< Numbers 19 >
1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
I PAN powiedział do Mojżesza i Aarona:
2 “Èyí ni ohun tí òfin Olúwa pàṣẹ béèrè lọ́wọ́ yín. Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí wọn mú ẹgbọrọ ọ̀dọ́ màlúù pupa tí kò lábùkù tàbí àbàwọ́n, lára èyí tí a kò tí ì di àjàgà mọ́.
To jest ustawa prawa, którą nadał PAN: Powiedz synom Izraela, aby przyprowadzili do ciebie czerwoną jałówkę, zdrową i bez skazy, na której jeszcze nie było jarzma.
3 Ẹ mú fún Eleasari àlùfáà, yóò sì mu jáde lọ sí ẹ̀yìn ibùdó kí ó sì pa á ní ojú rẹ.
Oddacie ją kapłanowi Eleazarowi, który ją wyprowadzi poza obóz, i zostanie przed nim zabita.
4 Nígbà náà ni Eleasari àlùfáà yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sórí ìka ọwọ́ rẹ̀ yóò sì wọn lẹ́ẹ̀méje ní ọ̀kánkán iwájú àgọ́ ìpàdé.
A kapłan Eleazar weźmie nieco z jej krwi na swój palec i pokropi nią siedem razy na wprost przed Namiotem Zgromadzenia.
5 Ní ojú rẹ̀ ni àlùfáà yóò ti sun ọ̀dọ́ abo màlúù yìí: awọ ara rẹ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, ẹran-ara àti ìgbẹ́ rẹ̀.
Potem każe spalić jałówkę na swoich oczach: spali jej skórę, mięso, krew wraz z jej odchodami.
6 Àlùfáà yóò mú igi kedari, hísópù àti òwú òdòdó yóò sì jù wọ́n sí àárín ọ̀dọ́ abo màlúù tí a ń sun.
I kapłan weźmie drewno cedrowe, hizop i karmazyn i wrzuci to do ognia, w którym płonie jałówka.
7 Lẹ́yìn náà, àlùfáà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ ara rẹ̀ pẹ̀lú omi lẹ́yìn náà ó lè wá sínú àgọ́. Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
Wtedy kapłan wypierze swoje szaty i umyje swoje ciało wodą; potem wejdzie do obozu i będzie nieczysty do wieczora.
8 Ẹni tí ó sun ún náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀ pẹ̀lú omi, òun náà yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Również ten, który ją będzie palić, wypierze swoje szaty w wodzie i umyje swoje ciało wodą, i będzie nieczysty do wieczora.
9 “Ẹni tó wà ní mímọ́ ni yóò kó eérú ọ̀dọ́ màlúù náà lọ sí ibi tí a yà sí mímọ́ lẹ́yìn ibùdó. Kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli kó o pamọ́ fún lílò fún omi ìwẹ̀nùmọ́. Ó jẹ́ ìwẹ̀nùmọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
Człowiek czysty zbierze popiół tej jałówki i złoży go poza obozem na miejscu czystym; będzie on przechowywany dla zgromadzenia synów Izraela do wody oczyszczenia; jest to ofiara za grzech.
10 Ọkùnrin tí ó kó eérú ọ̀dọ́ abo màlúù náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, òun náà yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún àwọn ọmọ Israẹli àti fún àwọn àjèjì tí ó ń gbé láàrín wọn.
Ten, który zbierał popiół jałówki, wypierze swoje szaty i będzie nieczysty do wieczora. Będzie to ustawa wieczysta dla synów Izraela i dla przybysza mieszkającego wśród was.
11 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ọwọ́ kan òkú ẹnikẹ́ni, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje.
Kto dotknie jakiegokolwiek ludzkiego trupa, będzie nieczysty przez siedem dni.
12 Ó gbọdọ̀ wẹ ara rẹ̀ pẹ̀lú omi ní ọjọ́ kẹta àti ní ọjọ́ keje; nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ pé kò wẹ ara rẹ̀ mọ́ ní ọjọ́ kẹta àti ní ọjọ́ keje yóò jẹ́ aláìmọ́.
Taki oczyści się tą [wodą] w trzecim i siódmym dniu i będzie czysty. Jeśli jednak nie oczyści się w trzecim i siódmym dniu, będzie nieczysty.
13 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ọwọ́ kan òkú ẹnìkan tí kò sì wẹ ara rẹ̀ mọ́, ó ba àgọ́ Olúwa jẹ́. A ó ké irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ọmọ Israẹli. Nítorí pé a kò tí ì wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ lé e lórí, ó jẹ́ aláìmọ́, àìmọ́ rẹ̀ sì wà lára rẹ̀.
