< Numbers 20 >

1 Ní oṣù kìn-ín-ní, gbogbo àgbájọ ọmọ Israẹli gúnlẹ̀ sí pápá Sini, wọ́n sì dúró ní Kadeṣi. Níbẹ̀ ni Miriamu kú, wọ́n sì sin ín.
Oubi age ganodini, Isala: ili fi dunu huluane da wadela: i hafoga: i soge amo Sini amoga doaga: le, Ga: idesie sogebi amoga fi dialu. Amogawi, Milia: me da bogole, ilia da ea da: i uli dogone sali.
2 Omi kò sí fún ìjọ ènìyàn, àwọn ènìyàn sì kó ara wọn jọ pọ̀ sí Mose àti Aaroni,
Ilia fisisu sogebi amoga hano hame dialebe ba: i. Amaiba: le, Isala: ili dunu da Mousese amola Elane elama gegedole,
3 wọ́n bá Mose jà wọ́n sì wí pé, “Ìbá kúkú sàn kí a kú nígbà tí àwọn arákùnrin ti kú níwájú Olúwa!
egane sia: i “Ninia da ninia fi Isala: ili dunu eno defele, Hina Gode Ea Abula Diasu midadi bogomu da defea galu.
4 Kí ni ó dé tí o sì kó gbogbo ìjọ ènìyàn Olúwa wá sí aginjù yìí, kí àwa àti àwọn ẹran ọ̀sìn wa bá à kú síbí?
Di da abuliba: le nini amo wadela: i hafoga: i sogega oule misibala: ? Dia da nini amola ninia ohe fi guiguda: bogoma: ne, goeguda: oule misibala: ?
5 Kí ni ó dé tí o fi mú wa gòkè kúrò ní Ejibiti wá sí ibi búburú yìí? Ibi tí kò ní oúnjẹ tàbí igi ọ̀pọ̀tọ́, èso àjàrà tàbí pomegiranate. Bẹ́ẹ̀ ni kò sí omi tí a ó mu níhìn-ín!”
Amo soge da wadela: idafa. Ha: i manu heda: mu da hamedei. Gagoma da hame - figi fage da hame - waini fage da hame - ‘bomegala: nede’ fage da hame. Hano amola da hame gala. Di abuliba: le nini Idibidi sogega fisili masa: ne, guiguda: oule misibala: ?”
6 Mose àti Aaroni kúrò ní ibi àpéjọ, wọ́n sì lọ dojúbolẹ̀ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahàn wọ́n.
Mousese amola Elane da Isala: ili dunu ilia gilisisu fisili, Abula Diasu ea holeiga lelu. Ela da beguduli osoboga mi bugila sa: i. Amalalu, Hina Gode Ea esalebe dawa: loma: ne sinenemegi hadigi da misini, ela da amo ba: i.
7 Olúwa sọ fún Mose pé,
Hina Gode da Mousesema amane sia: i,
8 “Mú ọ̀pá, náà kí o sì pe ìjọ àwọn ènìyàn jọ, ìwọ àti Aaroni arákùnrin rẹ, kí ẹ sọ̀rọ̀ sí àpáta náà ní ojú wọn, yóò sì tú omi rẹ̀ jáde, ìwọ ó sì fún ìjọ àti ẹran wọn mu.”
“Galiamo amo da Gode Ea Gousa: su Sema Gagili midadi diala, amo lale, di, Elane amo Isala: ili dunu gilisima: ne sia: ma. Amasea, ilia huluane ba: ma: ne, amo igi amoma sia: ma. Amasea, hano da amodili musa: gala: mu. Di da agoane hamosea, hano amo da gele musa: gala: le, dunu huluane amola ilia ohe da amo moma: ma.”
9 Báyìí ni Mose mú ọ̀pá láti iwájú Olúwa wá, gẹ́gẹ́ bí ó ti pàṣẹ fún un.
Mousese da Hina Gode Ea sia: i defele, asili, galiamo lai.
10 Òun àti Aaroni pe àwọn ènìyàn jọ sí ojú kan níwájú àpáta, Mose sì sọ fún wọn, “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀, àwa kì yóò lè mú omi jáde láti inú àpáta yìí wá bí?”
