< Numbers 14 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
Da opløftede hele Menigheden sin Røst og brød ud i Klageråb, og Folket græd Natten igennem.
2 Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
Og alle Israelitterne knurrede imod Moses og Aron, og hele Menigheden sagde til dem: "Gid vi var døde i Ægypten eller her i Ørkenen!
3 Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
Hvorfor fører HERREN os til dette Land, når vi skal falde for Sværdet og vore Kvinder og Børn blive til Bytte? Var det dog ikke bedre for os at vende tilbage til Ægypten?"
4 Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
Og de sagde til hverandre: "Lad os vælge os en Fører og vende tilbage til Ægypten!"
5 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
Da faldt Moses og Aron på deres Ansigt foran hele den israelitiske Menigheds Forsamling.
6 Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
Men Josua, Nuns Søn, og Kaleb, Jefunnes Søn, der havde været med til at undersøge Landet, sønderrev deres Klæder
7 Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
og sagde til hele Israelitternes Menighed: "Landet, vi har rejst igennem og undersøgt, er et såre, såre godt Land.
8 Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
Hvis HERREN har Behag i os, vil han føre os til det Land og give os det, et Land, der flyder med Mælk og Honning.
9 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
Gør kun ikke Oprør imod HERREN og frygt ikke for Landets Befolkning, thi dem tager vi som en Bid Brød; deres Skygge er veget fra dem, men med os er HERREN; frygt ikke for dem!"
10 Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Hele Menigheden tænkte allerede på at stene dem; men da kom HERRENs Herlighed til Syne for alle Israelitterne ved Åbenbaringsteltet.
11 Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
Og HERREN sagde til Moses: "Hvor længe skal dette Folk håne mig, og hvor længe vil det vægre sig ved at tro på mig, til Trods for alle de Tegn jeg har gjort i det?
12 Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
Jeg vil slå det med Pest og udrydde det, men dig vil jeg gøre til et Folk, større og stærkere end det!"
13 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
Men Moses sagde til HERREN: "Ægypterne har hørt, at du i din Vælde har ført dette Folk bort fra dem;
14 Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
og ligeledes har alle dette Lands Indbyggere hørt, at du, HERRE, er midt iblandt dette Folk, thi du, HERRE, åbenbarer dig synligt, idet din Sky står over dem, og du vandrer foran dem om Dagen i en Skystøtte og om Natten i en Ildstøtte.
15 Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
Hvis du nu dræber dette Folk alle som een, vil de Folk, der har hørt dit Ry, sige:
16 ‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
Fordi HERREN ikke evnede at føre dette Folk til det Land, han havde tilsvoret dem, lod han dem omkomme i Ørkenen.
17 “Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
Derfor, HERRE, lad din Vælde nu vise sig i sin Storhed, således som du forjættede, da du sagde:
18 ‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
HERREN er langmodig og rig på Miskundhed, han forlader Misgerning og Overtrædelse, men han lader ingen ustraffet, og han hjemsøger Fædrenes Brøde på Børnene i tredje og fjerde Led.
19 Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
Så tilgiv nu dette Folk dets Misgerning efter din store Miskundhed, således som du har tilgivet dette Folk hele Vejen fra Ægypten og hertil!"
20 Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Da sagde HERREN: "Jeg tilgiver dem på din Bøn.
21 Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
Men så sandt jeg lever så sandt hele Jorden skal opfyldes af HERRENs Herlighed:
22 Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
Ingen af de Mænd, der har set min Herlighed og de Tegn, jeg har gjort i Ægypten og i Ørkenen, og dog nu for tiende Gang har fristet mig og ikke villet lyde min Røst,
23 ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
ingen af dem skal se det Land, jeg tilsvor deres Fædre! Ingen af dem, der har hånet mig, skal få det at se;
24 Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
kun min Tjener Kaleb lader jeg komme til det Land, han har været i, og hans Efterkommere skal få det i Eje, fordi han havde en anden Ånd og viste mig fuld Lydighed.
25 Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
Men Amalekiterne og Kana'anæerne bor i Lavlandet. Vend derfor om i Morgen, bryd op og drag ud i Ørkenen ad det røde Hav til!"
26 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Fremdeles talede HERREN til Moses og Aron og sagde:
27 “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
"Hvor længe skal jeg tåle denne onde Menighed, dem, som bestandig knurrer imod mig? Jeg har hørt Israelitternes Knurren, hørt, hvorledes de knurrer imod mig.
28 Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
Sig til dem: Så sandt jeg lever lyder det fra HERREN, som I har råbt mig i Øret, således vil jeg handle med eder!
29 Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
I Ørkenen her skal eders Kroppe falde, alle I, der blev mønstret, så mange I er fra Tyveårsalderen og opefter, I, som har knurret imod mig.
30 Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
Sandelig, ingen af eder skal komme til det Land, jeg med løftet Hånd svor at ville giver eder at bo i, med Undtagelse af Kaleb, Jefunnes Søn, og Josua, Nuns Søn.
31 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
Eders små Børn, som I sagde vilde blive til Bytte, dem vil jeg lade komme derhen, og de skal tage det Land i Besiddelse, som I har vraget,
32 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
men eders egne Kroppe skal falde i Ørkenen her,
33 Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
og eders Sønner skal flakke om i Ørkenen i fyrretyve År og undgælde for eders Bolen, indtil eders Kroppe er gået til Grunde i Ørkenen.
34 Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
Som I brugte fyrretyve Dage til at undersøge Landet, således skal I undgælde for eders Misgerninger i fyrretyve År, eet År for hver Dag, og således få mit Mishag at føle.
35 Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
Jeg HERREN har sagt det: Sandelig, således vil jeg handle med hele denne onde Menighed, der har rottet sig sammen imod mig; i Ørkenen her skal de gå til Grunde, i den skal de dø!"
36 Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
Og de Mænd, Moses havde udsendt for at undersøge Landet, og som efter deres Tilbagekomst havde fået hele Menigheden til at knurre imod ham ved at tale nedsættende om Landet,
37 Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
de Mænd, der havde talt nedsættende om Landet, fik en brat Død for HERRENs Åsyn:
38 Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
kun Josua, Nuns Søn, og Kaleb, Jefunnes Søn, blev i Live af de Mænd, der var draget hen for at undersøge Landet.
39 Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
Men da Moses forebragte alle Israelitterne disse Ord, grebes Folket af stor Sorg;
40 Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
og tidligt næste Morgen drog de op mod det øverste af Bjerglandet og sagde: "Se, vi er rede til at drage op til det Sted, HERREN har talet om, thi vi, har syndet."
41 Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
Da sagde Moses: "Hvorfor vil I overtræde HERRENs Bud? Det vil ikke gå godt!
42 Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
Drag ikke derop, thi HERREN er ikke iblandt eder; gør I det, bliver I slået af eders Fjender!
43 Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
Thi Amalekiterne og Kana'anæerne vil møde eder der, og I skal falde for Sværdet; I har jo vendt eder fra HERREN, og HERREN er ikke med eder!"
44 Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
Alligevel formastede de sig til at drage op mod det øverste af Bjerglandet; men HERRENs Pagts Ark og Moses forlod ikke Lejren.
45 Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.
Da steg Amalekiterne og Kana'anæerne, der boede der i Bjerglandet, ned og slog dem og adsplittede dem lige til Horma.

< Numbers 14 >