< Numbers 14 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
És felemelé szavát az egész gyülekezet, és síra a nép azon az éjszakán.
2 Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
És mindnyájan zúgolódának Mózes ellen és Áron ellen Izráel fiai, és monda nékik az egész gyülekezet: Vajha megholtunk volna Égyiptom földén! vagy ebben a pusztában vajha meghalnánk!
3 Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
Miért is visz be minket az Úr arra a földre? hogy fegyver miatt hulljunk el? feleségeink és a kicsinyeink prédára legyenek? Nem jobb volna-é nékünk visszatérnünk Égyiptomba?
4 Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
És mondának egymásnak: Szerezzünk előttünk járót, és térjünk vissza Égyiptomba.
5 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
Akkor arczczal leborulának Mózes és Áron Izráel fiai gyülekezetének egész községe előtt.
6 Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
Józsué pedig, a Nún fia, és Káleb, a Jefunné fia, a kik a földnek kémlelői közül valók valának, meghasogaták ruháikat.
7 Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
És szólának Izráel fiai egész gyülekezetének, mondván: A föld, a melyen általmentünk, hogy megkémleljük azt, igen-igen jó föld.
8 Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
Ha az Úrnak kedve telik bennünk, akkor bevisz minket arra a földre, és nékünk adja azt, mely tejjel és mézzel folyó föld.
9 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
Csakhogy ne lázongjatok az Úr ellen, se ne féljetek annak a földnek népétől; mert ők nekünk csak olyanok, mint a kenyér; eltávozott tőlök az ő oltalmok, de az Úr velünk van: ne féljetek tőlök!
10 Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Mikor pedig az egész gyülekezet azon tanakodék, hogy megkövezze őket: megjelenék az Úrnak dicsősége a gyülekezet sátorában Izráel minden fiának.
11 Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
És monda az Úr Mózesnek: Meddig gyaláz engemet ez a nép? Meddig nem hisznek nékem, mind ama csudatételeim mellett sem, a melyeket cselekedtem közöttök?
12 Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
Megverem őket döghalállal, és elvesztem őket; téged pedig nagy néppé teszlek, és ő nálánál erősebbé.
13 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
És monda Mózes az Úrnak: Ha meghallják az égyiptombeliek (mert közülök hoztad fel e népet a te hatalmad által):
14 Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
Elmondják majd e föld lakosainak, a kik hallották, hogy te Uram e nép között vagy, hogy szemtől szembe megjelentetted magadat te Uram, és hogy a te felhőd megállott ő rajtok, és felhőoszlopban jársz te ő előttök nappal, éjjel pedig tűzoszlopban.
15 Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
Hogyha mind egyig elveszted e népet, így szólanak majd e népek, a melyek hallották a te híredet, mondván:
16 ‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
Mivelhogy nem vihette be az Úr e népet a földre, a mely felől megesküdött nékik, azért öldöste le őket a pusztában.
17 “Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
Most azért hadd magasztaltassék fel az Úrnak ereje, a miképen szólottál, mondván:
18 ‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
Az Úr késedelmes a haragra, nagy irgalmasságú, megbocsát hamisságot és vétket, de a bűnöst nem hagyja büntetlenül; megbünteti az atyák álnokságait a fiakban harmad és negyed íziglen.
19 Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
Kérlek, kegyelmezz meg e nép hamisságának a te irgalmasságod nagy volta szerint, a miképen megbocsátottál e népnek Égyiptomtól fogva mind eddig.
20 Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
És monda az Úr: Megkegyelmeztem a te beszéded szerint.
21 Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
De bizonnyal élek én, és betölti az Úr dicsősége az egész földet.
22 Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
Hogy mindazok az emberek, a kik látták az én dicsőségemet és csudáimat, a melyeket cselekedtem Égyiptomban és e pusztában, és megkisértettek engemet immár tízszer, és nem engedtek az én szómnak:
23 ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
Nem látják meg azt a földet, a mely felől megesküdtem az ő atyáiknak; senki nem látja azt azok közöl, a kik gyaláztak engem.
