ní aginjù tí ó wà ní agbègbè ilẹ̀ àwọn ọmọ Amori. Arnoni jẹ́ ààlà fún ilẹ̀ Moabu, láàrín Moabu àti Amori.
Derfra brøt de op og leiret sig på hin side Arnon, som går gjennem ørkenen og kommer fra amorittenes land; for Arnon er grensen mellem Moab og amorittene.
14 Ìdí nìyìí tí ìwé ogun Olúwa se wí pé, “…Wahebu ní Sufa, Òkun Pupa àti ní odò Arnoni
Derfor sies det i boken om Herrens kriger: Vaheb tok de med storm og bekkene, Arnons bekker,
15 àti ní ìṣàn odò tí ó darí sí ibùjókòó Ari tí ó sì fi ara ti ìpínlẹ̀ Moabu.”
og bekkelien som strekker sig bort til Ar-bygden og støter til Moabs grense.
16 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ rìn dé Beeri, èyí ni kànga tí Olúwa sọ fún Mose, “Kó àwọn ènìyàn jọ èmi ó sì fún wọn ní omi.”
Derfra brøt de op til Be'er; det er den brønn som Herren talte om da han sa til Moses: Kall folket sammen, så vil jeg gi dem vann.
17 Nígbà náà ni Israẹli kọ orin yìí pé, “Sun jáde, ìwọ kànga! Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,
Da sang Israel denne sang: Vell op, du brønn! Hils den med sang!
18 nípa kànga tí àwọn ọmọ-aládé gbẹ́, nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ ẹ; tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fi ọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.” Nígbà náà wọ́n kúrò láti aginjù lọ sí Mattana,
Du brønn som høvdinger har gravd, som folkets ypperste har boret med herskerstav, med sine kongespir! Fra ørkenen brøt de op til Matana
19 láti Mattana lọ sí Nahalieli, láti Nahalieli lọ sí Bamoti,
og fra Matana til Nahaliel og fra Nahaliel til Bamot
20 àti láti Bamoti lọ sí àfonífojì ní Moabu níbi tí òkè Pisga, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí aginjù.
og fra Bamot til den dal som ligger i Moab-marken, tett ved toppen av Pisga, og hvor en skuer ut over ørkenen.
21 Israẹli rán oníṣẹ́ láti sọ fún Sihoni ọba àwọn ará Amori wí pé,
Så sendte Israel bud til Sihon, amorittenes konge, og lot si:
22 “Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀-èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà àjàrà àbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”
La mig få dra gjennem ditt land! Vi skal ikke komme inn på akrene eller i vingårdene, heller ikke drikke vann av nogen brønn; efter kongeveien vil vi dra, til vi er kommet gjennem ditt land.
23 Ṣùgbọ́n Sihoni kò ní jẹ́ kí àwọn Israẹli kọjá ní ilẹ̀ wọn. Ó pe àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì wọ́de ogun lọ sí aginjù nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Nígbà tí ó dé Jahasi, ó bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
Men Sihon gav ikke Israel lov til å dra gjennem sitt land. Han samlet alt sitt folk og drog ut i ørkenen mot Israel, og han kom til Jahas og stred mot Israel.
24 Àmọ́, Israẹli ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Arnoni lọ dé Jabbok, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.
Men Israel slo ham med sverdets egg og tok hans land fra Arnon til Jabbok, til Ammons barns land; for Ammons barns grense var befestet.
25 Israẹli sì gba gbogbo ìlú Amori wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Heṣboni, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.
Og Israel tok alle disse byer; og Israel bosatte sig i alle amorittenes byer, i Hesbon og alle byer som hørte under det.
26 Heṣboni ni ìlú Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ó bá ọba Moabu ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Arnoni.
For Hesbon var Sihons, amoritter-kongens, stad; han hadde ført krig mot Moabs forrige konge og tatt alt hans land fra ham like til Arnon.
27 Ìdí nìyìí tí akọrin sọ wí pé, “Wá sí Heṣboni kí ẹ jẹ́ kí a tún un kọ́; jẹ́ kí ìlú Sihoni padà bọ̀ sípò.
Derfor sier skalden: Kom til Hesbon! Bygges og grunnfestes skal Sihons stad;
28 “Iná jáde láti Heṣboni, ọ̀wọ́-iná láti Sihoni. Ó jó Ari àti Moabu run, àti ìlú àwọn olùgbé ibi gíga Arnoni.
for ild fór ut fra Hesbon, en lue fra Sihons stad; den fortærte Ar i Moab, dem som bodde på høidene ved Arnon.
29 Ègbé ní fún ọ, ìwọ Moabu! Ẹ ti parun, ẹ̀yin ènìyàn Kemoṣi! Ó ti fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá àti ọmọ rẹ̀ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìgbèkùn fún Sihoni ọba àwọn Amori.
Ve dig, Moab! Fortapt er du, Kamos' folk! Han har sendt sine sønner som flyktninger og sine døtre som fanger til amorittenes konge Sihon.
30 “Ṣùgbọ́n àti bì wọ́n ṣubú; a ti pa ìjẹgàba Heṣboni run, a pa wọ́n run títí dé Diboni. A sì ti bì wọ́n lulẹ̀ títí dé Nofa, tí ó sì fi dé Medeba.”
Og vi skjøt dem ned; ødelagt er Hesbon, like til Dibon! vi herjet til Nofah, med ild helt til Medba.
31 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli sì ń gbé ní ilẹ̀ Amori.
Så blev Israel boende i amorittenes land.
32 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose rán ayọ́lẹ̀wò lọ sí Jaseri, àwọn ọmọ Israẹli sì gba àwọn agbègbè tó yí wọn ká wọ́n sì lé àwọn Amori tó wà níbẹ̀ jáde.
Og Moses sendte folk for å utspeide Jaser, og de tok de byer som hørte under det; og han drev ut amorittene som bodde der.
33 Nígbà náà wọ́n pẹ̀yìndà wọ́n sì gòkè lọ sí Baṣani, Ogu ọba ti Baṣani àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wọ́de ogun jáde láti pàdé wọn ní ojú ogun ní Edrei.
Så vendte de sig til en annen kant og drog opover til Basan; men Og, kongen i Basan, drog ut mot dem til Edre'i med alt sitt folk for å stride mot dem.
34 Olúwa sọ fún Mose pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀, kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
Da sa Herren til Moses: Frykt ikke for ham! For jeg har gitt ham og alt hans folk og hans land i din hånd, og du skal gjøre med ham som du gjorde med Sihon, amorittenes konge, som bodde i Hesbon.
35 Wọ́n sì pa á, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọn kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè. Wọ́n sì gba ìní ilẹ̀ rẹ̀.
Så slo de ham og hans sønner og alt hans folk, så ingen blev tilbake eller slapp unda; og de tok hans land i eie.

< Numbers 21 >