< Numbers 17 >

1 Olúwa sì sọ fún Mose pé,
And he spoke Yahweh to Moses saying.
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì gba ọ̀pá méjìlá lọ́wọ́ wọn, ọ̀kọ̀ọ̀kan lọ́wọ́ olórí ìdílé ẹ̀yà ìran wọn, kọ orúkọ ènìyàn kọ̀ọ̀kan sí ara ọ̀pá rẹ̀.
Speak - to [the] people of Israel and take from with them a rod a rod for [the] house of an ancestor from with all leaders their to [the] house of ancestors their two [plus] ten rods each name his you will write on rod his.
3 Lórí ọ̀pá Lefi kọ orúkọ Aaroni, nítorí ọ̀pá kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ wà fún olórí ìdílé kọ̀ọ̀kan tí yóò jẹ́ orí fún ẹ̀yà ìran kọ̀ọ̀kan.
And [the] name of Aaron you will write on [the] rod of Levi for a rod one [is] for [the] head of [the] house of ancestors their.
4 Kó wọn sí àgọ́ ìpàdé níwájú ẹ̀rí níbi tí èmi ti ń pàdé yín.
And you will deposit them in [the] tent of meeting before the testimony where I meet you there.
5 Ọ̀pá tí ó bá yí jẹ́ ti ẹni tí èmi bá yàn yóò rúwé, èmi yóò sì dá kíkùn gbogbo ìgbà àwọn ọmọ Israẹli sí yín dúró.”
And it will be the man whom I will choose him rod his it will bud and I will put an end to from on me [the] grumblings of [the] people of Israel which they [are] grumbling on you.
6 Nígbà náà Mose bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, àwọn olórí wọn sì fún un ní ọ̀pá méjìlá, ọ̀pá kan fún olórí kọ̀ọ̀kan ẹ̀yà ìran wọn, ọ̀pá Aaroni sì wà lára àwọn ọ̀pá náà.
And he spoke Moses to [the] people of Israel and they gave to him - all leaders their a rod for a leader one a rod for a leader one to [the] house of ancestors their two [plus] ten rods and [the] rod of Aaron [was] in among rods their.
7 Mose sì fi ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú Olúwa nínú àgọ́ ẹ̀rí.
And he deposited Moses the rods before Yahweh in [the] tent of the testimony.
8 Ó sì ṣe ní ọjọ́ kejì Mose wọ inú àgọ́ ẹ̀rí lọ, ó sì rí ọ̀pá Aaroni, tí ó dúró fún ẹ̀yà Lefi, kì í ṣe wí pé ó hù nìkan, ṣùgbọ́n ó rúwé, ó yọ ìtànná, ó sì so èso almondi.
And it was from [the] next day and he went Moses into [the] tent of the testimony and there! it had budded [the] rod of Aaron of [the] house of Levi and it had put forth bud[s] and it had blossomed blossom and it had ripened almonds.
9 Nígbà náà ni Mose kó gbogbo àwọn ọ̀pá jáde láti iwájú Olúwa wá fún àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n wò wọ́n, ẹnìkọ̀ọ̀kan sì mú ọ̀pá tirẹ̀.
And he brought out Moses all the rods from to before Yahweh to all [the] people of Israel and they saw and they took each one rod his.
10 Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú ọ̀pá Aaroni padà wá síwájú ẹ̀rí, láti fi pamọ́ gẹ́gẹ́ bí àmì fún àwọn ọlọ̀tẹ̀. Èyí ó sì mú òpin bá kíkùn sínú wọn sí mi, kí wọn kí ó má ba à kú.”
And he said Yahweh to Moses put back [the] rod of Aaron before the testimony for keeping for a sign for [the] sons of rebellion and may you put an end to grumblings their from on me and not they will die.
11 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti páláṣẹ fún un.
And he did Moses just as he had commanded Yahweh him so he did.
12 Àwọn ọmọ Israẹli sọ fún Mose pé, “Àwa yóò kú! A ti sọnù, gbogbo wa ti sọnù!
And they said [the] people of Israel to Moses saying here! we will die we will perish all of us (we will perish. *LAB(h)*)
13 Ẹnikẹ́ni tí ó bá súnmọ́ tabanaku Olúwa yóò kú. Ṣé gbogbo wa ni yóò kú?”
Every [person] approaching - [person] approaching to [the] tabernacle of Yahweh he will die ¿ or will we complete to die.

< Numbers 17 >