< Numbers 16 >

1 Kora ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi àwọn ọmọ Reubeni: Datani àti Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, àti Oni ọmọ Peleti mú ènìyàn mọ́ra.
And Korah, son of Izhar, son of Kohath, son of Levi, takes both Dathan and Abiram sons of Eliab, and On son of Peleth, sons of Reuben,
2 Wọ́n sì dìde sí Mose, pẹ̀lú àádọ́ta lé nígba ọkùnrin nínú àwọn ọmọ Israẹli, ìjòyè nínú ìjọ, àwọn olórúkọ nínú àjọ, àwọn ọkùnrin olókìkí.
and they rise up before Moses with men of the sons of Israel, two hundred and fifty princes of the congregation, called of the convention, men of renown,
3 Wọ́n kó ara wọn jọ láti tako Mose àti Aaroni, wọ́n sọ fún wọn pé, “Ẹ ti kọjá ààyè yín, ó tó gẹ́ẹ́! Mímọ́ ni gbogbo ènìyàn, kò sí ẹni tí kò mọ́ láàrín wọn, Olúwa sì wà pẹ̀lú wọn, nítorí kí wá ni ẹ̀yin ṣe gbé ara yín ga ju ìjọ ènìyàn Olúwa lọ?”
and they are assembled against Moses and against Aaron, and say to them, “Enough of you! For all the congregation—all of them [are] holy, and YHWH [is] in their midst; and why do you lift yourselves up above the assembly of YHWH?”
4 Nígbà tí Mose gbọ́ èyí, ó dojúbolẹ̀,
And Moses hears, and falls on his face,
5 Ó sì sọ fún Kora àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀ pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò fi ẹni tí í ṣe tirẹ̀ àti ẹni tó mọ́ hàn, yóò sì mú kí ẹni náà súnmọ́ òun. Ẹni tí ó bá yàn ni yóò mú kí ó súnmọ́ òun.
and he speaks to Korah and to all his congregation, saying, “Indeed, [in the] morning YHWH may cause [you] to know those who are His and him who is holy, and has brought [him] near to Him; even him whom He fixes on He brings near to Him.
6 Kí Kora àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀ ṣe èyí, ẹ mú àwo tùràrí.
Do this: take censers for yourselves—Korah and all his company—
7 Kí ẹ sì fi iná àti tùràrí sínú rẹ̀ lọ́la níwájú Olúwa, yóò sì ṣe, ọkùnrin tí Olúwa bá yàn òun ni. Ẹ̀yin ọmọ Lefi, ẹ ti kọjá ààyè yín!”
and put fire in them and put incense on them before YHWH tomorrow, and it has been, the man whom YHWH chooses, he [is] the holy one—enough of you, sons of Levi!”
8 Mose sì tún sọ fún Kora pé, “Ẹ gbọ́ báyìí o, ẹ̀yin ọmọ Lefi!
And Moses says to Korah, “Now hear, sons of Levi;
9 Kò ha tọ́ fún yín pé Ọlọ́run Israẹli ti yà yín sọ́tọ̀ lára ìjọ Israẹli yòókù, tó sì mú yín súnmọ́ ara rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ Olúwa àti láti dúró ṣiṣẹ́ ìsìn níwájú àwọn ènìyàn?
is it little to you that the God of Israel has separated you from the congregation of Israel to bring you near to Himself, to do the service of the Dwelling Place of YHWH, and to stand before the congregation to serve them?
10 Ó ti mú àwọn ènìyàn yín tó jẹ́ ọmọ Lefi súnmọ́ ara rẹ̀, ṣùgbọ́n báyìí ẹ tún ń wá ọnà láti ṣiṣẹ́ àlùfáà.
Indeed, He brings you near, and all your brothers, the sons of Levi, with you—and you have also sought the priesthood!
11 Olúwa ni ìwọ àti gbogbo ẹlẹgbẹ́ rẹ takò. Ta a ni Aaroni jẹ́ tí ẹ̀yin ó fi kùn sí i?”
Therefore, you and all your congregation are meeting against YHWH; and Aaron, what [is] he, that you murmur against him?”
12 Mose sì ránṣẹ́ sí Datani àti Abiramu àwọn ọmọ Eliabu. Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kò ní í wá!
And Moses sends to call for Dathan and for Abiram, sons of Eliab, and they say, “We do not come up!
