< Numbers 21 >

1 Nígbà tí ọba Aradi ará Kenaani, tí ń gbé ní gúúsù gbọ́ wí pé Israẹli ń bọ̀ wá ní ojú ọ̀nà Atarimu, ó bá Israẹli jà ó sì fi agbára mú díẹ̀ lára wọn.
And whanne Chananei, the kyng of Arad, that dwellide at the south, hadde herd this, that is, that Israel cam bi the weye of aspieris, he fauyt ayens hem; and Chananei was ouercomere and ledde pray of Israel.
2 Nígbà náà ni Israẹli jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí o bá lè fi àwọn ènìyàn yìí lé wa lọ́wọ́, gbogbo ìlú wọn ni a ó parun.”
And Israel bounde hym sylf bi avow to the Lord, and seide, If thou schalt bitake this puple in myn hond, Y schal do awei `the citees therof.
3 Olúwa gbọ́ ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fi àwọn ará Kenaani lé wọn lọ́wọ́. Wọ́n pa wọ́n run pátápátá; torí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ ní Horma.
And the Lord herde the preieris of Israel, and bitook the Chananey; and Israel killid hym, and distruyede hise citees; and clepide the name of that place Horma, that is, cursyng, `ethir hangyng up.
4 Wọ́n rin ìrìnàjò láti òkè Hori lọ sí ọ̀nà tó lọ sí Òkun Pupa, láti kọjá yípo Edomu. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn bínú ní ojú ọ̀nà;
`Forsothe thei yeden forth also fro the hil of Hor, bi the weie that ledith to the reed see, that thei schulden cumpasse the lond of Edom; and it bigan to anoye the puple, of the weie and trauel.
5 wọ́n sì sọ̀rọ̀ lòdì sí Ọlọ́run àti Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti kí a ba le wá kú sí aginjù yìí? Kò sí oúnjẹ! Kò sì sí omi! Àwa sì kórìíra oúnjẹ tí kò dára yìí!”
And the puple spak ayens the Lord and Moises, and seide, Whi leddist thou vs out of Egipt, that we schulden die in wildirnesse? breed failith, watris ben not; oure soule wlatith now on this `meete moost liyt.
6 Nígbà náà ni Olúwa rán ejò olóró sí àárín wọn; wọ́n gé àwọn ènìyàn jẹ, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Israẹli sì kú.
Wherfor the Lord sente `firid serpentis in to the puple; at the woundis of whiche serpentis, and the dethis of ful many men,
7 Àwọn ènìyàn sì wá sí ọ̀dọ̀ Mose wọn wí pé, “A ti dá ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí asọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa àti sí ìwọ pẹ̀lú. Gba àdúrà pé kí Olúwa mú ejò náà kúrò lọ́dọ̀ wa.” Nígbà náà ni Mose gbàdúrà fún àwọn ènìyàn.
thei camen to Moyses, and seiden, We synneden, for we spaken ayens the Lord and thee; preie thou, that he take awey fro vs the serpentis.
8 Olúwa sọ fún Mose pé, “Rọ ejò, a ó sì gbé e kọ́ sókè lórí igi, ẹni tí ejò bá ti gé jẹ lè wò ó yóò sì yè.”
And Moises preiede for the puple; and the Lord seide to hym, Make thou a serpent of bras, and sette thou it for a signe; he that is smytun and biholdith it, schal lyue.
9 Nígbà náà ni Mose sì rọ ejò onírin ó sì gbé e kọ́ sórí igi, bí ejò bá sì bu ẹnikẹ́ni jẹ bí ó bá ti wò ó yóò sì yè.
Therfor Moyses made a serpent of bras, and settide for a signe; and men smytun and biholdynge it, weren heelid.
10 Àwọn ọmọ Israẹli tẹ̀síwájú wọ́n sì péjọ sí Obotu.
And the sones of Israel yeden forth,
11 Wọ́n gbéra ní Obotu wọ́n sì pa ibùdó sí Iye-Abarimu, ní aginjù tí ó kọjú sí Moabu ní ìdojúkọ ìlà-oòrùn.
and settiden tentis in Oboth; fro whennus thei yeden forth, and settiden tentis in Neabarym, in the wildirnesse, that biholdith Moab, ayens the eest coost.
12 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gbéra wọ́n sì pa ibùdó ní àfonífojì Seredi.
And thei moueden fro thennus, and camen to the stronde of Zareth;
13 Láti ibẹ̀ lọ, wọn ṣí, wọ́n sì dó sí ìhà kejì Arnoni, tí ó wà ní aginjù tí ó wà ní agbègbè ilẹ̀ àwọn ọmọ Amori. Arnoni jẹ́ ààlà fún ilẹ̀ Moabu, láàrín Moabu àti Amori.
which thei leften, and settiden tentis ayens Arnon, which is in the deseert, and apperith in the coostis of Amorrei. Forsothe Arnon is the terme of Moab, and departith Moabitis and Ammoreis.
14 Ìdí nìyìí tí ìwé ogun Olúwa se wí pé, “…Wahebu ní Sufa, Òkun Pupa àti ní odò Arnoni
Wherfor it is seid in the book of batels of the Lord, As he dide in the reed see, so he schal do in the strondis of Arnon;
15 àti ní ìṣàn odò tí ó darí sí ibùjókòó Ari tí ó sì fi ara ti ìpínlẹ̀ Moabu.”
the harde rochis of the strondis weren bowid, that tho schulen reste in Arnon, and schulden ligge in the coostis of Moabitis.
16 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ rìn dé Beeri, èyí ni kànga tí Olúwa sọ fún Mose, “Kó àwọn ènìyàn jọ èmi ó sì fún wọn ní omi.”
