< Numbers 19 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Angraeng mah Mosi hoi Aaron khaeah,
2 “Èyí ni ohun tí òfin Olúwa pàṣẹ béèrè lọ́wọ́ yín. Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí wọn mú ẹgbọrọ ọ̀dọ́ màlúù pupa tí kò lábùkù tàbí àbàwọ́n, lára èyí tí a kò tí ì di àjàgà mọ́.
Angraeng mah thuih ih atawk lok loe, Coek koi kaom ai, rong angdaek ai, vaito doeh laikok atokhaih thing tahnong ah koeng vai ai, kathim maitaw tala to nang khaeah sin o hanah, Israel kaminawk khaeah thui paeh, tiah a naa.
3 Ẹ mú fún Eleasari àlùfáà, yóò sì mu jáde lọ sí ẹ̀yìn ibùdó kí ó sì pa á ní ojú rẹ.
To maitaw tala to qaima Eleazar khaeah paek oh, anih mah ohhaih im tasa bangah hoi ueloe, kami maeto mah anih hmaa ah bop tih.
4 Nígbà náà ni Eleasari àlùfáà yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sórí ìka ọwọ́ rẹ̀ yóò sì wọn lẹ́ẹ̀méje ní ọ̀kánkán iwájú àgọ́ ìpàdé.
Qaima Eleazar mah maitaw tala athii to a banpazung tadong hoiah lak pacoengah, amkhuenghaih kahni im hmaa ah vai sarihto haeh tih.
5 Ní ojú rẹ̀ ni àlùfáà yóò ti sun ọ̀dọ́ abo màlúù yìí: awọ ara rẹ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, ẹran-ara àti ìgbẹ́ rẹ̀.
Kami maeto mah anih hmaa ah maitaw tala to hmai hoiah qoeng tih; ahin, angan, athii hoi aeknawk to hmai hoiah qoeng boih tih.
6 Àlùfáà yóò mú igi kedari, hísópù àti òwú òdòdó yóò sì jù wọ́n sí àárín ọ̀dọ́ abo màlúù tí a ń sun.
Qaima mah sidar thing, hmuihoih husop kung tadok hoi thlangqui kathim to la ueloe, hmai hoi qoeng ih maitaw tala nuiah va tih.
7 Lẹ́yìn náà, àlùfáà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ ara rẹ̀ pẹ̀lú omi lẹ́yìn náà ó lè wá sínú àgọ́. Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
To pacoengah qaima mah a khukbuen to pasuk ueloe, tui doeh amhluh tih; to pacoengah ni a ohhaih im ah caeh vop tih; toe qaima loe duembang khoek to ciim mak ai vop.
8 Ẹni tí ó sun ún náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀ pẹ̀lú omi, òun náà yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Hmai qoeng kami doeh a khukbuen to pasuk pacoengah, tui amhluk han oh; anih doeh duembang khoek to ciim mak ai vop.
9 “Ẹni tó wà ní mímọ́ ni yóò kó eérú ọ̀dọ́ màlúù náà lọ sí ibi tí a yà sí mímọ́ lẹ́yìn ibùdó. Kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli kó o pamọ́ fún lílò fún omi ìwẹ̀nùmọ́. Ó jẹ́ ìwẹ̀nùmọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
Kaciim kami mah hmai hoi thlaek ih maitaw tala apoep to phrom ueloe, atai o haih tasa bang ih hmuenciim maeto ah suem tih; to maiphu loe ciimcai ah amsaehhaih tui ah patoh han oh pongah, Israel acaengnawk mah pakuem o tih; to hmuen loe zae ciimhaih ah om tih.
10 Ọkùnrin tí ó kó eérú ọ̀dọ́ abo màlúù náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, òun náà yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún àwọn ọmọ Israẹli àti fún àwọn àjèjì tí ó ń gbé láàrín wọn.
Maitaw tala ih maiphu phrom kami loe a khukbuen to pasuk han oh, anih loe duembang khoek to ciim mak ai; hae loe Israel kaminawk hoi nihcae salakah kaom angvin hanah dungzan ah paek ih zaehhoihhaih daan lok ah om tih.
11 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ọwọ́ kan òkú ẹnikẹ́ni, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje.
Kadueh qok sui kami loe, ni sarihto thung ciim mak ai.
12 Ó gbọdọ̀ wẹ ara rẹ̀ pẹ̀lú omi ní ọjọ́ kẹta àti ní ọjọ́ keje; nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ pé kò wẹ ara rẹ̀ mọ́ ní ọjọ́ kẹta àti ní ọjọ́ keje yóò jẹ́ aláìmọ́.
Ni thumto naah to ih maiphu hoiah a takpum to amsae tih, anih loe ni sarihto naah ni ciim vop tih; toe anih mah ni thumto naah a takpum to kaciim ah amsae ai nahaeloe, ni sarihto khoek to ciim mak ai boeh.
13 Ẹnikẹ́ni tí ó bá fi ọwọ́ kan òkú ẹnìkan tí kò sì wẹ ara rẹ̀ mọ́, ó ba àgọ́ Olúwa jẹ́. A ó ké irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ọmọ Israẹli. Nítorí pé a kò tí ì wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ lé e lórí, ó jẹ́ aláìmọ́, àìmọ́ rẹ̀ sì wà lára rẹ̀.
