< Numbers 16 >

1 Kora ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi àwọn ọmọ Reubeni: Datani àti Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, àti Oni ọmọ Peleti mú ènìyàn mọ́ra.
Now Korah, filho de Izhar, filho de Kohath, filho de Levi, com Datã e Abiram, filhos de Eliab, e On, filho de Peleth, filhos de Rúben, levou alguns homens.
2 Wọ́n sì dìde sí Mose, pẹ̀lú àádọ́ta lé nígba ọkùnrin nínú àwọn ọmọ Israẹli, ìjòyè nínú ìjọ, àwọn olórúkọ nínú àjọ, àwọn ọkùnrin olókìkí.
Levantaram-se diante de Moisés, com alguns dos filhos de Israel, duzentos e cinqüenta príncipes da congregação, chamados à assembléia, homens de renome.
3 Wọ́n kó ara wọn jọ láti tako Mose àti Aaroni, wọ́n sọ fún wọn pé, “Ẹ ti kọjá ààyè yín, ó tó gẹ́ẹ́! Mímọ́ ni gbogbo ènìyàn, kò sí ẹni tí kò mọ́ láàrín wọn, Olúwa sì wà pẹ̀lú wọn, nítorí kí wá ni ẹ̀yin ṣe gbé ara yín ga ju ìjọ ènìyàn Olúwa lọ?”
Eles se reuniram contra Moisés e contra Aarão, e lhes disseram: “Vocês assumem demais, pois toda a congregação é santa, todos eles, e Yahweh está entre eles! Por que vocês se elevam acima da assembléia de Iavé”?
4 Nígbà tí Mose gbọ́ èyí, ó dojúbolẹ̀,
Quando Moisés ouviu isso, caiu de cara.
5 Ó sì sọ fún Kora àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀ pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò fi ẹni tí í ṣe tirẹ̀ àti ẹni tó mọ́ hàn, yóò sì mú kí ẹni náà súnmọ́ òun. Ẹni tí ó bá yàn ni yóò mú kí ó súnmọ́ òun.
Ele disse a Korah e a toda sua companhia: “Pela manhã, Yahweh mostrará quem é seu, e quem é santo, e o fará aproximar-se dele”. Mesmo aquele que ele escolher, ele fará com que se aproxime dele.
6 Kí Kora àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀ ṣe èyí, ẹ mú àwo tùràrí.
Faça isto: faça com que Korah e toda sua companhia tomem censores,
7 Kí ẹ sì fi iná àti tùràrí sínú rẹ̀ lọ́la níwájú Olúwa, yóò sì ṣe, ọkùnrin tí Olúwa bá yàn òun ni. Ẹ̀yin ọmọ Lefi, ẹ ti kọjá ààyè yín!”
ponha fogo neles, e coloque incenso neles antes de Yahweh amanhã. Será que o homem que Yahweh escolher, ele será santo. Vocês foram longe demais, seus filhos de Levi”!
8 Mose sì tún sọ fún Kora pé, “Ẹ gbọ́ báyìí o, ẹ̀yin ọmọ Lefi!
Moisés disse a Coré: “Ouçam agora, filhos de Levi!
9 Kò ha tọ́ fún yín pé Ọlọ́run Israẹli ti yà yín sọ́tọ̀ lára ìjọ Israẹli yòókù, tó sì mú yín súnmọ́ ara rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ Olúwa àti láti dúró ṣiṣẹ́ ìsìn níwájú àwọn ènìyàn?
É uma coisa pequena para vocês que o Deus de Israel os separou da congregação de Israel, para trazê-los para perto de si, para fazer o serviço do tabernáculo de Javé, e para se apresentarem diante da congregação para ministrar a eles;
10 Ó ti mú àwọn ènìyàn yín tó jẹ́ ọmọ Lefi súnmọ́ ara rẹ̀, ṣùgbọ́n báyìí ẹ tún ń wá ọnà láti ṣiṣẹ́ àlùfáà.
e que ele os aproximou, e a todos os seus irmãos, os filhos de Levi, com vocês? Vocês também buscam o sacerdócio?
11 Olúwa ni ìwọ àti gbogbo ẹlẹgbẹ́ rẹ takò. Ta a ni Aaroni jẹ́ tí ẹ̀yin ó fi kùn sí i?”
Portanto, você e toda a sua empresa se reuniram contra Javé! O que é Aarão que você reclama contra ele”?
