< Numbers 20 >

1 Ní oṣù kìn-ín-ní, gbogbo àgbájọ ọmọ Israẹli gúnlẹ̀ sí pápá Sini, wọ́n sì dúró ní Kadeṣi. Níbẹ̀ ni Miriamu kú, wọ́n sì sin ín.
Atunci au ajuns copiii lui Israel, adică întreaga adunare, în deșertul Țin, în prima lună, și poporul a locuit în Cades; și acolo a murit Miriam și acolo a fost îngropată.
2 Omi kò sí fún ìjọ ènìyàn, àwọn ènìyàn sì kó ara wọn jọ pọ̀ sí Mose àti Aaroni,
Și acolo nu era apă pentru adunare și s-au adunat împotriva lui Moise și împotriva lui Aaron.
3 wọ́n bá Mose jà wọ́n sì wí pé, “Ìbá kúkú sàn kí a kú nígbà tí àwọn arákùnrin ti kú níwájú Olúwa!
Și poporul s-a certat cu Moise și a vorbit, spunând: De am fi murit când frații noștri au murit înaintea DOMNULUI!
4 Kí ni ó dé tí o sì kó gbogbo ìjọ ènìyàn Olúwa wá sí aginjù yìí, kí àwa àti àwọn ẹran ọ̀sìn wa bá à kú síbí?
Și de ce ați adus adunarea DOMNULUI în acest pustiu, ca noi și vitele noastre să murim aici?
5 Kí ni ó dé tí o fi mú wa gòkè kúrò ní Ejibiti wá sí ibi búburú yìí? Ibi tí kò ní oúnjẹ tàbí igi ọ̀pọ̀tọ́, èso àjàrà tàbí pomegiranate. Bẹ́ẹ̀ ni kò sí omi tí a ó mu níhìn-ín!”
Și de ce ne-ați scos din Egipt pentru a ne aduce în acest loc rău? Nu este loc pentru sămânță sau pentru smochine sau pentru viță sau pentru rodii; nici nu este deloc apă pentru băut.
6 Mose àti Aaroni kúrò ní ibi àpéjọ, wọ́n sì lọ dojúbolẹ̀ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahàn wọ́n.
Și Moise și Aaron au plecat din prezența adunării la ușa tabernacolului întâlnirii și au căzut cu fețele lor la pământ; și gloria DOMNULUI li s-a arătat.
7 Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
8 “Mú ọ̀pá, náà kí o sì pe ìjọ àwọn ènìyàn jọ, ìwọ àti Aaroni arákùnrin rẹ, kí ẹ sọ̀rọ̀ sí àpáta náà ní ojú wọn, yóò sì tú omi rẹ̀ jáde, ìwọ ó sì fún ìjọ àti ẹran wọn mu.”
Ia toiagul și strânge adunarea la un loc, tu și Aaron fratele tău și vorbiți stâncii înaintea ochilor lor; și ea va da apa ei, iar tu să le aduci apă din stâncă, astfel să dai adunării și vitelor lor să bea.
9 Báyìí ni Mose mú ọ̀pá láti iwájú Olúwa wá, gẹ́gẹ́ bí ó ti pàṣẹ fún un.
Și Moise a luat toiagul de dinaintea DOMNULUI, precum i-a poruncit.
10 Òun àti Aaroni pe àwọn ènìyàn jọ sí ojú kan níwájú àpáta, Mose sì sọ fún wọn, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀, àwa kì yóò lè mú omi jáde láti inú àpáta yìí wá bí?”
Și Moise și Aaron au strâns adunarea la un loc înaintea stâncii și el le-a spus: Ascultați acum, răzvrătiților; trebuie să vă aducem apă din această stâncă?
11 Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ó sì fi ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ lu àpáta lẹ́ẹ̀méjì. Omi sì tú jáde, gbogbo ìjọ ènìyàn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sì mu.
Și Moise și-a ridicat mâna și cu toiagul său a lovit stânca de două ori și apa a ieșit afară din abundență, și adunarea a băut și vitele lor la fel.
12 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Nítorí pé ẹ̀yin kò gbà mí gbọ́ tó láti bu ọlá fún mi níwájú àwọn ọmọ Israẹli, ìwọ kò ní kó àwọn ìjọ ènìyàn yìí dé ilẹ̀ tí mo fún wọn.”
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise și lui Aaron: Deoarece nu m-ați crezut, pentru a mă sfinți în ochii copiilor lui Israel, de aceea nu veți duce această adunare în țara pe care le-am dat-o.
13 Èyí ni omi ti Meriba, níbi tí àwọn ọmọ Israẹli ti bá Olúwa jà àti ibi tí O ti fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni mímọ́ láàrín wọn.
Acestea sunt apele Meriba, pentru că copiii lui Israel s-au certat cu DOMNUL și el a fost sfințit în ei.
14 Mose sì ránṣẹ́ láti Kadeṣi sí ọba Edomu, wí pé, “Èyí ni nǹkan tí arákùnrin rẹ Israẹli sọ, ìwọ ti mọ̀ nípa gbogbo ìnira, tí ó wá sí orí wa.
