< Numbers 14 >
1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
Hahoi teh, kamkhuengnaw pueng ni hote tangmin puenghoi a khuika awh.
2 Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
Isarel catounnaw pueng Mosi hoi Aron koe a phuenang awh. Kamkhueng e tamimaya koevah, Izip ram vah dout awh ngala pawiteh, hoehpawiteh hete kahrawngum dout ngala pawiteh,
3 Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
bangkongmaw, tahloi hoi thei vaiteh, yuca pueng taran kut dawk pha sak hanelah maw BAWIPA ni hete ram dawk na ceikhai. Izip ram bout ban pawiteh, maimouh han bet a hawihnawn nahoehmaw telah ati awh.
4 Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
Hahoi a kamkhueng awh teh kahrawikung rawi vaiteh, Izip ram vah ban awh sei telah ati awh.
5 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
Mosi hoi Aron teh kamkhueng e Isarelnaw pueng e hmalah a tabo roi.
6 Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
Hateiteh, Nun capa Joshua hoi Jephunneh capa Kalep, ram katuetnaw thung dawk ka bawk roi van e ni a hni a phi roi teh,
7 Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
kamkhueng e Isarelnaw pueng koe tuet hanelah ka cei sin awh e ram teh, kahawi poung tangngak e doeh.
8 Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
Maimouh koe BAWIPA a lunghawi pawiteh, ama ni na cetkhai awh vaiteh, khoitui hoi sanutui a lawngnae ram teh na poe han doeh.
9 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
BAWIPA taranlahoi taranthaw laipalah, hote ram dawk e tami taket laipalah, awm awh sei. Bangkongtetpawiteh, ahnimouh teh maimae rawca lah doeh awm awh ti, ahnimanaw teh a kângue awh e awm hoeh. BAWIPA teh maimouh koe ao. Ahnimouh teh taket awh hanh sei telah ati roi.
10 Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Hahoi ka kamkhueng e pueng ni talung hoi dêi han a noe awh. Hahoi BAWIPA bawilennae teh kamkhuengnae lukkareiim dawk hoi Isarelnaw pueng e hmalah a kamnue pouh.
11 Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
BAWIPA ni Mosi koevah hete taminaw pueng nâtotouh maw na pahnawt awh han. Ahnimouh koe mitnoutnae ka sak pouh ei teh, nâtotouh maw yuem laipalah ao awh han.
12 Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
Lacik hoi ka yue vaiteh, be ka pahma ngala han. Nang dawkvah, ahnimouh hlak ka sungren e hoi hno ka tet thai e miphun ka kangdue sak han telah a ti.
13 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
Mosi ni BAWIPA koevah hot teh Izipnaw ni thai langvaih. Bangkongtetpawiteh, hete tamihupui heh na thao e lahoi na tâcokhai e naw doeh.
14 Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
Hot teh hete ram taminaw koe a dei pou han. BAWIPA nang teh hete taminaw koevah na o teh, BAWIPA nang nama teh minhmai phek kadangka lah na hmu awh kanîthun tâmaikhom hoi karum lah hmaikhom hoi a hmalah na cei pouh tie a panue awh toe.
15 Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
Hot patetlah hete tamimaya heh tami buet touh e patetlah na thei pawiteh, na min kamthang ka panuek e miphunnaw ni,
16 ‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
BAWIPA ni hete tamimayanaw heh thoebo hoi a kam e ram dawk a hrawi thai hoeh dawkvah, kahrawngum koung a thei telah a dei awh han.
17 “Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
BAWIPA ni a lungsaw teh lungmanae hoi ka kawi e, payonnae hoi kâtapoenae ka ngaithoumkung yonpen e naw kayawicalah hloutsak laipalah,
18 ‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
napanaw yonnae kecu dawk canaw, catounnaw se thum se pali totouh, ouk karekkung doeh na a telah na dei tangcoung e patetlah BAWIPA na hnosakthainae teh, hoe lentoe lawiseh.
19 Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
Na lungmanae a pap e patetlah hoi Izip ram hoi atu totouh na ngaithoum e patetlah na tamimaya e payonnae naw hah ngaithoum pouh haw telah ka ratoum.
20 Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Hat toteh, BAWIPA ni na lawk patetlah ka ngaithoum toe.
21 Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
Hatei, ka hring e patetlah BAWIPA bawilennae hoi talai heh muen a kawi han.