13 Kò ha tó gẹ́ẹ́ pé o ti mú wa jáde láti ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin láti pa wá sínú aginjù yìí? O tún wá fẹ́ sọ ara rẹ di olúwa lé wa lórí bí?
Is it little that you have brought us up out of a land flowing with milk and honey, to put us to death in a wilderness, that you also certainly make yourself prince over us?
14 Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò sì tí ì mú wa dé ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, bẹ́ẹ̀ ni o kò sì pín ilẹ̀ ìní àti ọgbà àjàrà. Ìwọ ha fẹ́ sọ wá di ẹrú bí? Rárá o, àwa kì yóò gòkè wá!”
Indeed, you have not brought us into a land flowing with milk and honey, nor do you give an inheritance of field and vineyard to us; do you pick out the eyes of these men? We do not come up!”
15 Nígbà náà ni Mose bínú gidigidi, ó sì sọ fún Olúwa pé, “Má ṣe gba ọrẹ wọn, èmi kò gba kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ lọ́wọ́ wọn, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì pa ẹnikẹ́ni nínú wọn lára!”
And it is very displeasing to Moses, and he says to YHWH, “Do not turn to their present; I have not taken one donkey from them, nor have I afflicted one of them.”
16 Mose sọ fún Kora pé, “Ìwọ àti ọmọ lẹ́yìn rẹ gbọdọ̀ fi ara hàn níwájú Olúwa lọ́la—gbogbo yín, ìwọ, àwọn ọmọ lẹ́yìn rẹ àti Aaroni.
And Moses says to Korah, “You and all your congregation, be [present] before YHWH—you, and they, and Aaron—tomorrow;
17 Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín mú àwo tùràrí, kí ó sì fi tùràrí sínú rẹ̀, kí gbogbo rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta lé nígba àwo tùràrí kí ẹ sì ko wá síwájú Olúwa. Ìwọ àti Aaroni yóò mú àwo tùràrí wá pẹ̀lú.”
and let each take his censer and you have put incense on them, and each has brought his censer near before YHWH—two hundred and fifty censers; indeed, you and Aaron, each [with] his censer.”
18 Nígbà náà ni oníkálùkù wọn mú àwo tùràrí, wọ́n fi iná àti tùràrí sí i nínú, wọ́n sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, àwọn pẹ̀lú Mose àti Aaroni.
And they each take his censer, and put fire on them, and lay incense on them, and they stand at the opening of the Tent of Meeting with Moses and Aaron.
19 Nígbà tí Kora kó gbogbo àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ jọ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahan gbogbo ìjọ ènìyàn.
And Korah assembles all the congregation against them at the opening of the Tent of Meeting, and the glory of YHWH is seen by all the congregation.
20 Olúwa sì sọ fún Mose àti Aaroni pé,
And YHWH speaks to Moses and to Aaron, saying,
21 “Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín ìjọ wọ̀nyí, kí ń ba à le pa wọ́n run lẹ́ẹ̀kan náà.”
“Be separated from the midst of this congregation, and I consume them in a moment”;
22 Ṣùgbọ́n Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ wọ́n sì kígbe sókè pé, “Ọlọ́run, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, Ìwọ ó wa bínú sí gbogbo ìjọ ènìyàn nígbà tó jẹ́ pé ẹnìkan ló ṣẹ̀?”
and they fall on their faces, and say, “God, God of the spirits of all flesh—one man sins, and are You angry against all the congregation?”
23 Olúwa tún sọ fún Mose pé,
And YHWH speaks to Moses, saying,
24 “Sọ fún ìjọ ènìyàn pé, ‘Kí wọ́n jìnnà sí àgọ́ Kora, Datani àti Abiramu.’”
“Speak to the congregation, saying, Go up from around the dwelling place of Korah, Dathan, and Abiram.”
25 Mose sì dìde lọ bá Datani àti Abiramu àwọn àgbàgbà Israẹli sì tẹ̀lé.
And Moses rises, and goes to Dathan and Abiram, and [the] elderly of Israel go after him,
26 Ó sì kìlọ̀ fún ìjọ ènìyàn pé, “Ẹ kúrò ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú yìí! Ẹ má ṣe fọwọ́ kan ohun kan tí í ṣe tiwọn kí ẹ má ba à parun nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
and he speaks to the congregation, saying, “Now turn aside from the tents of these wicked men, and do not come against anything that they have, lest you are consumed in all their sins.”
