< Numbers 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Och HERREN talade till Mose och sade:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi ó fún yin gẹ́gẹ́ bí ibùgbé
Tala till Israels barn och säg till dem: Om I, när I kommen in i det land som jag vill giva eder, och där I skolen bo,
3 tí ẹ̀yin ó bá sì ṣe ẹbọ iná sí Olúwa ẹbọ sísun, tàbí ẹbọ, láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí ọrẹ àtinúwá, tàbí nínú àjọ yín, láti ṣe òórùn dídùn sí Olúwa nínú agbo ẹran tàbí ọ̀wọ́ ẹran,
viljen offra ett eldsoffer åt HERREN, ett brännoffer eller ett slaktoffer -- vare sig det gäller att fullgöra ett löfte, eller det gäller ett frivilligt offer, eller det gäller edra högtidsoffer -- för att bereda HERREN en välbehaglig lukt, genom fäkreatur eller småboskap,
4 nígbà náà ni kí ẹni tí ó bá mú ọrẹ rẹ̀ wá, yóò tún mú ẹbọ ohun jíjẹ ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná pẹ̀lú ìdámẹ́rin òsùwọ̀n òróró wá síwájú Olúwa.
så skall den som vill offra åt HERREN ett sådant offer bära fram såsom spisoffer en tiondedels efa fint mjöl, begjutet med en fjärdedels hin olja;
5 Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan yálà fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun ni, kí ẹ pèsè ìdámẹ́rin òsùwọ̀n wáìnì gẹ́gẹ́ bí ohun mímu.
och såsom drickoffer skall du offra en fjärdedels hin vin till vart lamm, vare sig det är ett brännoffer som offras, eller det är ett slaktoffer.
6 “‘Fún àgbò kan ni kí ẹ pèsè ọrẹ ohun jíjẹ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n òróró pò.
Men till en vädur skall du såsom spisoffer offra två tiondedels efa fint mjöl, begjutet med en tredjedels hin olja,
7 Àti ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n wáìnì fún ọrẹ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa.
och såsom drickoffer skall du bära fram en tredjedels hin vin, till er välbehaglig lukt för HERREN.
8 “‘Nígbà tí ẹ bá sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun, láti fi san ẹ̀jẹ́ tàbí fún ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa,
Och när du offrar en ungtjur till brännoffer eller till slaktoffer, vare sig det gäller att fullgöra ett löfte eller det gäller tackoffer åt HERREN.
9 ẹni náà yóò mú ọ̀dọ́ akọ màlúù náà wá pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdajì òsùwọ̀n òróró pò.
Så skall, jämte ungtjuren, såsom spisoffer frambäras tre tiondedels efa fint mjöl, begjutet med en halv in olja,
10 Kí ó tún mú ìdajì òsùwọ̀n wáìnì wá fún ọrẹ ohun mímu. Yóò jẹ́ ọrẹ àfinásun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
och såsom drickoffer skall du bära fram en halv hin vin: ett eldsoffer till en välbehaglig lukt för HERREN.
11 Báyìí ni kí ẹ ṣe pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù tàbí àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí ọmọ ewúrẹ́.
Vad här är sagt skall offras till var tjur, var vädur, vart djur av småboskapen, vare sig får eller get.
12 Ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ fún ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn, iyekíye tí ẹ̀yin ìbá à pèsè.
Efter antalet av de djur I offren skolen I offra till vart och ett vad här är sagt, efter deras antal.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín ni kí ó máa ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà tí ó bá mú ọrẹ àfinásun gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn wá fún Olúwa.
Var inföding skall offra detta, såsom här är sagt, när han vill offra ett eldsoffer till en välbehaglig lukt för HERREN.
14 Bí àlejò kan bá ń gbé láàrín yín ní gbogbo ìran yín, bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá fẹ́ mú ọrẹ àfinásun bí òórùn dídùn wá fún Olúwa, gbogbo bí ẹ bá ṣe ń ṣe náà ni kí ó ṣe.
Och när en främling som vistas hos eder, eller som i kommande släkten bor ibland eder, vill offra ett eldsoffer till en välbehaglig lukt för HERREN, så skall han offra på samma sätt som I offren.
