< Numbers 16 >

1 Kora ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi àwọn ọmọ Reubeni: Datani àti Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, àti Oni ọmọ Peleti mú ènìyàn mọ́ra.
Na rĩrĩ, Kora mũrũ wa Iziharu, mũrũ wa Kohathu, ũrĩa warĩ mũrũ wa Lawi, marĩ na andũ amwe a mũhĩrĩga wa Rubeni nĩo Dathani na Abiramu, ariũ a Eliabu, na Oni mũrũ wa Pelethu, magĩtuĩka a kũngʼathia.
2 Wọ́n sì dìde sí Mose, pẹ̀lú àádọ́ta lé nígba ọkùnrin nínú àwọn ọmọ Israẹli, ìjòyè nínú ìjọ, àwọn olórúkọ nínú àjọ, àwọn ọkùnrin olókìkí.
Nao magĩũkĩrĩra Musa. Hamwe nao haarĩ arũme a Isiraeli 250, atongoria mooĩkaine a kĩrĩndĩ kĩu arĩa maathuurĩtwo marĩ a kĩama.
3 Wọ́n kó ara wọn jọ láti tako Mose àti Aaroni, wọ́n sọ fún wọn pé, “Ẹ ti kọjá ààyè yín, ó tó gẹ́ẹ́! Mímọ́ ni gbogbo ènìyàn, kò sí ẹni tí kò mọ́ láàrín wọn, Olúwa sì wà pẹ̀lú wọn, nítorí kí wá ni ẹ̀yin ṣe gbé ara yín ga ju ìjọ ènìyàn Olúwa lọ?”
Nao magĩũka marĩ gĩkundi makararie Musa na Harũni, makĩmeera atĩrĩ, “Inyuĩ nĩmwĩtũgĩrĩtie mũno! Kĩrĩndĩ gĩkĩ gĩothe nĩ gĩtheru, mũndũ o mũndũ, nake Jehova arĩ hamwe nao. Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte mwĩtũũgĩrie igũrũ rĩa kĩũngano gĩkĩ kĩa Jehova?”
4 Nígbà tí Mose gbọ́ èyí, ó dojúbolẹ̀,
Rĩrĩa Musa aiguire ũguo-rĩ, akĩgũa, agĩturumithia ũthiũ thĩ.
5 Ó sì sọ fún Kora àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀ pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò fi ẹni tí í ṣe tirẹ̀ àti ẹni tó mọ́ hàn, yóò sì mú kí ẹni náà súnmọ́ òun. Ẹni tí ó bá yàn ni yóò mú kí ó súnmọ́ òun.
Ningĩ agĩcooka akĩĩra Kora na arũmĩrĩri ake othe atĩrĩ: “Rũciinĩ, Jehova nĩakonania nũũ wake na nũũ mũtheru, na nĩakareka mũndũ ũcio amũkuhĩrĩrie. Mũndũ ũrĩa agaathuura, ũcio nĩwe akaareka amũkuhĩrĩrie.
6 Kí Kora àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀ ṣe èyí, ẹ mú àwo tùràrí.
Wee Kora na arũmĩrĩri aku othe, ũũ nĩguo mũgeeka: mũkoya ngĩo cia gũcinĩra ũbumba,
7 Kí ẹ sì fi iná àti tùràrí sínú rẹ̀ lọ́la níwájú Olúwa, yóò sì ṣe, ọkùnrin tí Olúwa bá yàn òun ni. Ẹ̀yin ọmọ Lefi, ẹ ti kọjá ààyè yín!”
na rũciũ mũciĩkĩre mwaki na ũbumba mũrĩ mbere ya Jehova. Mũndũ ũrĩa Jehova agaathuura-rĩ, ũcio agaatuĩka nĩwe mũtheru. Inyuĩ Alawii nĩmwĩtũgĩrĩtie mũno!”
8 Mose sì tún sọ fún Kora pé, “Ẹ gbọ́ báyìí o, ẹ̀yin ọmọ Lefi!
Ningĩ Musa akĩĩra Kora atĩrĩ, “Ta thikĩrĩriai inyuĩ Alawii!
9 Kò ha tọ́ fún yín pé Ọlọ́run Israẹli ti yà yín sọ́tọ̀ lára ìjọ Israẹli yòókù, tó sì mú yín súnmọ́ ara rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ Olúwa àti láti dúró ṣiṣẹ́ ìsìn níwájú àwọn ènìyàn?