27 Àwọn ènìyàn sì sún kúrò ní àgọ́ Kora, Datani àti Abiramu. Datani àti Abiramu jáde, àwọn ìyàwó wọn àti àwọn ọmọ wọn sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ wọn.
And they go up from the dwelling place of Korah, Dathan, and Abiram, from all around, and Dathan and Abiram have come out, standing at the opening of their tents, with their wives, and their sons, and their infants.
28 Nígbà náà ni Mose wí pé, “Báyìí ni ẹ ó ṣe mọ̀ pé Olúwa ló rán mi láti ṣe gbogbo iṣẹ́ wọ̀nyí àti pé kì í ṣe ìfẹ́ inú mi ni àwọn ohun tí mò ń ṣe.
And Moses says, “By this you know that YHWH has sent me to do all these works, that [they are] not from my own heart;
29 Bí àwọn ènìyàn yìí bá kú bí gbogbo ènìyàn ti ń kú, bí ìrírí wọn kò bá sì yàtọ̀ sí ti àwọn ènìyàn yòókù, a jẹ́ pé kì í ṣe Olúwa ló rán mi.
if these die according to the death of all men, or the charge of all men is charged on them, YHWH has not sent me;
30 Ṣùgbọ́n bí Olúwa bá ṣe ohun tuntun, tí ilẹ̀ sì la ẹnu, tó gbé wọn mì, àwọn pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ní, tí wọ́n sì wọ inú ibojì wọn lọ láààyè, nígbà náà ni ẹ̀yin ó mọ̀ pé àwọn ènìyàn yìí ti kẹ́gàn Olúwa.” (Sheol h7585)
but if YHWH does a strange thing, and the ground has opened her mouth and swallowed them and all that they have, and they have gone down alive to Sheol, then you have known that these men have despised YHWH.” (Sheol h7585)
31 Bí ó sì ṣe parí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ilẹ̀ pín sí méjì nísàlẹ̀ wọn,
And it comes to pass at his finishing speaking all these words, that the ground which [is] under them cleaves,
32 ilẹ̀ sì lanu ó sì gbé wọn mì pẹ̀lú gbogbo ará ilé wọn àti àwọn ènìyàn Kora àti gbogbo ohun tí wọ́n ní.
and the earth opens her mouth and swallows them, and their houses, and all the men who [are] for Korah, and all the goods,
33 Gbogbo wọn sì sọ̀kalẹ̀ sínú ibojì wọn láààyè pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n ní, ilẹ̀ sì padé mọ́ wọn, wọ́n sì ṣègbé kúrò láàrín ìjọ ènìyàn. (Sheol h7585)
and they go down—they and all that they have—alive to Sheol, and the earth closes over them, and they perish from the midst of the assembly; (Sheol h7585)
34 Gbogbo ènìyàn Israẹli tí ó yí wọn ká sì sálọ tí àwọn yòókù gbọ́ igbe wọn, wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ yóò gbé àwa náà mì pẹ̀lú.”
and all Israel who [are] around them have fled at their voice, for they said, “Lest the earth swallow us”;
35 Iná sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì run àádọ́ta lé nígba ọkùnrin tí wọ́n mú tùràrí wá.
and fire has come out from YHWH and consumes the two hundred and fifty men bringing the incense near.
36 Olúwa sọ fún Mose pé,
And YHWH speaks to Moses, saying,
37 “Sọ fún Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà, pé kí ó mú àwọn àwo tùràrí jáde kúrò nínú iná nítorí pé wọ́n jẹ́ mímọ́, kí ó sì tan iná náà káàkiri sí ibi tó jìnnà.
“Say to Eleazar son of Aaron the priest to lift up the censers from the midst of the burning and scatter the fire away, for they have been hallowed.
38 Èyí ni àwo tùràrí àwọn tí ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Kí ẹ gún àwo tùràrí yìí, kí ẹ sì fi ṣe ìbòrí fún pẹpẹ, wọ́n jẹ́ mímọ́ nítorí pé wọ́n ti mú wọn wá síwájú Olúwa. Kí wọ́n jẹ́ àmì fún àwọn ọmọ Israẹli.”
