< Numbers 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh falou a Moisés, dizendo:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi ó fún yin gẹ́gẹ́ bí ibùgbé
“Fale aos filhos de Israel, e diga-lhes: 'Quando vocês entrarem na terra de suas habitações, que eu lhes dou,
3 tí ẹ̀yin ó bá sì ṣe ẹbọ iná sí Olúwa ẹbọ sísun, tàbí ẹbọ, láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí ọrẹ àtinúwá, tàbí nínú àjọ yín, láti ṣe òórùn dídùn sí Olúwa nínú agbo ẹran tàbí ọ̀wọ́ ẹran,
e fizerem uma oferta pelo fogo a Yahweh - uma oferta queimada, ou um sacrifício, para cumprir um voto', ou como uma oferta de livre vontade, ou em suas festas de conjunto, para fazer um aroma agradável a Javé, do rebanho, ou do rebanho -
4 nígbà náà ni kí ẹni tí ó bá mú ọrẹ rẹ̀ wá, yóò tún mú ẹbọ ohun jíjẹ ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná pẹ̀lú ìdámẹ́rin òsùwọ̀n òróró wá síwájú Olúwa.
então aquele que oferecer sua oferta oferecerá a Javé uma oferta de refeição de um décimo de um efa de farinha fina misturada com um quarto de um him de óleo.
5 Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan yálà fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun ni, kí ẹ pèsè ìdámẹ́rin òsùwọ̀n wáìnì gẹ́gẹ́ bí ohun mímu.
preparará vinho para a oferta de bebida, um quarto de um him, com a oferta queimada ou para o sacrifício, para cada cordeiro.
6 “‘Fún àgbò kan ni kí ẹ pèsè ọrẹ ohun jíjẹ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n òróró pò.
“'Para um carneiro, você se preparará para uma refeição oferecendo dois décimos de uma efa de farinha fina misturada com a terceira parte de um him de azeite;
7 Àti ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n wáìnì fún ọrẹ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa.
e para a oferta de bebida você oferecerá a terceira parte de um him de vinho, de aroma agradável a Yahweh.
8 “‘Nígbà tí ẹ bá sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun, láti fi san ẹ̀jẹ́ tàbí fún ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa,
Quando você preparar um touro para uma oferta queimada ou para um sacrifício, para cumprir um voto, ou para ofertas de paz a Iavé,
9 ẹni náà yóò mú ọ̀dọ́ akọ màlúù náà wá pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdajì òsùwọ̀n òróró pò.
então oferecerá com o touro uma oferta de refeição de três décimos de um efa de farinha fina misturada com meia parte de um hino de óleo;
10 Kí ó tún mú ìdajì òsùwọ̀n wáìnì wá fún ọrẹ ohun mímu. Yóò jẹ́ ọrẹ àfinásun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
e oferecerá pela oferta de bebida metade de um hino de vinho, por uma oferta feita pelo fogo, de aroma agradável a Iavé.
11 Báyìí ni kí ẹ ṣe pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù tàbí àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí ọmọ ewúrẹ́.
Assim será feito para cada touro, para cada carneiro, para cada um dos cordeiros machos, ou dos cabritos jovens.
12 Ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ fún ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn, iyekíye tí ẹ̀yin ìbá à pèsè.
De acordo com o número que você deve preparar, assim você deve fazer a todos de acordo com seu número.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín ni kí ó máa ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà tí ó bá mú ọrẹ àfinásun gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn wá fún Olúwa.
“'Todos os nativos devem fazer estas coisas desta maneira, oferecendo uma oferta feita pelo fogo, de um aroma agradável a Iavé.
14 Bí àlejò kan bá ń gbé láàrín yín ní gbogbo ìran yín, bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá fẹ́ mú ọrẹ àfinásun bí òórùn dídùn wá fún Olúwa, gbogbo bí ẹ bá ṣe ń ṣe náà ni kí ó ṣe.
Se um estrangeiro viver como estrangeiro com você, ou quem quer que esteja entre vocês através de suas gerações, e oferecer uma oferta feita pelo fogo, de aroma agradável a Iavé, como você faz, assim ele fará.