15 Gbogbo ìjọ ènìyàn gbọdọ̀ ní òfin kan náà fún ọmọ bíbí ilẹ̀ yín àti fún àwọn àlejò tó ń gbé láàrín yín, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún àwọn ìran tó ń bọ̀. Ẹ̀yin àti àlejò tó ń gbé láàrín yín sì jẹ́ bákan náà níwájú Olúwa.
Inom församlingen skall en och samma stadga gälla för eder och för främlingen som bor ibland eder. Detta skall vara en evärdlig stadga för eder från släkte till släkte: I själva och främlingen skolen förfara på samma sätt inför HERRENS ansikte.
16 Òfin kan àti ìlànà kan ni yóò wà fún yín àti fún àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín.’”
Samma lag och samma rätt skall gälla för eder och för främlingen som bor hos eder.
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
Och HERREN talade till Mose och sade:
18 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mo ń mú yín lọ.
Tala till Israels barn och säg till dem: När I kommen in i det land dit jag vill föra eder,
19 Tí ẹ sì jẹ oúnjẹ ilẹ̀ náà, ẹ mú nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè wá fún Olúwa.
skolen I, då I äten av landets bröd, giva åt HERREN en offergärd därav.
20 Ẹ mú àkàrà wá nínú àkọ́so oúnjẹ yín wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè sí Olúwa, ọrẹ láti inú ilẹ̀ ìpakà yín.
Såsom förstling av edert mjöl skolen I giva en kaka till offergärd; I skolen giva den, likasom I given en offergärd från eder loge.
21 Nínú àkọ́so oúnjẹ yín ni kí ẹ ti máa mú ọrẹ ìgbésókè yìí fún Olúwa.
Av förstlingen av edert mjöl skolen I giva åt HERREN en offergärd, släkte efter släkte.
22 “‘Bí ẹ bá kùnà láìròtẹ́lẹ̀ láti pa àwọn òfin tí Olúwa fún Mose mọ́,
Och om I begån synd ouppsåtligen, i det att I underlåten att göra efter något av dessa bud som HERREN har kungjort för Mose,
23 èyí ni gbogbo òfin tí Olúwa fún yín láti ẹnu Mose láti ọjọ́ tí Olúwa ti fún yín àti títí dé ìran tó ń bọ̀.
efter något av det som HERRENS har bjudit eder genom Mose, från den dag då HERREN gav sina bud och allt framgent, släkte efter släkte,
24 Bí ẹ̀ṣẹ̀ bá wáyé láìròtẹ́lẹ̀ láìjẹ́ pé ìjọ ènìyàn mọ̀ sí i, nígbà náà ni kí gbogbo ìjọ ènìyàn mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan wá fún ẹbọ sísun bí òórùn dídùn sí Olúwa, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà, pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
så skall, om synden har blivit begången ouppsåtligen, utan att menigheten visste det, hela menigheten offra en ungtjur såsom brännoffer, till en välbehaglig lukt för HERREN, med det spisoffer och det drickoffer som på föreskrivet sätt skall offras därtill, och tillika en bock såsom syndoffer.
25 Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù, fun gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, a ó sì dáríjì wọ́n, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀, wọ́n sì ti mú ọrẹ àfinásun wá fún Olúwa nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀.
Och prästen skall bringa försoning för Israels barns hela menighet, och så bliver dem förlåtet; ty det var en ouppsåtlig synd, och de hava burit fram sitt offer, ett eldsoffer åt HERREN, och sitt syndoffer inför HERRENS ansikte för sin ouppsåtliga synd.
26 A ó dárí jí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn nítorí pé ní àìròtẹ́lẹ̀ ni wọ́n sẹ ẹ̀ṣẹ̀ náà.
Ja, så bliver dem förlåtet, Israels barns hela menighet och främlingen som bor ibland dem; ty hela folket var delaktigt i den ouppsåtliga synden.
27 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ẹnìkan ló sẹ̀ ní àìròtẹ́lẹ̀, kí ó mú abo ewúrẹ́ ọlọ́dún kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Och om någon enskild syndar ouppsåtligen, skall han såsom syndoffer föra fram en årsgammal get.