[As for] the censers of these sinners against their own souls, indeed, they have made them [into] spread-out plates [for] a covering for the altar, for they have brought them near before YHWH, and they are hallowed; and they become a sign to the sons of Israel.”
39 Eleasari tí í ṣe àlùfáà sì kó gbogbo àwo tùràrí tí àwọn tí ó jóná mú wa, ó gún wọn pọ̀, ó fi ṣe ìbòrí fún pẹpẹ,
And Eleazar the priest takes the bronze censers which they who are burned had brought near, and they spread them out [for] a covering for the altar—
40 gẹ́gẹ́ bí Olúwa ṣe sọ láti ẹnu Mose. Èyí yóò jẹ́ ohun ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, àlejò yàtọ̀ sí irú-ọmọ Aaroni kò gbọdọ̀ jó tùràrí níwájú Olúwa, ẹni tí ó bá ṣe bẹ́ẹ̀, yóò dàbí Kora àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ̀.
a memorial to the sons of Israel, so that a stranger who is not of the seed of Aaron does not draw near to make incense before YHWH, and is not as Korah and as his congregation, as YHWH has spoken by the hand of Moses to him.
41 Ní ọjọ́ kejì gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kùn sí Mose àti Aaroni pé, “Ẹ ti pa àwọn ènìyàn Olúwa.”
And on the next day all the congregation of the sons of Israel murmurs against Moses and against Aaron, saying, “You have put the people of YHWH to death.”
42 Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn péjọ lòdì sí Mose àti Aaroni, níwájú àgọ́ ìpàdé, lójijì ni ìkùùkuu bolẹ̀, ògo Olúwa sì fi ara hàn.
And it comes to pass, in the congregation being assembled against Moses and against Aaron, that they turn toward the Tent of Meeting, and behold, the cloud has covered it and the glory of YHWH is seen;
43 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni lọ síwájú àgọ́ ìpàdé,
and Moses comes—Aaron also—to the front of the Tent of Meeting.
44 Olúwa sì sọ fún Mose pé,
And YHWH speaks to Moses, saying,
45 “Yàgò kúrò láàrín ìjọ ènìyàn yìí, kí ń ba le run wọ́n ní ìṣẹ́jú kan.” Wọ́n sì dojúbolẹ̀.
“Get up from the midst of this congregation, and I consume them in a moment”; and they fall on their faces,
46 Mose sì sọ fún Aaroni pé, “Mú àwo tùràrí, kí o fi iná sí i lórí pẹpẹ, fi tùràrí sínú rẹ̀, kí o sì tètè mu lọ sí àárín ìjọ ènìyàn láti ṣe ètùtù fún wọn nítorí pé ìbínú Olúwa ti jáde, àjàkálẹ̀-ààrùn sì ti bẹ̀rẹ̀.”
and Moses says to Aaron, “Take the censer and put fire on it from off the altar, and place incense, and go quickly to the congregation and make atonement for them, for the wrath has gone out from the presence of YHWH—the plague has begun.”
47 Aaroni ṣe bí Mose ti wí, ó sáré lọ sí àárín àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀-ààrùn ti bẹ̀rẹ̀ láàrín wọn, ṣùgbọ́n Aaroni fín tùràrí, ó sì ṣe ètùtù fún wọn.
And Aaron takes [it] as Moses has spoken, and runs to the midst of the assembly, and behold, the plague has begun among the people; and he gives the incense, and makes atonement for the people,
48 Ó dúró láàrín àwọn alààyè àti òkú, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dúró.
and stands between the dead and the living, and the plague is restrained;
49 Ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀-ààrùn ti pa ẹgbàá méje ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn ní àfikún sí àwọn tí ó kú níbi ìṣẹ̀lẹ̀ Kora.
and those who die by the plague are fourteen thousand and seven hundred, apart from those who die for the matter of Korah;
50 Aaroni padà tọ Mose lọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé nítorí pé àjàkálẹ̀-ààrùn náà ti dúró.
and Aaron turns back to Moses, to the opening of the Tent of Meeting, and the plague has been restrained.

< Numbers 16 >