Kto dotknie zwłok człowieka zmarłego, a nie oczyści się, ten zanieczyści przybytek PANA; ta dusza będzie wykluczona z Izraela. Człowiek ten nie został bowiem pokropiony wodą oczyszczenia; będzie nieczysty, a jego nieczystość pozostanie na nim.
14 “Èyí ni òfin tí ó jẹ mọ́ bí ènìyàn bá kú nínú àgọ́, ẹnikẹ́ni tí ó bá wọ inú àgọ́ àti ẹni tí ó wà nínú àgọ́ yóò di aláìmọ́ fún ọjọ́ méje,
Taka [jest] ustawa, gdy człowiek umrze w namiocie: ktokolwiek wejdzie do tego namiotu i cokolwiek [znajduje się] w tym namiocie będzie nieczyste przez siedem dni.
15 gbogbo ohun èlò tí a kò bá fi omọrí dé ni yóò jẹ́ aláìmọ́.
Każde naczynie odkryte, które nie ma przymocowanej pokrywy, będzie nieczyste.
16 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá wà ní ìta tí ó sì fi ọwọ́ kan ẹni tí a fi idà pa tàbí ẹni tí ó kú ikú àtọ̀runwá, tàbí bí ẹnìkan bá fi ọwọ́ kan egungun òkú ènìyàn tàbí isà òkú, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje.
Kto dotknie na polu zabitego mieczem lub umarłego, lub kości ludzkich, lub grobu będzie nieczysty przez siedem dni.
17 “Fún aláìmọ́ ènìyàn, mú eérú díẹ̀ lára eérú ọrẹ ìwẹ̀nùmọ́ sínú ìgò, kí o sì da omi tó ń sàn lé e lórí.
Wezmą dla [tego] nieczystego nieco popiołu [jałówki] spalonej za grzech i na to wleją do naczynia źródlanej wody.
18 Nígbà náà, ọkùnrin tí a yà sí mímọ́ yóò mú hísópù díẹ̀ yóò rì í sínú omi yóò sì fi wọ́n àgọ́ àti gbogbo ohun èlò tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ àti àwọn ènìyàn tí ó wà níbẹ̀. O gbọdọ̀ tún fi wọ́n ẹnikẹ́ni tí ó fi ọwọ́ kan egungun òkú ènìyàn tàbí isà òkú, tàbí ẹni tí ó kú ikú ara rẹ̀, tàbí ẹni tí ó kú ikú àti ọ̀run wá.
Człowiek czysty weźmie hizop, zmoczy go w tej wodzie i pokropi namiot oraz wszystkie naczynia i wszystkich ludzi, którzy tam byli, także tego, który dotknął kości lub zabitego, lub zmarłego, lub grobu.
19 Ọkùnrin tí ó mọ́ ni kí ó bu omi wọ́n àwọn ènìyàn aláìmọ́ ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje, ní ọjọ́ keje ó gbọdọ̀ wẹ ara rẹ̀ mọ́. Ẹni tí a wẹ̀mọ́ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀ pẹ̀lú omi, ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà yóò mọ́.
[Człowiek] czysty pokropi nieczystego w trzecim i siódmym dniu, a gdy go oczyści w siódmym dniu, wypierze on swoje szaty i umyje się wodą, i wieczorem będzie czysty.
20 Ṣùgbọ́n bí ẹni tí ó bá jẹ́ aláìmọ́ kò bá wẹ ara rẹ̀ mọ́, a gbọdọ̀ gé e kúrò nínú ìjọ ènìyàn, nítorí wí pé ó ti ba àgọ́ Olúwa jẹ́. A kò tí ì fi omi ìwẹ̀nùmọ́ sí ara rẹ̀, ó sì jẹ́ aláìmọ́.
A człowiek, który stał się nieczysty, a nie oczyścił się, zostanie wykluczony spośród zgromadzenia, gdyż ta dusza zbezcześciła świątynię PANA. Człowiek ten nie został pokropiony wodą oczyszczenia i jest nieczysty.
21 Èyí jẹ́ ìlànà láéláé fún wọn. “Ọkùnrin tí ó wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ àti ẹnikẹ́ni tí ó fi ọwọ́ kan omi ìwẹ̀nùmọ́ yóò di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Będzie to dla nich ustawą wieczystą: kto skrapia wodą oczyszczenia, wypierze swoje szaty, a kto dotknie tej wody oczyszczenia, będzie nieczysty do wieczora.
22 Gbogbo ohun tí ẹni tí ó jẹ́ aláìmọ́ bá fi ọwọ́ kàn yóò di àìmọ́, ẹnikẹ́ni tí ó bá sì fi ọwọ́ kàn án yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.”
Czegokolwiek dotknie nieczysty, będzie nieczyste; również człowiek, który [tego] dotknie, będzie nieczysty do wieczora.