Kadueh qok to sui to mah a takpum tui hoiah amsae ai kami loe, Angraeng ih kahni im to amhnongsak; to kami loe Israel kaminawk thung hoiah pahnawt han oh; kaciim ah amsaehhaih tui to a nuiah pathaek ai pongah, anih loe ciim ai; anih nuiah amhnonghaih to oh.
14 “Èyí ni òfin tí ó jẹ mọ́ bí ènìyàn bá kú nínú àgọ́, ẹnikẹ́ni tí ó bá wọ inú àgọ́ àti ẹni tí ó wà nínú àgọ́ yóò di aláìmọ́ fún ọjọ́ méje,
A ohhaih im ah kami dueh nahaeloe, sakhaih daan loe hae tiah oh; to kami ohhaih im ah akun kaminawk hoi imthung ah kaom kaminawk boih loe, ni sarihto thung ciim mak ai.
15 gbogbo ohun èlò tí a kò bá fi omọrí dé ni yóò jẹ́ aláìmọ́.
Kraeng ai ah kam-ong sut laom sabaenawk boih doeh ciim mak ai.
16 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá wà ní ìta tí ó sì fi ọwọ́ kan ẹni tí a fi idà pa tàbí ẹni tí ó kú ikú àtọ̀runwá, tàbí bí ẹnìkan bá fi ọwọ́ kan egungun òkú ènìyàn tàbí isà òkú, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje.
Sumsen hoi hum ih kami qok maw, to tih ai boeh loe kadueh qok maw, to tih ai boeh loe kami huh maw, to tih ai boeh loe taprong maw sui kami loe, ni sarihto thung ciim mak ai.
17 “Fún aláìmọ́ ènìyàn, mú eérú díẹ̀ lára eérú ọrẹ ìwẹ̀nùmọ́ sínú ìgò, kí o sì da omi tó ń sàn lé e lórí.
Kaciim ai kami ciimsak hanah hmai hoi thlaek ih maitaw tala ih apoep maiphu to la ah loe, kalong tui to laom thungah lawn pacoengah,
18 Nígbà náà, ọkùnrin tí a yà sí mímọ́ yóò mú hísópù díẹ̀ yóò rì í sínú omi yóò sì fi wọ́n àgọ́ àti gbogbo ohun èlò tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ àti àwọn ènìyàn tí ó wà níbẹ̀. O gbọdọ̀ tún fi wọ́n ẹnikẹ́ni tí ó fi ọwọ́ kan egungun òkú ènìyàn tàbí isà òkú, tàbí ẹni tí ó kú ikú ara rẹ̀, tàbí ẹni tí ó kú ikú àti ọ̀run wá.
kaciim kami mah hmuihoih husop kung tadok to tui thungah nup ueloe, a ohhaih im maw, laom sabaenawk maw, im ah kaom kaminawk nuiah maw, kami huh sui kami nuiah maw, to tih ai boeh loe hum ih kami maw, to tih ai boeh loe kadueh kami maw, to tih ai boeh loe taprong sui kami nuiah maw pathaek tih.
19 Ọkùnrin tí ó mọ́ ni kí ó bu omi wọ́n àwọn ènìyàn aláìmọ́ ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje, ní ọjọ́ keje ó gbọdọ̀ wẹ ara rẹ̀ mọ́. Ẹni tí a wẹ̀mọ́ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀ pẹ̀lú omi, ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà yóò mọ́.
Kaciim kami mah kaciim ai kami to ni thumto hoi ni sarihto niah pathaek tih; ni sarihto naah a takpum to ciimsak ueloe, a khukbuen to pasuk pacoengah, tui amhlu tih; duembang ah loe anih to ciim tih boeh.
20 Ṣùgbọ́n bí ẹni tí ó bá jẹ́ aláìmọ́ kò bá wẹ ara rẹ̀ mọ́, a gbọdọ̀ gé e kúrò nínú ìjọ ènìyàn, nítorí wí pé ó ti ba àgọ́ Olúwa jẹ́. A kò tí ì fi omi ìwẹ̀nùmọ́ sí ara rẹ̀, ó sì jẹ́ aláìmọ́.
Toe ciim ai kami mah a takpum to ciimsak ai nahaeloe, Angraeng ih hmuenciim to amhnongsak pongah, anih to amkhueng kaminawk salak hoi pahnawt han oh; kaciim ah pasaehhaih tui to anih nuiah pathaek ai pongah, anih loe ciim ai.
21 Èyí jẹ́ ìlànà láéláé fún wọn. “Ọkùnrin tí ó wọ́n omi ìwẹ̀nùmọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ àti ẹnikẹ́ni tí ó fi ọwọ́ kan omi ìwẹ̀nùmọ́ yóò di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
Hae loe nihcae han dungzan ah paek ih zaehhoihhaih daan lok ah oh; kaciim tui pathaek kami doeh a khukbuen to pasuk han angaih; to tui sui kami doeh duembang khoek to ciim mak ai.
22 Gbogbo ohun tí ẹni tí ó jẹ́ aláìmọ́ bá fi ọwọ́ kàn yóò di àìmọ́, ẹnikẹ́ni tí ó bá sì fi ọwọ́ kàn án yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.”
Kaciim ai kami mah sui ih hmuennawk boih loe, ciim mak ai; to hmuen sui kami doeh duembang khoek to ciim mak ai, tiah a naa.

< Numbers 19 >