< Numbers 14 >

1 Gbogbo ìjọ ènìyàn sì gbóhùn sókè, wọ́n sì sọkún ní òru ọjọ́ náà.
To aqum naah kaminawk loe tha hoi hangh o moe, qah o.
2 Gbogbo ọmọ Israẹli sì kùn sí Mose àti Aaroni, gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli sì wí fún wọn pé, “Àwa ìbá kúkú ti kú ní ilẹ̀ Ejibiti. Tàbí kí a kúkú kú sínú aginjù yìí.
Israel kaminawk boih mah Mosi hoi Aaron to laisaep o thuih, Izip prae ah maw, to tih ai boeh loe praezaek ah duek halat nahaeloe hoih han to mah!
3 Kí ló dé tí Olúwa fi mú wa wá sí ilẹ̀ yìí láti fi idà pa wá? Àwọn ìyàwó wa, àwọn ọmọ wa yóò sì di ìjẹ. Ǹjẹ́ kò wa, ní í dára fún wa bí a bá padà sí Ejibiti?”
Tikhoe aicae loe sumsen hoiah a duek o moe, aicae ih zu caanawk minawk mah lomh hanah, Angraeng mah hae prae ah caeh haih loe? Izip prae ah amlaem let nahaeloe, hoikhang tih, tiah nihnik khaeah thuih pae o.
4 Wọ́n sì sọ fún ara wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí á yan olórí kí á sì padà sí Ejibiti.”
To naah angmacae hoi angmacae zaehoikung to qoi o si loe, Izip prae ah amlaem o let si, tiah a thuih o.
5 Nígbà náà ni Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ níwájú gbogbo ìjọ ọmọ Israẹli.
Mosi hoi Aaron mah to ah amkhueng Israel kaminawk boih hma ah, long ah akuep pae hoi.
6 Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne, tí wọ́n wà lára àwọn to lọ yẹ ilẹ̀ wò sì fa aṣọ wọn ya.
Kanaan prae khet han kacaeh, Nun capa Joshua hoi Jephunneh capa Kaleb loe, angmah hnik ih kahni to angkhring hoi pacoengah,
7 Wọ́n sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli pé, “Ilẹ̀ tí a là kọjá láti yẹ̀ wò náà jẹ́ ilẹ̀ tí ó dára lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
to ah amkhueng Israel kaminawk boih khaeah, a caeh o moe, a khet o ih prae loe hoih parai.
8 Bí inú Olúwa bá dùn sí wa, yóò mú wa dé ilẹ̀ náà, ilẹ̀ tó ń sàn fún wàrà àti fún oyin, yóò fún wa ní ilẹ̀ náà.
Angraeng mah aicae nuiah palung tongh nahaeloe, tahnutui hoi khoitui longhaih prae thungah, aicae na caeh haih ueloe, hae prae hae aicae han na paek tih.
9 Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa. Kí ẹ sì má bẹ̀rù àwọn ènìyàn ìlú náà, nítorí pé a ó gbé wọn mì, ààbò wọn ti fi wọ́n sílẹ̀, Olúwa sì wà pẹ̀lú àwa, ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn.”
Angraeng nuiah laisaep o hmah loe, to ih prae kaminawk to zii o hmah; nihcae loe a caak o han koi takaw ah ni oh o; nihcae loe angvaenghaih tawn o ai; Angraeng loe aicae hoi nawnto oh; nihcae to zii o hmah, tiah a naa hoi.
10 Ṣùgbọ́n gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń sọ pé àwọn yóò sọ wọ́n lókùúta pa. Nígbà náà ni ògo Olúwa fi ara hàn ní àgọ́ ìpàdé níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Toe kaminawk mah nihnik to thlung hoiah vah han thuih o; to naah Angraeng lensawkhaih Israel kaminawk amkhuenghaih kahni imthung ah phak.
11 Olúwa sọ fún Mose pé, “Fún ìgbà wo ni àwọn ènìyàn yìí yóò ti kẹ́gàn mi tó? Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí wọ́n ó fi kọ̀ jálẹ̀ láti gbà mí gbọ́, pẹ̀lú gbogbo iṣẹ́ àmì tí mo ṣe láàrín wọn?
Angraeng mah Mosi khaeah, Hae kaminawk mah nasetto maw palung na phui o sak tih? Nihcae khaeah ka sak ih dawnrai hmuen to a hnuk o boeh; toe nasetto maw hae kaminawk mah kai tang ai ah om o vop tih?
12 Èmi ó kọlù wọ́n pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, èmi ó gba ogún wọn lọ́wọ́ wọn, èmi ó sì pa wọ́n run ṣùgbọ́n èmi ó sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá tó sì lágbára jù wọ́n lọ.”
