< Numbers 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
I korero ano a Ihowa, ki a Mohi, i mea,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi ó fún yin gẹ́gẹ́ bí ibùgbé
Korero ki nga tama a Iharaira, mea atu ki a ratou, E tae koutou ki te whenua e noho ai koutou, ki taku e hoatu ai ki a koutou,
3 tí ẹ̀yin ó bá sì ṣe ẹbọ iná sí Olúwa ẹbọ sísun, tàbí ẹbọ, láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí ọrẹ àtinúwá, tàbí nínú àjọ yín, láti ṣe òórùn dídùn sí Olúwa nínú agbo ẹran tàbí ọ̀wọ́ ẹran,
A ka mea i te whakahere ahi ki a Ihowa, i te tahunga tinana, i te patunga tapu ranei hei whakamana mo te ki taurangi, i te whakahere tuku noa ranei, i a koutou hakari nunui ranei, hei whakakakara reka ki a Ihowa, he mea no nga kau, no nga hipi ra nei:
4 nígbà náà ni kí ẹni tí ó bá mú ọrẹ rẹ̀ wá, yóò tún mú ẹbọ ohun jíjẹ ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná pẹ̀lú ìdámẹ́rin òsùwọ̀n òróró wá síwájú Olúwa.
Na me kawe mai tana whakahere e te kaiwhakahere ki a Ihowa he whakahere totokore, ko te whakatekau o te epa o te paraoa pai, he mea konatunatu ki te whakawha o te hine hinu:
5 Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan yálà fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun ni, kí ẹ pèsè ìdámẹ́rin òsùwọ̀n wáìnì gẹ́gẹ́ bí ohun mímu.
Kia rite mai ano i a koe te whakawha o te hine waina, hei ringihanga, hei kinaki mo te tahunga tinana, mo te patunga tapu ranei, mo te reme kotahi.
6 “‘Fún àgbò kan ni kí ẹ pèsè ọrẹ ohun jíjẹ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n òróró pò.
Ki te mea he hipi toa, kia rite i a koe hei whakahere totokore nga whakatekau e rua o te epa o te paraoa pai, he mea konatunatu ki te whakatoru o te hine nihu.
7 Àti ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n wáìnì fún ọrẹ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa.
Me whakahere ano e koe te whakatoru o te hine waina hei ringihanga, hei kakara reka ki a Ihowa.
8 “‘Nígbà tí ẹ bá sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun, láti fi san ẹ̀jẹ́ tàbí fún ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa,
A ka mea koe i te puru hei tahunga tinana, hei patunga tapu ranei, hei whakamana i te kupu taurangi, hei whakahere ranei mo te pai ki a Ihowa:
9 ẹni náà yóò mú ọ̀dọ́ akọ màlúù náà wá pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdajì òsùwọ̀n òróró pò.
Na me kawe tahi ano e ia me te puru, hei whakahere totokore, kia toru nga whakatekau o te epa o te paraoa pai, he mea konatunatu ki te hawhe o te hine hinu.
10 Kí ó tún mú ìdajì òsùwọ̀n wáìnì wá fún ọrẹ ohun mímu. Yóò jẹ́ ọrẹ àfinásun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
Me kawe ano e koe te hawhe o te hine waina hei ringihanga, hei whakahere ahi, hei kakara reka ki a Ihowa.
11 Báyìí ni kí ẹ ṣe pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù tàbí àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí ọmọ ewúrẹ́.
Kia penei te meatanga mo te puru kotahi, mo te hipi toa kotahi, mo te reme toa, mo te kuao koati.
12 Ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ fún ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn, iyekíye tí ẹ̀yin ìbá à pèsè.
Kia rite ki te maha o a koutou e tuku ai ta koutou e mea ai ki te tahi, ki tetahi, kia rite tonu ki te maha o ratou.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín ni kí ó máa ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà tí ó bá mú ọrẹ àfinásun gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn wá fún Olúwa.
Kia penei te meatanga a nga tangata whenua katoa i enei mea, ina whakahere i te whakahere ahi, hei kakara reka ki a Ihowa.
14 Bí àlejò kan bá ń gbé láàrín yín ní gbogbo ìran yín, bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá fẹ́ mú ọrẹ àfinásun bí òórùn dídùn wá fún Olúwa, gbogbo bí ẹ bá ṣe ń ṣe náà ni kí ó ṣe.
A, ki te noho i a koe tetahi manene, tetahi noa atu ranei, i roto i a koutou i o koutou whakatupuranga, a ka mea kia whakahere i te whakahere ahi, i te kakara reka ki a Ihowa; kia rite tana e mea ai ki ta koutou e mea ai.
