< Numbers 14 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
Therfor al the cumpeny criede, and wepte in that nyyt,
2 Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
and alle the sones of Israel grutchiden ayens Moises and Aaron, and seiden,
3 Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
We wolden that we hadden be deed in Egipt, and not in this waast wildirnesse; we wolden that we perischen, and that the Lord lede vs not in to this lond, lest we fallen bi swerd, and oure wyues and fre children ben led prisoneris; whether it is not betere to turne ayen in to Egipt?
4 Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
And thei seiden oon to another, Ordeyne we a duyk to vs, and turne we ayen in to Egipt.
5 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
And whanne this was herd, Moises and Aaron felden lowe to erthe, bifor al the multitude of the sones of Israel.
6 Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
And sotheli Josue, the sone of Nun, and Caleph, the sone of Jephone, whiche also cumpassiden the lond, to renten her clothis,
7 Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
and spaken to al the multitude of the sones of Israel, The lond which we cumpassiden is ful good;
8 Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
if the Lord is merciful to vs, he schal lede vs in to it, and schal yyue `to vs the lond flowynge with mylk and hony.
9 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
Nyle ye be rebel ayens the Lord, nether drede ye the puple of this lond, for we moun deuoure hem so as breed; al her help passide awei fro hem, the Lord is with vs, nyle ye drede.
10 Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
And whanne al the multitude criede, and wolde oppresse hem with stonys, the glorie of the Lord apperide on the roof of the boond of pees, while alle the sones of Israel sien.
11 Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
And the Lord seide to Moises, Hou long schal this puple bacbite me? Hou longe schulen thei not bileue to me in alle `signes, whiche Y haue do bifor hem?
12 Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
Therfor Y schal smyte hem with pestilence, and Y schal waste hem; forsothe Y schal make thee prince on a greet folk, and strongere than is this.
13 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
And Moises seide to the Lord, Egipcians `here not, fro whos myddil thou leddist out this puple,
14 Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
and the dwelleris of this loond, whiche herden that thou, Lord, art in this puple, and art seyn face to face, and that thi cloude defendith hem, and that thou goist bifore hem in a pilere of cloude bi dai,
15 Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
and in a piler of fier bi nyyt, that thou hast slayn so greet a multitude as o man,
16 ‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
and seie thei, He myyte not brynge this puple in to the lond for whiche he swoor, therfor he killide hem in wildirnesse;
17 “Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
therfor the strengthe of the Lord be magnified, as thou hast swore. And Moises seide,
18 ‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
Lord pacient, and of myche mercy, doynge awei wickidnesse and trespassis, and leeuynge no man vngilti, which visitist the synnes of fadris in to sones in to the thridde and fourthe generacioun, Y biseche,
19 Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
foryyue thou the synne of this thi puple, aftir the greetnesse of thi merci, as thou were merciful to men goynge out of Egipt `til to this place.
20 Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
And the Lord seide, Y haue foryouun to hem, bi thi word.
21 Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
Y lyue; and the glorie of the Lord schal be fillid in al erthe;
22 Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
netheles alle men that sien my mageste, and my signes, whiche Y dide in Egipt and in the wildirnesse, and temptiden me now bi ten sithis, and obeieden not to my vois,
23 ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
schulen not se the lond for which Y swore to her fadris, nethir ony of hem that bacbitide me, schal se it.
24 Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
Y schal lede my seruaunt Caleph, that was ful of anothir spirit, and suede me, in to this lond, which he cumpasside, and his seed schal welde it.
25 Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
For Amalech and Cananei dwellen in the valeis, to morewe moue ye tentis, and turne ye ayen in to wildirnesse bi the weie of the reed see.
26 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
And the Lord spak to Moises and to Aaron, and seide,
27 “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
Hou long grutchith this werste multitude ayens me? Y haue herd the pleyntis of the sones of Israel.
28 Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
Therfor seie thou to hem, Y lyue, seith the Lord; as ye spaken while Y herde, so Y schal do to you;
29 Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
youre careyns schulen ligge in this wildirnesse. Alle ye that ben noumbrid, fro twenti yeer and aboue, and grutchiden ayens me,
30 Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
schulen not entre in to the lond, on which Y reiside myn hond, that Y schulde make you to dwelle outakun Caleph, the sone of Jephone, and Josue, the sone of Nun.
31 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
Forsothe Y schal lede in youre litle children, of whiche ye seiden that thei schulden be preyes `ethir raueyns to enemyes, that thei se the lond which displeside you.
32 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
Forsothe youre careyns schulen ligge in the wildirnesse;
33 Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
youre sones schulen be walkeris aboute in the deseert bi fourti yeer, and thei schulen bere youre fornycacioun, til the careyns of the fadris ben wastid in the deseert,
34 Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
by the noumbre of fourti daies, in whiche ye bihelden the loond; a yeer schal be arettid for a dai, and bi fourti yeer ye schulen resseyue youre wickidnesse, and ye schulen knowe my veniaunce.
35 Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
For as Y spak, so Y schal do to al this werste multitude, that roos to gidere ayens me; it schal faile, and schal die in this wildirnesse.
36 Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
Therfor alle the men whyche Moises hadde sent to see the lond, and whiche turniden ayen, and maden al the multitude to grutche ayens hym, and depraueden the lond, that it was yuel,
37 Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
weren deed, and smytun in the siyt of the Lord.
38 Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
Sotheli Josue, the sone of Nun, and Caleph, the sone of Jephone, lyueden, of alle men that yeden to se the lond.
39 Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
And Moises spak alle these wordis to alle the sones of Israel, and the puple mourenyde gretli.
40 Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
And, lo! thei riseden in the morewtid first, and `stieden in to the cop of the hil, and seiden, We ben redi to stie to the place, of which the Lord spak, for we synneden.
41 Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
To whiche Moises seide, Whi passen ye the word of the Lord, that schal not bifalle to you in to prosperite?
42 Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
Nyle ye stie, for the Lord is not with you, lest ye fallen bifor youre enemyes.
43 Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
Amalech and Cananei ben bifor you, bi the swerd of whiche ye schulen falle, for ye nolden assente to the Lord, nether the Lord schal be with you.
44 Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
And thei weren maad derk, and stieden in to the cop of the hil; forsothe the ark of the testament of the Lord and Moises yeden not awey fro the tentis.
45 Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.
And Amalech cam doun, and Chananei, that dwelliden in the hil, and he smoot hem, and kittide doun, and pursuede hem til Horma.

< Numbers 14 >