12 Mose sì ránṣẹ́ sí Datani àti Abiramu àwọn ọmọ Eliabu. Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kò ní í wá!
Moisés enviou para chamar Dathan e Abiram, os filhos de Eliab; e eles disseram: “Nós não subiremos!
13 Kò ha tó gẹ́ẹ́ pé o ti mú wa jáde láti ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin láti pa wá sínú aginjù yìí? O tún wá fẹ́ sọ ara rẹ di olúwa lé wa lórí bí?
É uma pequena coisa que você nos fez subir de uma terra que flui com leite e mel, para nos matar no deserto, mas você também deve fazer-se um príncipe sobre nós?
14 Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò sì tí ì mú wa dé ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, bẹ́ẹ̀ ni o kò sì pín ilẹ̀ ìní àti ọgbà àjàrà. Ìwọ ha fẹ́ sọ wá di ẹrú bí? Rárá o, àwa kì yóò gòkè wá!”
Além disso, você não nos trouxe para uma terra que flui com leite e mel, nem nos deu herança de campos e vinhedos. Você vai apagar os olhos desses homens? Não vamos subir”.
15 Nígbà náà ni Mose bínú gidigidi, ó sì sọ fún Olúwa pé, “Má ṣe gba ọrẹ wọn, èmi kò gba kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ lọ́wọ́ wọn, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì pa ẹnikẹ́ni nínú wọn lára!”
Moisés ficou muito zangado e disse a Javé: “Não respeite a oferta deles”. Eu não tirei um burro deles, nem machuquei um deles”.
16 Mose sọ fún Kora pé, “Ìwọ àti ọmọ lẹ́yìn rẹ gbọdọ̀ fi ara hàn níwájú Olúwa lọ́la—gbogbo yín, ìwọ, àwọn ọmọ lẹ́yìn rẹ àti Aaroni.
Moisés disse a Korah: “Você e toda sua empresa vão antes de Yahweh, você, e eles, e Aaron, amanhã.
17 Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín mú àwo tùràrí, kí ó sì fi tùràrí sínú rẹ̀, kí gbogbo rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta lé nígba àwo tùràrí kí ẹ sì ko wá síwájú Olúwa. Ìwọ àti Aaroni yóò mú àwo tùràrí wá pẹ̀lú.”
Cada homem pega seu incensário e põe incenso nele, e cada homem traz diante de Javé seu incensário, duzentos e cinqüenta incensários; você também, e Aarão, cada um com seu incensário”.
18 Nígbà náà ni oníkálùkù wọn mú àwo tùràrí, wọ́n fi iná àti tùràrí sí i nínú, wọ́n sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, àwọn pẹ̀lú Mose àti Aaroni.
Cada um pegou seu incensário, colocou fogo, incendiou-o e ficou à porta da Tenda de Encontro com Moisés e Aarão.
19 Nígbà tí Kora kó gbogbo àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ jọ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahan gbogbo ìjọ ènìyàn.
Korah reuniu toda a congregação em frente à porta da Tenda de Reunião. A glória de Yahweh apareceu a toda a congregação.
20 Olúwa sì sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Yahweh falou com Moisés e com Arão, dizendo:
21 “Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín ìjọ wọ̀nyí, kí ń ba à le pa wọ́n run lẹ́ẹ̀kan náà.”
“Separem-se desta congregação, para que eu possa consumi-los em um momento”.
22 Ṣùgbọ́n Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ wọ́n sì kígbe sókè pé, “Ọlọ́run, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, Ìwọ ó wa bínú sí gbogbo ìjọ ènìyàn nígbà tó jẹ́ pé ẹnìkan ló ṣẹ̀?”
Eles caíram de cara, e disseram: “Deus, o Deus dos espíritos de toda a carne, pecará um só homem, e você ficará zangado com toda a congregação”?
23 Olúwa tún sọ fún Mose pé,
Yahweh falou com Moisés, dizendo,
24 “Sọ fún ìjọ ènìyàn pé, ‘Kí wọ́n jìnnà sí àgọ́ Kora, Datani àti Abiramu.’”
“Fale com a congregação, dizendo, 'Afaste-se da tenda de Corá, Datã e Abirão!
25 Mose sì dìde lọ bá Datani àti Abiramu àwọn àgbàgbà Israẹli sì tẹ̀lé.
Moisés levantou-se e foi para Datã e Abirão; e os anciãos de Israel o seguiram.