Nihcae nuiah kasae nathaih ka phaksak han, qawk doeh ka toepsak mak ai; toe nihcae pong kalen kue, thacak kue acaeng ah nang to kang sak han, tiah a naa.
13 Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà náà ni àwọn ará Ejibiti yóò gbọ́! Nítorí pé nípa agbára rẹ ni ìwọ fi mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí jáde kúrò láàrín wọn.
Mosi mah Angraeng khaeah, To tiah nahaeloe, Na thacakhaih hoiah hae kaminawk hae na zaehhoih, tiah Izip kaminawk mah panoek o tih boeh;
14 Wọ́n ó sì sọ fún àwọn olùgbé ilẹ̀ yìí. Àwọn tó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé ìwọ Olúwa wà láàrín àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti pé wọ́n rí ìwọ, Olúwa, ní ojúkojú, àti pé ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ dúró lórí wọn, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì ń lọ níwájú wọn pẹ̀lú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ní ọ̀sán àti pẹ̀lú ọ̀wọ́n iná ní òru.
to naah nihcae mah hae prae ah kaom kaminawk khaeah hae tamthang hae thui pae o tih; Angraeng, nang loe hae kaminawk hoi nawnto na oh, Angraeng, nang to mikhmai kangtong ah a hnuk o boeh; nang ih tamai loe nihcae nuiah angdoet moe, nang loe nihcae hma ah na caeh; khodai ah nihcae to tamai hoiah na zaeh moe, khoving ah hmaithaw hoiah na caeh haih.
15 Bí ìwọ bá pa àwọn ènìyàn wọ̀nyí lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, àwọn orílẹ̀-èdè tó bá gbọ́ ìròyìn yìí nípa rẹ yóò wí pé,
Hae kaminawk boih hae kami maeto baktiah vaihi na dueksak nahaeloe, nang ih tamthang thaih acaengnawk mah loe,
16 ‘Nítorí pé Olúwa kò le è mú àwọn ènìyàn wọ̀nyí dé ilẹ̀ tí ó ṣèlérí fún wọn; torí èyí ló ṣe pa wọ́n sínú aginjù yìí.’
Angraeng mah to kaminawk khaeah prae to kang paek han, tiah lokkamhaih a sak pae; toe anih mah to prae thungah caeh haih thai ai pongah, praezaek ah a hum boih, tiah thui o tih.
17 “Báyìí, mo gbàdúrà, jẹ́ kí agbára Olúwa tóbi gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ pé,
Na thuih ih lok baktih toengah, vaihiah ka Angraeng thacakhaih to len nasoe,
18 ‘Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ tó dúró ṣinṣin, tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ àti ìrékọjá jì. Bẹ́ẹ̀ ni kì í jẹ́ kí ẹlẹ́bi lọ láìjìyà; tó ń fi ìyà ẹ̀ṣẹ̀ baba jẹ ọmọ títí dé ìran kẹta àti ìran kẹrin.’
Angraeng loe palungsawk, amlunghaih hoiah koi moe, zaehaih hoi sakpazaehaihnawk to tahmen pae; toe zaehaih sah kami loe thuitaek ai ah om ai; anih loe ampanawk zaehaih pongah adung thum, adung pali karoek to a caanawk thuitaekkung ah oh.
19 Dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn yìí jì wọ́n, mo bẹ̀ ọ́, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ńlá rẹ, bí o ti ṣe ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n láti ìgbà tí o ti kó wọn kúrò ní Ejibiti di ìsin yìí.”
Kalen parai na palungnathaih rang hoiah, Izip prae thung hoi kamtong vaihni ni khoek to hae kaminawk hae na tahmen baktih toengah, hae kaminawk zaehaih doeh tahmen raeh, tiah a naa.
20 Olúwa sì dáhùn pé, “Mo ti dáríjì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Angraeng mah, Nang hnik ih lok baktih toengah, kang tahmen boeh;
21 Ṣùgbọ́n nítòótọ́ bí mo ti wà láààyè, gbogbo ayé yóò kún fún ògo Olúwa.
toe kai ka hing tangtang baktih toengah, longpum ah Angraeng lensawkhaih to koi tih.