E amola Elane da Isala: ili fi dunu huluane amo gele midadi gilisi. Amola, Mousese da amane sia: i, “Dilia odoga: su dunu! Nabima! Ania da dili hano moma: ne amo gele fana: dula: ?”
11 Nígbà náà ni Mose gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ó sì fi ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀ lu àpáta lẹ́ẹ̀méjì. Omi sì tú jáde, gbogbo ìjọ ènìyàn àti àwọn ẹran ọ̀sìn wọn sì mu.
Amalalu, Mousese da galiamo gaguia gadole, gele adunawane fai dagoi. Hano musa: su bagade musa: gala: le amola dunu huluane amola ohe da hano amo maiba: le sadi.
12 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Nítorí pé ẹ̀yin kò gbà mí gbọ́ tó láti bu ọlá fún mi níwájú àwọn ọmọ Israẹli, ìwọ kò ní kó àwọn ìjọ ènìyàn yìí dé ilẹ̀ tí mo fún wọn.”
Be Hina Gode da Mousese amola Elane elama amane gagabuli sia: i, “Alia da Isala: ili dunu amo soge Na da ilima ima: ne ilegele sia: i amoga hame oule masunu. Bai alia dafawaneyale dawa: su hou da gasa hame amola alia da Na hadigi gasa hou amo Isala: ili dunu ba: ma: ne, hame olelei.”
13 Èyí ni omi ti Meriba, níbi tí àwọn ọmọ Israẹli ti bá Olúwa jà àti ibi tí O ti fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni mímọ́ láàrín wọn.
Amo hou da Meliba sogebi (dawa: loma: ne da ‘egasu’) amoga ba: i. Amogawi Isala: ili dunu da Hina Godema egai amola E da ilima Ea hadigi hou olelei.
14 Mose sì ránṣẹ́ láti Kadeṣi sí ọba Edomu, wí pé, “Èyí ni nǹkan tí arákùnrin rẹ Israẹli sọ, ìwọ ti mọ̀ nípa gbogbo ìnira, tí ó wá sí orí wa.
Mousese da Ga: idesie sogega sia: ne iasu dunu Idome hina bagade ema asunasi. Ilia da amane sia: i, “Amo sia: ne iasu da dia ‘fi dunu’, Isala: ili fi dunu amoga misi. Ninia se nabasu di dawa:
15 Àwọn baba ńlá wa sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti, a sì gbé ibẹ̀ fún ọ̀pọ̀ ọdún. Àwọn ará Ejibiti ni wá lára àti àwọn baba wa,
Ninia aowalali dunu da Idibidi sogega asili, amogawi ode bagohame esalu. Idibidi dunu da ninia aowalali amola nini se nabima: ne ninima hamosu.
16 ṣùgbọ́n nígbà tí a sọkún sí Olúwa, ó gbọ́ ẹkún wa, ó sì rán angẹli kan sí wa, ó sì mú wa jáde láti Ejibiti. “Báyìí àwa wà ní Kadeṣi, ìlú tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ.
Amola ninia da Hina Godema Ea nini fidima: ne dini wesu. E da ninia wei amo nabi. E da a: igele dunu asunasili, amo da nini Idibidi sogega fisili masa: ne gadili oule asi. Wali ninia da Ga: idesie sogebi dia soge alalo amoga esala.
17 Jọ̀wọ́ jẹ́ kí a gba orílẹ̀-èdè rẹ kọjá, àwa kì yóò gba inú oko tàbí ọgbà àjàrà rẹ kọjá, tàbí mu omi láti inú kànga. A ó ma kọjá ní òpópónà ọba, àwa kì yóò yà sí ọ̀tún tàbí sí òsì títí àwa yóò fi kọjá ní ilẹ̀ rẹ.”
Ninia da dia sogedili baligili masunu hanai galebe. Dia ninima logo doasima. Ninia amola ninia ohe da logoba: le fawane masunu. Ninia da dia ifabi amola waini sagai amo ganodini hame masunu amola dia hano nasu amoga hame manu. Ninia da logoba: le fawane, dia sogedili baligimu.”
