< Numbers 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
I rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi ó fún yin gẹ́gẹ́ bí ibùgbé
Powiedz synom Izraelskim, a mów do nich: Gdy przyjdziecie do ziemi mieszkania waszego, którą Ja wam dam,
3 tí ẹ̀yin ó bá sì ṣe ẹbọ iná sí Olúwa ẹbọ sísun, tàbí ẹbọ, láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí ọrẹ àtinúwá, tàbí nínú àjọ yín, láti ṣe òórùn dídùn sí Olúwa nínú agbo ẹran tàbí ọ̀wọ́ ẹran,
A będziecie chcieli czynić ofiarę ognistą Panu na całopalenie, albo ofiarę, bądź poślubioną bądź dobrowolną, albo też na uroczyste święta wasze, czyniąc wdzięczną wonność Panu z wołów albo z owiec:
4 nígbà náà ni kí ẹni tí ó bá mú ọrẹ rẹ̀ wá, yóò tún mú ẹbọ ohun jíjẹ ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná pẹ̀lú ìdámẹ́rin òsùwọ̀n òróró wá síwájú Olúwa.
Tedy, ktobykolwiek ofiarował ofiarę swoję Panu, niechże ofiaruje ofiarę śniedną, pszennej mąki dziesiątą część, zagniecionej z oliwą, której będzie czwarta część hynu.
5 Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan yálà fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun ni, kí ẹ pèsè ìdámẹ́rin òsùwọ̀n wáìnì gẹ́gẹ́ bí ohun mímu.
Przytem wina na ofiarę mokrą czwartą część hynu ofiarować będziesz przy całopaleniu, albo przy ofierze innej do każdego baranka.
6 “‘Fún àgbò kan ni kí ẹ pèsè ọrẹ ohun jíjẹ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n òróró pò.
Przy baranie też ofiarować będziesz ofiarę śniedną, mąki pszennej dwie dziesiąte części, zaczynionej z oliwą z trzecią częścią hynu.
7 Àti ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n wáìnì fún ọrẹ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa.
Wina także na ofiarę mokrą trzecią część hynu ofiarować będziesz na wdzięczną wonność Panu.
8 “‘Nígbà tí ẹ bá sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun, láti fi san ẹ̀jẹ́ tàbí fún ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa,
Jeźli zaś cielca ofiarować będziesz na ofiarę całopalenia, albo na ofiarę wypełnienia ślubu, albo na ofiarę spokojną Panu,
9 ẹni náà yóò mú ọ̀dọ́ akọ màlúù náà wá pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdajì òsùwọ̀n òróró pò.
Tedy będziesz ofiarował społem z cielcem ofiarę śniedną, pszennej mąki trzy dziesiąte części, zagniecionej z oliwą z połową hynu.
10 Kí ó tún mú ìdajì òsùwọ̀n wáìnì wá fún ọrẹ ohun mímu. Yóò jẹ́ ọrẹ àfinásun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
Wina także będziesz ofiarował na ofiarę mokrą połowę hynu, na ofiarę ognistą ku wdzięcznej wonności Panu.
11 Báyìí ni kí ẹ ṣe pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù tàbí àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí ọmọ ewúrẹ́.
Także uczynisz przy każdym wole, i przy każdym baranie i baranku, bądź z owiec bądź z kóz.
12 Ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ fún ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn, iyekíye tí ẹ̀yin ìbá à pèsè.
Według liczby, którą ofiarować będziecie, tak uczynicie przy każdym z nich według liczby ich.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín ni kí ó máa ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà tí ó bá mú ọrẹ àfinásun gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn wá fún Olúwa.
Każdy w domu zrodzony tak też będzie czynił, gdy będzie oddawał ofiarę ognistą na wdzięczną wonność Panu.
14 Bí àlejò kan bá ń gbé láàrín yín ní gbogbo ìran yín, bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá fẹ́ mú ọrẹ àfinásun bí òórùn dídùn wá fún Olúwa, gbogbo bí ẹ bá ṣe ń ṣe náà ni kí ó ṣe.
A gdyby, gościem będąc między wami przychodzień, albo mieszkający między wami w narodziech waszych, ofiarował ognistą ofiarę ku wdzięcznej wonności Panu, jako wy czynicie, tak i on uczyni.