26 Ó sì kìlọ̀ fún ìjọ ènìyàn pé, “Ẹ kúrò ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú yìí! Ẹ má ṣe fọwọ́ kan ohun kan tí í ṣe tiwọn kí ẹ má ba à parun nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
Ele falou à congregação, dizendo: “Parta, por favor, das tendas destes homens maus, e não toque em nada do que é deles, para que não seja consumido em todos os seus pecados”!
27 Àwọn ènìyàn sì sún kúrò ní àgọ́ Kora, Datani àti Abiramu. Datani àti Abiramu jáde, àwọn ìyàwó wọn àti àwọn ọmọ wọn sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ wọn.
Então eles se afastaram da tenda de Corá, Datã e Abiram, de todos os lados. Datã e Abirão saíram, e ficaram à porta de suas tendas com suas esposas, seus filhos e seus pequenos.
28 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Báyìí ni ẹ ó ṣe mọ̀ pé Olúwa ló rán mi láti ṣe gbogbo iṣẹ́ wọ̀nyí àti pé kì í ṣe ìfẹ́ inú mi ni àwọn ohun tí mò ń ṣe.
Moisés disse: “Nisto sabereis que Javé me enviou para fazer todas estas obras; pois não são de minha própria mente.
29 Bí àwọn ènìyàn yìí bá kú bí gbogbo ènìyàn ti ń kú, bí ìrírí wọn kò bá sì yàtọ̀ sí ti àwọn ènìyàn yòókù, a jẹ́ pé kì í ṣe Olúwa ló rán mi.
Se estes homens morrerem a morte comum de todos os homens, ou se experimentarem o que todos os homens experimentam, então Iavé não me enviou.
30 Ṣùgbọ́n bí Olúwa bá ṣe ohun tuntun, tí ilẹ̀ sì la ẹnu, tó gbé wọn mì, àwọn pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ní, tí wọ́n sì wọ inú ibojì wọn lọ láààyè, nígbà náà ni ẹ̀yin ó mọ̀ pé àwọn ènìyàn yìí ti kẹ́gàn Olúwa.” (Sheol h7585)
Mas se Javé faz uma coisa nova, e o chão abre sua boca, e os engole com tudo o que lhes pertence, e eles descem vivos no Sheol, então vocês entenderão que estes homens desprezaram Javé”. (Sheol h7585)
31 Bí ó sì ṣe parí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ilẹ̀ pín sí méjì nísàlẹ̀ wọn,
Ao terminar de dizer todas estas palavras, o chão que estava sob elas se dividiu.
32 ilẹ̀ sì lanu ó sì gbé wọn mì pẹ̀lú gbogbo ará ilé wọn àti àwọn ènìyàn Kora àti gbogbo ohun tí wọ́n ní.
A terra abriu sua boca e os engoliu com suas casas, todos os homens de Corá e todos os seus bens.
33 Gbogbo wọn sì sọ̀kalẹ̀ sínú ibojì wọn láààyè pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n ní, ilẹ̀ sì padé mọ́ wọn, wọ́n sì ṣègbé kúrò láàrín ìjọ ènìyàn. (Sheol h7585)
Então eles, e tudo o que lhes pertencia, caíram vivos no Sheol. A terra se fechou sobre eles, e pereceram entre a assembléia. (Sheol h7585)
34 Gbogbo ènìyàn Israẹli tí ó yí wọn ká sì sálọ tí àwọn yòókù gbọ́ igbe wọn, wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ yóò gbé àwa náà mì pẹ̀lú.”
Todo Israel que estava ao seu redor fugiu ao seu grito; pois disseram: “Que a terra não nos engula”.
35 Iná sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì run àádọ́ta lé nígba ọkùnrin tí wọ́n mú tùràrí wá.
O fogo saiu de Javé, e devorou os duzentos e cinqüenta homens que ofereceram o incenso.
36 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh falou a Moisés, dizendo:
37 “Sọ fún Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà, pé kí ó mú àwọn àwo tùràrí jáde kúrò nínú iná nítorí pé wọ́n jẹ́ mímọ́, kí ó sì tan iná náà káàkiri sí ibi tó jìnnà.