28 Àlùfáà yóò ṣe ètùtù níwájú Olúwa fún ẹni tó ṣẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, tí wọ́n bá ṣe ètùtù fún un, a ó sì dáríjì í.
Och prästen skall bringa försoning för denne som har försyndat sig genom ouppsåtlig synd, inför HERRENS ansikte; på det att honom må bliva förlåtet, när försoning bringas för honom.
29 Òfin kan kí ẹ̀yin kí ó ní fún ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ̀ ní àìmọ̀, àti fún àwọn ẹni tí a bí nínú àwọn ọmọ Israẹli, àti fún àlejò tí ń ṣe àtìpó.
För infödingen bland Israels barn och för främlingen som bor ibland dem, för eder alla skall gälla en och samma lag, när någon begår synd ouppsåtligen.
30 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ yálà ó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín tàbí àlejò, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti kó ẹ̀gàn bá orúkọ Olúwa, a ó sì gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
Men den som begår något med upplyft hand, evad han är inföding eller främling, han hånar HERREN, och han skall utrotas ur sitt folk.
31 Nítorí pé ẹni náà ti kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa ó sì ti rú òfin rẹ̀, a gbọdọ̀ gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí rẹ̀.’”
Ty HERRENS ord har han föraktat, och mot hans bud har han brutit; utan förskoning skall han utrotas; missgärning vilar på honom.
32 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli wà nínú aginjù, wọ́n rí ọkùnrin kan tí ń ṣá igi ní ọjọ́ Ìsinmi.
Medan nu Israels barn voro i öknen, ertappades en man med att samla ihop ved på sabbatsdagen.
33 Àwọn tó sì rí i níbi tó ti ń ṣá igi wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Aaroni àti síwájú gbogbo ìjọ ènìyàn,
Och de som ertappade honom med att samla ihop ved förde honom fram inför Mose och Aron och hela menigheten.
34 wọ́n fi sí ìpamọ́ nítorí pé ohun tí wọn ó ṣe fún un kò tí ì yé wọn.
Och då det icke var bestämt vad som borde göras med honom, satte de honom i förvar.
35 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Kíkú ni ọkùnrin náà yóò kú kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sọ ọ́ lókùúta pa ní ẹ̀yìn ibùdó.”
Och HERREN sade till Mose: "Mannen skall straffas med döden; hela menigheten skall stena honom utanför lägret."
36 Wọ́n mú un jáde sí ẹ̀yìn ibùdó, gbogbo ìjọ ènìyàn sì sọ ọ́ lókùúta pa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Då förde hela menigheten ut honom utanför lägret och stenade honom till döds, såsom HERREN hade bjudit Mose.
37 Olúwa sọ fún Mose pé,
Och HERREN talade till Mose och sade:
38 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí o sọ fún wọn pé: ‘Títí dé àwọn ìran tó ń bọ̀ ni kí wọn máa ṣe wajawaja sí etí aṣọ wọn, kí wọn sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ aláwọ̀ búlúù sí wajawaja kọ̀ọ̀kan.
Tala till Israels barn och säg till dem att de och deras efterkommande skola göra sig tofsar i hörnen på sina kläder och sätta ett mörkblått snöre på var hörntofs.
39 Wajawaja yìí ni ẹ sì máa wọ̀ láti lè mú yín rántí gbogbo òfin Olúwa, kí ẹ bá à lè ṣe wọ́n, kí ẹ sì má bá à ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn àti ojú yín.
Och detta skolen I hava till tofsprydnad, för att I, när I sen därpå, mån tänka på alla HERRENS bud och göra efter dem, och icke sväva omkring efter edra hjärtans och ögons lustar, som I nu löpen efter i trolös avfällighet.
40 Nígbà náà ni ẹ ó gbọ́rọ̀ láti pa gbogbo òfin mi mọ́, ẹ ó sì jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run yín.
Ty jag vill att I skolen tänka på och göra efter alla mina bud och vara helgade åt eder Gud.
41 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti Ejibiti láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Jag är HERREN, eder Gud, som har fört eder ut ur Egyptens land, för att jag skall vara eder Gud Jag är HERREN, eder Gud.

< Numbers 15 >