< Numbers 18 >

1 Olúwa sọ fún Aaroni pé, “Ìwọ, àti àwọn ọmọ rẹ àti ìdílé baba rẹ ni yóò ru gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ti dá fún ilé tí a yà sí mímọ́ fún Ọlọ́run, àti ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ nìkan ni yóò máa ru ẹ̀ṣẹ̀ iṣẹ́ àlùfáà yín.
And the Lord sayd vnto Aaron, Thou, and thy sonnes and thy fathers house with thee, shall beare the iniquitie of the Sanctuarie: both thou and thy sonnes with thee shall beare the iniquitie of your Priestes office.
2 Kí o sì mú àwọn ènìyàn rẹ ará Lefi láti ẹ̀yà ìran rẹ láti dàpọ̀ mọ́ ìwọ láti ràn ọ́ lọ́wọ́ nígbà tí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin bá ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ níwájú Àgọ́ ẹ̀rí.
And bring also with thee thy brethren of the tribe of Leui of ye familie of thy father, which shalbe ioyned with thee, and minister vnto thee: but thou, and thy sonnes with thee shall minister before the Tabernacle of the Testimonie:
3 Àwọn ni ó yẹ láti dúró fún ọ àti láti ṣe gbogbo iṣẹ́ ti Àgọ́, ṣùgbọ́n wọn kò gbọdọ̀ súnmọ́ ibi tí a ti ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ tí a sì yà sí mímọ́ tàbí ibi pẹpẹ, tàbí gbogbo wọn àti ìwọ ló máa kú.
And they shall keepe thy charge, euen the charge of all the Tabernacle: but they shall not come neere the instruments of the Sanctuary, nor to the altar, lest they die, both they and you:
4 Ó yẹ kí wọ́n darapọ̀ mọ́ ọ láti jẹ ìyà iṣẹ́ fún àìtọ́jú ibi ti àgọ́ ìpàdé àti gbogbo iṣẹ́ tí ó wà ní ibi àgọ́, àti wí pé kò sí àlejò tí ó le wá sí ẹ̀gbẹ́ ibi tí o wà.
And they shalbe ioyned with thee, and keepe the charge of the Tabernacle of the Congregation for all the seruice of the Tabernacle: and no stranger shall come neere vnto you:
5 “Kí o sì mójútó iṣẹ́ ibi mímọ́ àti iṣẹ́ ibi pẹpẹ, kí ìbínú má ba wá sí orí àwọn ọmọ Israẹli mọ́.
Therefore shall ye keepe the charge of the Sanctuarie, and the charge of the altar: so there shall fall no more wrath vpon the children of Israel.
6 Èmi fúnra mi ti yan àwọn arákùnrin rẹ tí í ṣe ọmọ Lefi kún àwọn ọmọ Israẹli yòókù, wọn jẹ́ ẹ̀bùn fún ọ, èyí ni a fún Olúwa láti ṣe iṣẹ́ tí ó wà ní àgọ́ ìpàdé.
For lo, I haue taken your brethren the Leuites from among the children of Israel, which as a gift of yours, are giuen vnto the Lord, to do the seruice of the Tabernacle of the Congregation.
7 Ṣùgbọ́n ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ni yóò mójútó iṣẹ́ àlùfáà yín fún gbogbo ohun tó bá jẹ mọ́ ibi pẹpẹ àti ti ẹ̀yin aṣọ títa, ẹ ó sì máa ṣiṣẹ́ ibi pẹpẹ àti nínú aṣọ tí a ta. Mo fún ọ ní iṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn. Ṣùgbọ́n àlejò tí ó bá súnmọ́ tòsí ibi ìyàsímímọ́ fún Ọlọ́run ni a ó pa.”
But thou, and thy sonnes with thee shall keepe your Priestes office for all things of the altar, and within the vaile: therefore shall ye serue: for I haue made your Priestes office an office of seruice: therefore the stranger that cometh neere, shalbe slayne.
8 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Aaroni pé, “Èmi fúnra mi ti fi ọ́ ṣọ́ ìdí gbogbo ẹbọ tí a bá mú wá fún gbogbo ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli bá fún mi, mo fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpín rẹ tí yóò máa ṣe.
Againe the Lord spake vnto Aaron, Behold, I haue giuen thee the keeping of mine offrings, of all the hallowed things of the children of Israel: vnto thee I haue giuen them for the anoyntings sake, and to thy sonnes, for a perpetuall ordinance.
9 Ìwọ ni kí o ni ìpín ọrẹ mímọ́ jùlọ tí a mú kúrò ní ibi iná, nínú gbogbo ọrẹ tí wọ́n mú wá gẹ́gẹ́ bí ẹbọ mímọ́ jùlọ, yálà ẹbọ ohun jíjẹ, ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ tàbí ẹbọ ẹ̀bi, ìpín wọ̀nyí jẹ́ ti ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
This shalbe thine of the most holy things, reserued from the fire: all their offering of all their meate offring, and of all their sinne offring, and of all their trespasse offring, which they bring vnto me, that shalbe most holy vnto thee, and to thy sonnes.