“Fale a Eleazar, filho de Aarão, o sacerdote, que tire os censores da fogueira, e espalhe o fogo para longe do campo; pois eles são santos,
38 Èyí ni àwo tùràrí àwọn tí ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Kí ẹ gún àwo tùràrí yìí, kí ẹ sì fi ṣe ìbòrí fún pẹpẹ, wọ́n jẹ́ mímọ́ nítorí pé wọ́n ti mú wọn wá síwájú Olúwa. Kí wọ́n jẹ́ àmì fún àwọn ọmọ Israẹli.”
even os censores daqueles que pecaram contra suas próprias vidas. Que sejam espancados em pratos para uma cobertura do altar, pois eles os ofereceram diante de Javé. Portanto, eles são santos. Eles serão um sinal para os filhos de Israel”.
39 Eleasari tí í ṣe àlùfáà sì kó gbogbo àwo tùràrí tí àwọn tí ó jóná mú wa, ó gún wọn pọ̀, ó fi ṣe ìbòrí fún pẹpẹ,
Eleazar o padre levou os censores de bronze que aqueles que foram queimados tinham oferecido; e eles os espancaram para uma cobertura do altar,
40 gẹ́gẹ́ bí Olúwa ṣe sọ láti ẹnu Mose. Èyí yóò jẹ́ ohun ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, àlejò yàtọ̀ sí irú-ọmọ Aaroni kò gbọdọ̀ jó tùràrí níwájú Olúwa, ẹni tí ó bá ṣe bẹ́ẹ̀, yóò dàbí Kora àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ̀.
to ser um memorial aos filhos de Israel, para que nenhum estranho que não seja da descendência de Aarão, se aproximasse para queimar incenso diante de Javé, para que ele não fosse como Corá e como sua companhia; como Javé lhe falou por Moisés.
41 Ní ọjọ́ kejì gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kùn sí Mose àti Aaroni pé, “Ẹ ti pa àwọn ènìyàn Olúwa.”
But no dia seguinte toda a congregação das crianças de Israel reclamou contra Moisés e contra Arão, dizendo: “Vocês mataram o povo de Yahweh!
42 Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn péjọ lòdì sí Mose àti Aaroni, níwájú àgọ́ ìpàdé, lójijì ni ìkùùkuu bolẹ̀, ògo Olúwa sì fi ara hàn.
When a congregação foi reunida contra Moisés e contra Aaron, eles olharam para a Tenda da Reunião. Eis que a nuvem a cobriu e a glória de Yahweh apareceu.
43 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni lọ síwájú àgọ́ ìpàdé,
Moses e Aarão veio para a frente da Tenda da Reunião.
44 Olúwa sì sọ fún Mose pé,
Yahweh falou a Moisés, dizendo:
45 “Yàgò kúrò láàrín ìjọ ènìyàn yìí, kí ń ba le run wọ́n ní ìṣẹ́jú kan.” Wọ́n sì dojúbolẹ̀.
“Afaste-se do meio desta congregação, para que eu possa consumi-los em um momento”. Eles caíram de cara.
46 Mose sì sọ fún Aaroni pé, “Mú àwo tùràrí, kí o fi iná sí i lórí pẹpẹ, fi tùràrí sínú rẹ̀, kí o sì tètè mu lọ sí àárín ìjọ ènìyàn láti ṣe ètùtù fún wọn nítorí pé ìbínú Olúwa ti jáde, àjàkálẹ̀-ààrùn sì ti bẹ̀rẹ̀.”
Moses disse a Aaron: “Pegue seu incensário, ponha fogo no altar, coloque incenso nele, leve-o rapidamente à congregação e faça expiação por eles; pois a ira saiu de Javé! A praga já começou”.
47 Aaroni ṣe bí Mose ti wí, ó sáré lọ sí àárín àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀-ààrùn ti bẹ̀rẹ̀ láàrín wọn, ṣùgbọ́n Aaroni fín tùràrí, ó sì ṣe ètùtù fún wọn.
Aaron fez como Moisés disse, e correu para o meio da assembléia. A peste já havia começado entre o povo. Ele pôs o incenso, e fez expiação pelo povo.
48 Ó dúró láàrín àwọn alààyè àti òkú, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dúró.
He ficou entre os mortos e os vivos; e a peste ficou.
49 Ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀-ààrùn ti pa ẹgbàá méje ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn ní àfikún sí àwọn tí ó kú níbi ìṣẹ̀lẹ̀ Kora.
Now os que morreram pela peste eram quatorze mil e setecentos, além dos que morreram por causa da questão de Corá.
50 Aaroni padà tọ Mose lọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé nítorí pé àjàkálẹ̀-ààrùn náà ti dúró.
Aaron voltou para Moisés à porta da Tenda da Reunião, e a peste foi detida.

< Numbers 16 >