< Numbers 2 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
And the Lord spoke unto Moses and unto Aaron, saying,
2 “Kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn yí àgọ́ ìpàdé ká, kí wọ́n jẹ́ kí àgọ́ wọn jìnnà sí i díẹ̀, oníkálùkù lábẹ́ ọ̀págun pẹ̀lú àsíá ìdílé wọn.”
Every man by his own standard, by the ensign of their family division, shall the children of Israel pitch their tent; at some distance round about the tabernacle of the congregation shall they encamp.
3 Ní ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ àtiyọ oòrùn: ni kí ìpín ti Juda pa ibùdó wọn sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Juda ni Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
And they, who encamp on the east, toward the rising of the sun, shall be [those who belong to] the standard of the camp of Judah according to their armies: and the prince of the children of Judah shall be Nachshon the son of 'Amminadab.
4 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
And his host, and those that were numbered of them, were seventy and four thousand and six hundred.
5 Ẹ̀yà Isakari ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Isakari ni Netaneli ọmọ Suari.
And those that encamp next unto him shall be the tribe of Issachar: and the prince of the children of Issachar shall be Nethanel the son of Zuar.
6 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
And his host, and those that were numbered thereof, were fifty and four thousand and four hundred.
7 Ẹ̀yà Sebuluni ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Sebuluni ni Eliabu ọmọ Heloni.
[Then] the tribe of Zebulun: and the prince of the children of Zebulun shall be Eliab the son of Chelon.
8 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
And his host, and those that were numbered thereof, were fifty and seven thousand and four hundred.
9 Gbogbo àwọn tí a yàn sí ibùdó Juda, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàléláàdọ́rùn-ún ó lé irinwó. Àwọn ni yóò kọ́kọ́ ṣáájú.
All that were numbered of the camp of Judah were one hundred thousand and eighty thousand and six thousand and four hundred, according to their armies: they shall first set forward.
10 Ní ìhà gúúsù: ni ìpín ti Reubeni pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Reubeni ni Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
The standard of the camp of Reuben shall be on the south side, according to their armies: and the prince of the children of Reuben shall be Elizur the son of Shedeur.
11 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
And his host, and those that were numbered thereof, were forty and six thousand and five hundred.
12 Ẹ̀yà Simeoni ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Simoni ni Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
And those that encamp by him shall be the tribe of Simeon: and the prince of the children of Simeon shall be Shelumiel the son of 'Zurishaddai.
13 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbéje.
And his host, and those that were numbered of them, were fifty and nine thousand and three hundred.
14 Ẹ̀yà Gadi ló tẹ̀lé wọn. Olórí Gadi ni Eliasafu ọmọ Deueli.
Then the tribe of Gad: and the prince of the sons of Gad shall be Elyassaph the son of Reuel.
15 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
And his host, and those who were numbered of them, were forty and five thousand and six hundred and fifty.
16 Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Reubeni, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá márùndínlọ́gọ́rin ó lé àádọ́talélégbèje. Àwọn ni yóò jáde sìkéjì.
All that were numbered of the camp of Reuben were one hundred thousand and fifty and one thousand and four hundred and fifty, according to their armies; and as the second shall they set forward.
17 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi àti àgọ́ ìpàdé yóò tẹ̀síwájú láàrín ibùdó àwọn ènìyàn, wọn yóò tẹ̀síwájú ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe pa ibùdó, olúkúlùkù láààyè rẹ̀, àti lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀.
Then shall the tabernacle of the congregation, the camp of the Levites, set forward in the midst of the camps: as they encamp, so shall they set forward, every man in his place after their standards.
18 Ní ìhà ìlà-oòrùn: ni ìpín Efraimu yóò pa ibùdó rẹ̀ sí lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀. Olórí Efraimu ni Eliṣama ọmọ Ammihudu.
The standard of the camp of Ephraim shall be on the west side, according to their armies: and the prince of the sons of Ephraim shall be Elishama the son of 'Ammihud.
19 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì lé ó lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
And his host, and those that were numbered of them, were forty thousand and five hundred.
20 Ẹ̀yà Manase ni yóò tẹ̀lé wọn. Olórí Manase ni Gamalieli ọmọ Pedasuri.
And by him shall be the tribe of Menasseh; and the prince of the children of Menasseh shall be Gamliel the son of Pedahzur.
21 Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé igba.
And his host, and those that were numbered of them, were thirty and two thousand and two hundred.
22 Ẹ̀yà Benjamini ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Benjamini ni Abidani ọmọ Gideoni.
Then the tribe of Benjamin: and the prince of the sons of Benjamin shall be Abidan the son of Gidoni.
23 Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
And his host, and those that were numbered of them, were thirty and five thousand and four hundred.
24 Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Efraimu, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnléláàádọ́ta ó lé ọgọ́rùn-ún. Àwọn ni yóò jáde sìkẹ́ta.
All that were numbered of the camp of Ephraim were one hundred thousand and eight thousand and one hundred, according to their armies; and as the third shall they set forward.
25 Ní ìhà àríwá: ni ìpín Dani yóò pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Dani ni Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
The standard of the camp of Dan shall be on the north side, according to their armies: and the prince of the children of Dan shall be Achiezer the son of 'Ammishaddai.
26 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
And his host, and those that were numbered of them, were sixty and two thousand and seven hundred.
27 Ẹ̀yà Aṣeri ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Aṣeri ni Pagieli ọmọ Okanri.
And those that encamp by him shall be the tribe of Asher: and the prince of the children of Asher shall be Pagiel the son of 'Ochran.
28 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
And his host, and those that were numbered of them, were forty and one thousand and five hundred.
29 Ẹ̀yà Naftali ni yóò kàn lẹ́yìn wọn. Olórí Naftali ni Ahira ọmọ Enani.
Then the tribe of Naphtali: and the prince of the children of Naphtali shall be Achira the son of 'Enan.
30 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé egbèje.
And his host, and those that were numbered of them, were fifty and three thousand and four hundred.
31 Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Dani jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gọ̀rin ó lé ẹgbẹ̀jọ. Àwọn ni yóò jáde kẹ́yìn lábẹ́ ọ̀págun wọn.
All those that were numbered of the camp of Dan were one hundred thousand and fifty and seven thousand and six hundred; the hindmost shall they set forward according to their standards.
32 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n kà nípa ìdílé wọn. Gbogbo àwọn tó wà ní ibùdó, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, wọ́n jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
These are those that were numbered of the children of Israel according to their family divisions: and all those that were numbered of the camps, according to their armies, were six hundred thousand and three thousand and five hundred and fifty.
33 Ṣùgbọ́n a kò ka àwọn ọmọ Lefi papọ̀ mọ́ àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
But the Levites were not numbered among the children of Israel; as the Lord had commanded Moses.
34 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose, báyìí ni wọ́n ṣe pa ibùdó lábẹ́ ọ̀págun wọn, bẹ́ẹ̀ náà sì ni wọ́n ṣe jáde, oníkálùkù pẹ̀lú ẹbí àti ìdílé rẹ̀.
And the children of Israel did all just as the Lord had commanded Moses, so did they encamp by their standards, and so did they set forward every one after his family, by his division.

< Numbers 2 >