< Numbers 18 >

1 Olúwa sọ fún Aaroni pé, “Ìwọ, àti àwọn ọmọ rẹ àti ìdílé baba rẹ ni yóò ru gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti dá fún ilé tí a yà sí mímọ́ fún Ọlọ́run, àti ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ nìkan ni yóò máa ru ẹ̀ṣẹ̀ iṣẹ́ àlùfáà yín.
Och Herren sade till Aaron: Du och dine söner, och dins faders hus med dig, skolen bära helgedomens missgerning; och du och dine söner med dig skolen bära edars Presterskaps missgerning.
2 Kí o sì mú àwọn ènìyàn rẹ ará Lefi láti ẹ̀yà ìran rẹ láti dàpọ̀ mọ́ ìwọ láti ràn ọ́ lọ́wọ́ nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin bá ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ níwájú Àgọ́ ẹ̀rí.
Men dine bröder af Levi dins faders slägte skall du taga till dig, att de äro när dig, och tjena dig; men du och dine söner med dig skolen tjena inför vittnesbördsens tabernakel.
3 Àwọn ni ó yẹ láti dúró fún ọ àti láti ṣe gbogbo iṣẹ́ ti Àgọ́, ṣùgbọ́n wọn kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi tí a ti ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ tí a sì yà sí mímọ́ tàbí ibi pẹpẹ, tàbí gbogbo wọn àti ìwọ ló máa kú.
Och de skola taga vara på din tjenst, och hela tabernaklets tjenst; dock skola de intet nalkas intill helgedomens tyg, och till altaret, att både de och I icke skolen dö;
4 Ó yẹ kí wọ́n darapọ̀ mọ́ ọ láti jẹ ìyà iṣẹ́ fún àìtọ́jú ibi ti àgọ́ ìpàdé àti gbogbo iṣẹ́ tí ó wà ní ibi àgọ́, àti wí pé kò sí àlejò tí ó le wá sí ẹ̀gbẹ́ ibi tí o wà.
Utan de skola vara när dig, att de taga vara uppå vittnesbördsens tabernakels tjenst, uti all tabernaklets ämbete; och ingen främmande skall nalkas eder.
5 “Kí o sì mójútó iṣẹ́ ibi mímọ́ àti iṣẹ́ ibi pẹpẹ, kí ìbínú má ba wá sí orí àwọn ọmọ Israẹli mọ́.
Så akter nu uppå helgedomens tjenste, och uppå altarens tjenste, att icke mer en vrede kommer öfver Israels barn.
6 Èmi fúnra mi ti yan àwọn arákùnrin rẹ tí í ṣe ọmọ Lefi kún àwọn ọmọ Israẹli yòókù, wọn jẹ́ ẹ̀bùn fún ọ, èyí ni a fún Olúwa láti ṣe iṣẹ́ tí ó wà ní àgọ́ ìpàdé.
Ty si, jag hafver tagit edra bröder Leviterna ut ifrån Israels barn, och gifvit eder Herranom till en skänk, att de skola taga vara på ämbetet vid vittnesbördsens tabernakel.
7 Ṣùgbọ́n ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ni yóò mójútó iṣẹ́ àlùfáà yín fún gbogbo ohun tó bá jẹ mọ́ ibi pẹpẹ àti ti ẹ̀yin aṣọ títa, ẹ ó sì máa ṣiṣẹ́ ibi pẹpẹ àti nínú aṣọ tí a ta. Mo fún ọ ní iṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn. Ṣùgbọ́n àlejò tí ó bá súnmọ́ tòsí ibi ìyàsímímọ́ fún Ọlọ́run ni a ó pa.”
Men du och dine söner med dig skolen akta på edart Presterskap, att I tjenen uti all altarens handel, och innanför förlåten; ty edart Presterskap gifver jag eder till ett ämbete för en gåfvo; om någor främmande går härtill, han skall dö.
8 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Aaroni pé, “Èmi fúnra mi ti fi ọ́ ṣọ́ ìdí gbogbo ẹbọ tí a bá mú wá fún gbogbo ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli bá fún mi, mo fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpín rẹ tí yóò máa ṣe.
Och Herren sade till Aaron: Si, jag hafver gifvit dig mitt häfoffer, af allt det som Israels barn helga, för ditt Prestaämbete, och dinom sönom till en evig rätt.
9 Ìwọ ni kí o ni ìpín ọrẹ mímọ́ jùlọ tí a mú kúrò ní ibi iná, nínú gbogbo ọrẹ tí wọ́n mú wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ mímọ́ jùlọ, yálà ẹbọ ohun jíjẹ, ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tàbí ẹbọ ẹ̀bi, ìpín wọ̀nyí jẹ́ ti ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
Detta skall du hafva af det aldrahelgasta, som de offra: Alla deras gåfvor med allt deras spisoffer, och med allt deras syndoffer, och med allt deras skuldoffer, som de mig gifva, det skall vara dig och dinom sönom det aldrahelgasta.