10 Ẹ jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́ jùlọ, gbogbo ọkùnrin ni ó gbọdọ̀ jẹ ẹ́. Ó gbọdọ̀ kà á sí mímọ́.
In the most holy place shalt thou eate it: euery male shall eate of it: it is holy vnto thee.
11 “Èyí tún jẹ́ tìrẹ pẹ̀lú: ohunkóhun tí a bá yà sọ́tọ̀ lára ẹ̀bùn ọrẹ fífì àwọn ọmọ Israẹli. Mó fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìpín tí yóò máa ṣe déédé nínú ìdílé rẹ, tí o bá wà ní mímọ́ ni o le jẹ ẹ́.
This also shalbe thine: the heaue offering of their gift, with all the shake offerings of the children of Israel: I haue giuen them vnto thee and to thy sonnes and to thy daughters with thee, to be a duetie for euer al the cleane in thine house shall eate of it.
12 “Mo fún ọ ní gbogbo òróró tí ó dára jùlọ àti gbogbo ọtí tuntun dáradára jùlọ àti ọkà tí wọ́n mú wá fún Olúwa ní àkọ́so ohun ọ̀gbìn wọn tí wọ́n kórè.
All the fat of the oyle, and all the fat of the wine, and of the wheate, which they shall offer vnto the Lord for their first fruites, I haue giuen them vnto thee.
13 Gbogbo àkọ́so nǹkan ilẹ̀ wọ́n tí wọn mú wá fún Olúwa yóò jẹ́ tìrẹ. Ẹnikẹ́ni nínú ìdílé rẹ, àwọn tí ó jẹ́ mímọ́ nínú ìdílé rẹ lè jẹ ẹ́.
And the first ripe of al that is in their land, which they shall bring vnto Lord, shalbe thine: all the cleane in thine house shall eate of it.
14 “Gbogbo nǹkan tí a yà sọ́tọ̀ fún Olúwa ní Israẹli jẹ́ tìrẹ.
Euery thing separate from the common vse in Israel, shalbe thine.
15 Gbogbo àkọ́bí nínú gbogbo ohun alààyè tí wọ́n mú wá fún Olúwa, ìbá à jẹ́ ti ènìyàn tàbí ti ẹranko jẹ́ tìrẹ ṣùgbọ́n o gbọdọ̀ ra gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin padà àti àkọ́bí àwọn ẹranko aláìmọ́.
All that first openeth the matrice of any flesh, which they shall offer vnto the Lord, of man or beast, shalbe thine: but the first borne of man shalt thou redeeme, and the first borne of the vncleane beast shalt thou redeeme.
16 Nígbà tí wọ́n bá pé oṣù kan, o gbọdọ̀ rà wọ́n padà ní iye owó ìràpadà tí í ṣe ṣékélì márùn-ún fàdákà, gẹ́gẹ́ bí iye ṣékélì ibi mímọ́ tí ó wọn ìwọ̀n ogún gera.
And those that are to bee redeemed, shalt thou redeeme from the age of a moneth, according to thy estimation, for the money of fiue shekels, after the shekel of the Sanctuarie, which is twentie gerahs.
17 “Ṣùgbọ́n o kò gbọdọ̀ ra àwọn àkọ́bí ọmọ màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́; wọ́n jẹ́ mímọ́. Wọ́n ẹ̀jẹ̀ wọn sórí pẹpẹ kí o sì sun ọ̀rá rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ àfinásun, ẹbọ òórùn dídùn sí Olúwa.
But the first borne of a kow, or the first borne of a sheepe, or the first borne of a goate shalt thou not redeeme: for they are holy: thou shalt sprinkle their blood at the altar, and thou shalt burne their fat: it is a sacrifice made by fire for a sweete sauour vnto the Lord.
18 Ẹran wọn gbọdọ̀ jẹ́ tìrẹ, gẹ́gẹ́ bí igẹ̀ ọrẹ ẹbọ fífì àti itan ọ̀tún ṣe jẹ́ tìrẹ.
And the flesh of them shalbe thine, as the shake breast, and as the right shoulder shalbe thine.
19 Ohunkóhun tí a bá ti yà sọ́tọ̀ nínú ọrẹ àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n mú wá fún Olúwa ni mo fún ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ọmọ rẹ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìpín rẹ tí yóò máa ṣe déédé. Ó jẹ́ májẹ̀mú iyọ̀ láéláé níwájú Olúwa fún ìwọ àti ọmọ rẹ.”
All the heaue offrings of the holy things which the children of Israel shall offer vnto the Lord, haue I giuen thee, and thy sonnes, and thy daughters with thee, to be a duetie for euer: it is a perpetual couenant of salt before the Lord, to thee, and to thy seede with thee.