22 Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
Izip ram hoi kahrawngum ka sak e naw bawilennae hoi kângairunae a hmuen teh, vai hra totouh na tanouk teh, ka lawk ka ngaihoeh e naw pueng ni,
23 ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
kakhekungnaw koe thoebo nalaihoi ka kam pouh e ram teh, hmawt awh roeroe mahoeh. Ahnimouh rahak ka lawk banglahai ka ngaihoehnaw ni hmawt mahoeh.
24 Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
Hatei, ka san Kalep, aloukcalah kaawm e muitha hah tawn teh, atangcalah ka hnuk a kâbang dawk, ahni teh a pâtam e ram koe ka hrawi vaiteh, a catounnaw ni a coe awh han.
25 Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
Atuvah, Amaleknaw hoi Kanaan taminaw hah ayawn dawk ao awh. Tangtho vah ban awh nateh tuipui paling lam koelah hoi kahrawng dawk kâen awh telah a ti.
26 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
BAWIPA ni, Mosi hoi Aron a pato teh,
27 “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
hete kamkhueng e tamikathoutnaw e phuenangnae heh, nâtotouh maw ka ring han. Kai taranlahoi Isarel catounnaw lai a roe awh e ka thai.
28 Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
Ahnimouh koe ka hring e patetlah ka hnâthainae koe na dei awh e patetlah nangmouh lathueng ka sak han, telah BAWIPA ni a dei.
29 Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
Nangmouh ni milu na parei awh teh na touk awh tangcoung e patetlah, kum 20 lathueng kai koe laikaroenaw pueng teh, hete kahrawngum vah ro lah a o awh han.
30 Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
Kai ni hete ram dawk na o sak awh awh han ka ti e ram dawkvah, Jephunneh capa Kalep hoi Nun capa Joshua laipateh api hai phat awh mahoeh.
31 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
Hatei, thei hanelah doeh ao awh, na tie na canaw hah ka kâen sak vaiteh, na ngai awh hoeh ram dawk kho a sak awh han.
32 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
Hatei, nangmanaw teh na ronaw ramke dawk koung a kamlei han.
33 Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
Na capanaw hah kahrawngum vah kum 40 touh a kâva awh vaiteh, ramke dawk a ro hah a pawk awh hoehroukrak, namamouh na kâyo phu na phu awh han.
34 Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
Ram na tuetnae hnin 40 touh hah, hnin touh yueng lah kum touh telah to lahoi kum 40 touh thung kâtapoe phu na khang awh han. Ka noenae yo a kâthung toe tie na panue awh han.
35 Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
Kai BAWIPA ni hete tamikathoutnaw kai taranlahoi kamkhueng e maya pueng koevah, hetheh ka sak roeroe han ka ti toe. Hete kahrawngum vah kahmakata vaiteh, hawvah a due awh han ati telah a dei tet pouh loe.
36 Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
Hottelah ram tuet hanlah Mosi ni a patoun teh ka ban awh e ram kong kamthang kathout lah ka pathang e naw, ama taranlahoi tamimaya lai ka roe sak e hoi,
37 Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
ram kong dawk kamthangmathout kaphawtnaw roeroe hah BAWIPA hmalah lacik hoi a due awh.
38 Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
Hatei, ram tuet han kacetnaw thung dawk Nun capa Joshua hoi Jephunneh capa Kalep teh a hring roi rah.
39 Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
Hat toteh, Mosi ni hote lawk teh Isarelnaw pueng koevah a dei pouh teh, taminaw pueng ni a thai awh teh a lung koung a mathoe awh.
40 Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
Hottelah amom vah a thaw teh, monsom vah a luen. Khenhaw, ka tho toe. BAWIPA ni na kam pouh e koelah ka cei han. Bangkong, ka payon toe telah a ti.
41 Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
Mosi ni, bangkongmaw BAWIPA kâpoelawk na ek awh, Bangkongtetpawiteh, hete ni kuepcing sak thai mahoeh toe.
42 Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
Takhang awh hanh, telah hoehpawiteh, na tarannaw ni na tâ awh han, bangdawk nangmouh koe BAWIPA awm hoeh.
43 Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
Nangmouh hmalah Ameleknaw hoi Kanaannaw a o, tahloi hoi be na thet awh langvaih. BAWIPA teh na kamlang takhai dawkvah nangmouh koe BAWIPA awm hoeh telah a ti.
44 Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
Hatei, monsom cei han pou a kâcai awh. Hatei BAWIPA lawkkam thingkong hoi Mosi hai rim dawk hoi tâcawt hoeh.
45 Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.
Hottelah hot mon dawk kaawmnaw Ameleknaw hoi Kanaannaw hah a cathuk awh teh, a tuk awh. Hormah totouh a pâlei awh.