< Numbers 14 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
Rhaengpuei boeih hol uh tih a ol te a huel uh. Te phoeiah pilnam he tekah khoyin ah rhap uh.
2 Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
Israel ca pum he Moses taeng neh Aaron taengah nul uh. Te rhoi taengah rhaengpuei boeih loh, “Egypt kho ah n'duek uh mako, he khosoek ah nim n'duek mai mako.
3 Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
cunghang dongah cungku ham he BOEIPA loh balae tih he khohmuen la mamih n'khuen. Mamih yuu ca he maeh la om uh pawn ni. Egypt la mael he mamih ham then ngai pawt nim? a Boeipa loh mamih he hela ingkhueh uh? Egypt ramla koep mael he then ngai mah pawt a? Moses neh Aaron taengah ati nauh.
4 Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
Te vaengah hlang loh a manuca taengah, “A lu pakhat n'tuek uh vetih Egypt la m'mael uh mako,” a ti uh.
5 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
Te vaengah Moses neh Aaron tah Israel ca rhaengpuei hlangping boeih kah mikhmuh ah a maelhmai te a buenglueng rhoi.
6 Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
Tedae khohmuen aka yaam khuikah Nun capa Joshua neh Jephunneh capa Kaleb long tah a himbai te a phen rhoi.
7 Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Te phoeiah Israel ca rhaengpuei boeih te a thui rhoi tih, “Te khohmuen ka paan uh tih ka yaam vaengah khohmuen khaw bahoeng, bahoeng then.
8 Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
BOEIPA he mamih taengah hmae tih mamih he te khohmuen la m'pawk sak vaengah suktui neh khoitui aka long khohmuen te mamih taengah m'paek bitni.
9 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
BOEIPA bueng te tloelh uh boeh, nangmih loh khohmuen kah pilnam te rhih uh boeh. Amih kah hlipkhup te amih taeng lamloh nong coeng tih amih te mamih kah buh la om coeng. Tedae BOEIPA he mamih taengah a om dongah amih te rhih uh boeh,” a ti rhoi.
10 Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Te vaengah rhaengpuei pum loh amih rhoi te lungto neh dae ham cai uh. Tedae BOEIPA kah thangpomnah tah tingtunnah dap kah Israel ca boeih taengah a phoe pah.
11 Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
Te phoeiah BOEIPA loh Moses te, “He pilnam loh kai he mevaeng hil n'tlaitlaek uh vetih a khui ah miknoek cungkuem ka saii lalah mevaeng hil nim kai he n'tangnah uh pawtve.
12 Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
Amih te duektahaw neh ka ngawn vetih ka haek ni. Tedae nang te namtom tanglue la kang khueh vetih amih lakah na pilnu ngai ni,” a ti nah.
13 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
Tedae Moses loh BOEIPA taengah, “A khui lamloh na thadueng neh he pilnam na khuen te Egypt loh ya saeh.
14 Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
He khohmuen kah khosa rhoek taengah thui uh saeh. He pilnam lakli ah BOEIPA namah na om te a yaak uh tih BOEIPA namah taengah mik neh mik khaw hmu uh rhoi coeng. Nang kah cingmai khaw amih soah pai. Amih mikhmuh ah khothaih kah cingmai tung neh khoyin ah hmai tung la na caeh pah.
15 Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
He pilnam he hlang pakhat bangla na duek sak koinih nang olthang a yaak vaengah namtom loh a thui bal ni.
16 ‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
Te vaengah, “Amih ham a toemngam pah khohmuen la BOEIPA loh he pilnam he khuen ham a coeng pawt dongah amih te khosoek ah a ngawn,” a ti uh ni.
17 “Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
Thui ham na ti vanbangla ka Boeipa kah thadueng te pomsang mai laeh saeh.
18 ‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
BOEIPA tah thintoek a ueh tih sitlohnah khaw puh. Thaesainah neh boekoek khaw a phueih pah dae pa rhoek kathaesainah te ca rhoek soah khongthum, khongli duela a cawh tih hmil rhoe hmil pawh.
19 Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
Na sitlohnah dongkah boeilennah neh Egypt lamloh tahae hil pilnam na khuen bangla he pilnam kathaesainah he khodawkngai mai,” a ti nah.
20 Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Te dongah BOEIPA loh, “Nang ol bangla khodawk ka ngai coeng.
21 Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
Kai ka hingnah la ka om dongah BOEIPA kah thangpomnah he diklai pum ah bae.
