< Numbers 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
و خداوند موسی را خطاب کرده، گفت:۱
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi ó fún yin gẹ́gẹ́ bí ibùgbé
«بنی‌اسرائیل را خطاب کرده، به ایشان بگو: چون به زمین سکونت خود که من آن را به شما می‌دهم داخل شوید،۲
3 tí ẹ̀yin ó bá sì ṣe ẹbọ iná sí Olúwa ẹbọ sísun, tàbí ẹbọ, láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí ọrẹ àtinúwá, tàbí nínú àjọ yín, láti ṣe òórùn dídùn sí Olúwa nínú agbo ẹran tàbí ọ̀wọ́ ẹran,
و می‌خواهیدهدیه آتشین برای خداوند بگذرانید، چه قربانی سوختنی و چه ذبیحه وفای نذر، یا برای نافله یادر عیدهای خود، برای گذرانیدن هدیه خوشبوبجهت خداوند، خواه از رمه و خواه از گله،۳
4 nígbà náà ni kí ẹni tí ó bá mú ọrẹ rẹ̀ wá, yóò tún mú ẹbọ ohun jíjẹ ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná pẹ̀lú ìdámẹ́rin òsùwọ̀n òróró wá síwájú Olúwa.
آنگاه کسی‌که هدیه خود را می‌گذراند، برای هدیه آردی یک عشر ایفه آرد نرم مخلوط شده بایک ربع هین روغن بجهت خداوند بگذراند.۴
5 Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan yálà fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun ni, kí ẹ pèsè ìdámẹ́rin òsùwọ̀n wáìnì gẹ́gẹ́ bí ohun mímu.
وبرای هدیه ریختنی یک ربع هین شراب با قربانی سوختنی یا برای ذبیحه بجهت هر بره حاضرکن.۵
6 “‘Fún àgbò kan ni kí ẹ pèsè ọrẹ ohun jíjẹ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n òróró pò.
«یا بجهت قوچ برای هدیه آردی دو عشرایفه آرد نرم مخلوط شده با یک ثلث هین روغن حاضرکن.۶
7 Àti ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n wáìnì fún ọrẹ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa.
و بجهت هدیه ریختنی یک ثلث هین شراب برای خوشبویی بجهت خداوندحاضرکن.۷
8 “‘Nígbà tí ẹ bá sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun, láti fi san ẹ̀jẹ́ tàbí fún ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa,
«و چون گاوی برای قربانی سوختنی یاذبیحه‌ای برای ادای نذر یا برای ذبیحه سلامتی بجهت خداوند حاضر می‌کنی،۸
9 ẹni náà yóò mú ọ̀dọ́ akọ màlúù náà wá pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdajì òsùwọ̀n òróró pò.
آنگاه بجهت هدیه آردی، سه عشر آرد نرم مخلوط شده بانصف هین روغن با گاو بگذراند.۹
10 Kí ó tún mú ìdajì òsùwọ̀n wáìnì wá fún ọrẹ ohun mímu. Yóò jẹ́ ọrẹ àfinásun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
و برای هدیه ریختنی نصف هین شراب بگذران تا هدیه آتشین خوشبو برای خداوند بشود.۱۰
11 Báyìí ni kí ẹ ṣe pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù tàbí àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí ọmọ ewúrẹ́.
«همچنین برای هر گاو و برای هر قوچ وبرای هر بره نرینه و هر بزغاله کرده شود.۱۱
12 Ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ fún ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn, iyekíye tí ẹ̀yin ìbá à pèsè.
برحسب شماره‌ای که حاضر کنید بدین قسم برای هریک، موافق شماره آنها عمل نمایید.۱۲
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín ni kí ó máa ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà tí ó bá mú ọrẹ àfinásun gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn wá fún Olúwa.
«هر متوطن چون هدیه آتشین خوشبو برای خداوند می‌گذراند، این اوامر را به اینطور بجابیاورد.۱۳
14 Bí àlejò kan bá ń gbé láàrín yín ní gbogbo ìran yín, bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá fẹ́ mú ọrẹ àfinásun bí òórùn dídùn wá fún Olúwa, gbogbo bí ẹ bá ṣe ń ṣe náà ni kí ó ṣe.
و اگر غریبی که در میان شما ماواگزیند، هرکه در قرنهای شما در میان شما باشد، می‌خواهد هدیه آتشین خوشبو برای خداوندبگذراند، به نوعی که شما عمل می‌نمایید، او نیزعمل نماید.۱۴
15 Gbogbo ìjọ ènìyàn gbọdọ̀ ní òfin kan náà fún ọmọ bíbí ilẹ̀ yín àti fún àwọn àlejò tó ń gbé láàrín yín, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún àwọn ìran tó ń bọ̀. Ẹ̀yin àti àlejò tó ń gbé láàrín yín sì jẹ́ bákan náà níwájú Olúwa.
