< Numbers 14 >
1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
Ũtukũ ũcio andũ othe a kĩrĩndĩ gĩa Isiraeli makĩrĩra maanĩrĩire na mũgambo mũnene.
2 Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
Andũ acio othe a Isiraeli makĩnuguna nĩ ũndũ wa Musa na Harũni, na kĩũngano kĩu gĩothe gĩkĩmeera atĩrĩ, “Naarĩ korwo twakuĩrĩire Misiri! Kana werũ-inĩ ũyũ!
3 Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
Nĩ kĩĩ gĩgũtũma Jehova atũrehe bũrũri ũyũ atũrekererie tũũragwo na rũhiũ rwa njora? Atumia aitũ na ciana ciitũ megũtuĩka a gũtahwo. Githĩ wega ti tũcooke bũrũri wa Misiri?”
4 Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
Nao makĩĩrana mũndũ na ũrĩa ũngĩ atĩrĩ, “Twagĩrĩirwo nĩ tũthuure mũtongoria tũcooke bũrũri wa Misiri.”
5 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
Hĩndĩ ĩyo Musa na Harũni makĩĩgũithia maturumithĩtie mothiũ mao thĩ mbere ya kĩũngano kĩu gĩothe kĩa andũ a Isiraeli kĩrĩa kĩagomanĩte hau.
6 Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
Joshua mũrũ wa Nuni na Kalebu mũrũ wa Jefune, arĩa maarĩ hamwe na arĩa maathiĩte gũthigaana bũrũri ũcio magĩtembũranga nguo ciao.
7 Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Makĩĩra kĩũngano kĩu gĩothe kĩa andũ a Isiraeli atĩrĩ, “Bũrũri ũrĩa twatuĩkanĩirie na tũkĩũthigana, nĩ bũrũri mwega mũno makĩria.
8 Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
Jehova angĩkorwo nĩakenetio nĩ ithuĩ, nĩegũtũtongoria tũtoonye bũrũri ũcio, bũrũri ũcio ũiyũrĩte bũthi wa iria na ũũkĩ, na nĩegũtũhe guo ũtuĩke witũ.
9 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
No rĩrĩ, mũtikaremere Jehova. Na mũtigetigĩre andũ a bũrũri ũcio, nĩ ũndũ tũkũmameria biũ. Ũgitĩri wao nĩ mweherie, no Jehova arĩ hamwe na ithuĩ. Mũtikametigĩre.”
10 Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
No kĩũngano kĩu gĩothe gĩkĩaria ũhoro wa kũmahũũra na mahiga nyuguto. Hĩndĩ ĩyo riiri wa Jehova ũkiumĩrĩra andũ othe a Isiraeli hau Hema-inĩ ya Gũtũnganwo.
11 Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
Nake Jehova akĩũria Musa atĩrĩ, “Andũ aya megũtũũra maanyararĩte nginya-rĩ? Megũtũũra maregete kũnjĩtĩkia nginya-rĩ, o na ningĩte ciama nyingĩ ũguo gatagatĩ kao?
12 Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
Nĩngũmahũũra na mũthiro ndĩmaniine, no wee ngũgũtua rũrĩrĩ rũnene na rũrĩ na hinya kũmakĩra.”
13 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
Musa akĩĩra Jehova atĩrĩ, “Andũ a Misiri nĩmakaigua ũhoro ũcio! Nĩwe warutire andũ aya makiuma gatagatĩ kao na ũndũ wa ũhoti waku.
14 Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
Nao nĩmakeera aikari a bũrũri ũyũ ũhoro ũcio. Nĩmaiguĩte atĩ Wee, O Wee Jehova-rĩ, ũkoragwo na andũ aya, na atĩ Wee Jehova, wanonwo ũthiũ kwa ũthiũ, na atĩ itu rĩaku rĩikaraga igũrũ rĩao, o na atĩ Wee ũthiiaga mbere yao thĩinĩ wa gĩtugĩ kĩa itu mũthenya na ũrĩ thĩinĩ wa gĩtugĩ kĩa mwaki ũtukũ.