15 Gbogbo ìjọ ènìyàn gbọdọ̀ ní òfin kan náà fún ọmọ bíbí ilẹ̀ yín àti fún àwọn àlejò tó ń gbé láàrín yín, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún àwọn ìran tó ń bọ̀. Ẹ̀yin àti àlejò tó ń gbé láàrín yín sì jẹ́ bákan náà níwájú Olúwa.
O ludu mój! Ustawa jedna niechaj będzie tak wam, jako i przychodniowi, mieszkającemu z wami; ustawa to jest wieczna w narodziech waszych; jako wy, tak przychodzień będzie przed Panem.
16 Òfin kan àti ìlànà kan ni yóò wà fún yín àti fún àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín.’”
Prawo jedno, i jeden sąd będzie wam i przychodniowi mieszkającemu z wami.
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
I rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
18 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mo ń mú yín lọ.
Powiedz synom Izraelskim, a rzecz do nich: Gdy wnijdziecie do ziemi, do której Ja was wprowadzę:
19 Tí ẹ sì jẹ oúnjẹ ilẹ̀ náà, ẹ mú nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè wá fún Olúwa.
A jeść będziecie chleb onej ziemi, ofiarować będziecie ofiarę podnoszenia Panu.
20 Ẹ mú àkàrà wá nínú àkọ́so oúnjẹ yín wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè sí Olúwa, ọrẹ láti inú ilẹ̀ ìpakà yín.
Z pierwszych ciast waszych placek ofiarować będziecie na ofiarę podnoszenia; jako ofiarę z bojewiska, tak go ofiarować będziecie.
21 Nínú àkọ́so oúnjẹ yín ni kí ẹ ti máa mú ọrẹ ìgbésókè yìí fún Olúwa.
Z pierwszych ciast waszych ofiarować będziecie Panu ofiarę podnoszenia w narodziech waszych.
22 “‘Bí ẹ bá kùnà láìròtẹ́lẹ̀ láti pa àwọn òfin tí Olúwa fún Mose mọ́,
A gdybyście pobłądzili, i nie uczynilibyście wszystkich przykazań tych, które rozkazał Pan przez Mojżesza;
23 èyí ni gbogbo òfin tí Olúwa fún yín láti ẹnu Mose láti ọjọ́ tí Olúwa ti fún yín àti títí dé ìran tó ń bọ̀.
Wszystkiego, co wam Pan rozkazał przez Mojżesza, od onego dnia, którego wydał Pan przykazanie, i potem w narodziech waszych:
24 Bí ẹ̀ṣẹ̀ bá wáyé láìròtẹ́lẹ̀ láìjẹ́ pé ìjọ ènìyàn mọ̀ sí i, nígbà náà ni kí gbogbo ìjọ ènìyàn mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan wá fún ẹbọ sísun bí òórùn dídùn sí Olúwa, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà, pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Tedy jeźliby z niewiadomości zgromadzenia stało się to pobłądzenie, wszystko zgromadzenie ofiarować będzie cielca młodego jednego na całopalenie, na wdzięczną wonność Panu, także śniedną ofiarę jego, i mokrą ofiarę jego według zwyczaju, i kozła jednego z stada za grzech.
25 Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù, fun gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, a ó sì dáríjì wọ́n, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀, wọ́n sì ti mú ọrẹ àfinásun wá fún Olúwa nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀.
Tak oczyści kapłan wszystko zgromadzenie synów Izraelskich, i będzie im odpuszczona, gdyż się z niewiadomości stało. A oni ofiarować będą ofiarę swoję na ofiarę ognistą Panu, i na ofiarę za grzech swój przed Panem za obłądzenie swoje.
26 A ó dárí jí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn nítorí pé ní àìròtẹ́lẹ̀ ni wọ́n sẹ ẹ̀ṣẹ̀ náà.
I będzie odpuszczono wszystkiemu zgromadzeniu synów Izraelskich, i przychodniowi, który mieszka między nimi, ponieważ wszystkiego ludu pobłądzenie jest.
27 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ẹnìkan ló sẹ̀ ní àìròtẹ́lẹ̀, kí ó mú abo ewúrẹ́ ọlọ́dún kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
A jeźliby kto sam tylko zgrzeszył z niewiadomości, tedy przyniesie Panu kozę roczną na ofiarę za grzech;
28 Àlùfáà yóò ṣe ètùtù níwájú Olúwa fún ẹni tó ṣẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, tí wọ́n bá ṣe ètùtù fún un, a ó sì dáríjì í.