10 Ẹ jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́ jùlọ, gbogbo ọkùnrin ni ó gbọdọ̀ jẹ ẹ́. Ó gbọdọ̀ kà á sí mímọ́.
På aldrahelgasta rum skall du äta det; hvad mankön är, skall deraf äta; ty det skall vara dig heligt.
11 “Èyí tún jẹ́ tìrẹ pẹ̀lú: ohunkóhun tí a bá yà sọ́tọ̀ lára ẹ̀bùn ọrẹ fífì àwọn ọmọ Israẹli. Mó fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìpín tí yóò máa ṣe déédé nínú ìdílé rẹ, tí o bá wà ní mímọ́ ni o le jẹ ẹ́.
Jag hafver ock gifvit dig och dinom sönom, och dinom döttrom med dig, deras gåfvors häfoffer, i allo Israels barnas veftoffre till en evig rätt: Den som ren är i dino huse, han skall äta deraf.
12 “Mo fún ọ ní gbogbo òróró tí ó dára jùlọ àti gbogbo ọtí tuntun dáradára jùlọ àti ọkà tí wọ́n mú wá fún Olúwa ní àkọ́so ohun ọ̀gbìn wọn tí wọ́n kórè.
Alla bästa oljo, och all bästa vinmust, och deras förstlingskorn, det som de gifva Herranom, hafver jag gifvit dig.
13 Gbogbo àkọ́so nǹkan ilẹ̀ wọ́n tí wọn mú wá fún Olúwa yóò jẹ́ tìrẹ. Ẹnikẹ́ni nínú ìdílé rẹ, àwọn tí ó jẹ́ mímọ́ nínú ìdílé rẹ lè jẹ ẹ́.
Den första frukten af allt det i deras lande är, det som de bära Herranom, skall vara ditt; den som ren är i dino huse, han skall äta deraf.
14 “Gbogbo nǹkan tí a yà sọ́tọ̀ fún Olúwa ní Israẹli jẹ́ tìrẹ.
Allt det spillgifvet är i Israel, skall vara ditt.
15 Gbogbo àkọ́bí nínú gbogbo ohun alààyè tí wọ́n mú wá fún Olúwa, ìbá à jẹ́ ti ènìyàn tàbí ti ẹranko jẹ́ tìrẹ ṣùgbọ́n o gbọdọ̀ ra gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin padà àti àkọ́bí àwọn ẹranko aláìmọ́.
Allt det som moderlif öppnar ibland allt kött, det som de bära Herranom, vare sig menniska eller fänad, skall vara ditt; dock så, att du den första fruktena af mennisko låter lösa, och den första frukten af en oren fänad också lösa låter;
16 Nígbà tí wọ́n bá pé oṣù kan, o gbọdọ̀ rà wọ́n padà ní iye owó ìràpadà tí í ṣe ṣékélì márùn-ún fàdákà, gẹ́gẹ́ bí iye ṣékélì ibi mímọ́ tí ó wọn ìwọ̀n ogún gera.
Och skola de lösa det, när det är en månad gammalt; och skall gifvat till lösen för penningar, för fem siklar efter helgedomens sikel, hvilken tjugu gera gäller.
17 “Ṣùgbọ́n o kò gbọdọ̀ ra àwọn àkọ́bí ọmọ màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́; wọ́n jẹ́ mímọ́. Wọ́n ẹ̀jẹ̀ wọn sórí pẹpẹ kí o sì sun ọ̀rá rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ àfinásun, ẹbọ òórùn dídùn sí Olúwa.
Men den första frukten af fä eller får, eller get, skall du icke till lösen gifva; ty de äro helig. Deras blod skall du stänka på altaret, och deras feta skall du uppbränna till en söt lukts offer Herranom.
18 Ẹran wọn gbọdọ̀ jẹ́ tìrẹ, gẹ́gẹ́ bí igẹ̀ ọrẹ ẹbọ fífì àti itan ọ̀tún ṣe jẹ́ tìrẹ.
Deras kött skall vara ditt, såsom ock veftebröstet, och högre bogen din är.
19 Ohunkóhun tí a bá ti yà sọ́tọ̀ nínú ọrẹ àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n mú wá fún Olúwa ni mo fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìpín rẹ tí yóò máa ṣe déédé. Ó jẹ́ májẹ̀mú iyọ̀ láéláé níwájú Olúwa fún ìwọ àti ọmọ rẹ.”
Allt häfoffer, som Israels barn helga Herranom, hafver jag gifvit dig och dinom sönom, och dinom döttrom med dig till en evig rätt; det skall vara ett oförgängeligit och evigt förbund för Herranom, dig och dine säd med dig.
20 Olúwa sọ fún Aaroni pé, “O kò ní ní ogún nínú ilẹ̀ wọn bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò ní ní ìpín láàrín wọn; Èmi ni ìpín àti ogún rẹ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Och Herren sade till Aaron: Du skall ingen besittning hafva i deras land, och ingen lott hafva med dem; ty jag är din lott, och ditt arfvegods ibland Israels barn.
