< Numbers 20 >
1 Ní oṣù kìn-ín-ní, gbogbo àgbájọ ọmọ Israẹli gúnlẹ̀ sí pápá Sini, wọ́n sì dúró ní Kadeṣi. Níbẹ̀ ni Miriamu kú, wọ́n sì sin ín.
I przyszło całe zgromadzenie synów Izraela na pustynię Syn w pierwszym miesiącu. I lud zamieszkał w Kadesz. Tam umarła Miriam i tam została pogrzebana.
2 Omi kò sí fún ìjọ ènìyàn, àwọn ènìyàn sì kó ara wọn jọ pọ̀ sí Mose àti Aaroni,
A gdy zabrakło wody dla ludu, zebrali się przeciw Mojżeszowi i Aaronowi.
3 wọ́n bá Mose jà wọ́n sì wí pé, “Ìbá kúkú sàn kí a kú nígbà tí àwọn arákùnrin ti kú níwájú Olúwa!
Lud spierał się z Mojżeszem, mówiąc: Obyśmy umarli, gdy nasi bracia umarli przed PANEM.
4 Kí ni ó dé tí o sì kó gbogbo ìjọ ènìyàn Olúwa wá sí aginjù yìí, kí àwa àti àwọn ẹran ọ̀sìn wa bá à kú síbí?
Dlaczego przyprowadziliście to zgromadzenie PANA na tę pustynię, abyśmy tu pomarli wraz z naszym bydłem?
5 Kí ni ó dé tí o fi mú wa gòkè kúrò ní Ejibiti wá sí ibi búburú yìí? Ibi tí kò ní oúnjẹ tàbí igi ọ̀pọ̀tọ́, èso àjàrà tàbí pomegiranate. Bẹ́ẹ̀ ni kò sí omi tí a ó mu níhìn-ín!”
Po co wyprowadziliście nas z Egiptu, aby nas wprowadzić na to złe miejsce; na miejsce, w którym nie ma ani zboża, ani fig, ani winogron, ani jabłek granatu, nie ma nawet wody do picia?
6 Mose àti Aaroni kúrò ní ibi àpéjọ, wọ́n sì lọ dojúbolẹ̀ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahàn wọ́n.
Wtedy Mojżesz i Aaron przeszli sprzed ludu przed wejście do Namiotu Zgromadzenia i upadli na twarze. A chwała PANA ukazała się im.
I PAN powiedział do Mojżesza:
8 “Mú ọ̀pá, náà kí o sì pe ìjọ àwọn ènìyàn jọ, ìwọ àti Aaroni arákùnrin rẹ, kí ẹ sọ̀rọ̀ sí àpáta náà ní ojú wọn, yóò sì tú omi rẹ̀ jáde, ìwọ ó sì fún ìjọ àti ẹran wọn mu.”
Weź laskę, zgromadźcie [cały] lud, ty i twój brat Aaron, i przemówcie na ich oczach do tej skały, a ona wyda z siebie wodę; wydobędziesz dla nich wodę ze skały i dasz pić całemu zgromadzeniu oraz ich zwierzętom.
9 Báyìí ni Mose mú ọ̀pá láti iwájú Olúwa wá, gẹ́gẹ́ bí ó ti pàṣẹ fún un.
Wziął więc Mojżesz laskę sprzed oblicza PANA, tak jak mu rozkazał.
10 Òun àti Aaroni pe àwọn ènìyàn jọ sí ojú kan níwájú àpáta, Mose sì sọ fún wọn, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀, àwa kì yóò lè mú omi jáde láti inú àpáta yìí wá bí?”
I Mojżesz z Aaronem zgromadzili [cały] lud przed skałą, i [Mojżesz] mówił do nich: Słuchajcie teraz, buntownicy! Czy z tej skały mamy wyprowadzić dla was wodę?
11 Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ó sì fi ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ lu àpáta lẹ́ẹ̀méjì. Omi sì tú jáde, gbogbo ìjọ ènìyàn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sì mu.
Następnie Mojżesz podniósł rękę i uderzył swoją laską dwa razy w skałę. Wtedy wypłynęła obficie woda i napiło się zgromadzenie oraz jego bydło.
12 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Nítorí pé ẹ̀yin kò gbà mí gbọ́ tó láti bu ọlá fún mi níwájú àwọn ọmọ Israẹli, ìwọ kò ní kó àwọn ìjọ ènìyàn yìí dé ilẹ̀ tí mo fún wọn.”
I PAN powiedział do Mojżesza i Aarona: Ponieważ nie uwierzyliście mi, by mnie uświęcić na oczach synów Izraela, dlatego nie wprowadzicie tego zgromadzenia do ziemi, którą im daję.
13 Èyí ni omi ti Meriba, níbi tí àwọn ọmọ Israẹli ti bá Olúwa jà àti ibi tí O ti fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni mímọ́ láàrín wọn.
To są wody Meriba, gdzie synowie Izraela spierali się z PANEM i został uświęcony w nich.
14 Mose sì ránṣẹ́ láti Kadeṣi sí ọba Edomu, wí pé, “Èyí ni nǹkan tí arákùnrin rẹ Israẹli sọ, ìwọ ti mọ̀ nípa gbogbo ìnira, tí ó wá sí orí wa.