15 Gbogbo ìjọ ènìyàn gbọdọ̀ ní òfin kan náà fún ọmọ bíbí ilẹ̀ yín àti fún àwọn àlejò tó ń gbé láàrín yín, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún àwọn ìran tó ń bọ̀. Ẹ̀yin àti àlejò tó ń gbé láàrín yín sì jẹ́ bákan náà níwájú Olúwa.
Para a assembléia, haverá um estatuto para você e para o estrangeiro que vive como estrangeiro, um estatuto para sempre ao longo de suas gerações. Como você é, assim o estrangeiro estará perante Iavé.
16 Òfin kan àti ìlànà kan ni yóò wà fún yín àti fún àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín.’”
Uma lei e uma portaria serão para você e para o estrangeiro que vive como estrangeiro com você”.
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
Javé falou a Moisés, dizendo:
18 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mo ń mú yín lọ.
“Fala aos filhos de Israel, e diz-lhes: 'Quando entrardes na terra onde eu vos trago,
19 Tí ẹ sì jẹ oúnjẹ ilẹ̀ náà, ẹ mú nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè wá fún Olúwa.
então será que quando comerdes do pão da terra, oferecereis uma oferta de onda a Javé'.
20 Ẹ mú àkàrà wá nínú àkọ́so oúnjẹ yín wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè sí Olúwa, ọrẹ láti inú ilẹ̀ ìpakà yín.
da primeira de sua massa, você oferecerá um bolo para uma oferta de ondas. Como a oferta de onda da eira, assim você a oferecerá.
21 Nínú àkọ́so oúnjẹ yín ni kí ẹ ti máa mú ọrẹ ìgbésókè yìí fún Olúwa.
Da primeira de sua massa, você oferecerá a Iavé uma oferta de onda através de suas gerações.
22 “‘Bí ẹ bá kùnà láìròtẹ́lẹ̀ láti pa àwọn òfin tí Olúwa fún Mose mọ́,
“'Quando você errar, e não observar todos estes mandamentos que Javé falou a Moisés -
23 èyí ni gbogbo òfin tí Olúwa fún yín láti ẹnu Mose láti ọjọ́ tí Olúwa ti fún yín àti títí dé ìran tó ń bọ̀.
mesmo tudo o que Javé lhe ordenou por Moisés, desde o dia em que Javé lhe deu o mandamento e em diante através de sua geração -
24 Bí ẹ̀ṣẹ̀ bá wáyé láìròtẹ́lẹ̀ láìjẹ́ pé ìjọ ènìyàn mọ̀ sí i, nígbà náà ni kí gbogbo ìjọ ènìyàn mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan wá fún ẹbọ sísun bí òórùn dídùn sí Olúwa, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà, pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
então será, se foi feito involuntariamente, sem o conhecimento da congregação, que toda a congregação oferecerá um touro jovem para uma oferta queimada, para um aroma agradável a Iavé, com sua oferta de refeição e sua oferta de bebida, de acordo com a ordenança, e um bode macho para uma oferta pelo pecado.
25 Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù, fun gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, a ó sì dáríjì wọ́n, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀, wọ́n sì ti mú ọrẹ àfinásun wá fún Olúwa nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀.
O sacerdote fará expiação por toda a congregação dos filhos de Israel, e eles serão perdoados; pois foi um erro, e eles trouxeram sua oferta, uma oferta feita pelo fogo a Javé, e sua oferta pelo pecado diante de Javé, por seu erro.
26 A ó dárí jí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn nítorí pé ní àìròtẹ́lẹ̀ ni wọ́n sẹ ẹ̀ṣẹ̀ náà.
Toda a congregação dos filhos de Israel será perdoada, assim como o estrangeiro que vive como estrangeiro entre eles; pois em relação a todo o povo, isso foi feito involuntariamente.
27 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ẹnìkan ló sẹ̀ ní àìròtẹ́lẹ̀, kí ó mú abo ewúrẹ́ ọlọ́dún kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
“'Se uma pessoa pecar involuntariamente, então deve oferecer uma cabra de um ano de idade por uma oferta pelo pecado.
