< Numbers 15 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Mluvil opět Hospodin k Mojžíšovi, řka:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi ó fún yin gẹ́gẹ́ bí ibùgbé
Mluv k synům Izraelským a rci jim: Když vejdete do země přebývání vašich, kterouž já dám vám,
3 tí ẹ̀yin ó bá sì ṣe ẹbọ iná sí Olúwa ẹbọ sísun, tàbí ẹbọ, láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí ọrẹ àtinúwá, tàbí nínú àjọ yín, láti ṣe òórùn dídùn sí Olúwa nínú agbo ẹran tàbí ọ̀wọ́ ẹran,
A budete chtíti obětovati obět ohnivou Hospodinu v zápal, aneb obět buď slíbenou, buď dobrovolnou, aneb při slavnostech vašich, abyste učinili vůni spokojující Hospodina, buďto z skotů, aneb z drobného dobytku:
4 nígbà náà ni kí ẹni tí ó bá mú ọrẹ rẹ̀ wá, yóò tún mú ẹbọ ohun jíjẹ ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná pẹ̀lú ìdámẹ́rin òsùwọ̀n òróró wá síwájú Olúwa.
Tedy kdož by koli obětoval dar svůj Hospodinu, obětuj obět suchou, desátý díl efi mouky bělné, zadělané olejem, jehož bude čtvrtý díl míry hin.
5 Pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan yálà fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun ni, kí ẹ pèsè ìdámẹ́rin òsùwọ̀n wáìnì gẹ́gẹ́ bí ohun mímu.
A vína v obět mokrou čtvrtinku hin obětovati budeš při zápalu, aneb při oběti vítězné k jednomu každému beránku.
6 “‘Fún àgbò kan ni kí ẹ pèsè ọrẹ ohun jíjẹ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n òróró pò.
Při beranu pak obětovati budeš obět suchou, mouky bělné dvě desetiny, zadělané olejem, třetinkou míry hin.
7 Àti ìdákan nínú mẹ́ta òsùwọ̀n wáìnì fún ọrẹ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa.
Vína také k oběti mokré třetí díl míry hin obětovati budeš u vůni spokojující Hospodina.
8 “‘Nígbà tí ẹ bá sì pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù fún ọrẹ tàbí ẹbọ sísun, láti fi san ẹ̀jẹ́ tàbí fún ọrẹ àlàáfíà sí Olúwa,
Jestliže pak obětovati budeš volka v obět zápalnou, aneb v obět k splnění slibu, aneb v obět pokojnou Hospodinu:
9 ẹni náà yóò mú ọ̀dọ́ akọ màlúù náà wá pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi ìdajì òsùwọ̀n òróró pò.
Tedy budeš obětovati spolu s volkem obět suchou, tři desetiny mouky bělné, zadělané olejem, jehož by byla půlka hin.
10 Kí ó tún mú ìdajì òsùwọ̀n wáìnì wá fún ọrẹ ohun mímu. Yóò jẹ́ ọrẹ àfinásun, àní òórùn dídùn sí Olúwa.
A vína k oběti mokré obětovati budeš půlku hin. Ta jest obět ohnivá vůně spokojující Hospodina.
11 Báyìí ni kí ẹ ṣe pèsè ọ̀dọ́ akọ màlúù tàbí àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn tàbí ọmọ ewúrẹ́.
Tak uděláte s každým volem i s každým skopcem, i s dobytčetem buď ono z ovec neb z koz.
12 Ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ fún ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn, iyekíye tí ẹ̀yin ìbá à pèsè.
Podlé toho, jakž mnoho jich obětovati budete, tak se zachováte při jednom každém z nich.
13 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín ni kí ó máa ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí nígbà tí ó bá mú ọrẹ àfinásun gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn wá fún Olúwa.
Všeliký obyvatel tak bude to vykonávati, aby obětoval obět ohnivou vůně spokojující Hospodina.
14 Bí àlejò kan bá ń gbé láàrín yín ní gbogbo ìran yín, bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ bá fẹ́ mú ọrẹ àfinásun bí òórùn dídùn wá fún Olúwa, gbogbo bí ẹ bá ṣe ń ṣe náà ni kí ó ṣe.
Takž bude-li u vás i příchozí, aneb kdokoli mezi vámi v pronárodech vašich, a bude obětovati obět ohnivou vůně spokojující Hospodina, jakž vy se při tom chováte, tak i on chovati se bude.