15 Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
Ũngĩũraga andũ aya othe o ro rĩmwe-rĩ, ndũrĩrĩ iria ciiguĩte ũhoro ũyũ waku nĩikoiga atĩrĩ,
16 ‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
‘Jehova nĩaremirwo nĩgũkinyia andũ aya bũrũri ũrĩa aamerĩire na mwĩhĩtwa; nĩ ũndũ ũcio akĩmooragĩra werũ-inĩ.’
17 “Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
“Na rĩrĩ, hinya wa Mwathani ũrokĩonekana o ta ũrĩa ugĩte, atĩrĩ:
18 ‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
‘Jehova ndahiũhaga kũrakara, aiyũrĩtwo nĩ wendo, na nĩohanagĩra mehia na ũremi. No ndaagaga kũherithia mũndũ ũrĩa wĩhĩtie; nĩaherithagia ciana nĩ ũndũ wa mehia ma maithe nginya rũciaro rwa gatatũ na rwa kana.’
19 Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
Kũringana na wendo waku mũnene-rĩ, ohera andũ aya mehia mao, o ta ũrĩa wanamarekera kuuma hĩndĩ ĩrĩa moimire bũrũri wa Misiri nginya rĩu.”
20 Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Jehova akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩ ndamarekera o ta ũguo woria.
21 Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
No rĩrĩ, ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo, na ti-itherũ o ta ũrĩa riiri wa Jehova ũiyũrĩte thĩ yothe-rĩ,
22 Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
gũtirĩ o na ũmwe wa andũ arĩa moonire riiri wakwa na ciama iria ndaringĩire kũu bũrũri wa Misiri o na gũkũ werũ-inĩ, no makĩĩnemera na makĩĩngeria maita ikũmi-rĩ,
23 ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
gũtirĩ o na ũmwe wa acio ũkoona bũrũri ũcio nderĩire maithe mao ma tene na mwĩhĩtwa. Gũtirĩ o na ũmwe wao wa arĩa maanyararĩte ũkaawona.
24 Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
No tondũ ndungata yakwa Kalebu arĩ na roho wa mũthemba ũngĩ na nĩanũmagĩrĩra na ngoro yake yothe, nĩngamũtwara bũrũri ũcio aathiĩte, nacio njiaro ciake nĩikaũgaya.
25 Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
Na tondũ andũ a Amaleki na a Kaanani matũũraga cianda-inĩ-rĩ, rokai kũgarũrũka mumagare mũrorete na werũ-inĩ, mũthiĩ na njĩra ya Iria Itune.”
26 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Nake Jehova akĩĩra Musa na Harũni atĩrĩ:
27 “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
“Nĩ nginya hĩndĩ ĩrĩkũ kĩrĩndĩ gĩkĩ kĩaganu gĩgũtũũra kĩĩnugunagĩra? Nĩnjiguĩte mateta ma anugunĩki aya a Isiraeli.
28 Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
Nĩ ũndũ ũcio meere atĩrĩ, ‘Jehova ekuuga ũũ: Ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo-rĩ, nĩ ngũmwĩka o maũndũ macio njiguĩte mũkĩaria.
29 Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
Ciimba cianyu ikaagũa werũ-inĩ ũyũ, inyuĩ arĩa othe mũrĩ na ũkũrũ wa mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na makĩria arĩa mwatarirwo hĩndĩ ya itarana na arĩa manugunĩte nĩ ũndũ wakwa.
30 Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
Gũtirĩ o na ũmwe wanyu ũgatoonya bũrũri ũcio ndehĩtire nyambararĩtie guoko atĩ nĩũgatuĩka wanyu, tiga o Kalebu mũrũ wa Jefune, na Joshua mũrũ wa Nuni.