Fro that place the pit apperide, of which the Lord spak to Moyses, Gadere thou the puple, and Y schal yyue watir to it.
17 Nígbà náà ni Israẹli kọ orin yìí pé, “Sun jáde, ìwọ kànga! Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,
Thanne Israel soong this song, The pit stie;
18 nípa kànga tí àwọn ọmọ-aládé gbẹ́, nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ ẹ; tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fi ọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.” Nígbà náà wọ́n kúrò láti aginjù lọ sí Mattana,
thei sungen togidere, The pit which the princes diggiden, and the duykis of the multitude maden redi, in the yyuere of the lawe, and in her stauys. And thei yeden forth fro the wildirnesse to Mathana,
19 láti Mattana lọ sí Nahalieli, láti Nahalieli lọ sí Bamoti,
fro Mathana to Naaliel, fro Naaliel in to Bamoth;
20 àti láti Bamoti lọ sí àfonífojì ní Moabu níbi tí òkè Pisga, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí aginjù.
Bamoth is a valey in the cuntrey of Moab, in the cop of Phasga, that biholdith ayens the deseert.
21 Israẹli rán oníṣẹ́ láti sọ fún Sihoni ọba àwọn ará Amori wí pé,
Forsothe Israel sente messangeris to Seon, kyng of Ammorreis, and seide,
22 “Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀-èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà àjàrà àbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”
Y biseche that it be leueful to me to passe thorou thi loond; we schulen not bowe in to the feeldis and vyneris; we schulen not drynke watris of pittis; we schulen go in the kyngis weie, til we passen thi termes.
23 Ṣùgbọ́n Sihoni kò ní jẹ́ kí àwọn Israẹli kọjá ní ilẹ̀ wọn. Ó pe àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì wọ́de ogun lọ sí aginjù nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Nígbà tí ó dé Jahasi, ó bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
Which nolde graunte that Israel schulde passe thury hise coostis, but rather, whanne the oost was gaderid, he yede out ayens Israel, in to deseert. And he cam in to Yasa, and fauyt ayens Israel;
24 Àmọ́, Israẹli ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Arnoni lọ dé Jabbok, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.
of whom he was smytun in the scharpnesse of swerd, and his lond was weldid fro Arnon `til to Jeboth and `the sones of Amon; for the termes of Amonytis weren holdun bi strong help.
25 Israẹli sì gba gbogbo ìlú Amori wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Heṣboni, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.
Therfor Israel took alle `the citees of hym, and dwelliden in the citees of Amorrei, that is, in Esebon, and hise townes.
26 Heṣboni ni ìlú Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ó bá ọba Moabu ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Arnoni.
The citee of Esebon was Seons, kyng of Ammorei, which Seon fauyt ayens the kyng of Moab, and took al the lond that was of his lordschip, `til to Arnon.
27 Ìdí nìyìí tí akọrin sọ wí pé, “Wá sí Heṣboni kí ẹ jẹ́ kí a tún un kọ́; jẹ́ kí ìlú Sihoni padà bọ̀ sípò.
Therfor it is seid in prouerbe, Come ye in to Esebon, be it bildid, and maad the citee of Seon;
28 “Iná jáde láti Heṣboni, ọ̀wọ́-iná láti Sihoni. Ó jó Ari àti Moabu run, àti ìlú àwọn olùgbé ibi gíga Arnoni.
fier yede out of Esebon, flawme yede out of the citee `ethir greet castel of Seon, and deuouryde Ar of Moabitis, and the dwelleris of the `hiye places of Arnon.
29 Ègbé ní fún ọ, ìwọ Moabu! Ẹ ti parun, ẹ̀yin ènìyàn Kemoṣi! Ó ti fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá àti ọmọ rẹ̀ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìgbèkùn fún Sihoni ọba àwọn Amori.
Moab, wo to thee! thou, puple of Chamos, perischidist; it yaf the sones therof in to fliyt, and the douytris in to caitifte to Seon, kyng of Ammoreis;
30 “Ṣùgbọ́n àti bì wọ́n ṣubú; a ti pa ìjẹgàba Heṣboni run, a pa wọ́n run títí dé Diboni. A sì ti bì wọ́n lulẹ̀ títí dé Nofa, tí ó sì fi dé Medeba.”
the yok of hem perischide, fro Esebon `til to Dibon; the wery men camen in to Jophe, and `til to Medaba.
31 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli sì ń gbé ní ilẹ̀ Amori.
And so Israel dwellide in the lond of Ammorrey.
32 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose rán ayọ́lẹ̀wò lọ sí Jaseri, àwọn ọmọ Israẹli sì gba àwọn agbègbè tó yí wọn ká wọ́n sì lé àwọn Amori tó wà níbẹ̀ jáde.
And Moises sente men that schulden aspie Jaser, whos `townes thei token, and weldiden the dwelleris.
33 Nígbà náà wọ́n pẹ̀yìndà wọ́n sì gòkè lọ sí Baṣani, Ogu ọba ti Baṣani àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wọ́de ogun jáde láti pàdé wọn ní ojú ogun ní Edrei.
And thei turniden hem silf, and stieden bi the weie of Basan. And Og, the kyng of Basan, with al his puple cam ayens hem, to fiyte in Edray.
34 Olúwa sọ fún Mose pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀, kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
And the Lord seide to Moises, Drede thou not hym, for Y haue bitake hym, and al his loond, and puple, in thin hoond; and thou schalt do to hym as thou didist to Seon, kyng of Ammorreis, the dwellere of Esebon.
35 Wọ́n sì pa á, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọn kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè. Wọ́n sì gba ìní ilẹ̀ rẹ̀.
Therfor thei smytiden `bothe hym with hise sones and al his puple, `til to deeth; and thei weldiden `the lond of hym.

< Numbers 21 >