Anga mũtiganĩire nĩ Ngai wa Isiraeli kũmwamũrania na kĩrĩndĩ kĩrĩa kĩngĩ gĩothe kĩa andũ a Isiraeli, akamũrehe hakuhĩ nake nĩgeetha mũrutage wĩra hema-inĩ ĩrĩa nyamũre ya Jehova, na mũrũgamage mbere ya kĩrĩndĩ mũgĩtungatagĩre?
10 Ó ti mú àwọn ènìyàn yín tó jẹ́ ọmọ Lefi súnmọ́ ara rẹ̀, ṣùgbọ́n báyìí ẹ tún ń wá ọnà láti ṣiṣẹ́ àlùfáà.
Inyuĩ hamwe na Alawii othe a thiritũ yanyu nĩamũrehete hakuhĩ nake, no rĩu mũrageria kuoya wĩra wa ũthĩnjĩri-Ngai o naguo.
11 Olúwa ni ìwọ àti gbogbo ẹlẹgbẹ́ rẹ takò. Ta a ni Aaroni jẹ́ tí ẹ̀yin ó fi kùn sí i?”
Wee na arũmĩrĩri aku othe mũnganĩte hamwe mũũkĩrĩre Jehova. Harũni nũũ atĩ nĩguo mũnugune nĩ ũndũ wake?”
12 Mose sì ránṣẹ́ sí Datani àti Abiramu àwọn ọmọ Eliabu. Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kò ní í wá!
Musa agĩcooka agĩĩta Dathani na Abiramu, ariũ a Eliabu. No-o makiuga atĩrĩ, “Tũtigũũka!
13 Kò ha tó gẹ́ẹ́ pé o ti mú wa jáde láti ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin láti pa wá sínú aginjù yìí? O tún wá fẹ́ sọ ara rẹ di olúwa lé wa lórí bí?
Anga ti kũiganu atĩ nĩwatũrutire bũrũri warĩ bũthi wa iria na ũũkĩ ũũke ũtũũragĩre werũ-inĩ ũyũ? Rĩu ningĩ ũrenda gũtwatha?
14 Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò sì tí ì mú wa dé ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, bẹ́ẹ̀ ni o kò sì pín ilẹ̀ ìní àti ọgbà àjàrà. Ìwọ ha fẹ́ sọ wá di ẹrú bí? Rárá o, àwa kì yóò gòkè wá!”
Ningĩ-rĩ, ndũrĩ ũratũkinyia bũrũri ũrĩ na bũthi wa iria na ũũkĩ, kana ũgatũhe igai rĩa ithaka na mĩgũnda ya mĩthabibũ. Nĩ ũgũkũũra andũ aya maitho ũmaheenie? Aca, tũtigũũka!”
15 Nígbà náà ni Mose bínú gidigidi, ó sì sọ fún Olúwa pé, “Má ṣe gba ọrẹ wọn, èmi kò gba kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ lọ́wọ́ wọn, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì pa ẹnikẹ́ni nínú wọn lára!”
Nake Musa akĩrakara mũno, akĩĩra Jehova atĩrĩ, “Ndũgetĩkĩre maruta mao. Niĩ ndioete o na ndigiri kuuma kũrĩ o, o na ndihĩtĩirie mũndũ wao o na ũmwe.”
16 Mose sọ fún Kora pé, “Ìwọ àti ọmọ lẹ́yìn rẹ gbọdọ̀ fi ara hàn níwájú Olúwa lọ́la—gbogbo yín, ìwọ, àwọn ọmọ lẹ́yìn rẹ àti Aaroni.
Ningĩ Musa akĩĩra Kora atĩrĩ, “Wee na arũmĩrĩri aku othe mũgooka mbere ya Jehova rũciũ, wee, nao, na Harũni.
17 Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín mú àwo tùràrí, kí ó sì fi tùràrí sínú rẹ̀, kí gbogbo rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta lé nígba àwo tùràrí kí ẹ sì ko wá síwájú Olúwa. Ìwọ àti Aaroni yóò mú àwo tùràrí wá pẹ̀lú.”
O mũndũ nĩakoya rũgĩo rwake na arwĩkĩre ũbumba, ngĩo ciothe nĩ 250, na mũcirehe mbere ya Jehova. Wee, na Harũni, o na inyuĩ mũrehe ngĩo cianyu.”
18 Nígbà náà ni oníkálùkù wọn mú àwo tùràrí, wọ́n fi iná àti tùràrí sí i nínú, wọ́n sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, àwọn pẹ̀lú Mose àti Aaroni.
Nĩ ũndũ ũcio o mũndũ akĩoya rũgĩo rwake, akĩrwĩkĩra mwaki na ũbumba, na makĩrũgamania mbere ya Musa na Harũni itoonyero-inĩ rĩa Hema-ya-Gũtũnganwo.