Potem Mojżesz wysłał z Kadesz posłańców do króla Edomu, [mówiąc]: Tak mówi twój brat Izrael: Ty znasz całą udrękę, która nas spotkała;
15 Àwọn baba ńlá wa sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti, a sì gbé ibẹ̀ fún ọ̀pọ̀ ọdún. Àwọn ará Ejibiti ni wá lára àti àwọn baba wa,
Jak nasi ojcowie zstąpili do Egiptu i mieszkaliśmy w Egipcie wiele lat; i Egipcjanie dręczyli nas i naszych ojców;
16 ṣùgbọ́n nígbà tí a sọkún sí Olúwa, ó gbọ́ ẹkún wa, ó sì rán angẹli kan sí wa, ó sì mú wa jáde láti Ejibiti. “Báyìí àwa wà ní Kadeṣi, ìlú tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ.
I wołaliśmy do PANA, a wysłuchał naszego głosu i posłał Anioła, i wyprowadził nas z Egiptu. [Teraz] jesteśmy w Kadesz, w mieście przy twojej granicy.
17 Jọ̀wọ́ jẹ́ kí a gba orílẹ̀-èdè rẹ kọjá, àwa kì yóò gba inú oko tàbí ọgbà àjàrà rẹ kọjá, tàbí mu omi láti inú kànga. A ó ma kọjá ní òpópónà ọba, àwa kì yóò yà sí ọ̀tún tàbí sí òsì títí àwa yóò fi kọjá ní ilẹ̀ rẹ.”
Pozwól nam, proszę, przejść przez twoją ziemię; nie pójdziemy przez pola ani przez winnice i nie będziemy pić wód ze studni. Pójdziemy drogą królewską, nie zboczymy ani w prawo, ani w lewo, dopóki nie przejdziemy twoich granic.
18 Ṣùgbọ́n Edomu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò le gba ibí kọjá; bí ẹ bá dán an wò, a ó dìde ogun sí yín, a ó sì bá yín jà pẹ̀lú idà.”
Edom odpowiedział mu: Nie przejdziesz przez moją ziemię, bo inaczej wyjdę przeciwko tobie z mieczem.
19 Àwọn ọmọ Israẹli dáhùn pé, “A ó gba ọ̀nà tóóró, bí àwa tàbí ẹran ọ̀sìn wa bá sì mú lára omi rẹ, a ó san owó rẹ̀. A kàn fẹ́ rìn kọjá lórí ilẹ̀ rẹ ni kò sí nǹkan kan mìíràn tí a fẹ́ ṣe.”
I synowie Izraela powiedzieli mu: Pójdziemy główną drogą, a jeśli będziemy pili twoją wodę, my i nasze zwierzęta, zapłacimy za to. Niczego innego [nie żądamy]; tylko przejdziemy pieszo.
20 Wọ́n tún dáhùn wí pé, “Ẹ kò lè kọjá.” Nígbà náà ni Edomu jáde wá láti kọjú ìjà sí wọn pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àti alágbára ọmọ-ogun.
A on odpowiedział: Nie przejdziesz. I Edom wyruszył naprzeciwko nim z licznym ludem i mocną ręką.
21 Nígbà tí Edomu sì kọ̀ jálẹ̀ láti jẹ́ kí wọn kọjá ní ilẹ̀ wọn, Israẹli yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Tak Edom nie pozwolił Izraelowi przejść przez swoje granice. Izrael więc odstąpił od niego.
22 Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì jáde láti Kadeṣi wọ́n sì wá sí orí òkè Hori.
I synowie Izraela, całe zgromadzenie, wyruszyli z Kadesz i przyszli do góry Hor.
23 Ní orí òkè Hori, ní ẹ̀gbẹ́ ààlà Edomu Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
I PAN powiedział do Mojżesza i Aarona na górze Hor, na granicy ziemi Edomu:
24 “Aaroni yóò kú. Kò ní wọ ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn ọmọ Israẹli, nítorí ẹ̀yin méjèèjì ṣe àìgbọ́ràn sí òfin mi níbi omi Meriba.
Aaron zostanie przyłączony do swego ludu; nie wejdzie bowiem do ziemi, którą dałem synom Izraela, ponieważ sprzeciwiliście się mojemu słowu przy wodach Meriba.
25 Mú Aaroni àti ọmọ rẹ̀ Eleasari lọ sí orí òkè Hori.
Weź Aarona i jego syna Eleazara i przyprowadź ich na górę Hor;
26 Bọ́ aṣọ Aaroni kí o sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, nítorí pé Aaroni yóò kú síbẹ̀.”
I zdejmij z Aarona jego szaty, a ubierz w nie jego syna Eleazara. Aaron zaś zostanie przyłączony [do swego ludu] i tam umrze.
27 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n lọ sí orí òkè Hori ní ojú gbogbo ìjọ ènìyàn.
I Mojżesz uczynił tak, jak PAN rozkazał; i wstąpili na górę Hor na oczach całego zgromadzenia.
28 Mose bọ́ aṣọ Aaroni ó sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, Aaroni sì kú sí orí òkè. Nígbà náà Mose àti Eleasari sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè,
Mojżesz zdjął z Aarona jego szaty i ubrał w nie jego syna Eleazara. Aaron umarł tam na wierzchu góry, a Mojżesz i Eleazar zeszli z góry.
29 nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbọ́ pé Aaroni ti kú, gbogbo ilé Israẹli ṣe ìdárò rẹ̀ fún ọgbọ̀n ọjọ́.
Gdy całe zgromadzenie zobaczyło, że Aaron nie żyje, opłakiwał Aarona cały dom Izraela przez trzydzieści dni.