< Numbers 20 >
1 Ní oṣù kìn-ín-ní, gbogbo àgbájọ ọmọ Israẹli gúnlẹ̀ sí pápá Sini, wọ́n sì dúró ní Kadeṣi. Níbẹ̀ ni Miriamu kú, wọ́n sì sin ín.
The children of Israel [God prevails], even the whole congregation, came into the wilderness of Zin in the first month Nissan ·Miracles (in Aramaic), 1·. The people stayed in Kadesh. Miriam [Rebellion] died there, and was buried there.
2 Omi kò sí fún ìjọ ènìyàn, àwọn ènìyàn sì kó ara wọn jọ pọ̀ sí Mose àti Aaroni,
There was no water for the congregation; and they assembled themselves together against Moses [Drawn out] and against Aaron [Light-bringer].
3 wọ́n bá Mose jà wọ́n sì wí pé, “Ìbá kúkú sàn kí a kú nígbà tí àwọn arákùnrin ti kú níwájú Olúwa!
The people quarreled with Moses [Drawn out], and spoke, saying, “We wish that we had died when our brothers died before Adonai!
4 Kí ni ó dé tí o sì kó gbogbo ìjọ ènìyàn Olúwa wá sí aginjù yìí, kí àwa àti àwọn ẹran ọ̀sìn wa bá à kú síbí?
Why have you brought Adonai’s assembly into this wilderness, that we should die there, we and our animals?
5 Kí ni ó dé tí o fi mú wa gòkè kúrò ní Ejibiti wá sí ibi búburú yìí? Ibi tí kò ní oúnjẹ tàbí igi ọ̀pọ̀tọ́, èso àjàrà tàbí pomegiranate. Bẹ́ẹ̀ ni kò sí omi tí a ó mu níhìn-ín!”
Why have you made us to come up out of Egypt [Abode of slavery], to bring us in to this evil place? It is no place of seed, or of figs, or of vines, or of pomegranates; neither is there any water to drink.”
6 Mose àti Aaroni kúrò ní ibi àpéjọ, wọ́n sì lọ dojúbolẹ̀ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahàn wọ́n.
Moses [Drawn out] and Aaron [Light-bringer] went from the presence of the assembly to the door of the Tent of Meeting, and fell on their faces. The kavod Yahweh ·weighty glory of He sustains breathing· appeared to them.
Adonai spoke to Moses [Drawn out], saying,
8 “Mú ọ̀pá, náà kí o sì pe ìjọ àwọn ènìyàn jọ, ìwọ àti Aaroni arákùnrin rẹ, kí ẹ sọ̀rọ̀ sí àpáta náà ní ojú wọn, yóò sì tú omi rẹ̀ jáde, ìwọ ó sì fún ìjọ àti ẹran wọn mu.”
“Take the rod, and assemble the congregation, you, and Aaron [Light-bringer] your brother, and speak to the rock before their eyes, that it pour out its water. You shall bring water to them out of the rock; so you shall give the congregation and their livestock drink.”
9 Báyìí ni Mose mú ọ̀pá láti iwájú Olúwa wá, gẹ́gẹ́ bí ó ti pàṣẹ fún un.
Moses [Drawn out] took the rod from before Adonai, as he enjoined him.
10 Òun àti Aaroni pe àwọn ènìyàn jọ sí ojú kan níwájú àpáta, Mose sì sọ fún wọn, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀, àwa kì yóò lè mú omi jáde láti inú àpáta yìí wá bí?”
Moses [Drawn out] and Aaron [Light-bringer] gathered the assembly together before the rock, and he said to them, “Sh'ma ·Hear obey· now, you rebels! Shall we bring water out of this rock for you?”
11 Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ó sì fi ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ lu àpáta lẹ́ẹ̀méjì. Omi sì tú jáde, gbogbo ìjọ ènìyàn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sì mu.
Moses [Drawn out] lifted up his hand, and struck the rock with his rod twice, and water came out abundantly. The congregation and their livestock drank.
12 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Nítorí pé ẹ̀yin kò gbà mí gbọ́ tó láti bu ọlá fún mi níwájú àwọn ọmọ Israẹli, ìwọ kò ní kó àwọn ìjọ ènìyàn yìí dé ilẹ̀ tí mo fún wọn.”
Adonai said to Moses [Drawn out] and Aaron [Light-bringer], “Because you didn’t trust in me, to sanctify me in the eyes of the children of Israel [God prevails], therefore you shall not bring this assembly into the land which I have given them.”
13 Èyí ni omi ti Meriba, níbi tí àwọn ọmọ Israẹli ti bá Olúwa jà àti ibi tí O ti fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni mímọ́ láàrín wọn.
These are the waters of Meribah [Quarreling]; because the children of Israel [God prevails] strove with Yahweh M’Kaddesh [Yahweh our Santifier / He sustains breathing who makes you holy] who was set apart by them.
14 Mose sì ránṣẹ́ láti Kadeṣi sí ọba Edomu, wí pé, “Èyí ni nǹkan tí arákùnrin rẹ Israẹli sọ, ìwọ ti mọ̀ nípa gbogbo ìnira, tí ó wá sí orí wa.