22 Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
Egypt neh khosoek ah ka tueng sak kamah kah thangpomnah neh ka miknoek te hlang boeih loh a hmuh. Tedae kai he voei rha khaw n'noemcai uh tih kai ol he hnatun uh pawh.
23 ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
A napa rhoek taengah ka toemngam pah khohmuen te hmu uh pawt vetih kai aka tlaitlaek boeih loh te hmu mahpawh.
24 Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
Ka sal Kaleb tah a khuiah mueihla tloe a om tih kai hnukah hnawn uh. Te dongah anih te a pawk ham koi khohmuen la pahoi ka khuen vetih a tiingan loh te te a pang ni.
25 Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
Kol kah khosa Amalek neh Kanaan te thangvuen ah mael laeh saeh lamtah nangmih ham khosoek kah carhaek tuipuei longpuei te paan uh laeh,” a ti nah.
26 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Te phoeiah BOEIPA loh Moses neh Aaron te a voek tih,
27 “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
Boethae he rhaengpuei ham me hil nim kai taengah a nul uh ve? Amih Israel ca rhoek kah kohuetnah loh kai taengah a nul uh khaw ka yaak coeng.
28 Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
Kai hingnah BOEIPA kah olphong he amih taengah thui pah. Kai hna ah na thui bangla nangmih taengah ka saii van mahpawt nim?
29 Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
Na hlangmi boeih khuiah capa kum kul lamloh a so hang na soep thil boeih khaw kai taengah na nul vanbangla na rhok te he khosoek ah yalh ni.
30 Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
A khuiah nangmih khosak sak ham ka kut ka phuel coeng dae Jephunneh capa Kaleb neh Nun capa Joshua phoeiah tah te khohmuen la nangmih na kun uh mahpawh.
31 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
Na ca rhoek khaw maeh la om pawnko na ti uh cakhaw amih te a pawk puei vetih khohmuen na hnawt uh te khaw a ming uh bitni.
32 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
Tedae nangmih tah namamih rhok te he khosoek ah ni a. yalh eh.
33 Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
Na ca rhoek te khosoek ah boiva aka dawn la kum likip om uh vetih na rhok a cing hil khosoek ah nangmih kah pumyoihnah te a phueih uh ni.
34 Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
Khohnin la hnin likip khuiah khohmuen na yaam uh vaengkah khohnin tarhing ah a kum dongah khaw hnin at te kum khat la om ni. Nangmih kathaesainah te kum sawmli na phueih uh vaengah kai kah noihhainah te na ming uh bitni.
35 Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
Kai BOEIPA loh ka thui coeng atah he boethae rhaengpuei boeih taengah ka saii het mahpawt nim. Kai aka tuentah rhoek te he khosoek ah khawk uh tih pahoi duek uh ni,” a ti nah.
36 Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
Te dongah Moses loh khohmuen yaam ham a tueih hlang a mael uh vaengah tah rhaengpuei boeih te a taengah rhaeh la rhaeh uh tih khohmuen kawng te theetnah la a khuen.
37 Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
Khohmuen kah theetnah aka khuen hlang rhoek tah BOEIPA mikhmuh kah lucik dongah a thae la duek uh.
38 Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
Tedae khohmuen yaam ham aka cet hlang rhoek khui lamloh Nun capa Joshua neh Jephunneh capa Kaleb tah hing.
39 Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
Moses loh he ol he Israel ca boeih taengah a thui vaengah pilnam bung bung nguekcoi uh.
40 Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
Mincang ah thoo uh tih tlang som la luei uh. “Amah dae la he, n'tholh uh dongah BOEIPA kah a thui hmuen la cet uh pawn sih,” a ti uh.
41 Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
Te vaengah Moses loh, “Balae tih BOEIPA olka te na poe uh, te thaihtak he mahpawh.
42 Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
Cet uh boeh, nangmih khui ah BOEIPA a om moenih. Na thunkha rhoek mikhmuh ah na yawk uh mahpawt nim?
43 Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
Nangmih mikhmuh ah Amalek neh Kanaan om lah ko. BOEIPA hnuk lamloh na mael uh dongah cunghang neh na cungku uh ni. Nangmih taengah BOEIPA om mahpawh,” a ti nah.
44 Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
Te vaengah tlang som la luei ham calak uh dae BOEIPA kah paipi thingkawng neh Moses tah rhaehhmuen khui lamloh nong pawh.
45 Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.
Tlang kah khosa Amalek neh Kanaan te ha suntla vaengah tah Amih te a ngawn uh tih Hormah duela amih te a phop uh.

< Numbers 14 >