I oczyści kapłan człowieka obłądzonego, któryby zgrzeszył z niewiadomości; przed Panem oczyści go, i będzie mu odpuszczono.
29 Òfin kan kí ẹ̀yin kí ó ní fún ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ̀ ní àìmọ̀, àti fún àwọn ẹni tí a bí nínú àwọn ọmọ Israẹli, àti fún àlejò tí ń ṣe àtìpó.
Tak zrodzonemu między synami Izraelskimi, jako przychodniowi, który mieszka między nimi, zakon jeden będzie wam, gdyby kto zgrzeszył z niewiadomości.
30 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ yálà ó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín tàbí àlejò, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti kó ẹ̀gàn bá orúkọ Olúwa, a ó sì gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ale człowiek, któryby z hardości swawolnie zgrzeszył, tak urodzony w domu, jako i przychodzień, takowy Pana zelżył; przetoż wykorzeniony będzie on człowiek z pośrodku ludu swego.
31 Nítorí pé ẹni náà ti kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa ó sì ti rú òfin rẹ̀, a gbọdọ̀ gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí rẹ̀.’”
Albowiem słowem Pańskiem pogardził, i przykazanie jego zgwałcił; koniecznie wytracony będzie takowy człowiek; nieprawość jego na nim zostanie.
32 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli wà nínú aginjù, wọ́n rí ọkùnrin kan tí ń ṣá igi ní ọjọ́ Ìsinmi.
I stało się, gdy byli synowie Izraelscy na puszczy, że znaleźli człowieka zbierającego drwa w dzień sabatu.
33 Àwọn tó sì rí i níbi tó ti ń ṣá igi wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Aaroni àti síwájú gbogbo ìjọ ènìyàn,
I przywiedli go, którzy go znaleźli zbierającego drwa, przed Mojżesza, i przed Aarona, i przed wszystko zgromadzenie.
34 wọ́n fi sí ìpamọ́ nítorí pé ohun tí wọn ó ṣe fún un kò tí ì yé wọn.
I dali go do więzienia; bo jeszcze im nie było oznajmiono, coby miano czynić z takowym.
35 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Kíkú ni ọkùnrin náà yóò kú kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sọ ọ́ lókùúta pa ní ẹ̀yìn ibùdó.”
Tedy rzekł Pan do Mojżesza: śmiercią niech umrze człowiek ten; bez litości niechaj go ukamionuje wszystko zgromadzenie za obozem.
36 Wọ́n mú un jáde sí ẹ̀yìn ibùdó, gbogbo ìjọ ènìyàn sì sọ ọ́ lókùúta pa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
I wywiedli go wszystko zgromadzenie za obóz, i ciskali nań kamieniem, aż umarł, jako rozkazał Pan Mojżeszowi.
37 Olúwa sọ fún Mose pé,
Zatem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
38 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí o sọ fún wọn pé: ‘Títí dé àwọn ìran tó ń bọ̀ ni kí wọn máa ṣe wajawaja sí etí aṣọ wọn, kí wọn sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ aláwọ̀ búlúù sí wajawaja kọ̀ọ̀kan.
Mów do synów Izraelskich, a powiedz im, aby sobie poczynili bramy na krajach szat swoich w narodziech swych, a niech przyprawią do bram sznurek hijacyntowy.
39 Wajawaja yìí ni ẹ sì máa wọ̀ láti lè mú yín rántí gbogbo òfin Olúwa, kí ẹ bá à lè ṣe wọ́n, kí ẹ sì má bá à ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn àti ojú yín.
I będziecie mieli te bramy, żebyście poglądając na nie, wspominali sobie na wszystkie przykazania Pańskie, abyście je czynili, i abyście się nie unosili za sercem waszem, i za oczyma waszemi, za któremi wy idąc cudzołożylibyście.
40 Nígbà náà ni ẹ ó gbọ́rọ̀ láti pa gbogbo òfin mi mọ́, ẹ ó sì jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run yín.
Ale żebyście pamiętali i czynili wszystkie przykazania moje, a byli świętymi Bogu waszemu.
41 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti Ejibiti láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Ja Pan, Bóg wasz, którym was wywiódł z ziemi Egipskiej, abym wam był za Boga; Jam Pan, Bóg wasz.

< Numbers 15 >