24 Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
De az én szolgámat, Kálebet, mivelhogy más lélek volt vele, és tökéletességgel követett engem, beviszem őt arra a földre, a melyre bement vala, és örökségül bírja azt az ő magva.
25 Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
De Amálek és Kananeus lakik a völgyben; holnap forduljatok meg, és induljatok a pusztába, a veres tenger útján.
26 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Szóla annakfelette az Úr Mózesnek és Áronnak, mondván:
27 “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
Meddig tűrjek e gonosz gyülekezetnek, a mely zúgolódik ellenem? Hallottam Izráel fiainak zúgolódásait, a kik zúgolódnak ellenem!
28 Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
Mondd meg nékik: Élek én, azt mondja az Úr, hogy épen úgy cselekszem veletek, a miképen szólottatok az én füleim hallására!
29 Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
E pusztában hullanak el a ti holttesteitek, és pedig mindazok, a kik megszámláltattak a ti teljes számotok szerint, húsz esztendőstől fogva és azon felül, a kik zúgolódtatok ellenem.
30 Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
És nem mentek be arra a földre, a melyre nézve felemeltem az én kezemet, hogy lakosokká teszlek abban titeket; Kálebet, a Jefunné fiát és Józsuét, a Nún fiát kivéve.
31 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
De kicsinyeiteket, a kik felől azt mondtátok, hogy prédára lesznek; őket beviszem, és megismerik azt a földet, a melyet megútáltatok.
32 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
A ti holttesteitek azért a pusztában hullanak el.
33 Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
A ti fiaitok pedig, mint a pásztorok, bujdosnak e pusztában negyven esztendeig, és viselik a ti paráználkodásitoknak büntetését, míglen megemésztetnek a ti holttesteitek e pusztában.
34 Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
A napok száma szerint, a melyeken megkémleltétek a földet, (tudniillik negyven napon, egy-egy napért egy-egy esztendő), negyven esztendeig hordozzátok a ti hamisságotoknak büntetését, és megismeritek az én elfordulásomat.
35 Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
Én, az Úr, szólottam. Bizonyára ezt mívelem az egész gonosz gyülekezettel, a mely összegyülekezett vala ellenem; ebben a pusztában emésztetnek meg, és ugyanott halnak meg.
36 Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
A férfiak azért, a kiket elküldött vala Mózes a földnek megkémlelésére, és visszatérének és felzúdíták ellene az egész gyülekezetet, rossz hírt terjesztvén arról a földről:
37 Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
Azok a férfiak azért, a kik rossz hírt terjesztének a földről, meghalának az Úr előtt csapás által.
38 Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
Csak Józsué, a Nún fia, és Káleb, a Jefunné fia, maradának életben ama férfiak közül, a kik mentek vala a földet megkémlelni.
39 Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
A mint pedig elbeszélé Mózes e beszédeket Izráel fiainak, a nép felette igen keserge.
40 Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
És felkelének reggel, és felmenének a hegy tetejére, mondván: Ímé készek vagyunk elmenni a helyre, a melyről szólott az Úr, mert vétkeztünk.
41 Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
És monda Mózes: Miért hágjátok át ilyen módon az Úr akaratát, holott nem sikerülhet az néktek.
42 Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
Fel ne menjetek, mert nem lesz közöttetek az Úr, hogy el ne hulljatok a ti ellenségeitek előtt.
43 Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
Mert az Amálek és a Kananeus van ott előttetek, és fegyver által hulltok el. Mivelhogy elfordultatok az Úrtól, nem is lesz az Úr veletek.
44 Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
Mindazáltal merészkedének felmenni a hegy tetejére; de az Úr szövetségének ládája és Mózes meg sem mozdulának a táborból.
45 Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.
Alászálla azért az Amálek és a Kananeus, a ki lakik vala azon a hegyen, és megverék őket, és vágák őket mind Hormáig.

< Numbers 14 >