15 Gbogbo ìjọ ènìyàn gbọdọ̀ ní òfin kan náà fún ọmọ bíbí ilẹ̀ yín àti fún àwọn àlejò tó ń gbé láàrín yín, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún àwọn ìran tó ń bọ̀. Ẹ̀yin àti àlejò tó ń gbé láàrín yín sì jẹ́ bákan náà níwájú Olúwa.
Mo te whakaminenga kia kotahi te tikanga mo koutou, mo te manene hoki e noho tahi ana me koutou, hei tikanga pumau i o koutou whakatupuranga: kia pera ano me koutou te manene i te aroaro o Ihowa.
16 Òfin kan àti ìlànà kan ni yóò wà fún yín àti fún àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín.’”
Kia kotahi ano te ture, kia kotahi ano te ritenga mo koutou, mo te manene hoki e noho ana i a koutou.
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
I korero ano a Ihowa ki a Mohi, i mea,
18 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mo ń mú yín lọ.
Korero ki nga tama a Iharaira, mea atu ki a ratou, E tae koutou ki te whenua e kawea nei koutou e ahau ki reira,
19 Tí ẹ sì jẹ oúnjẹ ilẹ̀ náà, ẹ mú nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè wá fún Olúwa.
Na e kai koutou i te taro o te whenua, me whakahere he whakahere hapahapai ki a Ihowa.
20 Ẹ mú àkàrà wá nínú àkọ́so oúnjẹ yín wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè sí Olúwa, ọrẹ láti inú ilẹ̀ ìpakà yín.
Me whakahere he keke no ta koutou paraoa pokepoke mataati hei whakahere hapahapai: kia rite ki te whakahere hapahapai o te patunga witi ta koutou hapahapai.
21 Nínú àkọ́so oúnjẹ yín ni kí ẹ ti máa mú ọrẹ ìgbésókè yìí fún Olúwa.
Me hoatu tetahi wahi o ta koutou pokepokenga mataati ki a Ihowa, hei whakahere hapahapai, puta noa i o koutou whakatupuranga.
22 “‘Bí ẹ bá kùnà láìròtẹ́lẹ̀ láti pa àwọn òfin tí Olúwa fún Mose mọ́,
A ki te mea kua pohehe koutou, a kihai i rite enei whakahau katoa i korerotia nei e Ihowa ki a Mohi,
23 èyí ni gbogbo òfin tí Olúwa fún yín láti ẹnu Mose láti ọjọ́ tí Olúwa ti fún yín àti títí dé ìran tó ń bọ̀.
Ara nga mea katoa i whakahaua ai koutou e Ihowa, i korerotia e Mohi, o te ra ano i whakahau ai a Ihowa a tuku iho ki o koutou whakatupuranga;
24 Bí ẹ̀ṣẹ̀ bá wáyé láìròtẹ́lẹ̀ láìjẹ́ pé ìjọ ènìyàn mọ̀ sí i, nígbà náà ni kí gbogbo ìjọ ènìyàn mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan wá fún ẹbọ sísun bí òórùn dídùn sí Olúwa, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà, pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Ko reira, ki te meatia tetahi mea, he pohehe hoki, e ngaro ana i nga kanohi o te whakaminenga, na me whakahere e te whakaminenga katoa tetahi puru kuao hei tahunga tinana, hei kakara reka ki a Ihowa, me tona whakahere totokore, me tona ringihang a; kia rite ki te tikanga, kia kotahi hoki koati toa hei whakahere hara.
25 Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù, fun gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, a ó sì dáríjì wọ́n, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀, wọ́n sì ti mú ọrẹ àfinásun wá fún Olúwa nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀.
A ka whakamarie te tohunga mo te whakaminenga katoa o nga tama a Iharaira, a ka murua to ratou he; he pohehe hoki: a me kawe ta ratou whakahere, hei whakahere ahi ki a Ihowa, me ta ratou whakahere hara ki te aroaro o Ihowa, mo to ratou pohehe:
26 A ó dárí jí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn nítorí pé ní àìròtẹ́lẹ̀ ni wọ́n sẹ ẹ̀ṣẹ̀ náà.
A ka murua taua he o te whakaminenga katoa o nga tama a Iharaira, o te manene ano e noho ana i a ratou: no te mea i pohehe katoa te iwi.
27 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ẹnìkan ló sẹ̀ ní àìròtẹ́lẹ̀, kí ó mú abo ewúrẹ́ ọlọ́dún kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Ki te pohehe ano tetahi wairua, a ka hara, na me kawe mai e ia he koati uha, hei te tau tahi, hei whakahere hara.