21 “Mó ti fún àwọn ọmọ Lefi ní gbogbo ìdámẹ́wàá ní Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún fún iṣẹ́ tí wọ́n ṣe, nígbà tí wọ́n ń ṣiṣẹ́ níbi àgọ́ ìpàdé.
Men Levi barn hafver jag gifvit all tionde i Israel till ett arfvegods, för deras ämbete, som de göra mig vid vittnesbördsens tabernakel;
22 Láti ìsinsin yìí àwọn ọmọ Israẹli, kò gbọdọ̀ súnmọ́ àgọ́ ìpàdé, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò jẹ ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọn á sì kú.
Så att härefter Israels barn intet skola nalkas intill vittnesbördsens tabernakel, till att komma sig i synd och dö;
23 Àwọn ọmọ Lefi ní ó gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ tí ó wà nínú àgọ́ ìpàdé, wọn yóò sì jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí wọ́n bá kúrò láti ṣe é. Èyí ni ìlànà láéláé fún àwọn ìran tí ó ń bọ̀. Wọn kò nígbà ogún kankan láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
Utan Leviterna skola akta på ämbetet vid vittnesbördsens tabernakel, och de skola bära deras synder till en evig rätt till edra efterkommande; och de skola intet arfvegods besitta ibland Israels barn.
24 Kàkà bẹ́ẹ̀, mo fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí ogún wọn, ìdákan nínú ìdámẹ́wàá tí àwọn ọmọ Israẹli pèsè gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa. Èyí ni mo wí nípa wọn. Wọn kò ní gba ogún kankan láàrín àwọn ọmọ Israẹli.”
Ty Israels barnas tiond, som de häfoffra Herranom, hafver jag gifvit Leviterna till arfvegods; derföre hafver jag sagt till dem, att de ibland Israels barn intet arfvegods besitta skola.
25 Olúwa sọ fún Mose pé,
Och Herren talade med Mose, och sade:
26 “Sọ fún àwọn ọmọ Lefi kí o sì wí fún wọn pé: ‘Nígbà tí ìdámẹ́wàá bá ń wọlé láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún rẹ. O gbọdọ̀ mú ìdámẹ́wàá lára rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ Olúwa.
Tala till de Leviter, och säg till dem: När I tagen tionden af Israels barn, den jag eder af dem gifvit hafver till edart arfvegods, så skolen I göra Herranom deraf ett häfoffer, ju tiond af tiond;
27 A ó ka ọrẹ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọkà irúgbìn láti ilẹ̀ ìpakà tàbí wáìnì láti fún wa.
Och skolen sådana edart häfoffer hålla såsom I gåfven korn af ladone, och fyllo af pressen.
28 Báyìí ni ìwọ gan an náà yóò mú ọrẹ wa fún Olúwa láti ara ìdámẹ́wàá tí ìwọ gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli. Láti ara ìdámẹ́wàá ó gbọdọ̀ mú ọrẹ Olúwa fún Aaroni àlùfáà.
Alltså skolen I ock gifva Herranom häfoffer af allo edro tiond, som I tagen af Israels barnom; så att I sådant Herrans häfoffer gifven Prestenom Aaron.
29 Ìwọ gbọdọ̀ mú wá gẹ́gẹ́ bí ìpín Olúwa èyí tí ó dára jùlọ àti tí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ lára gbogbo nǹkan tí wọ́n mú wá fún ọ.’
Utaf allt, det eder gifvet varder, skolen I gifva Herranom allahanda häfoffer, af allt det bästa, som deraf helgadt varder.
30 “Sọ fún àwọn ọmọ pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin bá mú ìpín tí ó dára jù wá, a ó kà á sí fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí ìkórè láti ilẹ̀ ìpakà tàbí ìfúntí yín.
Och säg till dem: När I alltså det bästa deraf häfoffren, så skall det Levitomen räknadt varda, lika som det af ladone, och såsom det af pressen gåfves.
31 Ìwọ àti àwọn ìdílé rẹ̀ le jẹ èyí tí ó kù ní ibikíbi gbogbo. Nítorí pé ó jẹ́ ọrẹ fún iṣẹ́ rẹ níbi àgọ́ ìpàdé.
Och I mågen det äta allestäds, I och edor barn; ty det är edor lön för edart ämbete uti vittnesbördsens tabernakel.
32 Nípa ṣíṣe ìgbékalẹ̀ ìpín tí ó dára jùlọ o kò ní jẹ̀bi lórí ọ̀rọ̀ yìí, ìwọ kò sì ní ba ọrẹ mímọ́ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́, ìwọ kì yóò sì kú.’”
Så synden I icke deröfver, när I häfoffren det feta deraf, och icke ohelgen det Israels barn helgat hafva, att I icke dön.

< Numbers 18 >