20 Olúwa sọ fún Aaroni pé, “O kò ní ní ogún nínú ilẹ̀ wọn bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò ní ní ìpín láàrín wọn; Èmi ni ìpín àti ogún rẹ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
And the Lord sayde vnto Aaron, Thou shalt haue none inheritance in their lande, neyther shalt thou haue any parte among them: I am thy part and thine inheritance among the children of Israel.
21 “Mó ti fún àwọn ọmọ Lefi ní gbogbo ìdámẹ́wàá ní Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún fún iṣẹ́ tí wọ́n ṣe, nígbà tí wọ́n ń ṣiṣẹ́ níbi àgọ́ ìpàdé.
For beholde, I haue giuen the children of Leui all the tenth in Israel for an inheritance, for their seruice which they serue in the Tabernacle of the Congregation.
22 Láti ìsinsin yìí àwọn ọmọ Israẹli, kò gbọdọ̀ súnmọ́ àgọ́ ìpàdé, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò jẹ ìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọn á sì kú.
Neyther shall the children of Israel any more come neere the Tabernacle of the Congregation, lest they susteine sinne, and die.
23 Àwọn ọmọ Lefi ní ó gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ tí ó wà nínú àgọ́ ìpàdé, wọn yóò sì jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí wọ́n bá kúrò láti ṣe é. Èyí ni ìlànà láéláé fún àwọn ìran tí ó ń bọ̀. Wọn kò nígbà ogún kankan láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
But the Leuites shall do the seruice in the Tabernacle of the Congregation, and they shall beare their sinne: it is a law for euer in your generations, that among the children of Israel they possesse none inheritance.
24 Kàkà bẹ́ẹ̀, mo fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí ogún wọn, ìdákan nínú ìdámẹ́wàá tí àwọn ọmọ Israẹli pèsè gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa. Èyí ni mo wí nípa wọn. Wọn kò ní gba ogún kankan láàrín àwọn ọmọ Israẹli.”
For the tythes of the children of Israel, which they shall offer as an offring vnto the Lord, I haue giuen the Leuites for an inheritance: therfore I haue said vnto them, Among the children of Israel ye shall possesse none inheritance.
25 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord spake vnto Moses, saying,
26 “Sọ fún àwọn ọmọ Lefi kí o sì wí fún wọn pé: ‘Nígbà tí ìdámẹ́wàá bá ń wọlé láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún rẹ. O gbọdọ̀ mú ìdámẹ́wàá lára rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ Olúwa.
Speake also vnto the Leuites and say vnto them, When ye shall take of the children of Israel the tithes, which I haue giuen you of them for your inheritance, then shall ye take an heaue offring of that same for the Lord, euen the tenth part of the tithe.
27 A ó ka ọrẹ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọkà irúgbìn láti ilẹ̀ ìpakà tàbí wáìnì láti fún wa.
And your heaue offering shalbe reckened vnto you, as the corne of the barne, or as the abundance of the wine presse.
28 Báyìí ni ìwọ gan an náà yóò mú ọrẹ wa fún Olúwa láti ara ìdámẹ́wàá tí ìwọ gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli. Láti ara ìdámẹ́wàá ó gbọdọ̀ mú ọrẹ Olúwa fún Aaroni àlùfáà.
So ye shall also offer an heaue offring vnto the Lord of all your tithes, which ye shall receiue of the children of Israel, and ye shall giue thereof the Lords heaue offring to Aaron the Priest.
29 Ìwọ gbọdọ̀ mú wá gẹ́gẹ́ bí ìpín Olúwa èyí tí ó dára jùlọ àti tí ó jẹ́ mímọ́ jùlọ lára gbogbo nǹkan tí wọ́n mú wá fún ọ.’
Ye shall offer of all your gifts al the Lords heaue offrings: of all the fat of the same shall ye offer the holy things thereof.
30 “Sọ fún àwọn ọmọ pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin bá mú ìpín tí ó dára jù wá, a ó kà á sí fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí ìkórè láti ilẹ̀ ìpakà tàbí ìfúntí yín.
Therefore thou shalt say vnto them, When ye haue offred the fat thereof, then it shalbe couted vnto the Leuites, as the encrease of the corne floore, or as the encrease of the wine presse.
31 Ìwọ àti àwọn ìdílé rẹ̀ le jẹ èyí tí ó kù ní ibikíbi gbogbo. Nítorí pé ó jẹ́ ọrẹ fún iṣẹ́ rẹ níbi àgọ́ ìpàdé.
And ye shall eate it in al places, ye, and your housholdes: for it is your wages for your seruice in the Tabernacle of the Congregation.
32 Nípa ṣíṣe ìgbékalẹ̀ ìpín tí ó dára jùlọ o kò ní jẹ̀bi lórí ọ̀rọ̀ yìí, ìwọ kò sì ní ba ọrẹ mímọ́ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́, ìwọ kì yóò sì kú.’”
And ye shall beare no sinne by the reason of it, when ye haue offred the fatte of it: neither shall ye pollute the holy things of the children of Israel, lest ye die.

< Numbers 18 >