28 Àlùfáà yóò ṣe ètùtù níwájú Olúwa fún ẹni tó ṣẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, tí wọ́n bá ṣe ètùtù fún un, a ó sì dáríjì í.
A me whakamarie te tohunga mo te wairua i hara pohehe, ina hara pohehe ia, ki te aroaro o Ihowa, hei whakamarie mona; a ka murua tana.
29 Òfin kan kí ẹ̀yin kí ó ní fún ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ̀ ní àìmọ̀, àti fún àwọn ẹni tí a bí nínú àwọn ọmọ Israẹli, àti fún àlejò tí ń ṣe àtìpó.
Kia kotahi ano ta koutou ture mo te tangata i hara pohehe, mo te tangata whenua o nga tama a Iharaira raua ko te manene e noho ana i a ratou.
30 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ yálà ó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín tàbí àlejò, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti kó ẹ̀gàn bá orúkọ Olúwa, a ó sì gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ko te wairua ia i whakakake, ahakoa tangata whenua, manene ranei, he kohukohu tana i a Ihowa; a ka hatepea atu taua wairua i roto i tona iwi.
31 Nítorí pé ẹni náà ti kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa ó sì ti rú òfin rẹ̀, a gbọdọ̀ gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí rẹ̀.’”
I whakahawea ia ki te kupu a Ihowa, i whakataka hoki i tana whakahau; ka tino hatepea atu taua wairua; ka mau tona kino ki a ia.
32 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli wà nínú aginjù, wọ́n rí ọkùnrin kan tí ń ṣá igi ní ọjọ́ Ìsinmi.
A, i nga tama a Iharaira i te koraha, ka kitea tetahi tangata e kohikohi rakau ana i te ra hapati.
33 Àwọn tó sì rí i níbi tó ti ń ṣá igi wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Aaroni àti síwájú gbogbo ìjọ ènìyàn,
Na ka kawea ia e nga tangata, i kite ra i a ia e kohikohi ana i nga rakau, ki a Mohi raua ko Arona, a ki te whakaminenga katoa.
34 wọ́n fi sí ìpamọ́ nítorí pé ohun tí wọn ó ṣe fún un kò tí ì yé wọn.
Na hoatu ana ia e ratou kia tiakina, no te mea kahore ano i whakaaturia me aha ia.
35 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Kíkú ni ọkùnrin náà yóò kú kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sọ ọ́ lókùúta pa ní ẹ̀yìn ibùdó.”
A ka mea a Ihowa ki a Mohi, me whakamate rawa tena tangata: ma te whakaminenga katoa ia e aki ki te kohatu ki waho o te puni.
36 Wọ́n mú un jáde sí ẹ̀yìn ibùdó, gbogbo ìjọ ènìyàn sì sọ ọ́ lókùúta pa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Na kawea ana ia e te whakaminenga katoa ki waho o te puni, a akina ana ki te kohatu, a ka mate: pera me ta Ihowa i whakahau ai ki a Mohi.
37 Olúwa sọ fún Mose pé,
I korero ano a Ihowa ki a Mohi, i mea,
38 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí o sọ fún wọn pé: ‘Títí dé àwọn ìran tó ń bọ̀ ni kí wọn máa ṣe wajawaja sí etí aṣọ wọn, kí wọn sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ aláwọ̀ búlúù sí wajawaja kọ̀ọ̀kan.
Koreroki nga tama a Iharaira, mea atu ki a ratou kia hanga etahi taniko mo ratou, mo nga taha o o ratou kakahu, puta noa i o ratou whakatupuranga, kia karapitia hoki te taniko o te pito ki te miro puru:
39 Wajawaja yìí ni ẹ sì máa wọ̀ láti lè mú yín rántí gbogbo òfin Olúwa, kí ẹ bá à lè ṣe wọ́n, kí ẹ sì má bá à ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn àti ojú yín.
A hei taniko tena mo koutou, hei titiro iho ma koutou, na ka mahara ki nga whakahau katoa a Ihowa, a ka mahi; kei rapu koutou i ta o koutou ngakau, i ta o koutou kanohi, ara i nga mea e whaia atu nei, e puremutia atu nei e koutou:
40 Nígbà náà ni ẹ ó gbọ́rọ̀ láti pa gbogbo òfin mi mọ́, ẹ ó sì jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run yín.
Kia mahara ai koutou ki te mahi i aku whakahau katoa, kia tapu ai hoki ki to koutou Atua.
41 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti Ejibiti láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Ko Ihowa ahau, ko to koutou Atua i kawe mai nei a koutou i te whenua o Ihipa, kia waiho ai ahau hei Atua mo koutou: ko Ihowa ahau, ko to koutou Atua.

< Numbers 15 >