19 Nígbà tí Kora kó gbogbo àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ jọ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahan gbogbo ìjọ ènìyàn.
Rĩrĩa Kora aarĩkirie gũcookereria arũmĩrĩri ake othe nĩguo makararie Musa na Harũni marũngiĩ itoonyero-inĩ rĩa Hema-ya-Gũtũnganwo-rĩ, riiri wa Jehova ũkiumĩrĩra kĩũngano kĩu gĩothe.
20 Olúwa sì sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Nake Jehova akĩĩra Musa na Harũni atĩrĩ,
21 “Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín ìjọ wọ̀nyí, kí ń ba à le pa wọ́n run lẹ́ẹ̀kan náà.”
“Mwĩyamũraniei na kĩũngano gĩkĩ nĩguo ndĩkĩniine o ro rĩmwe.”
22 Ṣùgbọ́n Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ wọ́n sì kígbe sókè pé, “Ọlọ́run, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, Ìwọ ó wa bínú sí gbogbo ìjọ ènìyàn nígbà tó jẹ́ pé ẹnìkan ló ṣẹ̀?”
No Musa na Harũni makĩĩgũithia magĩturumithia mothiũ mao thĩ makĩanĩrĩra makiuga atĩrĩ, “Wee Ngai, Ngai wa Maroho ma andũ othe, kaĩ ũngĩrakarĩra kĩũngano gĩkĩ gĩothe hĩndĩ ĩrĩa arĩ o mũndũ ũmwe wĩhĩtie?”
23 Olúwa tún sọ fún Mose pé,
Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
24 “Sọ fún ìjọ ènìyàn pé, ‘Kí wọ́n jìnnà sí àgọ́ Kora, Datani àti Abiramu.’”
“Ĩra kĩũngano gĩothe atĩrĩ, ‘Eherai kuuma hema-inĩ cia Kora na Dathani na Abiramu.’”
25 Mose sì dìde lọ bá Datani àti Abiramu àwọn àgbàgbà Israẹli sì tẹ̀lé.
Musa agĩũkĩra, agĩthiĩ kũrĩ Dathani na Abiramu, nao athuuri a Isiraeli makĩmũrũmĩrĩra.
26 Ó sì kìlọ̀ fún ìjọ ènìyàn pé, “Ẹ kúrò ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú yìí! Ẹ má ṣe fọwọ́ kan ohun kan tí í ṣe tiwọn kí ẹ má ba à parun nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
Nake agĩkaania kĩũngano kĩu, agĩkĩĩra atĩrĩ, “Ehererai hema cia andũ aya aaganu! Mũtikahutie kĩndũ o na kĩmwe kĩao, nĩguo mũtikaniinwo nĩ ũndũ wa mehia mao mothe.”
27 Àwọn ènìyàn sì sún kúrò ní àgọ́ Kora, Datani àti Abiramu. Datani àti Abiramu jáde, àwọn ìyàwó wọn àti àwọn ọmọ wọn sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ wọn.
Nĩ ũndũ ũcio andũ makĩeherera hema icio cia Kora na Dathani na Abiramu. Dathani na Abiramu nĩ moimĩte makarũgama na atumia ao, na ciana cia ngenge itoonyero-inĩ rĩa hema ciao.
28 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Báyìí ni ẹ ó ṣe mọ̀ pé Olúwa ló rán mi láti ṣe gbogbo iṣẹ́ wọ̀nyí àti pé kì í ṣe ìfẹ́ inú mi ni àwọn ohun tí mò ń ṣe.
Ningĩ Musa akiuga atĩrĩ, “Ũndũ ũyũ nĩguo ũgũtũma mũmenye atĩ Jehova nĩwe ũndũmĩte njĩke maũndũ maya mothe, na atĩ rĩtiarĩ ithugunda rĩakwa:
29 Bí àwọn ènìyàn yìí bá kú bí gbogbo ènìyàn ti ń kú, bí ìrírí wọn kò bá sì yàtọ̀ sí ti àwọn ènìyàn yòókù, a jẹ́ pé kì í ṣe Olúwa ló rán mi.
Andũ aya mangĩkua gĩkuũ kĩa ndũire-rĩ, o na kana mone maũndũ o ta marĩa makoraga andũ othe-rĩ, nĩmũkũmenya atĩ ti Jehova ũndũmĩte.