18 Ṣùgbọ́n Edomu dáhùn pé, “Ẹ̀yin kò le gba ibí kọjá; bí ẹ bá dán an wò, a ó dìde ogun sí yín, a ó sì bá yín jà pẹ̀lú idà.”
Be Idome dunu da bu adole i, “Dilia da hamedafa ninia sogedili masunu. Dilia da amane hamosea, ninia da gadili mogodigili, dilima doagala: mu.”
19 Àwọn ọmọ Israẹli dáhùn pé, “A ó gba ọ̀nà tóóró, bí àwa tàbí ẹran ọ̀sìn wa bá sì mú lára omi rẹ, a ó san owó rẹ̀. A kàn fẹ́ rìn kọjá lórí ilẹ̀ rẹ ni kò sí nǹkan kan mìíràn tí a fẹ́ ṣe.”
Isala: ili dunu da amane sia: i, “Ninia da logo bagade amoga fawane masunu. Amola ninia o ninia ohe da dilia hano nasea, ninia da amo dabe dilima imunu. Ninia da logodili fodoma: ne fasimusa: fawane sia: sa.”
20 Wọ́n tún dáhùn wí pé, “Ẹ kò lè kọjá.” Nígbà náà ni Edomu jáde wá láti kọjú ìjà sí wọn pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àti alágbára ọmọ-ogun.
Be Idome dunu da bu adole i, “Hame mabu!” Amalalu, ilia da dadi gagui dunu bagohame gilisili, gadili mogodigili asili, Isala: ili dunu doagala: musa: asi.
21 Nígbà tí Edomu sì kọ̀ jálẹ̀ láti jẹ́ kí wọn kọjá ní ilẹ̀ wọn, Israẹli yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Idome dunu da Isala: ili dunu ilia sogega fadoma: ne masunu logo ga: iba: le, ilia da sinidigili, logo enoga asi.
22 Gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì jáde láti Kadeṣi wọ́n sì wá sí orí òkè Hori.
Isala: ili fi dunu huluane da Ga: idesie fisili, Ho Goumiga doaga: i.
23 Ní orí òkè Hori, ní ẹ̀gbẹ́ ààlà Edomu Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Ho Goumi da Idome soge alalo gadenene gala. Amogawi, Hina Gode da Mousese amola Elane elama amane sia: i,
24 “Aaroni yóò kú. Kò ní wọ ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn ọmọ Israẹli, nítorí ẹ̀yin méjèèjì ṣe àìgbọ́ràn sí òfin mi níbi omi Meriba.
“Elane da soge amo Na da Isala: ili fi ilima imunu ilegei, amoga e da amo soge ganodini hame masunu. E da bogomu. Bai alia da Meliba sogega Na sia: i amo lelei.
25 Mú Aaroni àti ọmọ rẹ̀ Eleasari lọ sí orí òkè Hori.
Elane amola egefe Elia: isa amo Ho Goumiba: le heda: ma: ne oule masa.
26 Bọ́ aṣọ Aaroni kí o sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, nítorí pé Aaroni yóò kú síbẹ̀.”
Amogawi, Elane ea gobele salasu abula gisa: le, Elia: isa ema gasisalasima.”
27 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n lọ sí orí òkè Hori ní ojú gbogbo ìjọ ènìyàn.
Mousese da Hina Gode Ea hamoma: ne sia: i defele hamoi dagoi. Ilia da Isala: ili dunu huluane ba: ma: ne, Ho Goumiba: le heda: i.
28 Mose bọ́ aṣọ Aaroni ó sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Eleasari, Aaroni sì kú sí orí òkè. Nígbà náà Mose àti Eleasari sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè,
Amogawi, Mousese da Elane ea gobele salasu abula gisa: le, bu Elia: isa ema gasisali. Amogawi, Ho Goumi da: iya dabuagado, Elane da bogoi dagoi. Amalalu, Mousese amola Elia: isa da bu gudu sa: i.
29 nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbọ́ pé Aaroni ti kú, gbogbo ilé Israẹli ṣe ìdárò rẹ̀ fún ọgbọ̀n ọjọ́.
Isala: ili dunu huluane da Elane ea bogoi nababeba: le, eso30amoga, e dawa: ha heawini didigia: lalu.

< Numbers 20 >