< Numbers 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
LEUM GOD El sang nu sel Moses
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi ó fún yin gẹ́gẹ́ bí ibùgbé
oakwuk inge tuh elan fahkang nu sin mwet Israel in oru fin facl se su El ac sang in ma lalos.
3 tí ẹ̀yin ó bá sì ṣe ẹbọ iná sí Olúwa ẹbọ sísun, tàbí ẹbọ, láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí ọrẹ àtinúwá, tàbí nínú àjọ yín, láti ṣe òórùn dídùn sí Olúwa nínú agbo ẹran tàbí ọ̀wọ́ ẹran,
Soko cow mukul, ku soko sheep mukul, ku soko sheep, ku nani, ac ku in kisakinyuk nu sin LEUM GOD oana sie mwe kisa firir, ku oana sie kisa in akpwaye wuleang, ku sie mwe sang ke engan na lun mwet se in oru, ku sie mwe sang ke pacl in kufwa uh. Foulin mwe kisa inge mwe akinsewowoye LEUM GOD.
4 nígbà náà ni kí ẹni tí ó bá mú ọrẹ rẹ̀ wá, yóò tún mú ẹbọ ohun jíjẹ ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná pẹ̀lú ìdámẹ́rin òsùwọ̀n òróró wá síwájú Olúwa.
Na kutena mwet su use soko sheep ku soko nani in sie mwe kisa firir nu sin LEUM GOD, fah oayapa use sie mwe kisa wheat, ma orek ke luo paun in flao wowo karyak ke akosr cup ke oil in olive,
5 Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan yálà fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun ni, kí ẹ pèsè ìdámẹ́rin òsùwọ̀n wáìnì gẹ́gẹ́ bí ohun mímu.
oayapa, akosr cup in wain tuh in okwokyang nu fin loang uh.
6 “‘Fún àgbò kan ni kí ẹ pèsè ọrẹ ohun jíjẹ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n òróró pò.
Pacl se ke soko sheep mukul kisaiyukla, paun akosr ke flao karyak ke cup onkosr ke oil in olive in tufah itukyang oana sie kisa wheat,
7 Àti ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n wáìnì fún ọrẹ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa.
weang cup onkosr ke wain ma ac okwokyang nu fin loang uh. Foulin mwe kisa inge mwe akinsewowoye LEUM GOD.
8 “‘Nígbà tí ẹ bá sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun, láti fi san ẹ̀jẹ́ tàbí fún ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa,
Pacl se ke soko cow mukul kisakinyukyang nu sin LEUM GOD tuh in sie mwe kisa firir, ku in sie kisa in akpwayei wuleang, ku in sie kisa in akinsewowo,
9 ẹni náà yóò mú ọ̀dọ́ akọ màlúù náà wá pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdajì òsùwọ̀n òróró pò.
sie mwe kisa wheat ke paun onkosr ke flao karyak ke cup oalkosr ke oil in olive in tufah itukyang pac in wi,
10 Kí ó tún mú ìdajì òsùwọ̀n wáìnì wá fún ọrẹ ohun mímu. Yóò jẹ́ ọrẹ àfinásun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
weang cup in wain oalkosr. Foulin mwe kisa se inge mwe akinsewowoye LEUM GOD.
11 Báyìí ni kí ẹ ṣe pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù tàbí àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí ọmọ ewúrẹ́.
Pa ingan ma eneneyuk in itukyang wi kais soko cow mukul, sheep mukul, sheep, ku nani.
12 Ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ fún ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn, iyekíye tí ẹ̀yin ìbá à pèsè.
Ke pacl se ma ac kisakinyuk kosro pus liki ma soko, na ma oakwuki nu kac enenu in lalela fal nu ke pisa ma kisakinyuk.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín ni kí ó máa ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà tí ó bá mú ọrẹ àfinásun gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn wá fún Olúwa.
Mwet nukewa su isusla mwet Israel fah oru ouinge ke elos ac kisakin ma inge ke e, su fohlo mwe akinsewowoye LEUM GOD.
14 Bí àlejò kan bá ń gbé láàrín yín ní gbogbo ìran yín, bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá fẹ́ mú ọrẹ àfinásun bí òórùn dídùn wá fún Olúwa, gbogbo bí ẹ bá ṣe ń ṣe náà ni kí ó ṣe.
Fin oasr mwetsac su muta inmasrlowos, finne ke kitin pacl na ku muta oakwuk, el fin lungse oru sie mwe kisa ke mwe mongo, su fohlo mwe akinsewowoye LEUM GOD, el fah oru oapana ke kowos oru uh.