30 Ṣùgbọ́n bí Olúwa bá ṣe ohun tuntun, tí ilẹ̀ sì la ẹnu, tó gbé wọn mì, àwọn pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ní, tí wọ́n sì wọ inú ibojì wọn lọ láààyè, nígbà náà ni ẹ̀yin ó mọ̀ pé àwọn ènìyàn yìí ti kẹ́gàn Olúwa.” (Sheol h7585)
No Jehova angĩrehe ũndũ ũngĩ mwerũ biũ, nayo thĩ yathamie kanua kayo ĩmamerie hamwe na indo ciao ciothe, na mathiĩ mbĩrĩra-inĩ marĩ muoyo, nĩmũkamenya atĩ andũ aya nĩ manyararĩte Jehova.” (Sheol h7585)
31 Bí ó sì ṣe parí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ilẹ̀ pín sí méjì nísàlẹ̀ wọn,
Na rĩrĩ, Musa aarĩkia kuuga ũguo wothe, thĩ ĩgĩatũka hau maarĩ.
32 ilẹ̀ sì lanu ó sì gbé wọn mì pẹ̀lú gbogbo ará ilé wọn àti àwọn ènìyàn Kora àti gbogbo ohun tí wọ́n ní.
Nayo thĩ ĩgĩathamia kanua kayo ĩkĩmameria, hamwe na andũ ao na arũmĩrĩri othe a Kora, na indo ciao ciothe.
33 Gbogbo wọn sì sọ̀kalẹ̀ sínú ibojì wọn láààyè pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n ní, ilẹ̀ sì padé mọ́ wọn, wọ́n sì ṣègbé kúrò láàrín ìjọ ènìyàn. (Sheol h7585)
Nao magĩikũrũka mbĩrĩra marĩ muoyo hamwe na indo ciao ciothe; nayo thĩ ĩkĩmahumbĩra, magĩkua, magĩthengio kĩrĩndĩ-inĩ kĩu. (Sheol h7585)
34 Gbogbo ènìyàn Israẹli tí ó yí wọn ká sì sálọ tí àwọn yòókù gbọ́ igbe wọn, wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ yóò gbé àwa náà mì pẹ̀lú.”
Nĩ ũndũ wa kĩrĩro kĩao, andũ othe a Isiraeli arĩa maamarigiicĩirie makĩũra, makĩanagĩrĩra atĩrĩ, “O na ithuĩ thĩ nĩĩgũtũmeria!”
35 Iná sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì run àádọ́ta lé nígba ọkùnrin tí wọ́n mú tùràrí wá.
Naguo mwaki ũkiuma kũrĩ Jehova ũgĩcina andũ acio 250 arĩa maarehete ũbumba.
36 Olúwa sọ fún Mose pé,
Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
37 “Sọ fún Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà, pé kí ó mú àwọn àwo tùràrí jáde kúrò nínú iná nítorí pé wọ́n jẹ́ mímọ́, kí ó sì tan iná náà káàkiri sí ibi tó jìnnà.
“Ĩra Eleazaru mũrũ wa Harũni, ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, oe ngĩo icio cia gũcinĩrwo ũbumba, acieherie hau irahĩĩra, na ahurunje makara macio handũ haraaya, nĩ ũndũ ngĩo icio nĩ nyamũre,
38 Èyí ni àwo tùràrí àwọn tí ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Kí ẹ gún àwo tùràrí yìí, kí ẹ sì fi ṣe ìbòrí fún pẹpẹ, wọ́n jẹ́ mímọ́ nítorí pé wọ́n ti mú wọn wá síwájú Olúwa. Kí wọ́n jẹ́ àmì fún àwọn ọmọ Israẹli.”
ngĩo icio cia andũ acio makuĩte nĩ ũndũ wa mehia mao. Ngĩo icio nĩiturwo ituĩke mabati ma kũhumbĩra kĩgongona, nĩ ũndũ nĩciarehetwo mbere ya Jehova, na igatuĩka nyamũre. Nacio nĩ ituĩke kĩmenyithia harĩ andũ a Isiraeli.”
39 Eleasari tí í ṣe àlùfáà sì kó gbogbo àwo tùràrí tí àwọn tí ó jóná mú wa, ó gún wọn pọ̀, ó fi ṣe ìbòrí fún pẹpẹ,
Nĩ ũndũ ũcio Eleazaru ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai akĩoya ngĩo icio cia gĩcango ciarehetwo nĩ andũ acio maacinĩtwo, nake agĩciturithia ituĩke cia kũhumbĩra kĩgongona,
40 gẹ́gẹ́ bí Olúwa ṣe sọ láti ẹnu Mose. Èyí yóò jẹ́ ohun ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, àlejò yàtọ̀ sí irú-ọmọ Aaroni kò gbọdọ̀ jó tùràrí níwájú Olúwa, ẹni tí ó bá ṣe bẹ́ẹ̀, yóò dàbí Kora àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ̀.
agĩĩka o ta ũrĩa Jehova aathĩrĩire Musa. Ũndũ ũyũ warĩ wa kũririkania andũ a Isiraeli atĩ gũtirĩ mũndũ o na ũrĩkũ, tiga wa rũciaro rwa Harũni, wagĩrĩirwo nĩ gũũka gũcina ũbumba mbere ya Jehova, kana atuĩke ta Kora na arũmĩrĩri ake.
