< Numbers 2 >
1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
And the Lord spake vnto Moses, and to Aaron, saying,
2 “Kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn yí àgọ́ ìpàdé ká, kí wọ́n jẹ́ kí àgọ́ wọn jìnnà sí i díẹ̀, oníkálùkù lábẹ́ ọ̀págun pẹ̀lú àsíá ìdílé wọn.”
Euery man of the children of Israel shall campe by his standerd, and vnder the ensigne of their fathers house: farre off about the Tabernacle of the Congregation shall they pitch.
3 Ní ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ àtiyọ oòrùn: ni kí ìpín ti Juda pa ibùdó wọn sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Juda ni Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
On the East side towarde the rising of the sunne, shall they of the standerd of the hoste of Iudah pitch according to their armies: and Nahshon the sonne of Amminadab shalbe captaine of the sonnes of Iudah.
4 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
And his hoste and the nomber of the were seuentie and foure thousande and sixe hundreth.
5 Ẹ̀yà Isakari ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Isakari ni Netaneli ọmọ Suari.
Next vnto him shall they of the tribe of Issachar pitch, and Nethaneel the sonne of Zuar shalbe the captaine of the sonnes of Issachar:
6 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
And his hoste, and the nomber thereof were foure and fiftie thousand, and foure hundreth.
7 Ẹ̀yà Sebuluni ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Sebuluni ni Eliabu ọmọ Heloni.
Then the tribe of Zebulun, and Eliab the sonne of Helon, captaine ouer the sonnes of Zebulun:
8 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
And his hoste, and the nomber thereof seuen and fiftie thousand and foure hundreth:
9 Gbogbo àwọn tí a yàn sí ibùdó Juda, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàléláàdọ́rùn-ún ó lé irinwó. Àwọn ni yóò kọ́kọ́ ṣáájú.
The whole nomber of the hoste of Iudah are an hundreth fourescore and sixe thousande, and foure hundreth according to their armies: they shall first set foorth.
10 Ní ìhà gúúsù: ni ìpín ti Reubeni pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Reubeni ni Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
On the South side shalbe ye standerd of the host of Reuben according to their armies, and the captaine ouer the sonnes of Reuben shalbe Elizur the sonne of Shedeur.
11 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
And his host, and the nomber thereof sixe and fourty thousand and fiue hundreth.
12 Ẹ̀yà Simeoni ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Simoni ni Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
And by him shall the tribe of Simeon pitch, and the captaiue ouer the sonnes of Simeon shall be Shelumiel the sonne of Zurishaddai:
13 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbéje.
And his hoste, and the nomber of them, nine and fiftie thousand and three hundreth.
14 Ẹ̀yà Gadi ló tẹ̀lé wọn. Olórí Gadi ni Eliasafu ọmọ Deueli.
And the tribe of Gad, and the captaine ouer the sonnes of Gad shall be Eliasaph the sonne of Deuel:
15 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
And his host and the nomber of the were fiue and fourtye thousande, sixe hundreth and fiftie.
16 Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Reubeni, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá márùndínlọ́gọ́rin ó lé àádọ́talélégbèje. Àwọn ni yóò jáde sìkéjì.
All the nomber of the campe of Reuben were an hundreth and one and fiftie thousande, and foure hundreth and fiftie according to their armies, and they shall set foorth in the seconde place.
17 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi àti àgọ́ ìpàdé yóò tẹ̀síwájú láàrín ibùdó àwọn ènìyàn, wọn yóò tẹ̀síwájú ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe pa ibùdó, olúkúlùkù láààyè rẹ̀, àti lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀.
Then the Tabernacle of the Congregation shall goe with the host of the Leuites, in the mids of the campe as they haue pitched, so shall they goe forwarde, euery man in his order according to their standerds.
18 Ní ìhà ìlà-oòrùn: ni ìpín Efraimu yóò pa ibùdó rẹ̀ sí lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀. Olórí Efraimu ni Eliṣama ọmọ Ammihudu.
The standerd of the campe of Ephraim shalbe toward the west according to their armies: and ye captaine ouer the sonnes of Ephraim shall be Elishama the sonne of Ammihud:
19 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì lé ó lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
And his host and the nomber of the were fortie thousand and fiue hundreth.
20 Ẹ̀yà Manase ni yóò tẹ̀lé wọn. Olórí Manase ni Gamalieli ọmọ Pedasuri.
And by him shalbe the tribe of Manasseh, and the captaine ouer the sonnes of Manasseh shalbe Gamliel the sonne of Pedahzur:
21 Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé igba.
And his hoste and the nomber of them were two and thirtie thousand and two hundreth.
22 Ẹ̀yà Benjamini ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Benjamini ni Abidani ọmọ Gideoni.
And the tribe of Beniamin, and ye captaine ouer the sonnes of Beniamin shalbe Abidan the sonne of Gideoni:
23 Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
And his host, and the nomber of the were fiue and thirtie thousand and foure hundreth.
24 Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Efraimu, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnléláàádọ́ta ó lé ọgọ́rùn-ún. Àwọn ni yóò jáde sìkẹ́ta.
All the nomber of the campe of Ephraim were an hundreth and eight thousande and one hundreth according to their armies, and they shall go in the third place.
25 Ní ìhà àríwá: ni ìpín Dani yóò pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Dani ni Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
The standerd of the host of Dan shalbe toward the North according to their armies: and the captaine ouer the children of Dan shall be Ahiezer the sonne of Ammishaddai:
26 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
And his host and the number of them were two and threescore thousand and seue hundreth.
27 Ẹ̀yà Aṣeri ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Aṣeri ni Pagieli ọmọ Okanri.
And by him shall the tribe of Asher pitch, and the captaine ouer the sonnes of Asher shalbe Pagiel the sonne of Ocran.
28 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
And his host and the nomber of them were one and fourtie thousand and fiue hundreth.
29 Ẹ̀yà Naftali ni yóò kàn lẹ́yìn wọn. Olórí Naftali ni Ahira ọmọ Enani.
Then the tribe of Naphtali, and the captaine ouer the children of Naphtali shall be Ahira the sonne of Enan:
30 Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé egbèje.
And his host and the nomber of them were three and fiftie thousand and foure hundreth.
31 Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Dani jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gọ̀rin ó lé ẹgbẹ̀jọ. Àwọn ni yóò jáde kẹ́yìn lábẹ́ ọ̀págun wọn.
All the nomber of the host of Dan was an hundreth and seuen and fiftie thousand and sixe hundreth: they shall goe hinmost with their standerdes.
32 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n kà nípa ìdílé wọn. Gbogbo àwọn tó wà ní ibùdó, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, wọ́n jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
These are the summes of the childre of Israel by ye houses of their fathers, all the nomber of ye host, according to their armies, six hundreth and three thousand, fiue hundreth and fiftie.
33 Ṣùgbọ́n a kò ka àwọn ọmọ Lefi papọ̀ mọ́ àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
But the Leuites were not nombred among the children of Israel, as the Lord had commanded Moses.
34 Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose, báyìí ni wọ́n ṣe pa ibùdó lábẹ́ ọ̀págun wọn, bẹ́ẹ̀ náà sì ni wọ́n ṣe jáde, oníkálùkù pẹ̀lú ẹbí àti ìdílé rẹ̀.
And the children of Israel did according to all that the Lord had commanded Moses: so they pitched according to their standards, and so they iourneyed euery one with his families, according to the houses of their fathers.