15 Gbogbo ìjọ ènìyàn gbọdọ̀ ní òfin kan náà fún ọmọ bíbí ilẹ̀ yín àti fún àwọn àlejò tó ń gbé láàrín yín, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún àwọn ìran tó ń bọ̀. Ẹ̀yin àti àlejò tó ń gbé láàrín yín sì jẹ́ bákan náà níwájú Olúwa.
Kowos, ac mwetsac su muta inmasrlowos, enenu in orekmakin oakwuk inge ke pacl nukewa fahsru uh. Kowos ac elos oana sie ye mutun LEUM GOD.
16 Òfin kan àti ìlànà kan ni yóò wà fún yín àti fún àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín.’”
Ma sap ac oakwuk nukewa nu suwos ac ma pac nu selos.
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
LEUM GOD El sang nu sel Moses
18 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mo ń mú yín lọ.
oakwuk inge tuh elan fahkang nu sin mwet Israel in oru fin facl se su El ac sang in ma lalos.
19 Tí ẹ sì jẹ oúnjẹ ilẹ̀ náà, ẹ mú nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè wá fún Olúwa.
Kutena pacl kowos kang fokin acn uh, srela kutu nu saya tuh in mwe sang nu sin LEUM GOD.
20 Ẹ mú àkàrà wá nínú àkọ́so oúnjẹ yín wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè sí Olúwa, ọrẹ láti inú ilẹ̀ ìpakà yín.
Pacl kowos manman flao, lof soko oemeet ke bread orek ke wheat sasu in tufah itukyang oana sie mwe sang sriyukla nu sin LEUM GOD. Ma se inge ac tufah orek oana mwe sang sriyukla su kowos oru ke wheat ma aknasnasyeyukla ke nien kulkul wheat.
21 Nínú àkọ́so oúnjẹ yín ni kí ẹ ti máa mú ọrẹ ìgbésókè yìí fún Olúwa.
Ingela nwe tok, mwe sang sriyukla inge in itukyang na nu sin LEUM GOD liki bread kowos munan uh.
22 “‘Bí ẹ bá kùnà láìròtẹ́lẹ̀ láti pa àwọn òfin tí Olúwa fún Mose mọ́,
Ac fuka, sie mwet fin kunausla kutu sin ma oakwuk inge su LEUM GOD El sang nu sel Moses, ke tia ma el nunkala elan oru?
23 èyí ni gbogbo òfin tí Olúwa fún yín láti ẹnu Mose láti ọjọ́ tí Olúwa ti fún yín àti títí dé ìran tó ń bọ̀.
Ku ac fuka fin mau tok, mwet Israel nukewa elos tia akfalye ma nukewa ma LEUM GOD El sapkin nu sel Moses?
24 Bí ẹ̀ṣẹ̀ bá wáyé láìròtẹ́lẹ̀ láìjẹ́ pé ìjọ ènìyàn mọ̀ sí i, nígbà náà ni kí gbogbo ìjọ ènìyàn mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan wá fún ẹbọ sísun bí òórùn dídùn sí Olúwa, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà, pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Tafongla ouinge fin orek ke sripen elos nukewa tia kalem kac, na elos fah kisakin soko cow mukul in sie mwe kisa firir, ma fohlo mwe akinsewowoye LEUM GOD, wi mwe kisa wheat ac mwe kisa wain fal nu kac. Sayen ma inge, elos in kisakin pac soko nani mukul tuh in sie mwe kisa ke ma koluk.
25 Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù, fun gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, a ó sì dáríjì wọ́n, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀, wọ́n sì ti mú ọrẹ àfinásun wá fún Olúwa nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀.
Mwet tol el fah oru alu in aknasnas nu sin mwet Israel nukewa, ac elos fah eis nunak munas, mweyen tafongla lalos uh tia ma srunenyak elos in oru, oayapa mweyen elos use mwe kisa ke ma koluk lalos oana mwe kisa mongo nu sin LEUM GOD.
26 A ó dárí jí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn nítorí pé ní àìròtẹ́lẹ̀ ni wọ́n sẹ ẹ̀ṣẹ̀ náà.
Mwet Israel nukewa, oayapa mwetsac su muta inmasrlolos, ac fah eis nunak munas mweyen mwet nukewa oru tafongla sac ke tia etu.
27 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ẹnìkan ló sẹ̀ ní àìròtẹ́lẹ̀, kí ó mú abo ewúrẹ́ ọlọ́dún kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Sie mwet fin orala sie ma koluk ke el tia nunku in oru, el fah sang soko nani mutan yac sie matwa tuh in sie mwe kisa ke ma koluk.
