< Numbers 21 >

1 Nígbà tí ọba Aradi ará Kenaani, tí ń gbé ní gúúsù gbọ́ wí pé Israẹli ń bọ̀ wá ní ojú ọ̀nà Atarimu, ó bá Israẹli jà ó sì fi agbára mú díẹ̀ lára wọn.
А арадският цар, ханаанецът, който живееше към юг, като чу, че Израил иде през пътя Атарим воюва против Израиля, и хвана от тях пленници.
2 Nígbà náà ni Israẹli jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí o bá lè fi àwọn ènìyàn yìí lé wa lọ́wọ́, gbogbo ìlú wọn ni a ó parun.”
И Израил направи обрек Господу, като каза: Ако наистина предадеш тия люде в ръката ми, то съвсем ще разоря градовете им.
3 Olúwa gbọ́ ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fi àwọn ará Kenaani lé wọn lọ́wọ́. Wọ́n pa wọ́n run pátápátá; torí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ ní Horma.
И Господ послуша гласа на Израиля и му предаде ханаанците; и те ги погубиха и разориха градовете им. И мястото се нарече Хорма.
4 Wọ́n rin ìrìnàjò láti òkè Hori lọ sí ọ̀nà tó lọ sí Òkun Pupa, láti kọjá yípo Edomu. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn bínú ní ojú ọ̀nà;
А когато отпътуваха от планината Ор, по пътя към Червеното море, за да обиколят Едомската земя, людете излязоха от търпение в душата си поради пътя.
5 wọ́n sì sọ̀rọ̀ lòdì sí Ọlọ́run àti Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti kí a ba le wá kú sí aginjù yìí? Kò sí oúnjẹ! Kò sì sí omi! Àwa sì kórìíra oúnjẹ tí kò dára yìí!”
И людете говориха против Бога и против Моисея, казвайки: Защо ни изведохте из Египет да измрем в пустинята? защото няма ни хляб ни вода, и душата ни се отвращава от тоя никакъв хляб.
6 Nígbà náà ni Olúwa rán ejò olóró sí àárín wọn; wọ́n gé àwọn ènìyàn jẹ, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Israẹli sì kú.
За това Господ изпрати между людете горителни змии, които хапеха людете, та измряха много люде от Израиля.
7 Àwọn ènìyàn sì wá sí ọ̀dọ̀ Mose wọn wí pé, “A ti dá ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí asọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa àti sí ìwọ pẹ̀lú. Gba àdúrà pé kí Olúwa mú ejò náà kúrò lọ́dọ̀ wa.” Nígbà náà ni Mose gbàdúrà fún àwọn ènìyàn.
Тогава людете дойдоха при Моисея и казаха: Съгрешихме за гдето говорихме против Господа и против тебе; помоли се Господу да махне змиите от нас. И Моисей се помоли за людете.
8 Olúwa sọ fún Mose pé, “Rọ ejò, a ó sì gbé e kọ́ sókè lórí igi, ẹni tí ejò bá ti gé jẹ lè wò ó yóò sì yè.”
И Господ рече на Моисея: Направи си една горителна змия, и тури я на висока върлина; и всеки ухапан, като погледне на нея, ще остане жив.
9 Nígbà náà ni Mose sì rọ ejò onírin ó sì gbé e kọ́ sórí igi, bí ejò bá sì bu ẹnikẹ́ni jẹ bí ó bá ti wò ó yóò sì yè.
И тъй, Моисей направи медна змия и я тури на най-високата върлина; и когато змия ухапеше някого, той, като погледнеше на медната змия, оставаше жив.
10 Àwọn ọmọ Israẹli tẹ̀síwájú wọ́n sì péjọ sí Obotu.
Тогава израилтяните отпътуваха и разположиха стан в Овот.
11 Wọ́n gbéra ní Obotu wọ́n sì pa ibùdó sí Iye-Abarimu, ní aginjù tí ó kọjú sí Moabu ní ìdojúkọ ìlà-oòrùn.
И като отпътуваха от Овот, разположиха стан в Е-Аварим, в пустинята, която е към Моав, към изгрева на слънцето.
12 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gbéra wọ́n sì pa ibùdó ní àfonífojì Seredi.
От там отпътуваха и разположиха стан в долината Заред.
13 Láti ibẹ̀ lọ, wọn ṣí, wọ́n sì dó sí ìhà kejì Arnoni, tí ó wà ní aginjù tí ó wà ní agbègbè ilẹ̀ àwọn ọmọ Amori. Arnoni jẹ́ ààlà fún ilẹ̀ Moabu, láàrín Moabu àti Amori.
От там отпътуваха и разположиха стан оттатък реката Арнон, която е в пустинята и изтича от пределите на аморейците; защото Арнон е моавска граница между моавците и аморейците.
14 Ìdí nìyìí tí ìwé ogun Olúwa se wí pé, “…Wahebu ní Sufa, Òkun Pupa àti ní odò Arnoni
За това е казано в книгата на Господните войни: - Ваев в Суфа И потоците на Арнон,
15 àti ní ìṣàn odò tí ó darí sí ibùjókòó Ari tí ó sì fi ara ti ìpínlẹ̀ Moabu.”
И течението на потоците, Което се простира до селището Ар И допира границата на Моав.
16 Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ rìn dé Beeri, èyí ni kànga tí Olúwa sọ fún Mose, “Kó àwọn ènìyàn jọ èmi ó sì fún wọn ní omi.”
А от там дойдоха при Вир. Тоя е кладенецът, за който Господ рече на Моисея: Събери людете, и ще им дам вода.