برای شما که اهل جماعت هستیدو برای غریبی که نزد شما ماوا گزیند یک فریضه باشد، فریضه ابدی در نسلهای شما؛ مثل شما به حضور خداوند مثل غریب است.۱۵
16 Òfin kan àti ìlànà kan ni yóò wà fún yín àti fún àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín.’”
یک قانون ویک حکم برای شما و برای غریبی که در میان شما ماوا گزیند، خواهد بود.»۱۶
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
و خداوند موسی را خطاب کرده، گفت:۱۷
18 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mo ń mú yín lọ.
«بنی‌اسرائیل را خطاب کرده، به ایشان بگو: چون به زمینی که من شما را در آن درمی آورم داخل شوید،۱۸
19 Tí ẹ sì jẹ oúnjẹ ilẹ̀ náà, ẹ mú nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè wá fún Olúwa.
و از محصول زمین بخورید، آنگاه هدیه افراشتنی برای خداوند بگذرانید.۱۹
20 Ẹ mú àkàrà wá nínú àkọ́so oúnjẹ yín wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè sí Olúwa, ọrẹ láti inú ilẹ̀ ìpakà yín.
از خمیر اول خود گرده‌ای بجهت هدیه افراشتنی بگذرانید؛ مثل هدیه افراشتنی خرمن، همچنان آن را بگذرانید.۲۰
21 Nínú àkọ́so oúnjẹ yín ni kí ẹ ti máa mú ọrẹ ìgbésókè yìí fún Olúwa.
از خمیر اول خود، هدیه افراشتنی در قرنهای خود برای خداوند بگذرانید.۲۱
22 “‘Bí ẹ bá kùnà láìròtẹ́lẹ̀ láti pa àwọn òfin tí Olúwa fún Mose mọ́,
«و هرگاه سهو خطا کرده، جمیع این اوامررا که خداوند به موسی گفته است، بجا نیاورده باشید،۲۲
23 èyí ni gbogbo òfin tí Olúwa fún yín láti ẹnu Mose láti ọjọ́ tí Olúwa ti fún yín àti títí dé ìran tó ń bọ̀.
یعنی هرچه خداوند به واسطه موسی شما را امر فرمود، از روزی که خداوند امر فرمودو از آن به بعد در قرنهای شما.۲۳
24 Bí ẹ̀ṣẹ̀ bá wáyé láìròtẹ́lẹ̀ láìjẹ́ pé ìjọ ènìyàn mọ̀ sí i, nígbà náà ni kí gbogbo ìjọ ènìyàn mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan wá fún ẹbọ sísun bí òórùn dídùn sí Olúwa, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà, pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
پس اگر این کارسهو و بدون اطلاع جماعت کرده شد، آنگاه تمامی جماعت یک گاو جوان برای قربانی سوختنی و خوشبویی بجهت خداوند با هدیه آردی و هدیه ریختنی آن، موافق رسم بگذرانند، و یک بز نر بجهت قربانی گناه.۲۴
25 Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù, fun gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, a ó sì dáríjì wọ́n, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀, wọ́n sì ti mú ọrẹ àfinásun wá fún Olúwa nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀.
و کاهن برای تمامی جماعت بنی‌اسرائیل کفاره نماید، و ایشان آمرزیده خواهندشد، زیراکه آن کار سهو شده است، و ایشان قربانی خود را بجهت هدیه آتشین خداوند و قربانی گناه خود را بجهت سهوخویش، به حضور خداوند گذرانیده‌اند.۲۵
26 A ó dárí jí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn nítorí pé ní àìròtẹ́lẹ̀ ni wọ́n sẹ ẹ̀ṣẹ̀ náà.
وتمامی جماعت بنی‌اسرائیل و غریبی که در میان ایشان ساکن باشد، آمرزیده خواهند شد، زیراکه به تمامی جماعت سهو شده بود.۲۶
27 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ẹnìkan ló sẹ̀ ní àìròtẹ́lẹ̀, kí ó mú abo ewúrẹ́ ọlọ́dún kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
«و اگر یک نفر سهو خطا کرده باشد، آنگاه بز ماده‌یک ساله برای قربانی گناه بگذراند.۲۷
28 Àlùfáà yóò ṣe ètùtù níwájú Olúwa fún ẹni tó ṣẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, tí wọ́n bá ṣe ètùtù fún un, a ó sì dáríjì í.