15 Gbogbo ìjọ ènìyàn gbọdọ̀ ní òfin kan náà fún ọmọ bíbí ilẹ̀ yín àti fún àwọn àlejò tó ń gbé láàrín yín, èyí jẹ́ ìlànà títí láé fún àwọn ìran tó ń bọ̀. Ẹ̀yin àti àlejò tó ń gbé láàrín yín sì jẹ́ bákan náà níwájú Olúwa.
V shromáždění tomto ustanovení jednostejné buď vám i příchozímu, kterýž by u vás byl, ustanovení věčné v pronárodech vašich; jakož vy, tak příchozí bude před Hospodinem.
16 Òfin kan àti ìlànà kan ni yóò wà fún yín àti fún àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín.’”
Zákon jednostejný a pořádek jednostejný bude vám i přichozímu kterýž by u vás byl.
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
Mluvil také Hospodin k Mojžíšovi, řka:
18 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí mo ń mú yín lọ.
Mluv k synům Izraelským a rci jim: Když přijdete do země, do kteréž já uvedu vás,
19 Tí ẹ sì jẹ oúnjẹ ilẹ̀ náà, ẹ mú nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè wá fún Olúwa.
Tedy, když počnete jísti chléb země, obětovati budete obět vzhůru pozdvižení Hospodinu.
20 Ẹ mú àkàrà wá nínú àkọ́so oúnjẹ yín wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ìgbésókè sí Olúwa, ọrẹ láti inú ilẹ̀ ìpakà yín.
Z prvotin těsta vašeho koláč obětovati budete v obět vzhůru pozdvižení; tak jako obět z humna, obětovati budete ji.
21 Nínú àkọ́so oúnjẹ yín ni kí ẹ ti máa mú ọrẹ ìgbésókè yìí fún Olúwa.
Z prvotin těsta vašeho dávati budete Hospodinu obět vzhůru pozdvižení, vy i potomci vaši.
22 “‘Bí ẹ bá kùnà láìròtẹ́lẹ̀ láti pa àwọn òfin tí Olúwa fún Mose mọ́,
A když byste pozbloudili, a neučinili všech přikázaní těch, kteráž mluvil Hospodin k Mojžíšovi,
23 èyí ni gbogbo òfin tí Olúwa fún yín láti ẹnu Mose láti ọjọ́ tí Olúwa ti fún yín àti títí dé ìran tó ń bọ̀.
Totiž všech věcí, kteréž přikázal Hospodin vám skrze Mojžíše, od toho dne, v kterémž přikázaní vydal Hospodin, i potom v pronárodech vašich:
24 Bí ẹ̀ṣẹ̀ bá wáyé láìròtẹ́lẹ̀ láìjẹ́ pé ìjọ ènìyàn mọ̀ sí i, nígbà náà ni kí gbogbo ìjọ ènìyàn mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan wá fún ẹbọ sísun bí òórùn dídùn sí Olúwa, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà, pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Tedy jestliže z nedopatření všeho shromáždění to stalo se, obětovati bude všecko množství volka mladého jednoho v obět zápalnou, k vůni spokojující Hospodina, též obět suchou, a obět mokrou při něm podlé pořádku, a kozla jednoho v obět za hřích.
25 Àlùfáà yóò sì ṣe ètùtù, fun gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli, a ó sì dáríjì wọ́n, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àìròtẹ́lẹ̀, wọ́n sì ti mú ọrẹ àfinásun wá fún Olúwa nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀.
I očistí kněz všecko množství synů Izraelských, a odpuštěno jim bude; nebo poblouzení jest. A oni také obětovati budou obět svou, obět ohnivou Hospodinu, a obět za hřích svůj před Hospodinem za poblouzení své.
26 A ó dárí jí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli àti àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín wọn nítorí pé ní àìròtẹ́lẹ̀ ni wọ́n sẹ ẹ̀ṣẹ̀ náà.
I bude odpuštěno všemu shromáždění synů Izraelských i příchozímu, kterýž jest pohostinu u prostřed nich; nebo všeho lidu poblouzení jest.
27 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé ẹnìkan ló sẹ̀ ní àìròtẹ́lẹ̀, kí ó mú abo ewúrẹ́ ọlọ́dún kan wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
Jestliže by pak člověk jeden zhřešil z poblouzení, bude obětovati kozu roční v obět za hřích.
28 Àlùfáà yóò ṣe ètùtù níwájú Olúwa fún ẹni tó ṣẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, tí wọ́n bá ṣe ètùtù fún un, a ó sì dáríjì í.
