< Numbers 21 >
1 Nígbà tí ọba Aradi ará Kenaani, tí ń gbé ní gúúsù gbọ́ wí pé Israẹli ń bọ̀ wá ní ojú ọ̀nà Atarimu, ó bá Israẹli jà ó sì fi agbára mú díẹ̀ lára wọn.
Meghallotta a Kánaáni, Árod királya, aki délen lakott, hogy eljött Izrael a kémek útján, és harcolt Izrael ellen és foglyokat ejtett közüle.
2 Nígbà náà ni Israẹli jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí o bá lè fi àwọn ènìyàn yìí lé wa lọ́wọ́, gbogbo ìlú wọn ni a ó parun.”
Ekkor fogadalmat tett Izrael az Örökkévalónak és mondta: Ha kezembe adod ezt a népet, akkor átokként kiirtom az ő városaikat.
3 Olúwa gbọ́ ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fi àwọn ará Kenaani lé wọn lọ́wọ́. Wọ́n pa wọ́n run pátápátá; torí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ ní Horma.
Az Örökkévaló meghallgatta Izrael szavát és kezébe adta a Kánaánit és átokként kiirtotta azokat és városaikat és elnevezte a helyet Chormonak.
4 Wọ́n rin ìrìnàjò láti òkè Hori lọ sí ọ̀nà tó lọ sí Òkun Pupa, láti kọjá yípo Edomu. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn bínú ní ojú ọ̀nà;
És elvonultak Hór hegyétől a nádastenger felé, hogy megkerüljék Edom országát; és elcsüggedt a nép az úton.
5 wọ́n sì sọ̀rọ̀ lòdì sí Ọlọ́run àti Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti kí a ba le wá kú sí aginjù yìí? Kò sí oúnjẹ! Kò sì sí omi! Àwa sì kórìíra oúnjẹ tí kò dára yìí!”
És beszélt a nép Isten ellen és Mózes ellen. Miért hoztatok ide fel bennünket Egyiptomból, hogy meghaljunk a pusztában, mert nincs kenyér és nincs víz; lelkünk pedig undorodik a nyomorult kenyértől.
6 Nígbà náà ni Olúwa rán ejò olóró sí àárín wọn; wọ́n gé àwọn ènìyàn jẹ, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Israẹli sì kú.
Erre rábocsátotta az Örökkévaló a népre mérges kígyókat és megmarták a népet; és elhalt sok nép Izraelből.
7 Àwọn ènìyàn sì wá sí ọ̀dọ̀ Mose wọn wí pé, “A ti dá ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí asọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa àti sí ìwọ pẹ̀lú. Gba àdúrà pé kí Olúwa mú ejò náà kúrò lọ́dọ̀ wa.” Nígbà náà ni Mose gbàdúrà fún àwọn ènìyàn.
És eljött a nép Mózeshez, és mondták: Vétkeztünk, mert beszéltünk az Örökkévaló ellen és ellened, imádkozz az Örökkévalóhoz, hogy távolítsa el tőlünk a kígyókat. És Mózes imádkozott a népért.
8 Olúwa sọ fún Mose pé, “Rọ ejò, a ó sì gbé e kọ́ sókè lórí igi, ẹni tí ejò bá ti gé jẹ lè wò ó yóò sì yè.”
És mondta az Örökkévaló Mózesnek: Készíts magadnak egy kígyót és tedd azt póznára; és lesz minden megmart, ha arra néz, életben marad.
9 Nígbà náà ni Mose sì rọ ejò onírin ó sì gbé e kọ́ sórí igi, bí ejò bá sì bu ẹnikẹ́ni jẹ bí ó bá ti wò ó yóò sì yè.
Mózes készített egy rézkígyót és rátette a póznára; és volt, ha megmart a kígyó valakit és az tekintett a rézkígyóra, akkor életben maradt.
10 Àwọn ọmọ Israẹli tẹ̀síwájú wọ́n sì péjọ sí Obotu.
És elvonultak Izrael fiai és táboroztak Óvószban.
11 Wọ́n gbéra ní Obotu wọ́n sì pa ibùdó sí Iye-Abarimu, ní aginjù tí ó kọjú sí Moabu ní ìdojúkọ ìlà-oòrùn.
Elvonultak Óvószból és táboroztak Ijjé-haávorimban a pusztában, mely Móáb előtt van napkelet felől.
12 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gbéra wọ́n sì pa ibùdó ní àfonífojì Seredi.
Onnan elvonultak és táboroztak Zered völgyében.
13 Láti ibẹ̀ lọ, wọn ṣí, wọ́n sì dó sí ìhà kejì Arnoni, tí ó wà ní aginjù tí ó wà ní agbègbè ilẹ̀ àwọn ọmọ Amori. Arnoni jẹ́ ààlà fún ilẹ̀ Moabu, láàrín Moabu àti Amori.
Onnan elvonultak és táboroztak az Árnónon túl, mely a pusztában van, mely jön az Emóri határából; mert az Árnon Móáb határa, Móáb és az Emóri között.
14 Ìdí nìyìí tí ìwé ogun Olúwa se wí pé, “…Wahebu ní Sufa, Òkun Pupa àti ní odò Arnoni
Azért mondják az Örökkévaló harcainak könyvében: Váhebet Szúfoban és a patakokat, az Árnónt;
15 àti ní ìṣàn odò tí ó darí sí ibùjókòó Ari tí ó sì fi ara ti ìpínlẹ̀ Moabu.”
és a patakok lejtőjét, amely hajlik Or helye felé és támaszkodik Móáb határára.
16 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ rìn dé Beeri, èyí ni kànga tí Olúwa sọ fún Mose, “Kó àwọn ènìyàn jọ èmi ó sì fún wọn ní omi.”
