< Numbers 17 >

1 Olúwa sì sọ fún Mose pé,
And the Lord spak to Moises, `and seide, Speke thou to the sones of Israel,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì gba ọ̀pá méjìlá lọ́wọ́ wọn, ọ̀kọ̀ọ̀kan lọ́wọ́ olórí ìdílé ẹ̀yà ìran wọn, kọ orúkọ ènìyàn kọ̀ọ̀kan sí ara ọ̀pá rẹ̀.
and take thou yerdis, bi her kynredis, bi ech kynrede o yeerde, take thou of alle the princes of the lynagis twelue yerdis; and thou schalt write the name of each lynage aboue his yerde;
3 Lórí ọ̀pá Lefi kọ orúkọ Aaroni, nítorí ọ̀pá kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ wà fún olórí ìdílé kọ̀ọ̀kan tí yóò jẹ́ orí fún ẹ̀yà ìran kọ̀ọ̀kan.
forsothe the name of Aaron schal be in the lynage of Leuy, and o yerde schal conteyne alle the meynees of hem.
4 Kó wọn sí àgọ́ ìpàdé níwájú ẹ̀rí níbi tí èmi ti ń pàdé yín.
And thou schalt putte tho yerdis in the tabernacle of boond of pees, bifor the witnessyng, where Y schal speke to thee; the yerde of hym schal buriowne, whom Y schal chese of hem;
5 Ọ̀pá tí ó bá yí jẹ́ ti ẹni tí èmi bá yàn yóò rúwé, èmi yóò sì dá kíkùn gbogbo ìgbà àwọn ọmọ Israẹli sí yín dúró.”
and Y schal refreyne fro me the playnyngis of the sones of Israel, bi whiche thei grutchen ayens you.
6 Nígbà náà Mose bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, àwọn olórí wọn sì fún un ní ọ̀pá méjìlá, ọ̀pá kan fún olórí kọ̀ọ̀kan ẹ̀yà ìran wọn, ọ̀pá Aaroni sì wà lára àwọn ọ̀pá náà.
And Moyses spak to the sones of Israel; and alle princes yauen to hym yerdis, bi alle lynagis; and the yerdis weren twelue, without the yerde of Aaron.
7 Mose sì fi ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú Olúwa nínú àgọ́ ẹ̀rí.
And whanne Moises hadde put tho yerdis bifor the Lord, in the tabernacle of witnessyng, he yede ayen in the day suynge,
8 Ó sì ṣe ní ọjọ́ kejì Mose wọ inú àgọ́ ẹ̀rí lọ, ó sì rí ọ̀pá Aaroni, tí ó dúró fún ẹ̀yà Lefi, kì í ṣe wí pé ó hù nìkan, ṣùgbọ́n ó rúwé, ó yọ ìtànná, ó sì so èso almondi.
and founde that the yerde of Aaron, `in the hows of Leuy, buriounnede; and whanne knoppis weren greet, the blossoms `hadden broke out, whiche weren alargid in leeuys, and weren fourmed in to alemaundis.
9 Nígbà náà ni Mose kó gbogbo àwọn ọ̀pá jáde láti iwájú Olúwa wá fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n wò wọ́n, ẹnìkọ̀ọ̀kan sì mú ọ̀pá tirẹ̀.
Therfor Moyses brouyte forth alle the yerdis fro the siyt of the Lord to al the sones of Israel; and thei sien, and resseyueden ech his yerde.
10 Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú ọ̀pá Aaroni padà wá síwájú ẹ̀rí, láti fi pamọ́ gẹ́gẹ́ bí àmì fún àwọn ọlọ̀tẹ̀. Èyí ó sì mú òpin bá kíkùn sínú wọn sí mi, kí wọn kí ó má ba à kú.”
And the Lord seide to Moises, Bere ayen the yerde of Aaron in to the tabernacle of witnessyng, that it be kept there in to `the signe of the rebel sones of Israel, and that her `playntis reste fro me, lest thei dien.
11 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti páláṣẹ fún un.
And Moises dide, as the Lord comaundide.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sọ fún Mose pé, “Àwa yóò kú! A ti sọnù, gbogbo wa ti sọnù!
Forsothe the sones of Israel seiden to Moises, Lo! we ben wastid, alle we perischiden;
13 Ẹnikẹ́ni tí ó bá súnmọ́ tabanaku Olúwa yóò kú. Ṣé gbogbo wa ni yóò kú?”
who euer neiyeth to the tabernacle of the Lord, he dieth; whethir we schulen be doon awei alle `til to deeth?

< Numbers 17 >