22 Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn tó rí ògo mi àti àwọn iṣẹ́ àmì tí mo ṣe ní ilẹ̀ Ejibiti àti nínú aginjù ṣùgbọ́n tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí mi, tí wọn sì dán mi wò ní ìgbà mẹ́wàá yìí,
Izip prae hoi praezaek ah ka sak ih lensawkhaih hoi dawnrai hmuennawk hnu kaminawk boih mah ka lok hae tahngai o ai, vai hato Kai ang tanoek o pongah,
23 ọ̀kan nínú wọn kò ní rí ilẹ̀ náà tí mo ṣe ìlérí ní ìbúra láti fún baba ńlá wọn. Kò sí ọ̀kan nínú àwọn tó kẹ́gàn mi tí yóò rí ilẹ̀ náà.
ampanawk khaeah paek han tiah lokkam ih prae to mi mah doeh hnu o mak ai; kai palungphuisak kawbaktih kami mah doeh to prae to hnu o mak ai.
24 Ṣùgbọ́n nítorí pé Kalebu ìránṣẹ́ mi ní ẹ̀mí ọ̀tọ̀, tí ó sì tún tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, èmi ó mu dé ilẹ̀ náà tó lọ yẹ̀ wò, irú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì jogún rẹ̀.
Toe ka tamna Kaleb loe, kalah poekhaih pakhra to tawnh moe, palungthin boih hoiah kai ang bang pongah, anih to a caehhaih prae thungah ka hoih han; anih ih caanawk mah prae to toep o tih.
25 Níwọ́n ìgbà tí àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń gbé ní àfonífojì, ẹ yípadà lọ́la kí ẹ sì dojúkọ aginjù lọ́nà Òkun Pupa.”
Amalek hoi Kanaan kaminawk loe azawn ah khosak o; khawnbang ah amlaem oh loe, tuipui kathim bang hoiah praezaek ah caeh oh, tiah a naa.
26 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Angraeng mah Mosi hoi Aaron khaeah,
27 “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó tí àwọn ìjọ ènìyàn búburú yìí yóò fi máa kùn sí mi? Mo ti gbọ́ kíkùn tí àwọn ọmọ Israẹli ń kùn sí mi.
ka lok to aek moe, laisaep hae ih kasae kaminawk hae nasetto maw ka pauep han vop? Israel kaminawk mah kasae ang thuih o moe, kai laisaep thuihaih lok to ka thaih boeh.
28 Sọ fún wọn, bí mo ti wà láààyè nítòótọ́ ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ wí létí mi ni èmi ó ṣe fún un yín.
Nihcae khaeah, Kai ka hing pongah, ka naa ah nang thuih o ih baktih toengah, ka sak han, tiah Angraeng mah thuih.
29 Nínú aginjù yìí ni ẹ ó kú sí, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kùn láti ọmọ ogún ọdún ó lé àní gbogbo ẹ̀yin tí a kà.
Na kroek o ih nangmacae kaminawk boih thungah, kai laisaep thuih, saning pumphaeto hoi ranuih bang kaminawk loe praezaek ah dueh o tih.
30 Ọ̀kan nínú yín kò ní í dé ilẹ̀ tí mo búra nípa ìgbọ́wọ́sókè láti fi ṣe ibùgbé yín, bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne àti Joṣua ọmọ Nuni.
Jephunneh capa Kaleb hoi Nun capa Joshua khue ai ah loe, ban ka payangh moe, ohsak hanah lok ka kam ih prae thungah mi doeh akun o mak ai.
31 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn ọmọ yín tí ẹ wí pé wọn ó di ìjẹ, àwọn ni n ó mú dé bẹ̀ láti gbádùn ilẹ̀ tí ẹ kọ̀sílẹ̀.
Misa mah lomh ving tih, tiah na thuih o ih na caanawk to kai mah ka zaeh han, nangcae mah na khet patoek o ih prae to nihcae mah panoek o tih.
32 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, òkú yín yóò ṣubú ní aginjù yìí.
Toe nangcae loe hae praezaek ah na dueh o ueloe, qok doeh pong sut tih.
33 Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ yín yóò sì máa rin kiri nínú aginjù fun ogójì ọdún wọn ó máa jìyà nítorí àìnígbàgbọ́ yín, títí tí ọkàn gbogbo yín yóò fi ṣòfò tán ní aginjù.
Nangcae loe oepthok ah kho na sah o ai pongah, praezaek ah nangcae ih qok to pong sut boih ai karoek to, na caanawk loe saning qui palito thung praezaek ah amhet o tih.
34 Fún ogójì ọdún èyí jẹ́ ọdún kan fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan nínú ogójì ọjọ́ tí ẹ fi yẹ ilẹ̀ náà wò ẹ̀yin ó sì jìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ yín, ẹ ó sì mọ bí ó ti rí láti lòdì sí mi.
Prae pakrong hanah ni qui palito akra baktih toengah, nito hae saningto ah suem oh, na sak o ih zaehaih atho baktih toengah, saning qui palito thung patang na khang o tih; to naah ka lok aekhaih atho to na panoek o tih, tiah a naa.