I očistí kněz duši pobloudilou, kteráž zhřešila poblouzením před Hospodinem; očistí ji, a budeť jí odpuštěno.
29 Òfin kan kí ẹ̀yin kí ó ní fún ẹnikẹ́ni tó bá ṣẹ̀ ní àìmọ̀, àti fún àwọn ẹni tí a bí nínú àwọn ọmọ Israẹli, àti fún àlejò tí ń ṣe àtìpó.
Domácímu mezi syny Izraelskými i příchozímu, kterýž pohostinu mezi nimi jest, zákon tento jednostejný bude vám, když by kdo zhřešil z poblouzení.
30 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ yálà ó jẹ́ ọmọ bíbí ilẹ̀ yín tàbí àlejò, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ti kó ẹ̀gàn bá orúkọ Olúwa, a ó sì gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn rẹ̀.
Èlověk pak, kterýž by z pychu svévolně zhřešil, tak doma zrozený jako příchozí, takový potupil velice Hospodina; protož vyhlazen bude z prostředku lidu svého.
31 Nítorí pé ẹni náà ti kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa ó sì ti rú òfin rẹ̀, a gbọdọ̀ gé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí rẹ̀.’”
Nebo slovem Hospodinovým pohrdl, a přikázaní jeho za nic sobě položil; protož konečně vyhlazen bude člověk ten, a nepravost jeho zůstane na něm.
32 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli wà nínú aginjù, wọ́n rí ọkùnrin kan tí ń ṣá igi ní ọjọ́ Ìsinmi.
Stalo se pak, když synové Izraelští byli na poušti, že nalezli jednoho, an sbírá dříví v den sobotní.
33 Àwọn tó sì rí i níbi tó ti ń ṣá igi wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Aaroni àti síwájú gbogbo ìjọ ènìyàn,
A ti, kteříž ho nalezli sbírajícího dříví, přivedli jej k Mojžíšovi a k Aronovi i ke všemu množství.
34 wọ́n fi sí ìpamọ́ nítorí pé ohun tí wọn ó ṣe fún un kò tí ì yé wọn.
I dali jej do vězení; nebo ještě nebylo jim oznámeno, co by s ním mělo činěno býti.
35 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Kíkú ni ọkùnrin náà yóò kú kí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sọ ọ́ lókùúta pa ní ẹ̀yìn ibùdó.”
I řekl Hospodin Mojžíšovi: Smrtí ať umře člověk ten; nechať ho bez milosti ukamenuje všecko množství vně za stany.
36 Wọ́n mú un jáde sí ẹ̀yìn ibùdó, gbogbo ìjọ ènìyàn sì sọ ọ́ lókùúta pa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
A protož vyvedli jej všecko množství ven za stany, a uházeli ho kamením, až umřel, jakož rozkázal Hospodin.
37 Olúwa sọ fún Mose pé,
I mluvil Hospodin k Mojžíšovi, řka:
38 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí o sọ fún wọn pé: ‘Títí dé àwọn ìran tó ń bọ̀ ni kí wọn máa ṣe wajawaja sí etí aṣọ wọn, kí wọn sì fi okùn tẹ́ẹ́rẹ́ aláwọ̀ búlúù sí wajawaja kọ̀ọ̀kan.
Mluv k synům Izraelským a rci jim, ať sobě dělají třepení široké na podolcích oděvů svých všickni rodové jejich, a ať dávají nad třepením šňůrku modrou.
39 Wajawaja yìí ni ẹ sì máa wọ̀ láti lè mú yín rántí gbogbo òfin Olúwa, kí ẹ bá à lè ṣe wọ́n, kí ẹ sì má bá à ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn àti ojú yín.
A to budete míti za premování, na něžto hledíce, rozpomínati se budete na všecka přikázaní Hospodinova, abyste je činili, a nepustíte se po žádosti srdce svého, a po očích svých, jichžto následujíce, smilnili byste,
40 Nígbà náà ni ẹ ó gbọ́rọ̀ láti pa gbogbo òfin mi mọ́, ẹ ó sì jẹ́ mímọ́ sí Ọlọ́run yín.
Ale abyste pamatovali a činili všecka přikázaní má, a byli svatí Bohu svému.
41 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti Ejibiti láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
Já jsem Hospodin Bůh váš, kterýž jsem vyvedl vás z země Egyptské, abych vám byl za Boha: Já Hospodin Bůh váš.

< Numbers 15 >