Onnan a Kúthoz; ez a kút, melynél az Örökkévaló mondta Mózesnek: Gyűjtsd egybe a népet, hadd adjak nekik vizet.
17 Nígbà náà ni Israẹli kọ orin yìí pé, “Sun jáde, ìwọ kànga! Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,
Akkor énekelte Izrael ezt az éneket: Buzogj föl kút, énekeljetek neki!
18 nípa kànga tí àwọn ọmọ-aládé gbẹ́, nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ ẹ; tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fi ọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.” Nígbà náà wọ́n kúrò láti aginjù lọ sí Mattana,
A kút, melyet fejedelmek ástak, a nép nemesei vájtak törvényhozó pálcájukkal! A pusztából (vonultak) Máttonoba;
19 láti Mattana lọ sí Nahalieli, láti Nahalieli lọ sí Bamoti,
Máttonóból Nácháliélbe, Nácháliélből Bómószra;
20 àti láti Bamoti lọ sí àfonífojì ní Moabu níbi tí òkè Pisga, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí aginjù.
Bomószról a völgybe, mely Móáb mezején van, a Piszga csúcsánál és a sivatag felé tekint.
21 Israẹli rán oníṣẹ́ láti sọ fún Sihoni ọba àwọn ará Amori wí pé,
És Izrael követeket küldött Szichónhoz, Emóri királyához, mondván:
22 “Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀-èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà àjàrà àbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”
Hadd vonuljak át országodon, nem térünk le a mezőre és szőlőbe, nem iszunk a kút vizéből, az országúton fogunk menni, amíg átvonulunk határodon.
23 Ṣùgbọ́n Sihoni kò ní jẹ́ kí àwọn Israẹli kọjá ní ilẹ̀ wọn. Ó pe àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì wọ́de ogun lọ sí aginjù nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Nígbà tí ó dé Jahasi, ó bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
De Szichón nem engedte Izraelnek, hogy átvonuljon a határán; összegyűjtötte Szichón az ő egész népét és kiment Izrael ellen a pusztába, elérkezett Jóhcóig és harcolt Izrael ellen.
24 Àmọ́, Israẹli ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Arnoni lọ dé Jabbok, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.
De Izrael megverte őt a kard élével, és elfoglalta az országát az Árnóntól Jábbókig, Ámmón fiáig, mert erős volt Ámmón fiainak határa.
25 Israẹli sì gba gbogbo ìlú Amori wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Heṣboni, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.
És elvette Izrael mindezeket a városokat és lakott Izrael az Emóri minden városaiban, Chesbonban és mind a leányvárosaiban.
26 Heṣboni ni ìlú Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ó bá ọba Moabu ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Arnoni.
Mert Chesbón Szichónnak, Emóri királyának városa volt, ő harcolt Móáb első királya ellen és elvette az egész országát annak kezéből az Árnónig.
27 Ìdí nìyìí tí akọrin sọ wí pé, “Wá sí Heṣboni kí ẹ jẹ́ kí a tún un kọ́; jẹ́ kí ìlú Sihoni padà bọ̀ sípò.
Azért mondják a költők: Menjetek Chesbónba, építtessék föl és szilárdittassék meg Szichón városa.
28 “Iná jáde láti Heṣboni, ọ̀wọ́-iná láti Sihoni. Ó jó Ari àti Moabu run, àti ìlú àwọn olùgbé ibi gíga Arnoni.
Mert tűz ment ki Chesbónból, láng Szichón városából, megemésztette Ór-Móábot, az Árnón magaslatainak urait.
29 Ègbé ní fún ọ, ìwọ Moabu! Ẹ ti parun, ẹ̀yin ènìyàn Kemoṣi! Ó ti fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá àti ọmọ rẹ̀ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìgbèkùn fún Sihoni ọba àwọn Amori.
Jaj neked, Móáb! Elvesztél Kemós népe! Odaengedte fiait menekülőknek, leányait fogságba Szichón, Emóri királyához.
30 “Ṣùgbọ́n àti bì wọ́n ṣubú; a ti pa ìjẹgàba Heṣboni run, a pa wọ́n run títí dé Diboni. A sì ti bì wọ́n lulẹ̀ títí dé Nofa, tí ó sì fi dé Medeba.”
Leterítettük őket, elveszett Chesbón Divónig, elpusztítottuk azokat Nófáchig, mely Médvóig terjed.
31 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli sì ń gbé ní ilẹ̀ Amori.
És Izrael lakott az Emóri országában.
32 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose rán ayọ́lẹ̀wò lọ sí Jaseri, àwọn ọmọ Israẹli sì gba àwọn agbègbè tó yí wọn ká wọ́n sì lé àwọn Amori tó wà níbẹ̀ jáde.
És elküldött Mózes, hogy kikémleljék Jázért, elfoglalták leányvárosaikat és elűzte az Emórit, aki ott volt.
33 Nígbà náà wọ́n pẹ̀yìndà wọ́n sì gòkè lọ sí Baṣani, Ogu ọba ti Baṣani àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wọ́de ogun jáde láti pàdé wọn ní ojú ogun ní Edrei.
Azután megfordultak és fölmentek Boson útján; Óg, Boson királya pedig kiment ellenük, ő és egész népe harcra, Edreibe.
34 Olúwa sọ fún Mose pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀, kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
És mondta az Örökkévaló Mózesnek: Ne félj tőle, mert kezedbe adom őt és egész népét, meg országát; tegyél vele úgy, amint tettél Szichónnal, Emóri királyával, aki Chesbónban lakott.
35 Wọ́n sì pa á, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọn kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè. Wọ́n sì gba ìní ilẹ̀ rẹ̀.
És megverték őt, meg fiait és egész népét, hogy nem hagytak neki maradékot; országát pedig elfoglalták.