31 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
No ha ũhoro wa ciana cianyu iria mwoigire atĩ nĩ igaatahwo-rĩ, nĩngamakinyia kuo makenagĩre bũrũri ũcio mũregete.
32 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
No inyuĩ-rĩ, ciimba cianyu ikaagũa werũ-inĩ ũyũ.
33 Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
Ciana cianyu igũtuĩka arĩithi gũkũ werũ-inĩ mĩaka mĩrongo ĩna, igĩthĩnĩkaga nĩ ũndũ wa kwaga kwĩhokeka kwanyu, nginya rĩrĩa kĩimba kĩanyu kĩa mũthia gĩkaagũa werũ-inĩ.
34 Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
Mĩaka mĩrongo ĩna, o mwaka ũmwe ũrũgamĩrĩire mũthenya ũmwe wa mĩthenya mĩrongo ĩna ĩrĩa mwathigaanire bũrũri ũcio, mĩaka ĩyo nĩyo mũgaathĩnĩka nĩ ũndũ wa mehia manyu, na mũmenye ũũru wa gũũkĩrĩrwo nĩ niĩ.’
35 Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
Niĩ Jehova nĩ niĩ njarĩtie, na ti-itherũ nĩngeeka maũndũ macio kũrĩ kĩrĩndĩ gĩkĩ gĩothe kĩaganu, kĩrĩa gĩĩcookanĩrĩirie hamwe kĩnjũkĩrĩre. Gĩgaathirĩra werũ-inĩ ũyũ; gũkũ nĩkuo gĩgaakuĩra.”
36 Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
Nĩ ũndũ ũcio, andũ arĩa Musa aatũmĩte magathigaane bũrũri ũcio wa Kaanani, o acio macookire na magĩtũma kĩrĩndĩ gĩothe kĩnugunĩre Musa nĩkũmemerekia ũhoro mũũru wa bũrũri ũcio,
37 Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
andũ acio mamemerekirie ũhoro ũcio mũũru wa bũrũri ũcio makĩhũũrwo na mũthiro, magĩkuĩra hau mbere ya Jehova.
38 Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
Harĩ andũ arĩa maathiĩte gũthigaana bũrũri ũcio, no Joshua mũrũ wa Nuni, na Kalebu mũrũ wa Jefune maatigarire.
39 Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
Rĩrĩa Musa aaheire andũ othe a Isiraeli ũhoro ũcio, makĩgirĩka mũno.
40 Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
Mũthenya ũyũ ũngĩ rũciinĩ tene makĩambata marorete bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma. Makiuga atĩrĩ, “Nĩtwĩhĩtie, nĩtũkwambata tũthiĩ nginya kũrĩa Jehova aatwĩrĩire.”
41 Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
No Musa akĩmooria atĩrĩ, “Mũraremera watho wa Jehova nĩkĩ? Ũndũ ũyũ ndũngĩgaacĩra!
42 Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
Mũtikambate tondũ Jehova ndarĩ hamwe na inyuĩ. Nĩmũkũhootwo nĩ thũ cianyu,
43 Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
nĩgũkorwo andũ a Amaleki na Akaanani nĩmakarũa na inyuĩ kũu. Nĩ ũndũ nĩ mũhutatĩire Jehova, nake ndegũkorwo hamwe na inyuĩ, na nĩmũkũũragwo na rũhiũ rwa njora.”
44 Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
No rĩrĩ, nĩ ũndũ wa mwĩĩro wao, makĩambata marorete bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma o na gũkorwo Musa ndoimire kambĩ o na kana ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova rĩkiuma kambĩ.
45 Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.
No rĩrĩ, andũ a Amaleki na Akaanani arĩa maatũũraga bũrũri ũcio ũrĩ irĩma, magĩikũrũka, makĩmatharĩkĩra, na makĩmahũũra mamaikũrũkĩtie o nginya Horoma.