28 Àlùfáà yóò ṣe ètùtù níwájú Olúwa fún ẹni tó ṣẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, tí wọ́n bá ṣe ètùtù fún un, a ó sì dáríjì í.
O sacerdote fará expiação pela alma que erra quando peca involuntariamente diante de Yahweh. Ele fará expiação por ele; e ele será perdoado.
29 Òfin kan kí ẹ̀yin kí ó ní fún ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ̀ ní àìmọ̀, àti fún àwọn ẹni tí a bí nínú àwọn ọmọ Israẹli, àti fún àlejò tí ń ṣe àtìpó.
Tereis uma lei para aquele que faz qualquer coisa involuntariamente, para aquele que nasceu entre os filhos de Israel, e para o estrangeiro que vive como estrangeiro entre eles.
30 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ yálà ó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín tàbí àlejò, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti kó ẹ̀gàn bá orúkọ Olúwa, a ó sì gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
“'Mas a alma que faz qualquer coisa com mão alta, quer seja nativa ou estrangeira, blasfema Yahweh. Essa alma será cortada do meio de seu povo.
31 Nítorí pé ẹni náà ti kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa ó sì ti rú òfin rẹ̀, a gbọdọ̀ gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí rẹ̀.’”
Por ter desprezado a palavra de Javé, e por ter violado seu mandamento, essa alma será totalmente extirpada. Sua iniqüidade estará sobre ele”.
32 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli wà nínú aginjù, wọ́n rí ọkùnrin kan tí ń ṣá igi ní ọjọ́ Ìsinmi.
Enquanto as crianças de Israel estavam no deserto, eles encontraram um homem juntando paus no dia de sábado.
33 Àwọn tó sì rí i níbi tó ti ń ṣá igi wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Aaroni àti síwájú gbogbo ìjọ ènìyàn,
Aqueles que o encontraram reunindo paus o trouxeram a Moisés e Aarão, e a toda a congregação.
34 wọ́n fi sí ìpamọ́ nítorí pé ohun tí wọn ó ṣe fún un kò tí ì yé wọn.
Eles o colocaram sob custódia, porque não havia sido declarado o que deveria ser feito com ele.
35 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Kíkú ni ọkùnrin náà yóò kú kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sọ ọ́ lókùúta pa ní ẹ̀yìn ibùdó.”
Yahweh disse a Moisés: “O homem certamente será condenado à morte. Toda a congregação o apedrejará fora do acampamento”.
36 Wọ́n mú un jáde sí ẹ̀yìn ibùdó, gbogbo ìjọ ènìyàn sì sọ ọ́ lókùúta pa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Toda a congregação o levou para fora do acampamento e o apedrejou até a morte, como Yahweh ordenou a Moisés.
37 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh falou com Moisés, dizendo:
38 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí o sọ fún wọn pé: ‘Títí dé àwọn ìran tó ń bọ̀ ni kí wọn máa ṣe wajawaja sí etí aṣọ wọn, kí wọn sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ aláwọ̀ búlúù sí wajawaja kọ̀ọ̀kan.
“Fale com os filhos de Israel, e diga-lhes que eles devem fazer-se franjas nas bordas de suas vestes através de suas gerações, e que eles coloquem na franja de cada fronteira um cordão de azul.
39 Wajawaja yìí ni ẹ sì máa wọ̀ láti lè mú yín rántí gbogbo òfin Olúwa, kí ẹ bá à lè ṣe wọ́n, kí ẹ sì má bá à ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn àti ojú yín.
Será para vocês uma franja, para que possam vê-la e lembrar-se de todos os mandamentos de Javé e cumpri-los; e para que não sigam seu próprio coração e seus próprios olhos, depois do que costumavam fazer de prostituta;
40 Nígbà náà ni ẹ ó gbọ́rọ̀ láti pa gbogbo òfin mi mọ́, ẹ ó sì jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run yín.
para que possam lembrar-se e cumprir todos os meus mandamentos, e serem santos para seu Deus.
41 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti Ejibiti láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Eu sou Yahweh, vosso Deus, que vos tirou da terra do Egito, para ser vosso Deus: Eu sou Yahweh, vosso Deus”.

< Numbers 15 >