17 Nígbà náà ni Israẹli kọ orin yìí pé, “Sun jáde, ìwọ kànga! Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,
Тогава Израил изпя тая песен: - Бликай, о кладенче; пейте за него;
18 nípa kànga tí àwọn ọmọ-aládé gbẹ́, nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ ẹ; tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fi ọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.” Nígbà náà wọ́n kúrò láti aginjù lọ sí Mattana,
Кладенец изкопаха първенците, Благородните от людете изкопаха, Чрез заповедта на законодателя; с жезлите си. А от пустинята отидоха в Матана,
19 láti Mattana lọ sí Nahalieli, láti Nahalieli lọ sí Bamoti,
и от Матана в Наалиил, и от Наалиил във Вамот,
20 àti láti Bamoti lọ sí àfonífojì ní Moabu níbi tí òkè Pisga, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí aginjù.
а от Вамот в долината, която е в моавското поле, при върха на Фасга, която гледа към Есимон.
21 Israẹli rán oníṣẹ́ láti sọ fún Sihoni ọba àwọn ará Amori wí pé,
Тогава Израил изпрати посланици при аморейския цар Сион да кажат:
22 “Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀-èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà àjàrà àbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”
Остави ме да замина през земята ти; няма да свръщаме ни по нивите ни по лозята; не ще да пием вода от кладенците; през царевия друм ще вървим, докато преминем твоите предели.
23 Ṣùgbọ́n Sihoni kò ní jẹ́ kí àwọn Israẹli kọjá ní ilẹ̀ wọn. Ó pe àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì wọ́de ogun lọ sí aginjù nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Nígbà tí ó dé Jahasi, ó bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
А Сион не пусна Израиля да мина през пределите му; но Сион събра всичките си люде, излезе та се опълчи срещу Израиля в пустинята, и дойде в Яса та воюва против Израиля.
24 Àmọ́, Israẹli ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Arnoni lọ dé Jabbok, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.
Но Израил го порази с острото на ножа, и завладя земята му от Арнон до Явок, до амонците; защото границата на амонците беше крепка.
25 Israẹli sì gba gbogbo ìlú Amori wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Heṣboni, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.
Израил завладя всички тия градове; и Израил се засели във всичките градове на аморейците, в Есевон и във всичките му села.
26 Heṣboni ni ìlú Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ó bá ọba Moabu ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Arnoni.
Понеже Есевон бе град на аморейския цар Сион, който беше воювал с предишния моавски цар и беше отнел от ръката му всичката му земя до Арнон.
27 Ìdí nìyìí tí akọrin sọ wí pé, “Wá sí Heṣboni kí ẹ jẹ́ kí a tún un kọ́; jẹ́ kí ìlú Sihoni padà bọ̀ sípò.
За това, ония, които говорят с притчи, казват: - Дойдете в Есевон; Да се съгради и да се закрепи града Сионов;
28 “Iná jáde láti Heṣboni, ọ̀wọ́-iná láti Sihoni. Ó jó Ari àti Moabu run, àti ìlú àwọn olùgbé ibi gíga Arnoni.
Защото огън излезе от Есевон, Пламък из града Сионов; Пояде Ар моавски, И първенците на високите места на Арнон.
29 Ègbé ní fún ọ, ìwọ Moabu! Ẹ ti parun, ẹ̀yin ènìyàn Kemoṣi! Ó ti fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá àti ọmọ rẹ̀ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìgbèkùn fún Sihoni ọba àwọn Amori.
Горко ти Моаве! Погина ти, Хамосови люде! Даде синовете си на бяг И дъщерите си на плен При Сиона аморейския цар.
30 “Ṣùgbọ́n àti bì wọ́n ṣubú; a ti pa ìjẹgàba Heṣboni run, a pa wọ́n run títí dé Diboni. A sì ti bì wọ́n lulẹ̀ títí dé Nofa, tí ó sì fi dé Medeba.”
Ние го застреляхме Есевон погина до Девон; И запустихме ги до Нофа, Която се простира до Медева.
31 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli sì ń gbé ní ilẹ̀ Amori.
Така Израил се засели в земята на Аморейците.
32 Lẹ́yìn ìgbà tí Mose rán ayọ́lẹ̀wò lọ sí Jaseri, àwọn ọmọ Israẹli sì gba àwọn agbègbè tó yí wọn ká wọ́n sì lé àwọn Amori tó wà níbẹ̀ jáde.
После Моисей изпрати човеци да съгледат Язир; и, като превзеха селата му, изпъдиха аморейците, които бяха в тях.
33 Nígbà náà wọ́n pẹ̀yìndà wọ́n sì gòkè lọ sí Baṣani, Ogu ọba ti Baṣani àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wọ́de ogun jáde láti pàdé wọn ní ojú ogun ní Edrei.
Тогава се върнаха и отидоха по пътя към Васан; а васанският цар Ог излезе против тях, той и всичките му люде, на бой в Едраи.
34 Olúwa sọ fún Mose pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀, kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
Но Господ рече на Моисея: Не бой се от Него, защото Аз ще предам в ръцете ви него, всичките му люде и земята му; ще му направиш така, както направи на аморейския цар Сион, който живееше в Есевон.
35 Wọ́n sì pa á, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọn kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè. Wọ́n sì gba ìní ilẹ̀ rẹ̀.
И тъй, поразиха него, синовете му и всичките му люде, догдето не му остана ни един оцелял; и завладяха земята му.

< Numbers 21 >