وکاهن بجهت آن کسی‌که سهو کرده است چونکه خطای او از نادانستگی بود، به حضور خداوندکفاره کند تا بجهت وی کفاره بشود و آمرزیده خواهد شد.۲۸
29 Òfin kan kí ẹ̀yin kí ó ní fún ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ̀ ní àìmọ̀, àti fún àwọn ẹni tí a bí nínú àwọn ọmọ Israẹli, àti fún àlejò tí ń ṣe àtìpó.
بجهت کسی‌که سهو خطا کند، خواه متوطنی از بنی‌اسرائیل و خواه غریبی که در میان ایشان ساکن باشد، یک قانون خواهدبود.۲۹
30 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ yálà ó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín tàbí àlejò, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti kó ẹ̀gàn bá orúkọ Olúwa, a ó sì gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
«و اما کسی‌که به‌دست بلند عمل نماید، چه متوطن و چه غریب، او به خداوند کفر کرده باشد، پس آن شخص از میان قوم خود منقطع خواهد شد.۳۰
31 Nítorí pé ẹni náà ti kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa ó sì ti rú òfin rẹ̀, a gbọdọ̀ gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí rẹ̀.’”
چونکه کلام خداوند را حقیرشمرده، حکم او را شکسته است، آن کس البته منقطع شود و گناهش بر وی خواهد بود.»۳۱
32 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli wà nínú aginjù, wọ́n rí ọkùnrin kan tí ń ṣá igi ní ọjọ́ Ìsinmi.
و چون بنی‌اسرائیل در صحرا بودند، کسی را یافتند که در روز سبت هیزم جمع می‌کرد.۳۲
33 Àwọn tó sì rí i níbi tó ti ń ṣá igi wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Aaroni àti síwájú gbogbo ìjọ ènìyàn,
وکسانی که او را یافتند که هیزم جمع می‌کرد، او رانزد موسی و هارون و تمامی جماعت آوردند.۳۳
34 wọ́n fi sí ìpamọ́ nítorí pé ohun tí wọn ó ṣe fún un kò tí ì yé wọn.
و او را در حبس نگاه داشتند، زیراکه اعلام نشده بود که با وی چه باید کرد.۳۴
35 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Kíkú ni ọkùnrin náà yóò kú kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sọ ọ́ lókùúta pa ní ẹ̀yìn ibùdó.”
و خداوند به موسی گفت: «این شخص البته کشته شود، تمامی جماعت او را بیرون از لشکرگاه با سنگها سنگسارکنند.»۳۵
36 Wọ́n mú un jáde sí ẹ̀yìn ibùdó, gbogbo ìjọ ènìyàn sì sọ ọ́ lókùúta pa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
پس تمامی جماعت او را بیرون ازلشکرگاه آورده، او را سنگسار کردند و بمرد، چنانکه خداوند به موسی‌امر کرده بود.۳۶
37 Olúwa sọ fún Mose pé,
و خداوند موسی را خطاب کرده، گفت:۳۷
38 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí o sọ fún wọn pé: ‘Títí dé àwọn ìran tó ń bọ̀ ni kí wọn máa ṣe wajawaja sí etí aṣọ wọn, kí wọn sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ aláwọ̀ búlúù sí wajawaja kọ̀ọ̀kan.
«بنی‌اسرائیل را خطاب کرده، به ایشان بگو که: برای خود بر گوشه های رخت خویش در قرنهای خود صیصیت بسازند و رشته لاجوردی بر هرگوشه صیصیت بگذارند.۳۸
39 Wajawaja yìí ni ẹ sì máa wọ̀ láti lè mú yín rántí gbogbo òfin Olúwa, kí ẹ bá à lè ṣe wọ́n, kí ẹ sì má bá à ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn àti ojú yín.
و بجهت شماصیصیت خواهد بود تا برآن بنگرید و تمام اوامرخداوند را بیاد آورده، بجا آورید، و در‌پی دلها وچشمان خود که شما در‌پی آنها زنا می‌کنید، منحرف نشوید.۳۹
40 Nígbà náà ni ẹ ó gbọ́rọ̀ láti pa gbogbo òfin mi mọ́, ẹ ó sì jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run yín.
تا تمامی اوامر مرا بیاد آورده، بجا آورید، و بجهت خدای خود مقدس باشید.۴۰
41 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti Ejibiti láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
من یهوه خدای شما هستم که شما را از زمین مصر بیرون آوردم تا خدای شما باشم. من یهوه خدای شما هستم.»۴۱

< Numbers 15 >