Moses [Drawn out] sent messengers from Kadesh to the king of Edom [Red], saying: “Thus says your brother Israel [God prevails]: You know all the travail that has happened to us;
15 Àwọn baba ńlá wa sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti, a sì gbé ibẹ̀ fún ọ̀pọ̀ ọdún. Àwọn ará Ejibiti ni wá lára àti àwọn baba wa,
how our fathers went down into Egypt [Abode of slavery], and we lived in Egypt [Abode of slavery] a long time. The Egyptians [people from Abode of slavery] mistreated us and our fathers.
16 ṣùgbọ́n nígbà tí a sọkún sí Olúwa, ó gbọ́ ẹkún wa, ó sì rán angẹli kan sí wa, ó sì mú wa jáde láti Ejibiti. “Báyìí àwa wà ní Kadeṣi, ìlú tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ.
When we cried to Adonai, he sh'ma ·heard obeyed· our voice, sent an angel, and brought us out of Egypt [Abode of slavery]. Behold, we are in Kadesh, a city in the edge of your border.
17 Jọ̀wọ́ jẹ́ kí a gba orílẹ̀-èdè rẹ kọjá, àwa kì yóò gba inú oko tàbí ọgbà àjàrà rẹ kọjá, tàbí mu omi láti inú kànga. A ó ma kọjá ní òpópónà ọba, àwa kì yóò yà sí ọ̀tún tàbí sí òsì títí àwa yóò fi kọjá ní ilẹ̀ rẹ.”
“Please let us pass through your land. We will not pass through field or through vineyard, neither will we drink from the water of the wells. We will go along the king’s highway. We will not turn aside to the right hand nor to the left, until we have passed your border.”
18 Ṣùgbọ́n Edomu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò le gba ibí kọjá; bí ẹ bá dán an wò, a ó dìde ogun sí yín, a ó sì bá yín jà pẹ̀lú idà.”
Edom [Red] said to him, “You shall not pass through me, lest I come out with the sword against you.”
19 Àwọn ọmọ Israẹli dáhùn pé, “A ó gba ọ̀nà tóóró, bí àwa tàbí ẹran ọ̀sìn wa bá sì mú lára omi rẹ, a ó san owó rẹ̀. A kàn fẹ́ rìn kọjá lórí ilẹ̀ rẹ ni kò sí nǹkan kan mìíràn tí a fẹ́ ṣe.”
The children of Israel [God prevails] said to him, “We will go up by the highway; and if we drink your water, I and my livestock, then I will give its price. Only let me, without doing anything else, pass through on my feet.”
20 Wọ́n tún dáhùn wí pé, “Ẹ kò lè kọjá.” Nígbà náà ni Edomu jáde wá láti kọjú ìjà sí wọn pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àti alágbára ọmọ-ogun.
He said, “You shall not pass through.” Edom [Red] came out against him with many people, and with a strong hand.
21 Nígbà tí Edomu sì kọ̀ jálẹ̀ láti jẹ́ kí wọn kọjá ní ilẹ̀ wọn, Israẹli yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Thus Edom [Red] refused to give Israel [God prevails] passage through his border, so Israel [God prevails] turned away from him.
22 Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì jáde láti Kadeṣi wọ́n sì wá sí orí òkè Hori.
They traveled from Kadesh: and the children of Israel [God prevails], even the whole congregation, came to Mount Hor.
23 Ní orí òkè Hori, ní ẹ̀gbẹ́ ààlà Edomu Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Adonai spoke to Moses [Drawn out] and Aaron [Light-bringer] in Mount Hor, by the border of the land of Edom [Red], saying,
24 “Aaroni yóò kú. Kò ní wọ ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn ọmọ Israẹli, nítorí ẹ̀yin méjèèjì ṣe àìgbọ́ràn sí òfin mi níbi omi Meriba.
“Aaron [Light-bringer] shall be gathered to his people; for he shall not enter into the land which I have given to the children of Israel [God prevails], because you rebelled against my word at the waters of Meribah [Quarreling].
25 Mú Aaroni àti ọmọ rẹ̀ Eleasari lọ sí orí òkè Hori.
Take Aaron [Light-bringer] and Eleazar [Help of God] his son, and bring them up to Mount Hor;
26 Bọ́ aṣọ Aaroni kí o sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, nítorí pé Aaroni yóò kú síbẹ̀.”
and strip Aaron [Light-bringer] of his garments, and put them on Eleazar [Help of God] his son. Aaron [Light-bringer] shall be taken, and shall die there.”
27 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n lọ sí orí òkè Hori ní ojú gbogbo ìjọ ènìyàn.
Moses [Drawn out] did as Adonai enjoined. They went up into Mount Hor in the sight of all the congregation.
28 Mose bọ́ aṣọ Aaroni ó sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, Aaroni sì kú sí orí òkè. Nígbà náà Mose àti Eleasari sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè,
Moses [Drawn out] stripped Aaron [Light-bringer] of his garments, and put them on Eleazar [Help of God] his son. Aaron [Light-bringer] died there on the top of the mountain, and Moses [Drawn out] and Eleazar [Help of God] came down from the mountain.
29 nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbọ́ pé Aaroni ti kú, gbogbo ilé Israẹli ṣe ìdárò rẹ̀ fún ọgbọ̀n ọjọ́.
When all the congregation saw that Aaron [Light-bringer] was dead, they wept for Aaron [Light-bringer] thirty days, even all the house of Israel [God prevails].