28 Àlùfáà yóò ṣe ètùtù níwájú Olúwa fún ẹni tó ṣẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, tí wọ́n bá ṣe ètùtù fún un, a ó sì dáríjì í.
Mwet tol el fah oru alu in aknasnas ke loang uh in eela ma koluk lun mwet se inge, na ac fah nunak munas nu sel.
29 Òfin kan kí ẹ̀yin kí ó ní fún ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ̀ ní àìmọ̀, àti fún àwọn ẹni tí a bí nínú àwọn ọmọ Israẹli, àti fún àlejò tí ń ṣe àtìpó.
Oakwuk sefanna in orekmakinyuk nu sin kutena mwet su orala ma koluk ke tia nunku in oru, el fin sie mwet isusla mwet Israel, ku sie mwetsac su muta inmasrlowos.
30 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ yálà ó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín tàbí àlejò, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti kó ẹ̀gàn bá orúkọ Olúwa, a ó sì gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
Tusruktu kutena mwet su akoo in oru ma koluk ac orala, el finne mwet isusla mwet Israel ku sie mwetsac, oasr mwatal ke sripen el aklusrongtenye LEUM GOD, na ac fah anwuki el
31 Nítorí pé ẹni náà ti kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa ó sì ti rú òfin rẹ̀, a gbọdọ̀ gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí rẹ̀.’”
mweyen el pilesru kas lun LEUM GOD, ac el kunausla sie sin ma sap lun God ke etu lal. Sripen misa lal, ma el sifacna oru.
32 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli wà nínú aginjù, wọ́n rí ọkùnrin kan tí ń ṣá igi ní ọjọ́ Ìsinmi.
Sie pacl ah, ke mwet Israel srakna muta yen mwesis, koneyukyak mwet se lah el ti etong ke len Sabbath.
33 Àwọn tó sì rí i níbi tó ti ń ṣá igi wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Aaroni àti síwájú gbogbo ìjọ ènìyàn,
Na utukla el nu yorol Moses ac Aaron, ac nu yurin mwet Israel nukewa,
34 wọ́n fi sí ìpamọ́ nítorí pé ohun tí wọn ó ṣe fún un kò tí ì yé wọn.
ac elos sang sie mwet in liyalang, mweyen tia kalem lah mea fal in orek nu sel.
35 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Kíkú ni ọkùnrin náà yóò kú kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sọ ọ́ lókùúta pa ní ẹ̀yìn ibùdó.”
Na LEUM GOD El fahk nu sel Moses, “Enenu mwet se inge in anwuki. Mwet Israel nukewa in tanglal likin nien aktuktuk uh nwe ke el misa.”
36 Wọ́n mú un jáde sí ẹ̀yìn ibùdó, gbogbo ìjọ ènìyàn sì sọ ọ́ lókùúta pa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Ke ma inge mwet Israel nukewa usalla nu likin nien aktuktuk uh, ac tanglal nwe ke na el misa, oana ke LEUM GOD El sapkin.
37 Olúwa sọ fún Mose pé,
LEUM GOD El sapkin nu sel Moses
38 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí o sọ fún wọn pé: ‘Títí dé àwọn ìran tó ń bọ̀ ni kí wọn máa ṣe wajawaja sí etí aṣọ wọn, kí wọn sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ aláwọ̀ búlúù sí wajawaja kọ̀ọ̀kan.
in fahk nu sin mwet Israel: “Orala mwe yun ke turet in oan atla ke pulun nuknuk lowos uh, ac sang soko ah folfol an kapriya kais sie mwe yun inge. Kowos fah oru ouinge ke pacl nukewa fahsru.
39 Wajawaja yìí ni ẹ sì máa wọ̀ láti lè mú yín rántí gbogbo òfin Olúwa, kí ẹ bá à lè ṣe wọ́n, kí ẹ sì má bá à ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn àti ojú yín.
Mwe yun inge ac fah mwe akesmakinye kowos, tuh kais sie pacl kowos liye uh kowos fah esamak ma sap luk nukewa ac akos; na kowos fah tia forla likiyu ac fahsr tukun lungse ac kena lowos sifacna.
40 Nígbà náà ni ẹ ó gbọ́rọ̀ láti pa gbogbo òfin mi mọ́, ẹ ó sì jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run yín.
Mwe yun inge ac fah akesmakinye kowos in liyaung ma sap luk nukewa, ac kowos fah kisakinyukla tuh kowos in mwet luk na pwaye.
41 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti Ejibiti láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Nga LEUM GOD lowos. Nga pa uskowosme liki acn Egypt tuh nga in God lowos. Nga LEUM GOD.”

< Numbers 15 >