Și Moise a trimis mesageri de la Cades la împăratul din Edom: Astfel spune fratele tău Israel: Tu cunoști toată durerea căzută peste noi;
15 Àwọn baba ńlá wa sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti, a sì gbé ibẹ̀ fún ọ̀pọ̀ ọdún. Àwọn ará Ejibiti ni wá lára àti àwọn baba wa,
Cum părinții noștri au coborât în Egipt și am locuit în Egipt o lungă perioadă de timp; și egiptenii ne-au chinuit pe noi și pe părinții noștri;
16 ṣùgbọ́n nígbà tí a sọkún sí Olúwa, ó gbọ́ ẹkún wa, ó sì rán angẹli kan sí wa, ó sì mú wa jáde láti Ejibiti. “Báyìí àwa wà ní Kadeṣi, ìlú tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ.
Și când am strigat către DOMNUL, el a ascultat vocea noastră și a trimis un înger și ne-a scos afară din Egipt; și, iată, noi suntem în Cades, o cetate la marginea graniței tale;
17 Jọ̀wọ́ jẹ́ kí a gba orílẹ̀-èdè rẹ kọjá, àwa kì yóò gba inú oko tàbí ọgbà àjàrà rẹ kọjá, tàbí mu omi láti inú kànga. A ó ma kọjá ní òpópónà ọba, àwa kì yóò yà sí ọ̀tún tàbí sí òsì títí àwa yóò fi kọjá ní ilẹ̀ rẹ.”
Lasă-ne să trecem, te rog, prin țara ta, nu vom trece nici prin câmpuri, nici prin vii, nici nu vom bea din apa fântânilor, vom merge pe drumul mare al împăratului, nu ne vom abate nici la dreapta nici la stânga, până ce vom fi trecut de granițele tale.
18 Ṣùgbọ́n Edomu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò le gba ibí kọjá; bí ẹ bá dán an wò, a ó dìde ogun sí yín, a ó sì bá yín jà pẹ̀lú idà.”
Și Edom i-a spus: Să nu treci pe la mine ca nu cumva să ies împotriva ta cu sabia.
19 Àwọn ọmọ Israẹli dáhùn pé, “A ó gba ọ̀nà tóóró, bí àwa tàbí ẹran ọ̀sìn wa bá sì mú lára omi rẹ, a ó san owó rẹ̀. A kàn fẹ́ rìn kọjá lórí ilẹ̀ rẹ ni kò sí nǹkan kan mìíràn tí a fẹ́ ṣe.”
Și copiii lui Israel i-au spus: Vom merge pe drumul mare și dacă eu și vitele mele beau din apa ta, atunci voi plăti pentru ea; voi trece doar prin țară, cu piciorul, fără să fac niciun alt lucru.
20 Wọ́n tún dáhùn wí pé, “Ẹ kò lè kọjá.” Nígbà náà ni Edomu jáde wá láti kọjú ìjà sí wọn pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àti alágbára ọmọ-ogun.
Și el a spus: Să nu treci. Și Edom a ieșit împotriva lui cu mult popor și cu mână tare.
21 Nígbà tí Edomu sì kọ̀ jálẹ̀ láti jẹ́ kí wọn kọjá ní ilẹ̀ wọn, Israẹli yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Astfel Edom a refuzat să lase pe Israel să treacă prin granița sa, pentru aceasta Israel s-a abătut de la el.
22 Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì jáde láti Kadeṣi wọ́n sì wá sí orí òkè Hori.
Și copiii lui Israel și întreaga adunare, au călătorit de la Cades și au ajuns la muntele Hor.
23 Ní orí òkè Hori, ní ẹ̀gbẹ́ ààlà Edomu Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise și Aaron, în muntele Hor, la granița țării lui Edom, spunând:
24 “Aaroni yóò kú. Kò ní wọ ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn ọmọ Israẹli, nítorí ẹ̀yin méjèèjì ṣe àìgbọ́ràn sí òfin mi níbi omi Meriba.
Aaron va fi adunat la poporul său, pentru că nu va intra în țara pe care eu am dat-o copiilor lui Israel, pentru că v-ați răzvrătit împotriva cuvântului meu la apele Meriba.
25 Mú Aaroni àti ọmọ rẹ̀ Eleasari lọ sí orí òkè Hori.
Ia pe Aaron și pe Eleazar, fiul său, și urcă-i la muntele Hor;
26 Bọ́ aṣọ Aaroni kí o sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, nítorí pé Aaroni yóò kú síbẹ̀.”
Și dezbracă pe Aaron de veștmintele sale și îmbracă-l cu ele pe Eleazar fiul său; și Aaron va fi adunat la poporul său și va muri acolo.
27 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n lọ sí orí òkè Hori ní ojú gbogbo ìjọ ènìyàn.
Și Moise a făcut precum DOMNUL i-a poruncit, și ei au urcat pe muntele Hor înaintea ochilor întregii adunări.
28 Mose bọ́ aṣọ Aaroni ó sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, Aaroni sì kú sí orí òkè. Nígbà náà Mose àti Eleasari sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè,
Și Moise a dezbrăcat pe Aaron de veștmintele sale și l-a îmbrăcat pe Eleazar, fiul său, cu ele; și Aaron a murit acolo în vârful muntelui, iar Moise și Eleazar au coborât de pe munte.
29 nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbọ́ pé Aaroni ti kú, gbogbo ilé Israẹli ṣe ìdárò rẹ̀ fún ọgbọ̀n ọjọ́.
Și când toată adunarea a văzut că Aaron a murit, toată casa lui Israel a jelit pentru Aaron, treizeci de zile.

< Numbers 20 >