35 Èmi, Olúwa, lo sọ bẹ́ẹ̀; Èmi ó sì ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí ìjọ ènìyàn búburú yìí tí wọ́n kó ra wọn jọ lòdì sí mi. Nínú aginjù yìí ni òpin yóò dé bá wọn, ibẹ̀ ni wọn yóò kú sí.”
Kai, Angraeng mah lokthuih boeh; kai ih lok aek hanah nawnto amkhueng, kahoih ai hae kaminawk nuiah, hae hmuen hae ka sak tangtang han; nihcae loe hae praezaek ah amro o ueloe, dueh o tih, tiah a naa.
36 Àwọn ọkùnrin tí Mose rán láti yẹ ilẹ̀ wò, tí wọ́n sì mú gbogbo ìjọ kùn sí i nípa ìròyìn búburú tí wọ́n mú wá nípa ilẹ̀ náà;
To pongah prae khet hanah Mosi mah patoeh ih kaminawk amlaem o pacoengah, a khet o ih prae loe hoih ai, tiah amkhueng kaminawk hmaa ah laisaep thuih kaminawk,
37 Olúwa sì kọlu àwọn ọkùnrin tó mú ìròyìn búburú wá nípa ilẹ̀ náà, àjàkálẹ̀-ààrùn sì pa wọ́n níwájú Olúwa.
kanaan prae loe hoih ai tiah thui kaminawk loe, Angraeng hmaa ah kasae nathaih mah phak thuih moe, duek o.
38 Nínú gbogbo àwọn tó lọ yẹ ilẹ̀ náà wò, Joṣua ọmọ Nuni àti Kalebu ọmọ Jefunne ló yè é.
Prae khet han kacaeh kaminawk boih thungah, Nun capa Joshua hoi Jephunneh capa Kaleb hnik khue ni hing hoi.
39 Nígbà tí Mose sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọkún gidigidi.
To lok to Mosi mah Israel kaminawk khaeah thuih pae naah, kaminawk loe paroeai hangh o.
40 Wọ́n dìde ní àárọ̀ ọjọ́ kejì wọ́n sì gòkè lọ sí ìlú orí òkè, wọ́n wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀, àwa yóò lọ sí ibi tí Olúwa ṣèlérí fún wa.”
Khawnbang khawnthaw ah angthawk o moe, mae nuiah caeh o; khenah, a zae o boeh; toe Angraeng mah lokkam ih ahmuen ah caeh o si, tiah a thuih o.
41 Mose sì dá wọn lóhùn pé, “Kí ló dé tí ẹ fi ṣẹ̀ sí òfin Olúwa? Èyí kò le yọrí sí rere!
Toe Mosi mah, Tipongah vaihi Angraeng mah paek ih lok to na tahngai o ai loe? Hae tiah na sak o nahaeloe na qoeng o thai mak ai.
42 Ẹ má ṣe gòkè lọ nítorí pé Olúwa kò sí láàrín yín. Ki á má ba à lù yín bolẹ̀ níwájú àwọn ọ̀tá yín.
Nangcae khaeah Angraeng om ai pongah, caeh o tahang hmah; na caeh o nahaeloe misanawk to na pazawk o mak ai.
43 Nítorí pé àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani ń bẹ níwájú yín, ẹ̀yin yóò sì ti ipa idà ṣubú. Nítorí pé, ẹ ti yà kúrò ní ọ̀nà Olúwa, Olúwa kò sì ní í wà pẹ̀lú yín.”
Amalek hoi Kanaan kaminawk loe, nangcae hma ah oh o boeh pongah, nangcae loe sumsen hoiah na dueh o tih; nangcae mah Angraeng to nang qoi o taak boeh pongah, nangcae khaeah Angraeng om mak ai boeh, tiah a naa.
44 Síbẹ̀síbẹ̀, pẹ̀lú àìfarabalẹ̀ wọn, wọ́n gòkè lọ sórí òkè náà, láìjẹ́ pé àpótí ẹ̀rí Olúwa tàbí Mose kúrò nínú ibùdó.
Toe Mosi hoi Angraeng ih thingkhong loe, ataihaih ahmuen to caehtaak ai; toe nihcae loe palungthah o pongah, mae nuiah caeh o nganga.
45 Àwọn ará Amaleki àti àwọn ará Kenaani tó ń gbé lórí òkè sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n, wọ́n bá wọn jà, wọ́n sì lé wọn títí dé Horma.
To naah to mae nuiah kaom, Amalek hoi Kanaan kaminawk anghum o tathuk moe, Israel kaminawk to tuk o, nihcae to pazawk o pacoengah, Hormah vangpui khoek to patom o.

< Numbers 14 >