41 Ní ọjọ́ kejì gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kùn sí Mose àti Aaroni pé, “Ẹ ti pa àwọn ènìyàn Olúwa.”
Mũthenya ũyũ ũngĩ, kĩrĩndĩ gĩothe kĩa andũ a Isiraeli gĩgĩtetia Musa na Harũni, gĩkĩmeera atĩrĩ, “Inyuĩ nĩ mũũragĩte andũ a Jehova.”
42 Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn péjọ lòdì sí Mose àti Aaroni, níwájú àgọ́ ìpàdé, lójijì ni ìkùùkuu bolẹ̀, ògo Olúwa sì fi ara hàn.
Na rĩrĩa kĩũngano kĩu gĩecookanĩrĩirie gĩũkĩrĩre Musa na Harũni, o na gĩkĩerekera na kũrĩa Hema-ya-Gũtũnganwo yarĩ-rĩ, o rĩmwe itu rĩkĩhumbĩra hema ĩyo, naguo riiri wa Jehova ũkĩonekana.
43 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni lọ síwájú àgọ́ ìpàdé,
Nao Musa na Harũni magĩthiĩ hau mbere ya Hema-ya-Gũtũnganwo,
44 Olúwa sì sọ fún Mose pé,
nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
45 “Yàgò kúrò láàrín ìjọ ènìyàn yìí, kí ń ba le run wọ́n ní ìṣẹ́jú kan.” Wọ́n sì dojúbolẹ̀.
“Ehererai mume kĩũngano-inĩ gĩkĩ nĩguo ndĩkĩniine o ro rĩmwe.” No-o makĩĩgũithia thĩ, na magĩturumithia mothiũ mao thĩ.
46 Mose sì sọ fún Aaroni pé, “Mú àwo tùràrí, kí o fi iná sí i lórí pẹpẹ, fi tùràrí sínú rẹ̀, kí o sì tètè mu lọ sí àárín ìjọ ènìyàn láti ṣe ètùtù fún wọn nítorí pé ìbínú Olúwa ti jáde, àjàkálẹ̀-ààrùn sì ti bẹ̀rẹ̀.”
Ningĩ Musa akĩĩra Harũni atĩrĩ, “Oya rũgĩo rwaku ũrwĩkĩre ũbumba hamwe na mwaki wa kuuma kĩgongona-inĩ, na ũthiĩ narua kĩũngano-inĩ kĩu ũkĩhoroherie. Mangʼũrĩ moimĩte kũrĩ Jehova; mũthiro nĩwambĩrĩirie kũmaniina.”
47 Aaroni ṣe bí Mose ti wí, ó sáré lọ sí àárín àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀-ààrùn ti bẹ̀rẹ̀ láàrín wọn, ṣùgbọ́n Aaroni fín tùràrí, ó sì ṣe ètùtù fún wọn.
Nĩ ũndũ ũcio Harũni agĩĩka o ta ũrĩa Musa aamwĩrire, agĩtengʼera agĩtoonya thĩinĩ wa kĩũngano kĩu. Mũthiro nĩwarĩĩkĩtie kwambĩrĩria thĩinĩ wa andũ, no Harũni akĩruta ũbumba akĩmahoroheria.
48 Ó dúró láàrín àwọn alààyè àti òkú, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dúró.
Akĩrũgama gatagatĩ ka andũ arĩa maarĩ muoyo na arĩa maakuĩte, naguo mũthiro ũgĩthira.
49 Ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀-ààrùn ti pa ẹgbàá méje ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn ní àfikún sí àwọn tí ó kú níbi ìṣẹ̀lẹ̀ Kora.
No andũ 14,700 magĩkua nĩ ũndũ wa mũthiro ũcio, kuonganĩrĩria na andũ arĩa maakuĩte nĩ ũndũ wa Kora.
50 Aaroni padà tọ Mose lọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé nítorí pé àjàkálẹ̀-ààrùn náà ti dúró.
Thuutha ũcio Harũni agĩcooka kũrĩ Musa itoonyero-inĩ rĩa Hema-ya-Gũtũnganwo, tondũ mũthiro ũcio nĩwathirĩte.

< Numbers 16 >